< Ezekiel 29 >

1 Ní ọjọ́ kejìlá, oṣù kẹwàá, ọdún kẹwàá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
I det tiende Aar, i den tiende Maaned, paa den tolvte Dag i Maaneden kom Herrens Ord til mig saaledes:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọjú sí Farao ọba Ejibiti kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí i àti sí gbogbo Ejibiti.
Du Menneskesøn! vend dit Ansigt imod Farao, Kongen af Ægypten, og spaa imod ham og imod al Ægypten.
3 Sọ̀rọ̀, kí ó sì wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi lòdì sí ọ, Farao ọba Ejibiti ìwọ ẹ̀mí búburú ńlá inú òkun tí ó dùbúlẹ̀ sí àárín àwọn odò ṣíṣàn rẹ. Èyí tí ó sọ wí pé, “Tèmi ni odò Naili; èmi ni ó sì ṣe é fún ara mi.”
Tal og sig: Saa siger den Herre, Herre: Se, jeg kommer imod dig, Farao, Konge i Ægypten, du, som er den store Drage, der ligger midt i sine Strømme, og som siger: Min Strøm er min, og jeg har skabt mig den.
4 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ìwọ̀ mú ẹnu rẹ èmi yóò sì mú ẹja inú odò rẹ gbogbo lẹ̀ mọ́ ìpẹ́ ara rẹ. Èmi yóò fà ọ́ síta kúrò láàrín àwọn odò rẹ, àti gbogbo ẹja odò rẹ yóò lẹ̀ mọ́ ìpẹ́ ara rẹ.
Men jeg vil kaste Kroge i dine Kæver og lade Fiskene i dine Strømme hænge ved dine Skæl, og jeg vil trække dig op midt af dine Strømme tillige med alle de Fisk i dine Strømme, der hænge ved dine Skæl.
5 Èmi yóò sọ ọ́ nù sí aginjù ìwọ àti gbogbo ẹja inú odò rẹ: ìwọ yóò ṣubú sí gbangba oko a kì yóò sì ṣà ọ́ jọ tàbí gbé ọ sókè. Èmi ti fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn ẹranko igbó àti fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run láti jẹ.
Og jeg vil kaste dig ud i Ørken, dig og alle Fisk fra dine Strømme, paa Marken skal du falde hen, du skal ikke samles til Hobe og ej sankes op, jeg har givet dig til Dyrene i Landet og til Fuglene under Himmelen som Føde.
6 Nígbà náà gbogbo àwọn olùgbé ni Ejibiti yóò mọ pé, Èmi ni Olúwa. “‘Ìwọ ti jẹ́ ọ̀pá ìyè fún ilé Israẹli.
Og alle Ægyptens Indbyggere skulle fornemme, at jeg er Herren. Fordi de have været Israels Hus en Rørkæp —
7 Nígbà tí wọn fi ọwọ́ agbára wọn dì ọ́ mú. Ìwọ fọ́, ìwọ sì ya gbogbo èjìká wọn; nígbà tí wọn fi ara tì ọ́, ìwọ sẹ́, ìwọ sì mú gbogbo ẹ̀gbẹ́ wọn gbọ̀n.
naar de gribe din Haand, knækker du og splitter dem hver Skulder; og naar de støtte sig paa dig, sønderbrydes du og bringer dem alle Lænder til at vakle —
8 “‘Nítorí náà, èyí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi, Èmi yóò mú idà kan wá sórí rẹ tí yóò sì gé ènìyàn àti ẹran kúrò nínú rẹ.
derfor, saa siger den Herre, Herre: Se, jeg lader et Sværd komme over dig, og jeg vil udrydde Mennesker og Kvæg af dig.
9 Ilẹ̀ Ejibiti yóò di aginjù àti ahoro, nígbà náà ní wọn yóò sì mọ̀ wí pé èmi ní Olúwa. “‘Nítorí tí ìwọ wí pé, “Tèmi ni odò Naili, Èmi ni mo ṣe é,”
Og Ægyptens Land skal blive til Ødelæggelse og Øde; og de skulle fornemme, at jeg er Herren. Fordi han siger: Det er min Strøm, og jeg har skabt den:
10 nítorí náà, mo lòdì sí ọ àti sí àwọn odò rẹ, èmi yóò sì mú kí ilẹ̀ Ejibiti di píparun àti ahoro, pátápátá, láti Migdoli lọ dé Siene, dé ààlà ilẹ̀ Kuṣi.
Derfor se! vil jeg komme til dig og til dine Strømme og gøre Ægyptens Land til aldeles øde Ørkener, fra Migdol til Sy ene, og indtil Morlands Landemærke.
11 Kò sí ẹsẹ̀ ènìyàn tàbí tí ẹranko tí yóò gba ibẹ̀ kọjá; ẹni kankan kò ní gbé ibẹ̀ fún ogójì ọdún.
Der skal ikke gaa Menneskefod igennem det, og Fæs Fod skal ikke gaa der igennem; og det skal ikke bebos i fyrretyve Aar.
12 Èmi yóò sọ ilẹ̀ Ejibiti di ọ̀kan ní àárín àwọn ìlú tí ó di ahoro, fún ogójì ọdún, Èmi yóò sì fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sáàárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sáàárín gbogbo ilẹ̀.
Og jeg vil gøre Ægyptens Land til et Øde midt iblandt de ødelagte Lande, og dets Stæder skulle blive øde midt iblandt de ødelagte Stæder, fyrretyve Aar; og jeg vil adsprede Ægypterne iblandt Folkene og strø dem ud i Landene.
13 “‘Ṣùgbọ́n báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Ní òpin ogójì ọdún, èmi yóò ṣa àwọn ará Ejibiti jọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn níbi tí a fọ́n wọn ká sí.
Thi saa siger den Herre, Herre: Naar fyrretyve Aar ere til Ende, vil jeg samle Ægypterne hjem fra Folkene, hvorhen de vare adspredte.
14 Èmi yóò sì tún mú ìgbèkùn Ejibiti padà bọ̀, èmi yóò sì dá wọn padà sí ilẹ̀ Paturosi, ilẹ̀ àwọn baba ńlá wọn. Wọn yóò wà níbẹ̀ bí ìjọba tí a rẹ̀ sílẹ̀.
Og jeg vil vende Ægyptens Fangenskab og føre dem tilbage til Pathros Land, til deres Stammeland, og de skulle der være et ringe Rige.
15 Ibẹ̀ yóò jẹ́ ìjọba tí ó rẹlẹ̀ jùlọ nínú àwọn ìjọba, kì yóò sì gbé ara rẹ̀ ga mọ́ sórí àwọn orílẹ̀-èdè: nítorí èmi ni ó dín wọn kù, tiwọn kì yóò fi ṣe olórí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù mọ́.
Det skal være ringe fremfor andre Riger og ikke ophøje sig ydermere over Folkene; og jeg vil gøre dem ubetydelige, at de ikke skulle regere over Folkene.
16 Ejibiti kí yóò sì jẹ orísun ìgbẹ́kẹ̀lé fún ilé Israẹli mọ́ ṣùgbọ́n, yóò jẹ́ ìrántí fún àìṣedéédéé wọn, nígbà tí yóò bá wò wọ́n fún ìrànlọ́wọ́. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.’”
Og det skal ikke ydermere være Israels Hus til Fortrøstning, saa at det bringer mig deres Synd i Erindring, naar disse vende sig om efter dem, og de skulle fornemme, at jeg er den Herre, Herre.
17 Ó sì ṣe ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní, ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Og det skete i det syv og tyvende Aar, i den første Maaned, paa den første Dag i Maaneden, at Herrens Ord kom til mig saaledes:
18 “Ọmọ ènìyàn, Nebukadnessari ọba Babeli mú kí ogun rẹ sin ìrú ńlá fún Tire. Gbogbo orí pá, àti gbogbo èjìká bó, síbẹ̀, òun àti àwọn ogun rẹ̀, kò rí owó ọ̀yà gbà láti Tire fún wa, fún ìrú ti a ti sìn.
Du Menneskesøn! Nebukadnezar, Kongen af Babel, har paalagt sin Krigshær et svart Arbejde imod Tyrus, saa at hvert Hoved er skaldet og hver Skulder opslidt, og Løn har han og hans Hær ikke faaet ud af Tyrus for det Arbejde, han har haft med den.
19 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, Èmi yóò fi Ejibiti fún Nebukadnessari ọba Babeli, òun yóò sì kó ọrọ̀ rẹ̀ lọ. Òun yóò bo ilé, yóò sì ṣe ìkógun ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí owó iṣẹ́ tí a san fún ológun rẹ̀.
Derfor, saa siger den Herre, Herre: Se, jeg giver Nebukadnezar, Kongen af Babel, Ægyptens Land, og han skal tage dets Gods og bytte dets Bytte og røve dets Rov, og det skal være Løn for hans Hær.
20 Èmi ti fi Ejibiti fún un gẹ́gẹ́ bí èrè wàhálà rẹ̀ nítorí òun àti àwọn ológun rẹ ṣe é fún mi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Som hans Løn, for hvilken han har tjent imod den, har jeg givet ham Ægyptens Land; thi for mig have de tjent, siger den Herre, Herre.
21 “Ní ọjọ́ náà, èmi yóò mú kí ìwo Israẹli ru jáde, èmi yóò sì fún ọ ní ẹnu ọ̀rọ̀ ní àárín wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”
Paa den Dag vil jeg lade et Horn skyde op for Israels Hus, og dig vil jeg give en opladt Mund midt iblandt dem; og de skulle fornemme, at jeg er Herren.

< Ezekiel 29 >