< Ezekiel 28 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
I doszło do mnie słowo PANA mówiące:
2 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún ọmọ-aládé Tire pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Nítorí tí ọkàn rẹ gbé sókè sí mi, ìwọ wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run; Èmi jókòó sí orí ìtẹ́ òrìṣà, ní àárín gbùngbùn Òkun.” Ṣùgbọ́n ènìyàn ni ọ́, kì i ṣe òrìṣà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ rò pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run.
Synu człowieczy, powiedz księciu Tyru: Tak mówi Pan BÓG: Ponieważ uniosło się twoje serce i powiedziałeś: Ja jestem Bogiem, zasiadam na Bożym tronie w sercu mórz – ale ty jesteś człowiekiem, a nie Bogiem, choć twoje serce stawiasz na równi z sercem Boga;
3 Ìwọ gbọ́n ju Daniẹli lọ bí? Ṣé kò sí àṣírí kan tí ó pamọ́ fún ọ?
Oto jesteś mądrzejszy od Daniela, żadna tajemnica nie jest zakryta przed tobą;
4 Pẹ̀lú ọgbọ́n àti ìmọ̀ rẹ, ìwọ tí jèrè ọrọ̀ fún ara rẹ, àti àkójọpọ̀ wúrà àti fàdákà, nínú àwọn ilé ìṣúra rẹ.
Swoją mądrością i roztropnością zdobyłeś sobie bogactwo i nagromadziłeś złota i srebra w swoich skarbcach;
5 Nípa ọgbọ́n rẹ ńlá àti nípa òwò rẹ, ìwọ ti sọ ọrọ̀ rẹ di púpọ̀, àti nítorí ọrọ̀ rẹ di púpọ̀, ọkàn rẹ gbé sókè, nítorí ọrọ̀ rẹ.
Dzięki wielkości twojej mądrości i twojemu kupiectwu rozmnożyłeś swoje bogactwa; a tak uniosło się twoje serce z powodu twoich bogactw;
6 “‘Nítorí náà èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Nítorí pé ìwọ rò pé o gbọ́n, pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run.
Dlatego tak mówi Pan BÓG: Ponieważ postawiłeś swoje serce jak serce Boga;
7 Èmi yóò mú kí àwọn àjèjì dìde sí ọ, ẹlẹ́rù nínú àwọn orílẹ̀-èdè; wọn yóò yọ idà wọn sí ọ, ẹwà rẹ àti ọgbọ́n rẹ, wọn yóò sì ba dídán rẹ̀ jẹ́.
Oto sprowadzę na ciebie cudzoziemców, najsroższe z narodów. Dobędą swoje miecze przeciwko piękności twej mądrości i splugawią twój blask.
8 Wọn yóò mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá sínú ihò, ìwọ yóò sì kú ikú gbígbóná, àwọn tí a pa ní àárín Òkun.
Strącą cię do dołu i umrzesz srogą śmiercią w sercu mórz.
9 Ṣé ìwọ yóò wá wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run,” ní ojú àwọn tí ó pa ọ́? Ìwọ yóò jẹ́ ènìyàn, kì í ṣe Ọlọ́run, ní ọwọ́ àwọn ti yóò pa ọ́.
Czy powiesz przed tym, który cię zabije: Jestem Bogiem? Przecież jesteś człowiekiem, a nie Bogiem w ręku tego, który cię zabije.
10 Ìwọ yóò kú ikú aláìkọlà, ní ọwọ́ àwọn àjèjì. Èmi ni ó ti sọ ọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
Umrzesz śmiercią nieobrzezanych, z ręki cudzoziemców. Ja bowiem [to] powiedziałem, mówi Pan BÓG.
11 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
I doszło do mnie słowo PANA mówiące:
12 “Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún sórí ọba Tire kí ó sì sọ fún un pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ìwọ jẹ́ àpẹẹrẹ ìjẹ́pípé náà, o kún fún ọgbọ́n, o sì pé ní ẹwà.
Synu człowieczy, podnieś lament nad królem Tyru i mów do niego: Tak mówi Pan BÓG: Ty pieczętujesz sumę, pełen mądrości i doskonały w swej piękności;
13 Ìwọ ti wà ní Edeni, ọgbà Ọlọ́run; onírúurú òkúta oníyebíye ni ìbora rẹ; sardiu, topasi àti diamọndi, berili, óníkìsì, àti jasperi, safire, emeradi, turikuose, àti karbunkili, àti wúrà, ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ àti àwọn òkè rẹ ní a dà, láti ara wúrà, ní ọjọ́ tí á dá ọ ní a pèsè wọn.
Byłeś w Edenie, ogrodzie Bożym; twoim nakryciem był wszelki drogi kamień: karneol, topaz i jaspis, chryzolit, onyks i beryl, szafir, karbunkuł i szmaragd oraz złoto. Wykonanie twoich bębenków i fletów zostało przygotowane w dniu, kiedy zostałeś stworzony.
14 A fi àmì òróró yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí olùtọ́jú kérúbù, torí èyí ni mo fi yàn ọ́. Ìwọ wà lórí òkè mímọ́ Ọlọ́run; ìwọ rìn ni àárín òkúta a mú bí iná.
Ty jesteś namaszczonym cherubinem nakrywającym; ja cię ustanowiłem. Byłeś na świętej górze Boga, przechadzałeś się wśród kamieni ognistych.
15 Ìwọ pé ní ọ̀nà rẹ, láti ọjọ́ tí a ti dá ọ, títí a fi rí àìṣedéédéé ní inú rẹ.
Byłeś doskonały w swoich drogach od dnia, kiedy zostałeś stworzony, aż znalazła się w tobie nieprawość.
16 Nípa ìtànkálẹ̀ òwò rẹ, ìwọ kún fún ìwà ipá; ìwọ sì dẹ́ṣẹ̀. Nítorí náà ni mo ṣe sọ ọ nù, bí ohun àìlọ́wọ̀ kúrò lórí òkè Ọlọ́run. Èmi sì pa ọ run, ìwọ kérúbù, tí ó bọ́ kúrò ní àárín òkúta a mú bí iná.
Przez twój ogromny handel pełno pośród ciebie bezprawia, i zgrzeszyłeś. Dlatego zrzucę cię z góry Boga, cherubinie nakrywający, wyniszczę cię spośród kamieni ognistych.
17 Ọkàn rẹ gbéraga, nítorí ẹwà rẹ. Ìwọ sì ba ọgbọ́n rẹ jẹ́, nítorí dídára rẹ. Nítorí náà mo le ọ sórí ayé; mo sọ ọ di awòojú níwájú àwọn ọba.
Uniosło się twoje serce z powodu twojej piękności, znieważyłeś swoją mądrość z powodu twojego blasku. Rzucę cię na ziemię i postawię cię przed królami, aby się tobie przypatrzyli.
18 Nípa ẹ̀ṣẹ̀ púpọ̀ rẹ àti òwò àìṣòótọ́ rẹ, ìwọ ti ba àwọn ibi mímọ́ rẹ jẹ́. Nítorí náà mo mú kí iná jáde wá, láti inú rẹ, yóò sì jó ọ run, èmi yóò sì sọ ọ́ di eérú lórí ilẹ̀, lójú gbogbo àwọn tí ó ń wò ọ́.
Mnóstwem twoich nieprawości [i] nieprawością twego handlu splugawiłeś swoją świątynię. Dlatego wywiodę ogień z twego wnętrza, który cię pożre, a zamienię cię w popiół na ziemi na oczach wszystkich, którzy na ciebie patrzą.
19 Gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó mọ̀ ọ́n, ní ẹnu ń yà sí ọ; ìwọ yóò sì jẹ́ ẹ̀rù, ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́ láéláé.’”
Wszyscy, którzy cię znają wśród narodów, zdumieją się nad tobą. Staniesz się postrachem i nie będzie ciebie już na wieki.
20 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
I doszło do mnie słowo PANA mówiące:
21 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú sí Sidoni; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ sí i,
Synu człowieczy, zwróć swoją twarz przeciw Sydonowi i prorokuj przeciw niemu;
22 kí ó sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi lòdì sí ọ, ìwọ Sidoni, a ó sì ṣe mí lógo láàrín rẹ. Wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá mú ìdájọ́ mi ṣẹ nínú rẹ, tí a sì yá mí sí mímọ́ nínú rẹ.
Mów: Tak mówi Pan BÓG: Oto [jestem] przeciwko tobie, Sydonie, będę uwielbiony pośród ciebie. I poznają, że ja jestem PANEM, gdy wykonam na niego sądy i będę w nim uświęcony.
23 Èmi yóò sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn sínú rẹ, èmi yóò sì mú kí ẹ̀jẹ̀ sàn ní ìgboro rẹ, ẹni ti á pa yóò ṣubú ní àárín rẹ, pẹ̀lú idà lára rẹ ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, nígbà náà wọn yóò mọ̀ wí pé èmi ni Olúwa.
I ześlę na niego zarazę i krew na jego ulice; zranieni upadną pośród niego od miecza, który [spadnie] na nich ze wszystkich stron. I poznają, że ja jestem PANEM.
24 “‘Kì yóò sì ṣí ẹ̀gún tí ń gun ni ní ilẹ̀ Israẹli mọ́, tàbí ẹ̀gún bíbani nínú jẹ́ ti gbogbo àwọn tí wọn wà ní àyíká wọn, tí wọ́n sì ń fi ojú yẹpẹrẹ wò wọ́n, nígbà náà ni wọn yóò mọ́ wí pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.
I tak dla domu Izraela nie będzie już kłującego ciernia ani bolesnego kolca spośród wszystkich okolicznych mieszkańców, którzy nim wzgardzili. I poznają, że ja jestem Panem BOGIEM.
25 “‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí èmi yóò bá sa àwọn ènìyàn Israẹli jọ kúrò ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti fọ́nká sí, tí a ó sì yà mí sí mímọ́ láàrín wọn lójú àwọn aláìkọlà. Nígbà náà ni wọn yóò gbé ní ilẹ̀ àwọn tìkálára wọn, èyí tí mo fún ìránṣẹ́ mi Jakọbu.
Tak mówi Pan BÓG: Gdy zgromadzę dom Izraela spośród narodów, wśród których został rozproszony, i będę w nich uświęcony na oczach pogan, wtedy będą mieszkać w swojej ziemi, którą dałem swemu słudze Jakubowi.
26 Wọn yóò sì máa gbé ní inú rẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì kọ́lé, wọn yóò sì gbin ọgbà àjàrà; nítòótọ́ wọn yóò wà ní ìbàlẹ̀ àyà, nígbà tí èmi bá ti mú ìdájọ́ mi ṣẹ̀ sí ara àwọn tí ń ṣátá wọn ní gbogbo àyíká wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.’”
I będą w niej mieszkać bezpiecznie, pobudują domy i zasadzą winnice. Będą mieszkać bezpiecznie, gdy wykonam sądy na wszystkich dokoła nich, którzy nimi wzgardzili. I poznają, że ja jestem PANEM, ich Bogiem.

< Ezekiel 28 >