< Exodus 9 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sọ fún Farao, ‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn Heberu sọ, “Jẹ́ kí àwọn ènìyàn Mi kí ó lọ, kí wọn bá à lè sìn Mí.”
Potem PAN powiedział do Mojżesza: Idź do faraona i powiedz mu: Tak mówi PAN, Bóg Hebrajczyków: Wypuść mój lud, aby mi służył;
2 Bí ìwọ bá kọ̀ láti jẹ́ kí wọn ó lọ, tí ó sì dá wọn dúró.
Bo jeśli będziesz się wzbraniał go wypuścić i nadal będziesz go zatrzymywał;
3 Ọwọ́ Olúwa yóò mú ààrùn búburú wá sí ara ẹran ọ̀sìn nínú oko, sí ara ẹṣin, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ìbákasẹ, màlúù, àgùntàn àti ewúrẹ́ yín.
Oto ręka PANA będzie na twoje stada, które [są] na polu, na koniach, na osłach, na wielbłądach, na wołach i na owcach. [Będzie] bardzo ciężka zaraza.
4 Ṣùgbọ́n Olúwa yóò pààlà sí àárín ẹran ọ̀sìn tí ó jẹ́ ti Israẹli àti ti àwọn ara Ejibiti tí yóò fi jẹ́ pé kò sí ẹran ọ̀sìn ti ó jẹ́ ti ará Israẹli tí yóò kùú.’”
PAN rozdzieli stada Izraela i stada Egiptu, aby nie zdechło nic ze wszystkiego, co należy do synów Izraela.
5 Olúwa sì dá àkókò kan wí pé, “Ní ọ̀la ni Olúwa yóò ṣe èyí ni ilẹ̀ yìí.”
I PAN wyznaczył czas, mówiąc: Jutro PAN to uczyni na [tej] ziemi.
6 Olúwa sí ṣe é ni ọjọ́ kejì. Gbogbo ẹran ọ̀sìn ará Ejibiti kú, ṣùgbọ́n ẹyọ kan kò kú lára ẹran ọ̀sìn àwọn Israẹli.
Nazajutrz PAN tak uczynił. Pozdychały wszystkie stada Egiptu, lecz ze stad synów Izraela nie zdechło ani jedno.
7 Farao rán àwọn ènìyàn rẹ̀ láti lọ ṣe ìwádìí, wọ́n sì rí pé ẹyọ kan kò kú lára àwọn ẹran ọ̀sìn ará Israẹli. Síbẹ̀ náà, Farao kò yí ọkàn rẹ̀ padà àti pé kò jẹ́ kí àwọn ènìyàn ó lọ.
Faraon posłał więc [na zwiady], a oto z bydła Izraela nie zdechło ani jedno. Ale serce faraona pozostało zatwardziałe i nie wypuścił ludu.
8 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni, “Ẹ bu ẹ̀kúnwọ́ eérú gbígbóná láti inú ààrò, kí Mose kù ú sí inú afẹ́fẹ́ ni iwájú Farao.
Potem PAN powiedział do Mojżesza i Aarona: Weźcie pełne garści popiołu z pieca i niech Mojżesz rozrzuci go ku niebu na oczach faraona.
9 Yóò sì di eruku lẹ́búlẹ́bú ni gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, yóò sì di oówo ti ń tú pẹ̀lú ìléròrò sí ara àwọn ènìyàn àti ẹran jákèjádò gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.”
Zamieni się w pył na całej ziemi Egiptu, który spowoduje wrzody pęczniejące ropą na ludziach i na zwierzętach na całej ziemi Egiptu.
10 Nígbà náà ni wọ́n bú eérú gbígbóná láti inú ààrò, wọ́n dúró ní iwájú Farao. Mose sì ku eérú náà sínú afẹ́fẹ́, ó sì di oówo tí ń tú pẹ̀lú ìléròrò ni ara àwọn ènìyàn àti lára ẹran.
Wzięli więc popiół z pieca i stanęli przed faraonem, a Mojżesz rozrzucił popiół ku niebu i powstały wrzody pęczniejące ropą na ludziach i na zwierzętach.
11 Àwọn onídán kò le è dúró níwájú Mose nítorí oówo ti ó wà lára wọn àti ni ara gbogbo àwọn ara Ejibiti.
Czarownicy zaś nie mogli stanąć przed Mojżeszem z powodu wrzodów, bo wrzody były na nich i na wszystkich Egipcjanach.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sé ọkàn Farao le, kò sì gbọ́ ti Mose àti Aaroni, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún Mose.
I PAN zatwardził serce faraona, i [ten] nie posłuchał ich, jak PAN zapowiedział Mojżeszowi.
13 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Dìde ni òwúrọ̀ kùtùkùtù, kí o sì tọ Farao lọ, kí o sì wí fún un pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Heberu wí, Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn bá à lè sìn mí,
PAN powiedział do Mojżesza: Wstań rano, stań przed faraonem i powiedz mu: Tak mówi PAN, Bóg Hebrajczyków: Wypuść mój lud, aby mi służył;
14 nítorí nígbà yìí ni èmi yóò rán àjàkálẹ̀-ààrùn ti ó ní agbára gidigidi sí ọ, sí àwọn ìjòyè rẹ àti sí àwọn ènìyàn rẹ, kí ìwọ kí ó lè mọ̀ pé, kò sí ẹni bí èmi ni gbogbo ayé.
Tym razem bowiem ześlę wszystkie moje plagi na twoje serce, na twoje sługi i na twój lud, abyś wiedział, że nie ma równego mi na całej ziemi.
15 Ó ti yẹ kí n ti na ọwọ́ mi jáde láti kọlù ọ́ àti àwọn ènìyàn rẹ pẹ̀lú ààrùn búburú ti kò bá ti run yín kúrò ni orí ilẹ̀.
Bo teraz wyciągnę rękę i uderzę ciebie i twój lud zarazą, i będziesz wytracony z ziemi.
16 Ṣùgbọ́n nítorí èyí ni èmi ṣe mú ọ dúró, kí èmi kí ó le fi agbára mi hàn lára rẹ, àti kí a bá à le máa ròyìn orúkọ mi ká gbogbo ayé.
Lecz dlatego cię postawiłem, aby okazać na tobie moją moc i żeby rozgłaszano moje imię na całej ziemi.
17 Síbẹ̀ ìwọ tún gbógun ti àwọn ènìyàn mi, ìwọ kò sì jẹ́ kí wọn lọ.
A ty jeszcze się wynosisz [i stajesz] przeciw memu ludowi, nie chcąc go wypuścić?
18 Nítorí náà, ni ìwòyí ọ̀la, Èmi yóò rán òjò o yìnyín tí irú rẹ̀ kò tí i rọ̀ rí ni Ejibiti láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ títí di àkókò yìí.
Jutro o tej porze spuszczę bardzo ciężki grad, jakiego nie było w Egipcie od dnia jego założenia aż do tego czasu.
19 Pàṣẹ nísinsin yìí láti kó ẹran ọ̀sìn yín àti ohun gbogbo ti ẹ ni ní pápá wá sí abẹ́ ààbò, nítorí òjò yìnyín yóò rọ̀ sí orí àwọn ènìyàn àti ẹran ti a kò kó wá sí abẹ́ ààbò tí wọ́n sì wà ni orí pápá, wọn yóò sì kú.’”
Poślij więc teraz i zgromadź swoje bydło i wszystko, co masz na polu; [bo] każdy człowiek i każde zwierzę, które znajdzie się na polu, a nie zostanie zegnane do domu, zginie, gdy na nich spadnie grad.
20 Àwọn ti ó bẹ̀rù ọ̀rọ̀ Olúwa lára àwọn ìjòyè Farao yára lọ láti kó àwọn ẹrú àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn wá sí abẹ́ ààbò.
Kto więc ze sług faraona uląkł się słowa PANA, kazał uciekać swym sługom wraz z bydłem do domu;
21 Ṣùgbọ́n àwọn ti kò kà ọ̀rọ̀ Olúwa sí fi àwọn ẹrú wọn àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sílẹ̀ ni pápá.
Ale kto nie wziął do serca słowa PANA, ten zostawił swe sługi i bydło na polu.
22 Olúwa sọ fún Mose pé, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ọ̀run kí yìnyín bá à lè rọ̀ sí orí gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, sí orí ènìyàn àti ẹranko, àti sí orí gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ni inú oko.”
PAN powiedział do Mojżesza: Wyciągnij rękę ku niebu, by spadł grad na całej ziemi Egiptu, na ludzi, na bydło i na wszelkie rośliny polne w ziemi Egiptu.
23 Nígbà tí Mose gbé ọ̀pá rẹ̀ sókè sí ojú ọ̀run, Olúwa rán àrá àti yìnyín, mọ̀nàmọ́ná sì bùsi orí ilẹ̀. Olúwa rọ òjò yìnyín sí orí ilẹ̀ Ejibiti.
I Mojżesz wyciągnął swą laskę ku niebu, a PAN zesłał grzmoty i grad i na ziemię zstąpił ogień. PAN spuścił grad na ziemię Egiptu.
24 Yìnyín rọ̀, mọ̀nàmọ́ná sì bẹ̀rẹ̀ sí bùsi orí ilẹ̀ èyí ni ó tí ì burú jù ti ó ṣẹlẹ̀ láti ìgbà ti Ejibiti ti di orílẹ̀-èdè.
I był grad i ogień zmieszany z bardzo ciężkim gradem, jakiego nie było w całej ziemi Egiptu, odkąd stał się narodem.
25 Jákèjádò gbogbo ilẹ̀ Ejibiti ni yìnyín ti pa gbogbo ohun tí ó wà ni orí pápá; ènìyàn àti ẹranko, ó wò gbogbo ohun ọ̀gbìn lulẹ̀ ó sì fa gbogbo igi ya pẹ̀lú.
Grad poraził na całej ziemi Egiptu cokolwiek było na polu, od człowieka aż do zwierzęcia. Poraził też wszelkie rośliny polne i połamał wszystkie drzewa na polu;
26 Ilẹ̀ Goṣeni ni ibi ti àwọn Israẹli wà nìkan ni òjò yìnyín náà kò rọ̀ dé.
Tylko w ziemi Goszen, gdzie mieszkali synowie Izraela, nie było gradu.
27 Nígbà náà ni Farao pe Mose àti Aaroni sì ọ̀dọ́ rẹ̀, ó sì wí fún wọn pé, “Èmi ti ṣẹ̀ ní àkókò yìí; Olúwa jẹ́ olódodo ṣùgbọ́n èmi àti àwọn ènìyàn mi ni aláìṣòdodo.
Faraon kazał więc wezwać Mojżesza i Aarona i powiedział do nich: Tym razem zgrzeszyłem. PAN jest sprawiedliwy, a ja i mój lud jesteśmy niegodziwi.
28 Èyí ti òjò yìnyín àti àrá rọ̀ yìí tó gẹ́ẹ́, gbàdúrà sí Olúwa kí ó dáwọ́ rẹ̀ dúró. Èmi yóò jẹ́ kí ẹ lọ, n kò tún ni dá a yín dúró mọ́.”
Wstawcie się u PANA, aby ustały Boże grzmoty i grad, bo [już] dość. Wypuszczę was i nie będziecie [tu] dłużej mieszkać.
29 Mose dá a lóhùn pé, “Bí mo bá ti jáde kúrò ní àárín ìlú, èmi yóò gbé ọwọ́ mi sókè sí Olúwa, sísán àrá yóò dáwọ́ dúró, yìnyín kò sì ni rọ̀ mọ́, kí ìwọ kí ó lè mọ̀ pé Olúwa ni ó ni ilẹ̀.
Mojżesz powiedział do niego: Gdy wyjdę z miasta, wyciągnę ręce do PANA, a grzmoty ustaną i nie będzie więcej gradu, abyś wiedział, że ziemia należy do PANA.
30 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ àti àwọn ìjòyè rẹ kò bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run.”
Ale wiem, że ty i twoi słudzy jeszcze nie boicie się PANA Boga.
31 (A sì lu ọ̀gbọ̀ àti ọkà barle bolẹ̀; nítorí barle wà ní ìpẹ́, ọ̀gbọ̀ sì rudi.
Len i jęczmień zostały zbite, bo jęczmień miał już kłosy, a len zakwitł.
32 Alikama àti ọkà ni a kò lù bolẹ̀, nítorí tí wọ́n kò tí ì dàgbà.)
Pszenica jednak i żyto nie zostały zbite, bo były późniejsze.
33 Nígbà náà ni Mose jáde kúrò ni iwájú Farao, ó kúrò ni àárín ìgboro kọjá lọ sí ẹ̀yìn odi ìlú, ó sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí Olúwa, sísán àrá àti òjò yìnyín ti ń rọ̀ sì dáwọ́ dúró, òjò kò sì rọ̀ sí orí ilẹ̀ mọ́.
Mojżesz wyszedł więc od faraona za miasto i wyciągnął ręce do PANA. Ustały wtedy grzmoty i grad, a deszcz nie padał na ziemię.
34 Nígbà tí Farao rí i pé òjò àti yìnyín àti àrá ti ń sán ti dáwọ́ dúró, ó tún ṣẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀kan sí i. Òun àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ṣì sé àyà wọn le.
Kiedy faraon zobaczył, że deszcz, grad i grzmoty ustały, jeszcze bardziej zgrzeszył i zatwardził serce, on i jego słudzy.
35 Àyà Farao sì le, bẹ́ẹ̀ ni kò sì jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli kí ó lọ, bí Olúwa ti sọ láti ẹnu Mose.
I serce faraona pozostało zatwardziałe i nie wypuścił synów Izraela, jak PAN zapowiedział przez Mojżesza.

< Exodus 9 >