< Ezekiel 29 >

1 Ní ọjọ́ kejìlá, oṣù kẹwàá, ọdún kẹwàá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
W dziesiątym roku, dziesiątego [miesiąca], dwunastego [dnia] tego miesiąca doszło do mnie słowo PANA mówiące:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọjú sí Farao ọba Ejibiti kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí i àti sí gbogbo Ejibiti.
Synu człowieczy, zwróć swoją twarz przeciwko faraonowi, królowi Egiptu, i prorokuj przeciw niemu i całemu Egiptowi.
3 Sọ̀rọ̀, kí ó sì wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi lòdì sí ọ, Farao ọba Ejibiti ìwọ ẹ̀mí búburú ńlá inú òkun tí ó dùbúlẹ̀ sí àárín àwọn odò ṣíṣàn rẹ. Èyí tí ó sọ wí pé, “Tèmi ni odò Naili; èmi ni ó sì ṣe é fún ara mi.”
Przemów i powiedz: Tak mówi Pan BÓG: Oto [jestem] przeciwko tobie, faraonie, królu Egiptu, wielki smoku leżący wśród swoich rzek, który mówisz: Moja jest rzeka, ja [ją] sobie uczyniłem.
4 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ìwọ̀ mú ẹnu rẹ èmi yóò sì mú ẹja inú odò rẹ gbogbo lẹ̀ mọ́ ìpẹ́ ara rẹ. Èmi yóò fà ọ́ síta kúrò láàrín àwọn odò rẹ, àti gbogbo ẹja odò rẹ yóò lẹ̀ mọ́ ìpẹ́ ara rẹ.
Dlatego włożę haki w twoje szczęki i sprawię, że ryby twoich rzek przylgną do twoich łusek. Wyciągnę cię spośród twoich rzek i wszystkie ryby twoich rzek przylgną do twoich łusek.
5 Èmi yóò sọ ọ́ nù sí aginjù ìwọ àti gbogbo ẹja inú odò rẹ: ìwọ yóò ṣubú sí gbangba oko a kì yóò sì ṣà ọ́ jọ tàbí gbé ọ sókè. Èmi ti fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn ẹranko igbó àti fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run láti jẹ.
I zostawię cię na pustyni, ciebie i wszystkie ryby twoich rzek. Upadniesz na otwartym polu i nie będziesz zebrany ani zgromadzony. Dam cię na pożarcie zwierzętom ziemi i ptactwu nieba.
6 Nígbà náà gbogbo àwọn olùgbé ni Ejibiti yóò mọ pé, Èmi ni Olúwa. “‘Ìwọ ti jẹ́ ọ̀pá ìyè fún ilé Israẹli.
I poznają wszyscy mieszkańcy Egiptu, że ja jestem PANEM, ponieważ byłeś laską z trzciny dla domu Izraela.
7 Nígbà tí wọn fi ọwọ́ agbára wọn dì ọ́ mú. Ìwọ fọ́, ìwọ sì ya gbogbo èjìká wọn; nígbà tí wọn fi ara tì ọ́, ìwọ sẹ́, ìwọ sì mú gbogbo ẹ̀gbẹ́ wọn gbọ̀n.
Gdy chwytali się ciebie ręką, łamałeś się i rozcinałeś im całe ramię. Gdy się opierali na tobie, kruszyłeś się i unieruchamiałeś im wszystkie biodra.
8 “‘Nítorí náà, èyí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi, Èmi yóò mú idà kan wá sórí rẹ tí yóò sì gé ènìyàn àti ẹran kúrò nínú rẹ.
Dlatego tak mówi Pan BÓG: Oto sprowadzę na ciebie miecz i wytracę z ciebie człowieka i zwierzę.
9 Ilẹ̀ Ejibiti yóò di aginjù àti ahoro, nígbà náà ní wọn yóò sì mọ̀ wí pé èmi ní Olúwa. “‘Nítorí tí ìwọ wí pé, “Tèmi ni odò Naili, Èmi ni mo ṣe é,”
A ziemia Egiptu będzie spustoszeniem i pustkowiem; i poznają, że ja jestem PANEM, ponieważ mówiłeś: Moja jest rzeka, ja [ją] sobie uczyniłem.
10 nítorí náà, mo lòdì sí ọ àti sí àwọn odò rẹ, èmi yóò sì mú kí ilẹ̀ Ejibiti di píparun àti ahoro, pátápátá, láti Migdoli lọ dé Siene, dé ààlà ilẹ̀ Kuṣi.
Dlatego oto ja będę przeciwko tobie i przeciwko twojej rzece i zamienię ziemię Egiptu w straszną ruinę i spustoszenie, od wieży Sewene aż do granic Etiopii.
11 Kò sí ẹsẹ̀ ènìyàn tàbí tí ẹranko tí yóò gba ibẹ̀ kọjá; ẹni kankan kò ní gbé ibẹ̀ fún ogójì ọdún.
Nie przejdzie przez nią noga człowieka ani też nie przejdzie przez nią noga zwierzęcia, i nie będzie zamieszkana przez czterdzieści lat.
12 Èmi yóò sọ ilẹ̀ Ejibiti di ọ̀kan ní àárín àwọn ìlú tí ó di ahoro, fún ogójì ọdún, Èmi yóò sì fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sáàárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sáàárín gbogbo ilẹ̀.
I uczynię z ziemi Egiptu pustkowie pośród spustoszonych ziem, a jej miasta wśród zrujnowanych miast będą spustoszone [przez] czterdzieści lat. I rozproszę Egipcjan między narodami, i rozrzucę ich po ziemiach.
13 “‘Ṣùgbọ́n báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Ní òpin ogójì ọdún, èmi yóò ṣa àwọn ará Ejibiti jọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn níbi tí a fọ́n wọn ká sí.
Jednak tak mówi Pan BÓG: Po upływie czterdziestu lat zgromadzę Egipcjan z narodów, wśród których zostali rozproszeni.
14 Èmi yóò sì tún mú ìgbèkùn Ejibiti padà bọ̀, èmi yóò sì dá wọn padà sí ilẹ̀ Paturosi, ilẹ̀ àwọn baba ńlá wọn. Wọn yóò wà níbẹ̀ bí ìjọba tí a rẹ̀ sílẹ̀.
I odwrócę niewolę Egiptu, i przyprowadzę ich do ziemi Patros, do ziemi ich zamieszkania, i będą tam nieznacznym królestwem.
15 Ibẹ̀ yóò jẹ́ ìjọba tí ó rẹlẹ̀ jùlọ nínú àwọn ìjọba, kì yóò sì gbé ara rẹ̀ ga mọ́ sórí àwọn orílẹ̀-èdè: nítorí èmi ni ó dín wọn kù, tiwọn kì yóò fi ṣe olórí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù mọ́.
Będzie ono najmniej znaczące spośród królestw i nie wyniesie się więcej nad [inne] narody. Umniejszę ich, aby nie panowali nad narodami.
16 Ejibiti kí yóò sì jẹ orísun ìgbẹ́kẹ̀lé fún ilé Israẹli mọ́ ṣùgbọ́n, yóò jẹ́ ìrántí fún àìṣedéédéé wọn, nígbà tí yóò bá wò wọ́n fún ìrànlọ́wọ́. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.’”
I nie będzie już ufnością domu Izraela, co przypominałoby o jego nieprawości, gdy zwracał się do niego. I poznają, że ja jestem Panem BOGIEM.
17 Ó sì ṣe ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní, ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Potem, w roku dwudziestym siódmym, w pierwszym miesiącu, pierwszego [dnia] tego miesiąca, doszło do mnie słowo PANA:
18 “Ọmọ ènìyàn, Nebukadnessari ọba Babeli mú kí ogun rẹ sin ìrú ńlá fún Tire. Gbogbo orí pá, àti gbogbo èjìká bó, síbẹ̀, òun àti àwọn ogun rẹ̀, kò rí owó ọ̀yà gbà láti Tire fún wa, fún ìrú ti a ti sìn.
Synu człowieczy, Nabuchodonozor, król Babilonu, zmusił swoje wojsko do ciężkiej służby przeciwko Tyrowi: każda głowa wyłysiała i każde ramię się obnażyło, [lecz] ani on, ani jego wojsko nie otrzymali zapłaty z Tyru za tę służbę, którą podejmował, [walcząc] przeciwko niemu.
19 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, Èmi yóò fi Ejibiti fún Nebukadnessari ọba Babeli, òun yóò sì kó ọrọ̀ rẹ̀ lọ. Òun yóò bo ilé, yóò sì ṣe ìkógun ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí owó iṣẹ́ tí a san fún ológun rẹ̀.
Dlatego tak mówi Pan BÓG: Oto daję Nabuchodonozorowi, królowi Babilonu, ziemię Egiptu, i zabierze jej dostatek, weźmie jej łup, i pochwyci jej zdobycze, aby to było zapłatą dla jego wojska.
20 Èmi ti fi Ejibiti fún un gẹ́gẹ́ bí èrè wàhálà rẹ̀ nítorí òun àti àwọn ológun rẹ ṣe é fún mi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Daję im ziemię Egiptu za ich pracę, którą dla mnie podjęli, gdyż dla mnie pracowali, mówi Pan BÓG.
21 “Ní ọjọ́ náà, èmi yóò mú kí ìwo Israẹli ru jáde, èmi yóò sì fún ọ ní ẹnu ọ̀rọ̀ ní àárín wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”
W tym dniu sprawię, że wyrośnie róg domu Izraela, tobie też pozwolę otworzyć usta pośród nich. I poznają, że ja jestem PANEM.

< Ezekiel 29 >