< Ezekiel 39 >

1 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí Gogu, kí ó sì wí pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, Ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé ti Meṣeki àti Tubali.
" Et toi, fils de l'homme, prophétise contre Gog et dis: Ainsi parle le Seigneur Yahweh: Voici que je viens à toi, Gog, prince souverain de Mosoch et de Thubal.
2 Èmi yóò dá ọ padà, èmi yóò sì darí rẹ. Èmi yóò mú ọ wá láti jìnnàjìnnà ìhà àríwá, Èmi yóò rán ọ lòdì sí orí àwọn òkè gíga Israẹli.
Je t'emmènerai, je te conduirai et je te ferai monter des confins du septentrion, et je t'amènerai sur les montagnes d'Israël.
3 Nígbà náà èmi yóò lu ọrùn awọ rẹ ní ọwọ́ òsì rẹ, èmi yóò sì mú kí àwọn ọfà rẹ jábọ́ ni ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
Là j'abattrai ton arc de ta main gauche, et je ferai tomber tes flèches de ta main droite.
4 Ìwọ yóò sì ṣubú ní orí àwọn òkè Israẹli, ìwọ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn onírúurú ẹyẹ àti fún àwọn ẹranko igbó.
Tu tomberas sur les montagnes d'Israël, toi et tous tes bataillons, et les peuples qui seront avec toi; aux oiseaux de proie, aux oiseaux de toute sorte, et aux animaux des champs je t'ai donné en pâture.
5 Ìwọ yóò ṣubú ní gbangba pápá, nítorí tì mo ti sọ̀rọ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Tu tomberas sur la face des champs, car moi j'ai parlé, — oracle du Seigneur Yahweh.
6 Èmi yóò fi iná sí Magogu àti sí àwọn tí ń gbé ní agbègbè ilẹ̀ ibẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
J'enverrai le feu dans le pays de Magog et chez ceux qui habitent en sécurité dans les îles, et ils sauront que je suis Yahweh.
7 “‘Èmi yóò sọ orúkọ mímọ́ mí di mí mọ̀ láàrín àwọn ènìyàn mì Israẹli. Èmi ki yóò jẹ́ kí orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́ àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa, Èmi ni ẹni mímọ́ ní Israẹli.
Et je ferai connaître mon saint nom au milieu de mon peuple d'Israël, et je ne profanerai plus mon saint nom; et les nations sauront que je suis Yahweh, saint en Israël.
8 Ó ń bọ̀! Ó dájú pé yóò ṣẹlẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè. Èyí yìí ni ọjọ́ tí mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.
Ces choses viennent et elles s'accompliront, — oracle du Seigneur Yahweh; c'est là le jour dont j'ai parlé!
9 “‘Nígbà náà, àwọn ti ó ń gbé nì àárín àwọn ìlú tí ó wà ni Israẹli yóò jáde, wọn yóò sì lo àwọn ohun ìjà bi epo ìdáná yóò sì jó wọ́n kanlẹ̀—àpáta kéékèèké àti àpáta ńlá, àwọn ọfà, àwọn kùmọ̀ ogun àti ọ̀kọ̀ fún ọdún méje wọn yóò lò wọ́n bi epo ìdáná.
Alors les habitants des villes d'Israël sortiront; ils brûleront et mettront en flammes les armes, l'écu, le bouclier, l'arc, les flèches, le bâton et le javelot; ils en feront du feu pendant sept ans.
10 Wọn kò ní nílò láti kó igi jọ láti inú pápá, tàbí gé e láti inú igbó, nítorí pé wọ́n yóò lo òhun ìjà ogun bi epo ìdáná. Wọn yóò sì kógun àwọn tí ó ṣe ìgárá sí wọn, wọn yóò sì bo ilé àwọn tí ó bo ilé wọn, ni Olúwa Olódùmarè.
Ils n'apporteront plus le bois de la campagne, et ils n'en couperont point dans les forêts; car c'est avec les armes qu'ils feront du feu; ils dépouilleront ceux qui les dépouillaient, ils pilleront ceux qui les pillaient, — oracle du Seigneur Yahweh.
11 “‘Ní ọjọ́ náà èmi yóò sì fi ibi ìsìnkú fún Gogu ní Israẹli, ni àfonífojì àwọn ti ó rìn ìrìnàjò lọ sí agbègbè ilà oòrùn Òkun. Yóò di ojú ọ̀nà àwọn arìnrìn-àjò, nítorí Gogu àti gbogbo ìjọ rẹ̀ ni àwa yóò sin síbẹ̀. Nítorí náà, a yóò pè é ní àfonífojì tí Ammoni Gogu.
Et il arrivera en ce jour-là: Je donnerai à Gog un lieu où sera son sépulcre en Israël, la vallée des Passants, à l'orient de la mer; et ce sépulcre fermera le chemin aux passants. C'est là qu'on enterrera Gog et toute sa multitude, et on appellera ce lieu la vallée d'Hamon-Gog.
12 “‘Fún oṣù méje ní ilé Israẹli yóò fi máa sìn wọ́n láti ṣe àfọ̀mọ́ ilẹ̀ náà.
La maison d'Israël les enterrera, afin de purifier le pays, sept mois durant.
13 Gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà yóò sìn wọ́n, ọjọ́ tí a yìn mi lógo yóò jẹ́ ọjọ́ ìrántí, ní Olúwa Olódùmarè wí.
Tout le peuple du pays enterrera, et ce sera pour eux un jour glorieux; celui où j'aurai fait éclater ma gloire, — oracle du Seigneur Yahweh.
14 “‘Wọn yóò gbà àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ lóòrèkóòrè láti ṣe àfọ̀mọ́ náà. Ọ̀pọ̀ yóò lọ káàkiri ilẹ̀ náà, ní àfikún pẹ̀lú wọn, àwọn tókù yóò sìn àwọn tí ó kú lórí ilẹ̀. Ní ìparí oṣù keje wọn yóò bẹ̀rẹ̀ wíwá kiri wọn.
Et ils désigneront des hommes dont la charge sera de parcourir le pays, enterrant les passants, ceux qui seront restés sur la face de la terre, — pour la purifier; après sept mois ils feront leurs recherches.
15 Bí wọ́n n lọ káàkiri ilẹ̀ náà ọ̀kan nínú wọn rí egungun ènìyàn, òun yóò gbé àmì ńlá kalẹ̀ ni ẹ̀gbẹ́ rẹ títí àwọn asìnkú yóò fi sìn ín ní àfonífojì Hamoni Gogu.
Et quand ces hommes parcourront le pays, si l'un d'eux voit des ossements humains, il dressera à coté un signal, jusqu'à ce que les enterreurs les aient mis en terre dans la vallée d'Hamon-Gog.
16 Bákan náà ìlú kan tí a ń pè ni Hamona yóò wà níbẹ̀. Nítorí náà wọn yóò wẹ ilẹ̀ náà.’
Et Hamona sera même le nom d'une ville; et c'est ainsi qu'ils purifieront le pays.
17 “Ọmọ ènìyàn èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí pé, pe gbogbo oríṣìíríṣìí ẹyẹ àti gbogbo àwọn ẹranko igbó jáde, ‘Kí wọn péjọpọ̀ láti gbogbo agbègbè sí ìrúbọ tí mó ń múra rẹ̀ fún ọ, ìrúbọ ńlá náà ní orí òkè gíga tí Israẹli. Níbẹ̀ ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀.
Et toi, fils de l'homme, ainsi parle le Seigneur Yahweh: Dis aux oiseaux de toute sorte, et à tous les animaux des champs: Assemblez-vous et venez! Réunissez-vous des alentours à mon sacrifice que je fais pour vous, un grand sacrifice sur les montagnes d'Israël; vous mangerez de la chair et vous boirez du sang.
18 Ẹ̀yin yóò jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn ńlá, ẹ o sì mú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ-aládé ayé bí ẹni pé wọn jẹ́ àgbò àti ọ̀dọ́-àgùntàn, ewúrẹ́ àti akọ màlúù gbogbo wọn jẹ́ ẹran ọlọ́ràá láti Baṣani.
C'est de la chair de héros que vous mangerez, c'est du sang de princes de la terre que vous boirez, béliers, agneaux et boucs, jeunes taureaux, bœufs gras de Basan tous ensemble.
19 Níbi ìrúbọ tí mo ń múra kalẹ̀ fún yín, ẹ̀yin yóò jẹ ọ̀rá títí ẹ̀yin yóò fi jẹ àjẹkì, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ títí ẹ̀yin yóò fi yó.
Vous mangerez de la graisse à satiété, vous boirez du sang jusqu'à l'ivresse, à mon sacrifice que j'ai fait pour vous.
20 Ní orí tábìlì mi ni àwa yóò ti fi ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin bọ yín yó, pẹ̀lú àwọn alágbára ńlá àti oríṣìíríṣìí jagunjagun,’ ni Olúwa Olódùmarè wí.
Vous vous rassasierez à ma table de coursiers et de cavaliers, de héros et de guerriers de toute sorte, — oracle du Seigneur Yahweh.
21 “Èmi yóò ṣe àfihàn ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì rí ìyà tí mo fi jẹ wọ́n.
Je manifesterai ma gloire parmi les nations, et toutes les nations verront mon jugement que j'exécuterai; et ma main que j'étendrai sur eux.
22 Láti ọjọ́ náà lọ, ilé Israẹli yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.
Et la maison d'Israël saura que je suis Yahweh, son Dieu, dès ce jour et à l'avenir:
23 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì mọ̀ pé àwọn ènìyàn Israẹli lọ sí ìgbèkùn nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, nítorí pé wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí mi. Nítorí náà mo mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, mo sì fi wọn lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, gbogbo wọn sì ṣubú nípasẹ̀ idà.
et les nations sauront que c'est à cause de son iniquité que la maison d'Israël a été menée en exil, parce qu'ils m'ont été infidèles; aussi je leur ai caché ma face, je les ai livrés aux mains de leurs ennemis, afin qu'ils tombassent tous par l'épée.
24 Mo ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí àìmọ́ àti àìṣedéédéé wọn, mo sì mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
C'est en raison de leur souillure et de leur prévarication que je les ai traités ainsi et que je leur ai caché ma face.
25 “Nítorí náà èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Jakọbu padà kúrò ní oko ẹrú, èmi yóò ní ìyọ́nú si gbogbo ènìyàn Israẹli, èmi yóò sì ní ìtara fún orúkọ mímọ́ mi.
C'est pourquoi ainsi parle le Seigneur Yahweh: Maintenant, je ramènerai les captifs de Jacob, j'aurai compassion de toute la maison d'Israël, et je me montrerai jaloux de mon nom.
26 Wọn yóò gbàgbé ìtìjú wọn àti gbogbo àìṣòdodo tí wọ́n fihàn sí mi nígbà tí wọn ń gbé ni àìléwu ni ilẹ̀ wọn níbi tí kò ti sí ẹnikẹ́ni láti dẹ́rùbà wọ́n.
Ils porteront leur ignominie, et toutes les infidélités qu'ils ont commises envers moi, quand ils habiteront sur leur terre en sécurité, sans que personne les inquiète.
27 Nígbà tí mo ti mú wọn padà kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì kó wọn jọ pọ̀ kúrò ni ìlú àwọn ọ̀tá wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ wọn ní ojú àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀.
Quand je les ramènerai d'entre les peuples, que je les rassemblerai des pays de leurs ennemis et que je me serai sanctifié en eux, aux yeux de beaucoup de nations,
28 Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn nítorí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo rán wọn lọ sí ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò kó wọn jọ sí orí ilẹ̀ wọn, láìfi nǹkan kan sẹ́yìn.
ils sauront que je suis Yahweh, leur Dieu, en ce que je les aurai emmenés captifs chez les nations, et rassemblés ensuite sur leur propre sol; et je ne laisserai plus aucun d'eux là-bas.
29 Èmi kì yóò sì fi ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn mọ nítorí èmi yóò tú èémí mi jáde sí ilé Israẹli, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
Et je ne leur cacherai plus ma face, parce que j'aurai répandu mon Esprit sur la maison d'Israël, — oracle du Seigneur Yahweh. "

< Ezekiel 39 >