< Genesis 14 >

1 Ní àsìkò yìí ni Amrafeli ọba Ṣinari, Arioku ọba Ellasari, Kedorlaomeri ọba Elamu àti Tidali ọba Goyimu
Or, il arriva que pendant les règnes d'Amarphal, roi de Sennaar, et d'Arioch, roi d'Ellasar, Chodollogomor, roi d'Élam, et Thargal, roi des nations.
2 jáde lọ láti bá Bera ọba Sodomu, Birṣa ọba Gomorra, Ṣenabu ọba Adma, Ṣemeberi ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari) jagun.
Firent la guerre contre Balla, roi de Sodome, et Barsa, roi de Gomorrhe, et Sennaar, roi d'Adama, et Symobor, roi de Séboïm, et le roi de Balac (aujourd'hui Ségor).
3 Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí ni ó kó ogun wọn jọ pọ̀ sí àfonífojì Siddimu (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀).
Tous ces derniers se confédérèrent dans le vallon Salé (aujourd'hui mer des Sels).
4 Fún ọdún méjìlá gbáko ni wọ́n ti ń sin Kedorlaomeri bí ẹrú. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di ọdún kẹtàlá wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i.
Pendant douze ans ils avaient servi Chodollogomor; mais dans la treizième année ils se révoltèrent.
5 Ní ọdún kẹrìnlá, ni Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí wọ́n ti jọ ni májẹ̀mú àṣepọ̀ wá, wọ́n ṣígun, wọ́n sì ṣẹ́gun ará Refaimu ní Aṣteroti-Karnaimu, àwọn ará Susimu ni Hamu, àwọn ará Emimu ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kiriataimu,
Et, en la quatorzième année, Chodollogomor arriva avec les rois ses alliés; ils vainquirent les géants d'Asvaroth et de Carnaï, ainsi que les nations puissantes leurs alliées, et les Omméens de la ville de Savé,
6 àti àwọn ará Hori ní orí òkè wọ̀n-ọn-nì Seiri, títí ó fi dé Eli-Parani ní etí ijù.
Et les Horrhéens qui habitent les montagnes de Séir, jusqu'au térébinthe de Phara, dans le désert.
7 Wọ́n sì tún yípadà lọ sí En-Miṣpati (ti o túmọ̀ sí Kadeṣi), wọ́n sì ṣẹ́gun gbogbo ilẹ̀ àwọn Amaleki, àti àwọn ará Amori tí ó tẹ̀dó sí Hasason Tamari pẹ̀lú.
Puis, s'étant retournés, ils vinrent vers la fontaine du jugement, aujourd'hui Cadès, et ils vainquirent tous les chefs d'Amalec ainsi que les Amorrhéens qui habitent Asason-Thamar.
8 Nígbà náà ni ọba Sodomu, ọba Gomorra, ọba Adma, ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari), kó àwọn ọmọ-ogun wọn, wọ́n sì pa ibùdó ogun wọn sí Àfonífojì Siddimu,
Mais le roi de Sodome sortit, et avec lui le roi de Gomorrhe, le roi d'Adama, le roi de Séboïm, le roi de Balac, aujourd'hui Ségor, et ils se rangèrent en bataille dans le vallon Salé.
9 láti kojú ìjà sí Kedorlaomeri ọba Elamu, Tidali ọba Goyimu, Amrafeli ọba Ṣinari àti Arioku ọba Ellasari (ọba mẹ́rin kọjú ìjà sí ọba márùn-ún).
Contre Chodollogomor, roi d'Élam, Thargal, roi des nations, Amarphal, roi de Sennaar, et Arioch, roi d'Ellabar; cinq rois contre quatre.
10 Àfonífojì Siddimu sì kún fún kòtò ọ̀dà ilẹ̀, nígbà tí ọba Sodomu àti ọba Gomorra sì sá, díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin ogun náà ṣubú sínú àwọn kòtò náà, àwọn tókù sì sálọ sì orí òkè.
Or, le vallon Salé n'était que puits de bitume; bientôt le roi de Sodome s'enfuit avec le roi de Gomorrhe; ils furent vaincus, et ceux qui survécurent s'enfuirent dans les montagnes.
11 Àwọn ọba mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà sì kó gbogbo ẹrù Sodomu àti Gomorra àti oúnjẹ wọn; wọ́n sì lọ.
Les vainqueurs prirent tous les chevaux de ceux de Sodome, tous leurs vivres; et ils partirent.
12 Wọ́n sì mú Lọti ọmọ arákùnrin Abramu tí ń gbé ní Sodomu àti gbogbo ohun ìní rẹ̀.
Ils prirent aussi, avec tout son avoir, Lot, fils du frère d'Abram, car il habitait Sodome; et ils s'éloignèrent.
13 Ẹnìkan tí ó sá àsálà sì wá ròyìn fún Abramu, ará Heberu ni. Abramu sá ti tẹ̀dó sí ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre ará Amori, arákùnrin Eṣkolu àti Aneri: àwọn ẹni tí ó ń bá Abramu ní àṣepọ̀.
Or, l'un de ceux qui s'étaient sauvés, survenant, apprit ces choses à Abram, le passager sur cette terre, qui demeurait auprès du chêne de l'Amorrhéen Membré, frère d'Eschol, et frère d'Onan, tous alliés d'Abram.
14 Nígbà tí Abramu gbọ́ wí pé, a di Lọti ní ìgbèkùn, ó kó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí a bí sí ilẹ̀ rẹ̀ tí ó sì ti kọ́ ni ogun jíjà jáde, wọ́n jẹ́ okòó lé lọ́ọ̀dúnrún ó dín méjì ènìyàn, ó sì lépa wọn títí dé Dani.
Celui-ci, ayant appris que son neveu Lot était captif, compta ses serviteurs au nombre de trois cent dix-huit, et il poursuivit les ravisseurs jusqu'à Dan.
15 Ní ọ̀gànjọ́ òru, Abramu pín àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sí méjì, ó sì kọlù wọ́n, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì lé wọn títí dé Hoba tí ó wà ní apá òsì Damasku.
La nuit venue, il tomba sur eux, avec ses serviteurs, les battit, et les chassa jusqu'à Hoba, qui est à la gauche de Damas.
16 Gbogbo ìkógun ni ó rí gbà padà àti ọmọ arákùnrin rẹ̀, Lọti pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, àti àwọn obìnrin pẹ̀lú àwọn ènìyàn tókù.
Il ramena tous les chevaux de Sodome, Lot son neveu, tous ses serviteurs, les femmes, et le peuple.
17 Nígbà tí Abramu ti ṣẹ́gun Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí ó pẹ̀lú rẹ̀, ọba Sodomu lọ pàdé rẹ̀ ní àfonífojì Ṣafe (èyí ni àfonífojì Ọba).
Le roi de Sodome sortit alors à sa rencontre, après avoir échappé au carnage fait par Chodollogomor et les rois ses alliés, dans la vallée de Saby (c'était le champ de bataille des rois).
18 Melkisedeki ọba Salẹmu sì mú oúnjẹ àti ọtí wáìnì jáde wá. Òun ni àlùfáà Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo.
Et Melchisédech, roi de Salem (Jérusalem), offrit des pains et du vin; car il était prêtre du Dieu Très-Haut.
19 Ó sì súre fún Abramu, wí pé, “Ìbùkún ni fún Abramu ti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, Ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
Il bénit Abram, en disant: Béni soit Abram du Dieu Très-Haut qui a créé le ciel et la terre.
20 Ìbùkún sì ni fún Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ, tí ó fi àwọn ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́.” Abramu sì fún un ní ìdámẹ́wàá ohun gbogbo.
Béni soit le Dieu Très -Haut qui t'a soumis tes ennemis. Et Abram lui donna la dîme de toutes choses.
21 Ọba Sodomu sì wí fún Abramu pé, “Kó àwọn ènìyàn mi fún mi, ṣùgbọ́n mú àwọn ẹrù fún ara rẹ.”
Le roi de Sodome dit à Abram: Donne-moi les hommes, et prends pour toi les chevaux.
22 Ṣùgbọ́n Abramu dá ọba Sodomu lóhùn pé, “Mo ti búra fún Olúwa, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ó dá ọ̀run àti ayé, mo sì ti gbọ́wọ́ sókè,
Abram dit au roi de Sodome: J'étendrai la main vers le Seigneur Dieu, le Très-Haut qui a créé le ciel et la terre,
23 pé, èmi kì yóò mú láti fọ́nrán òwú títí dé okùn bàtà, àti pé, èmi kí yóò mú ohun kan tí ṣe tìrẹ, kí ìwọ kí ó má ba à wí pé, ‘Mo sọ Abramu di ọlọ́rọ̀.’
Pour attester que je ne veux pour moi rien de ce qui t'appartient, depuis la corde jusqu'à la courroie de la sandale, de peur que tu ne puisses dire: J'ai enrichi Abram.
24 Èmi kì yóò gba ohunkóhun yàtọ̀ sí ohun tí àwọn ọkùnrin mi ti jẹ́, ṣùgbọ́n fi ìpín fún àwọn ọkùnrin tí ó bá mi lọ, Aneri, Eṣkolu àti Mamre. Jẹ́ kí wọn kí ó gba ìpín wọn.”
J'excepte ce que les jeunes gens ont mangé, et la part de mes alliés Eschol, Onan et Membré, qui prendront ce qui leur revient.

< Genesis 14 >