< Ezra 6 >

1 Nígbà náà ni ọba Dariusi pàṣẹ, wọ́n sì wá inú ilé ìfí nǹkan pamọ́ sí ní ilé ìṣúra ní Babeli.
Wtedy król Dariusz rozkazał, aby szukano w archiwum, gdzie przechowywano skarby w Babilonie.
2 A rí ìwé kíká kan ní Ekbatana ibi kíkó ìwé sí ní ilé olódi agbègbè Media, wọ̀nyí ni ohun tí a kọ sínú rẹ̀. Ìwé ìrántí.
I znaleziono w Achmecie, w pałacu w prowincji Medii, pewien zwój, w którym tak było napisane:
3 Ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba ọba Kirusi, ọba pa àṣẹ kan nípa tẹmpili Ọlọ́run ní Jerusalẹmu. Jẹ́ kí a tún tẹmpili ibi tí a ti ń rú onírúurú ẹbọ kọ́, kí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ ni gíga àti fífẹ̀ rẹ̀ jẹ́ àádọ́rùn-ún ẹsẹ̀ bàtà,
W pierwszym roku króla Cyrusa, król Cyrus wydał dekret w sprawie domu Bożego w Jerozolimie: Dom ten ma być odbudowany, to miejsce, gdzie składano ofiary. Fundamenty mają być położone. Jego wysokość – sześćdziesiąt łokci i jego szerokość – sześćdziesiąt łokci.
4 pẹ̀lú ipele òkúta ńlá ńlá mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ àti ipele pákó kan, kí a san owó rẹ̀ láti inú ilé ìṣúra ọba.
Trzy rzędy z kamienia wielkiego i jeden rząd z nowego drewna. Koszty ma pokryć dom królewski.
5 Sì jẹ́ kí wúrà àti àwọn ohun èlò fàdákà ti ilé Ọlọ́run, tí Nebukadnessari kó láti ilé Olúwa ní Jerusalẹmu tí ó sì kó lọ sí Babeli, di dídápadà sí ààyè wọn nínú tẹmpili ní Jerusalẹmu; kí a kó wọn sí inú ilé Ọlọ́run.
Ponadto złote i srebrne naczynia z domu Bożego, które zabrał Nabuchodonozor ze świątyni w Jerozolimie i przeniósł do Babilonu, mają być zwrócone i przeniesione do świątyni w Jerozolimie na swoje miejsce, i złożone w domu Bożym.
6 Nítorí náà, kí ìwọ, Tatenai baálẹ̀ agbègbè Eufurate àti Ṣetar-bosnai àti àwọn ẹlẹgbẹ́ yín, àwọn ìjòyè ti agbègbè náà kúrò níbẹ̀.
Teraz więc ty, Tattenaju, namiestniku zarzecza, Szetarboznaju, [i] wy, Afarsachajczycy, ich towarzysze, którzy jesteście za rzeką, trzymajcie się z dala od tego miejsca.
7 Ẹ fi iṣẹ́ ilé Ọlọ́run yìí lọ́rùn sílẹ̀ láì dí i lọ́wọ́. Ẹ jẹ́ kí baálẹ̀ àwọn Júù àti àwọn àgbàgbà Júù tún ilé Ọlọ́run yín kọ́ sí ipò rẹ̀.
Zostawcie w spokoju prace nad tym domem Bożym. Niech namiestnik Żydów i starsi żydowscy odbudują ten dom Boży na swoim miejscu.
8 Síwájú sí i, mo pàṣẹ ohun tí ẹ gbọdọ̀ ṣe fún àwọn àgbàgbà Júù wọ̀nyí lórí kíkọ́ ilé Ọlọ́run yìí. Gbogbo ìnáwó àwọn ọkùnrin yìí ni kí ẹ san lẹ́kùnrẹ́rẹ́ lára ìṣúra ti ọba, láti ibi àkójọpọ̀ owó ìlú ti agbègbè Eufurate kí iṣẹ́ náà má bà dúró.
Wydaję też dekret o tym, co macie uczynić dla starszych spośród Żydów na budowę tego domu Bożego, mianowicie: koszty mają być bezzwłocznie wypłacone tym ludziom z dochodów króla, z danin [pobieranych] za rzeką, aby nie przestawali [budować].
9 Ohunkóhun tí wọ́n bá fẹ́—àwọn ọ̀dọ́ akọ màlúù, àwọn àgbò, ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun sí Ọlọ́run ọ̀run, àti jéró, iyọ̀, wáìnì àti òróró, bí àwọn àlùfáà ní Jerusalẹmu ti béèrè ni ẹ gbọdọ̀ fún wọn lójoojúmọ́ láìyẹ̀.
Także i to, co będzie potrzebne do całopaleń dla Boga niebios: cielce, barany i jagnięta oraz pszenica, sól, wino i oliwa, według rozkazu kapłanów w Jerozolimie, niech im będzie dawane każdego dnia bez zaniedbania;
10 Kí wọn lè rú àwọn ẹbọ tí ó tẹ́ Ọlọ́run ọ̀run lọ́rùn kí wọ́n sì gbàdúrà fún àlàáfíà ọba àti àwọn ọmọ rẹ̀.
Aby mogli składać wonne ofiary Bogu niebios i aby modlili się za życie króla i jego synów.
11 Síwájú sí i, mo pàṣẹ pé tí ẹnikẹ́ni bá yí àṣẹ yìí padà, kí fa igi àjà ilé rẹ̀ yọ jáde, kí a sì gbe dúró, kí a sì fi òun náà kọ́ sí orí rẹ̀ kí ó wo ilé rẹ̀ palẹ̀ a ó sì sọ ọ́ di ààtàn.
Ponadto wydaję taki dekret: Ktokolwiek zmieni ten rozkaz, to belka z jego domu ma być wyrwana i podniesiona, a on będzie na niej powieszony; jego dom zaś zostanie zamieniony w gnojowisko.
12 Kí Ọlọ́run, tí ó ti jẹ́ kí orúkọ rẹ̀ máa gbé ibẹ̀, kí ó pa gbogbo ọba àti orílẹ̀-èdè rún tí ó bá gbé ọwọ́ sókè láti yí àṣẹ yìí padà tàbí láti wó tẹmpili yìí tí ó wà ní Jerusalẹmu run. Èmi Dariusi n pàṣẹ rẹ̀, jẹ́ kí ó di mímúṣẹ láìyí ohunkóhun padà.
A Bóg, który uczynił tam mieszkanie dla swojego imienia, niech zniszczy każdego króla i [każdy] naród, który by się odważył zmienić [ten rozkaz] i zniszczyć ten dom Boży w Jerozolimie. Ja, Dariusz, wydałem ten dekret; niech będzie wykonany bezzwłocznie.
13 Nígbà náà, nítorí àṣẹ tí ọba Dariusi pa, Tatenai, baálẹ̀ ti agbègbè Eufurate, àti Ṣetar-bosnai pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn pa á mọ́ láìyí ọ̀kan padà.
Wtedy Tattenaj, namiestnik zarzecza, Szetarboznaj i ich towarzysze niezwłocznie uczynili tak, jak król Dariusz rozkazał.
14 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà Júù tẹ̀síwájú wọ́n sì ń gbèrú sí i lábẹ́ ìwàásù wòlíì Hagai àti wòlíì Sekariah, ìran Iddo. Wọ́n parí kíkọ́ ilé Olúwa gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Ọlọ́run Israẹli àti àwọn àṣẹ Kirusi, Dariusi àti Artasasta àwọn ọba Persia pọ̀.
A starsi żydowscy budowali i szczęściło im się według proroctwa Aggeusza, proroka, i Zachariasza, syna Iddo. Budowali i dokończyli [dom] zgodnie z rozkazem Boga Izraela oraz z rozkazem Cyrusa, Dariusza oraz Artakserksesa, króla Persji.
15 A parí ilé Olúwa ní ọjọ́ kẹta, oṣù Addari tí í se oṣù kejì ní ọdún kẹfà ti ìjọba ọba Dariusi.
I ten dom został zakończony w trzecim dniu miesiąca Adar, w szóstym roku panowania króla Dariusza.
16 Nígbà náà ni àwọn ènìyàn Israẹli—àwọn àlùfáà, àwọn Lefi àti àwọn ìgbèkùn tí ó padà, ṣe ayẹyẹ yíya ilé Ọlọ́run sí mímọ́ pẹ̀lú ayọ̀.
Wówczas synowie Izraela, kapłani, Lewici oraz reszta ludu, który powrócił z niewoli, z radością obchodzili poświęcenie tego domu Bożego.
17 Fún yíya ilé Ọlọ́run yìí sí mímọ́, wọ́n pa ọgọ́rùn-ún akọ màlúù, igba àgbò àti irinwó akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, àti gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo Israẹli, àgbò méjìlá, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún olúkúlùkù àwọn ẹ̀yà Israẹli.
I złożyli ofiary przy poświęcaniu tego domu Bożego: sto cielców, dwieście baranów, czterysta jagniąt, a jako ofiarę za grzech za całego Izraela – dwanaście kozłów, według liczby pokoleń Izraela.
18 Wọ́n sì fi àwọn àlùfáà sí àwọn ìpín wọ́n àti àwọn Lefi sì ẹgbẹẹgbẹ́ wọn fún ìsin ti Ọlọ́run ní Jerusalẹmu, gẹ́gẹ́ bí ohun tí a kọ sínú ìwé Mose.
Do służby Bożej w Jerozolimie ustanowili kapłanów – według ich oddziałów, i Lewitów – według ich zmian, jak jest napisane w księdze Mojżesza.
19 Ní ọjọ́ kẹrìnlá ti oṣù Nisani, àwọn tí a kó ní ìgbèkùn ṣe ayẹyẹ àjọ ìrékọjá.
Ci, którzy powrócili z niewoli, obchodzili też Paschę w czternastym [dniu] pierwszego miesiąca.
20 Àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì jẹ́ mímọ́. Àwọn ará Lefi pa ọ̀dọ́-àgùntàn ti àjọ ìrékọjá fún gbogbo àwọn tí a kó ní ìgbèkùn, fún àwọn àlùfáà arákùnrin wọn àti fún ara wọn.
Kapłani bowiem i Lewici oczyścili się jak jeden mąż, wszyscy byli oczyszczeni. Zabili więc [baranka] paschalnego dla wszystkich, którzy przybyli z niewoli, dla swoich braci kapłanów i dla siebie samych.
21 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Israẹli tí ó ti dé láti ìgbèkùn jẹ ẹ́ lápapọ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ti ya ara wọn kúrò nínú gbogbo iṣẹ́ àìmọ́ ti àwọn kèfèrí aládùúgbò wọn láti wá Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
I spożywali to synowie Izraela, którzy powrócili z niewoli, i każdy, kto odłączył się od nieczystości pogan tej ziemi i [przyłączył się] do nich, aby szukać PANA, Boga Izraela.
22 Fún ọjọ́ méje, wọ́n ṣe ayẹyẹ àkàrà àìwú pẹ̀lú àjẹtì àkàrà. Nítorí tí Olúwa ti kún wọn pẹ̀lú ayọ̀ nípa yíyí ọkàn ọba Asiria padà, tí ó fi ràn wọ́n lọ́wọ́ lórí iṣẹ́ ilé Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.
Przez siedem dni z radością obchodzili też Święto Przaśników, gdyż PAN napełnił ich radością i zwrócił ku nim serce króla Asyrii, aby wzmocnił ich ręce przy pracy [wokół] domu Bożego, Boga Izraela.

< Ezra 6 >