< Ezekiel 2 >

1 Ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, dìde dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ. Èmi yóò bá ọ sọ̀rọ̀.”
I powiedział do mnie: Synu człowieczy, stań na nogi, a będę do ciebie mówił.
2 Bí ó ṣe ń sọ̀rọ̀, ẹ̀mí sì wọ inú mi ó mú mi dúró lórí ẹsẹ̀ mi, mo sì ń gbọ́ tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀.
I wstąpił we mnie duch, gdy przemówił do mnie, i postawił mnie na nogi; potem słyszałem tego, który mówił do mnie.
3 Ó sọ pé, “Ọmọ ènìyàn, mo ń rán ọ sí àwọn ọmọ Israẹli, sí ọlọ̀tẹ̀ orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi; àwọn àti baba ńlá wọn ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi títí di òní olónìí.
Powiedział mi: Synu człowieczy, ja cię posyłam do synów Izraela, do narodu buntowniczego, który mi się sprzeciwił. Oni i ich ojcowie występowali przeciwko mnie aż do dziś.
4 Àwọn ènìyàn tí mo ń rán ọ sí jẹ́ aláìgbọ́ràn àti ọlọ́kàn líle. Sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí.’
Są to synowie o bezczelnych twarzach i zatwardziałym sercu. Do nich cię posyłam. Powiesz im: Tak mówi Pan BÓG.
5 Bí wọn fetísílẹ̀ tàbí wọn kò fetísílẹ̀ nítorí pé wọ́n ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n—wọn yóò mọ̀ pé wòlíì kan wà láàrín wọn.
A oni, czy posłuchają, czy nie – gdyż są domem buntowniczym – przecież będą wiedzieć, że był wśród nich prorok.
6 Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn, má ṣe bẹ̀rù wọn tàbí ọ̀rọ̀ ẹnu wọn. Má ṣe bẹ̀rù, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òṣùṣú àti ẹ̀gún yí ọ ká, tí o sì ń gbé àárín àwọn àkéekèe. Má ṣe bẹ̀rù ohun tí wọ́n ń sọ tàbí bẹ̀rù wọn, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ìdílé ni wọ́n.
Ale ty, synu człowieczy, nie bój się ich ani nie lękaj się ich słów, chociaż otaczają cię osty i ciernie i mieszkasz wśród skorpionów. Nie bój się ich słów ani nie lękaj się ich twarzy, gdyż są domem buntowniczym.
7 Ìwọ gbọdọ̀ sọ ọ̀rọ̀ mi fún wọn, bí wọ́n gbọ́ bí wọn kọ̀ láti gbọ́ torí pé ọlọ̀tẹ̀ ni wọ́n.
Powiedz im moje słowa, czy usłuchają, czy nie, gdyż są zbuntowani.
8 Ṣùgbọ́n ìwọ, ọmọ ènìyàn, gbọ́ ohun tí mo ń sọ fún ọ. Má ṣe ṣọ̀tẹ̀ bí i ti ìdílé ọlọ́tẹ̀; la ẹnu rẹ kí o sì jẹ ohun tí mo fún ọ.”
Lecz ty, synu człowieczy, słuchaj, co mówię do ciebie: Nie bądź zbuntowany jak [ten] dom buntowniczy. Otwórz swe usta i zjedz, co ci daję.
9 Mo sì wò, mo sì rí ọwọ́ kan tí a nà sí mi. Ìwé kíká sì wà níbẹ̀,
I spojrzałem, a oto ręka [była] wyciągnięta do mnie, a w niej zwój księgi;
10 ó sì tú ìwé náà fún mi. Ní ojú àti ẹ̀yìn ìwé náà ni a kọ ìpohùnréré ẹkún, ọ̀fọ̀ àti ègún sí.
A on rozwinął go przede mną. Był zapisany z jednej i z drugiej strony, a spisane były w nim lamenty, żal i biadania.

< Ezekiel 2 >