< Exodus 33 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé, “Fi ìhín yìí sílẹ̀, ìwọ àti àwọn ènìyàn tí o mú gòkè láti Ejibiti wá, kí ẹ sì gòkè lọ sí ilẹ̀ tí Èmi ti pinnu ní ìbúra fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu wí pé, ‘Èmi yóò fi fún irú-ọmọ rẹ.’
Potem PAN mówił do Mojżesza: Idź, wyrusz stąd, ty i lud, który wyprowadziłeś z ziemi Egiptu, do ziemi, którą przysiągłem Abrahamowi, Izaakowi i Jakubowi, mówiąc: Dam ją twemu potomstwu.
2 Èmi yóò rán angẹli ṣáájú yín, Èmi yóò sì lé àwọn Kenaani, àwọn ará Amori, àwọn ará Hiti, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi jáde.
Poślę przed tobą Anioła i wyrzucę Kananejczyka, Amorytę, Chetytę, Peryzzytę, Chiwwitę i Jebusytę;
3 Ẹ gòkè lọ sí ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin. Ṣùgbọ́n èmi kò ní lọ pẹ̀lú yín, nítorí ènìyàn ọlọ́rùn líle ni ẹ̀yin, kí èmi má ba à run yín ní ọ̀nà.”
Do ziemi opływającej mlekiem i miodem. Lecz [sam] nie pójdę z tobą, bo [jesteś] ludem twardego karku, bym cię w drodze nie wytracił.
4 Nígbà tí àwọn ènìyàn náà gbọ́ ọ̀rọ̀ ìparun wọ̀nyí, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sì ní kùn, ẹnìkankan kò sì le è wọ ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀.
Gdy lud usłyszał te złe wieści, zasmucił się i nikt nie włożył na siebie swoich ozdób.
5 Nítorí Olúwa ti wí fún Mose pé, “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ènìyàn Ọlọ́rùn líle ní ẹ̀yin, bí Èmi bá lè wá sí àárín yín ni ìṣẹ́jú kan, Èmi lè pa yín run. Nísìnsinyìí, bọ́ ohun ọ̀ṣọ́ rẹ kúrò, Èmi yóò sì gbèrò ohun tí Èmi yóò ṣe pẹ̀lú rẹ.’”
PAN bowiem powiedział do Mojżesza: Powiedz synom Izraela: Jesteście ludem twardego karku. Przyjdę niespodziewanie pośród ciebie i wytracę cię. Teraz więc zdejmij z siebie swoje ozdoby, abym wiedział, co mam ci uczynić.
6 Bẹ́ẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli bọ́ ohun ọ̀ṣọ́ wọn kúrò lára wọn ní òkè Horebu.
I synowie Izraela zdjęli swoje ozdoby przy górze Horeb.
7 Mose máa ń gbé àgọ́ náà, ó sì pa á sí ìta ibùdó, ó jìnnà díẹ̀ sí ibùdó, ó pè é ni “Àgọ́ àjọ.” Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń béèrè Olúwa yóò lọ sí ibi àgọ́ àjọ náà ní ìta ibùdó.
A Mojżesz wziął namiot i rozbił [go] poza obozem, z dala od obozu, i nazwał go Namiotem Zgromadzenia. Każdy, kto chciał się poradzić PANA, wychodził do Namiotu Zgromadzenia, który był poza obozem.
8 Nígbàkígbà tí Mose bá jáde lọ sí ibi àgọ́, gbogbo ènìyàn á dìde, wọ́n á sì dúró sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ wọn, wọn yóò máa wo Mose títí yóò fi wọ inú àgọ́ náà.
A gdy Mojżesz wychodził do namiotu, cały lud powstawał i każdy stał u wejścia do swego namiotu, i patrzył na Mojżesza, aż wszedł do namiotu.
9 Bí Mose ṣe wọ inú àgọ́ náà, ọ̀wọ́n àwọsánmọ̀ yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì dúró sí ẹnu ọnà, nígbà tí Olúwa ń sọ̀rọ̀ pẹ̀lú Mose.
Gdy Mojżesz wchodził do namiotu, słup obłoku zstępował i stawał u wejścia do namiotu, i [PAN] rozmawiał z Mojżeszem.
10 Nígbàkígbà tí àwọn ènìyàn bá rí i ti ọ̀wọ́n àwọsánmọ̀ bá dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, gbogbo wọn yóò dìde wọn yóò sì sìn, olúkúlùkù ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ rẹ̀.
A cały lud widział słup obłoku stojący u wejścia do namiotu. Wtedy cały lud powstawał i oddawał pokłon, każdy u wejścia do swego namiotu.
11 Olúwa máa ń bá Mose sọ̀rọ̀ lójúkojú, gẹ́gẹ́ bí i pé ènìyàn ń bá ọ̀rẹ́ rẹ̀ sọ̀rọ̀. Nígbà náà ni Mose yóò tún padà lọ sí ibùdó, ṣùgbọ́n ọ̀dọ́mọkùnrin Joṣua ìránṣẹ́ rẹ̀ ọmọ Nuni kò fi àgọ́ sílẹ̀.
I PAN rozmawiał z Mojżeszem twarzą w twarz, jak człowiek rozmawia ze swoim przyjacielem. Potem [Mojżesz] wracał do obozu, a jego sługa Jozue, syn Nuna, młodzieniec, nie opuszczał namiotu.
12 Mose sọ fún Olúwa pé, “Ìwọ ti ń sọ fún mi, ‘Darí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,’ ṣùgbọ́n ìwọ kò jẹ́ kí ń mọ ẹni tí ìwọ yóò rán pẹ̀lú mi. Ìwọ ti wí pé, ‘Èmi mọ̀ ọ́n nípa orúkọ, ìwọ sì ti rí ojúrere mi pẹ̀lú.’
I Mojżesz powiedział do PANA: Oto mówisz mi: Prowadź ten lud, a nie oznajmiłeś mi, kogo poślesz ze mną. Ponadto powiedziałeś: Znam cię po imieniu, znalazłeś też łaskę w moich oczach.
13 Bí ìwọ bá ní inú dídùn pẹ̀lú mi, kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, kí èmi kí ó lè mọ̀ ọ́n, kí n sì le máa wá ojúrere rẹ pẹ̀lú. Rántí wí pé orílẹ̀-èdè yìí ènìyàn rẹ ni.”
Teraz więc, jeśli znalazłem łaskę w twoich oczach, ukaż mi, proszę, twoją drogę, żebym cię poznał i żebym znalazł łaskę w twoich oczach. Zważ także, że ten naród jest twoim ludem.
14 Olúwa dáhùn wí pé, “Ojú mi yóò máa bá ọ lọ, Èmi yóò sì fún ọ ní ìsinmi.”
I PAN odpowiedział: Moje oblicze pójdzie przed tobą i dam ci odpoczynek.
15 Nígbà náà ni, Mose wí fún un pé, “Bí ojú rẹ kò bá bá wa lọ, má ṣe rán wa gòkè láti ìhín lọ.
[Mojżesz] powiedział do niego: Jeśli twoje oblicze nie pójdzie [z nami], nie wyprowadzaj nas stąd.
16 Báwo ni ẹnikẹ́ni yóò ṣe mọ̀ pé inú rẹ dùn pẹ̀lú mi àti pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ àyàfi ti o bá bá wa lọ? Kí ni yóò lè yà mí àti àwọn ènìyàn rẹ kúrò lára gbogbo ènìyàn tí ó wà ní ayé?”
Po czym bowiem będzie można poznać, że ja i twój lud znaleźliśmy łaskę w twoich oczach? Czy nie [po tym], że pójdziesz z nami? W ten sposób ja i twój lud będziemy wyróżnieni spośród wszystkich ludów, które są na ziemi.
17 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Èmi yóò ṣe ohun gbogbo tí ìwọ ti béèrè, nítorí inú mi dún sí o, Èmi sì mọ̀ ọ́n nípa orúkọ rẹ̀.”
I PAN powiedział do Mojżesza: Uczynię także to, o czym mówiłeś, bo znalazłeś łaskę w moich oczach i znam cię po imieniu.
18 Mose sì wí pé, “Nísinsin yìí fi ògo rẹ hàn mí.”
[Mojżesz] powiedział też: Ukaż mi, proszę, twoją chwałę.
19 Olúwa sì wí pé, “Èmi yóò sì mú gbogbo ìre mí kọjá níwájú rẹ, Èmi yóò sì pòkìkí orúkọ Olúwa níwájú rẹ. Èmi yóò ṣàánú fún ẹni tí Èmi yóò ṣàánú fún, Èmi yóò sì ṣoore-ọ̀fẹ́ fún ẹni tí Èmi yóò ṣoore-ọ̀fẹ́ fún.
A [on] odpowiedział: Sprawię, że cała moja dobroć przejdzie przed twoją twarzą, i wypowiem imię PANA przed tobą. Zmiłuję się, nad kim się zmiłuję, i zlituję się, nad kim się zlituję.
20 Ṣùgbọ́n,” ó wí pé, “Ìwọ kò le è rí ojú mi, nítorí kò sí ènìyàn kan tí ń rí mi, tí ó lè yè.”
I dodał: Nie będziesz mógł widzieć mego oblicza, bo nie może człowiek ujrzeć mnie i pozostać przy życiu.
21 Olúwa sì wí pé, “Ibìkan wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀dọ̀ mi, níbi tí o ti lè dúró lórí àpáta.
PAN mówił dalej: Oto miejsce przy mnie, staniesz na skale.
22 Nígbà tí ògo mi bá kọjá, Èmi yóò gbé ọ sínú pàlàpálá àpáta, Èmi yóò sì bò ọ́ pẹ̀lú ọwọ́ mi títí Èmi yóò fi rékọjá.
A gdy będzie przechodzić moja chwała, postawię cię w rozpadlinie skalnej i zakryję cię swoją dłonią, aż przejdę.
23 Nígbà tí Èmi yóò mú ọwọ́ mi kúrò, ìwọ yóò sì rí ẹ̀yìn mi; ṣùgbọ́n ojú mi ni o kò ní rí.”
Potem odejmę dłoń i ujrzysz mnie od tyłu, ale moje oblicze nie będzie widziane.

< Exodus 33 >