< Genesis 12 >

1 Olúwa sì wí fún Abramu, “Jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ àti kúrò lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ, lọ sí ilẹ̀ kan tí èmi yóò fihàn ọ́.
Then the LORde sayd vnto Abra Gett the out of thy contre and from thy kynred and out of thy fathers house into a londe which I wyll shewe the.
2 “Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, èmi yóò sì bùkún fún ọ; èmi yóò sọ orúkọ rẹ di ńlá, ìbùkún ni ìwọ yóò sì jásí.
And I wyll make of the a myghtie people and wyll blesse the and make thy name grete that thou mayst be a blessinge.
3 Èmi yóò bùkún fún àwọn tí ó súre fún ọ, ẹni tí ó fi ọ́ ré ni Èmi yóò fi ré; nínú rẹ ni a ó bùkún gbogbo ìdílé ayé.”
And I wyll blesse the that blesse the ad curse the that curse the. And in the shall be blessed all the generations of the erth.
4 Bẹ́ẹ̀ ni Abramu lọ bí Olúwa ti sọ fún un. Lọti náà sì bá a lọ. Abramu jẹ́ ẹni àrùndínlọ́gọ́rin ọdún nígbà tí ó jáde kúrò ní Harani.
And Abram wet as the LORde badd hym and Lot went wyth him. Abram was. lxxv. yere olde when he went out of Haran.
5 Abramu sì mú Sarai aya rẹ̀, àti Lọti ọmọ arákùnrin rẹ̀: gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti kójọ àti àwọn ènìyàn tí wọ́n ní ní Harani. Wọ́n sì jáde lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Wọ́n sì gúnlẹ̀ síbẹ̀.
And Abram toke Sarai his wyfe ad Lot his brothers sonne wyth all their goodes which they had goten and soulles which they had begoten in Haran. And they departed to goo in to the lade of Chanaan. And when they were come in to the lande of Chanaan
6 Abramu sì rìn la ilẹ̀ náà já títí dé ibi igi ńlá kan tí à ń pè ni More ní Ṣekemu. Àwọn ará Kenaani sì wà ní ilẹ̀ náà.
Abram went furth in to the lade tyll he came vnto a place called Sychem and vnto the oke of More. And the Canaanytes dwelled then in the lande.
7 Olúwa sì farahan Abramu, ó sì wí fún un pé, “Irú-ọmọ rẹ ni Èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún.” Abramu tẹ́ pẹpẹ kan síbẹ̀ fún Olúwa tí ó fi ara hàn án.
Then the LORde apeared vnto Abram ad sayd: vnto thy seed wyll I geue thys lade. And he buylded an aultere there vnto the LORDE which apeared to hym.
8 Ó sì kúrò níbẹ̀ lọ sí agbègbè àwọn òkè kan ní ìhà ìlà-oòrùn Beteli, ó sì pàgọ́ rẹ̀ síbẹ̀. Beteli wà ní ìwọ̀-oòrùn, Ai wà ní ìlà-oòrùn. Ó tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ fún Olúwa, ó sì ké pe orúkọ Olúwa.
Then departed he thence vnto a mountayne that lyeth on the east syde of BETHEL and pytched hys tente: BETHEL beynge on the west syde and Ay on the east: And he buylded there an aulter vnto the LORde and called on the name of ye LORde.
9 Nígbà náà ni Abramu tẹ̀síwájú sí ìhà gúúsù.
And than Abram departed and toke his iourney southwarde
10 Ìyàn kan sì mú ní ilẹ̀ náà, Abramu sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti ṣe àtìpó níbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, nítorí ìyàn náà mú gidigidi.
After thys there came a derth in the lande. And Abram went doune in to Egipte to soiourne there for the derth was sore in the lande.
11 Bí ó ti ku díẹ̀ kí ó wọ Ejibiti, ó wí fún Sarai, aya rẹ̀ pé, “Mo mọ̀ pé arẹwà obìnrin ni ìwọ,
And when he was come nye for to entre in to Egipte he sayd vnto sarai his wife. Beholde I knowe that thou art a fayre woman to loke apo.
12 nígbà tí àwọn ará Ejibiti bá rí ọ, wọn yóò wí pé, ‘Aya rẹ̀ nìyí.’ Wọn yóò si pa mí, ṣùgbọ́n wọn yóò dá ọ sí.
It wyll come to passe therfore whe the Egiptians see the that they wyll say: she is his wyfe. And so shall they sley me and save the.
13 Nítorí náà, sọ pé, arábìnrin mi ni ìwọ, wọn yóò sì ṣe mí dáradára, a ó sì dá ẹ̀mí mi sí nítorí tìrẹ.”
saye I praye the therfore that thou art my sister that I maye fare the better by reason of the and that my soule maye lyue for thy sake.
14 Nígbà tí Abramu dé Ejibiti, àwọn ará Ejibiti ri i pé aya rẹ̀ rẹwà gidigidi.
As soone as he came in to Egipte the Egiptias sawe the woman that she was very fayre.
15 Nígbà tí àwọn ìjòyè Farao sì rí i, wọ́n ròyìn rẹ̀ níwájú Farao, wọ́n sì mú un lọ sí ààfin.
And Pharaos lordes sawe hir also and praysed hir vnto Pharao: So that she was taken in to Pharaos house
16 Ó sì kẹ́ Abramu dáradára nítorí Sarai, Abramu sì ní àgùntàn àti màlúù, akọ àti abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin, pẹ̀lú ìbákasẹ.
which entreated Abram well for hir sake so that he had shepe oxsen ad he asses men seruantes mayde seruates she asses and camels.
17 Olúwa sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn búburú sí Farao àti ilé rẹ̀, nítorí Sarai aya Abramu.
But God plaged Pharao and his house wyth grete plages because of Sarai Abrams wyfe.
18 Nítorí náà Farao ránṣẹ́ pe Abramu, ó sì wí fun pé, “Èwo ni ìwọ ṣe sí mi yìí? Kí ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé aya rẹ ní í ṣe?
Then Pharao called Abram and sayd: why hast thou thus dealt with me? Wherfore toldest thou me not that she was thy wyfe?
19 Èéṣe tí o fi wí pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ tí èmi sì fi fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí aya? Nítorí náà nísinsin yìí, aya rẹ náà nìyí, mú un kí o sì máa lọ.”
Why saydest thou that she was thy sister and causedest me to take hyr to my wyfe? But now loo there is the wife take hir ad be walkynge.
20 Nígbà náà ni Farao pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ nípa Abramu, wọ́n sì lé e jáde ti òun ti aya rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní.
Pharao also gaue a charge vnto his men over Abram to leade hym out wyth his wyfe and all that he had.

< Genesis 12 >