< Exodus 30 >

1 “Ìwọ yóò sì ṣe pẹpẹ igi kasia kan; máa jó tùràrí lórí rẹ̀.
Uczynisz też ołtarz do spalania kadzidła. Uczynisz go z drewna akacjowego.
2 Kí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin rẹ̀ ṣe déédé, kí ó jẹ́ ìdajì mita ní gígùn, ìdajì mita ní fífẹ̀ àti ìgbọ̀nwọ́ méjì ni gíga rẹ̀—kí ìwo rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
Na łokieć długi i na łokieć szeroki, będzie kwadratowy, na dwa łokcie wysoki. Jego rogi [będą] z tego samego.
3 Ìwọ yóò sì bo òkè rẹ̀, gbogbo ìhà rẹ̀ àti ìwo rẹ̀ pẹ̀lú u kìkì wúrà, ìwọ yóò sì ṣe wúrà gbà á yíká.
Pokryjesz go szczerym złotem, jego wierzch i ściany wokoło oraz rogi. Uczynisz też dokoła niego złotą listwę.
4 Ìwọ yóò sì ṣe òrùka wúrà méjì fún pẹpẹ náà níṣàlẹ̀ ìgbátí méjèèjì ní òdìkejì ìhà rẹ̀—láti gbá àwọn òpó rẹ̀ mú, láti lè máa fi gbé e.
Pod listwą, na dwóch jego narożnikach, po obu jego stronach, uczynisz też dwa złote pierścienie, a przez nie przewleczesz drążki, aby był na nich noszony.
5 Ìwọ yóò sì ṣe òpó igi kasia, ìwọ yóò sì bọ́ wọ́n pẹ̀lú wúrà.
Drążki te uczynisz z drewna akacjowego i pokryjesz je złotem.
6 Ìwọ yóò gbé pẹpẹ náà sí iwájú aṣọ ìkélé, èyí tí ó wà níwájú àpótí ẹ̀rí níwájú ìtẹ́ àánú èyí tí ó wà lórí àpótí ẹ̀rí níbi ti èmi yóò ti máa bá ọ pàdé.
Następnie postawisz go przed zasłoną, za którą jest arka świadectwa, przed przebłagalnią, która jest nad świadectwem, gdzie będę się z tobą spotykać.
7 “Aaroni yóò sì máa jó tùràrí dídùn lórí pẹpẹ náà ní àràárọ̀, nígbà tí ó tún àwọn fìtílà náà ṣe.
I każdego poranka Aaron będzie spalał na nim wonne kadzidło. Gdy będzie przygotowywał lampy, będzie je spalał.
8 Aaroni yóò sì tún jó tùràrí nígbà tí ó bá tan fìtílà ní àṣálẹ́, bẹ́ẹ̀ ní tùràrí yóò máa jó títí láé níwájú Olúwa fún àwọn ìran tó ń bọ̀.
Także wieczorem, gdy Aaron rozpali lampy, będzie spalał kadzidło, [będzie to] ustawiczne kadzenie przed PANEM przez wszystkie wasze pokolenia.
9 Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ mú àjèjì tùràrí wá sórí pẹpẹ yìí tàbí ẹbọ sísun kankan tàbí ọrẹ oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò gbọdọ̀ da ẹbọ ohun mímu sórí i rẹ̀.
Nie składajcie na nim obcego kadzidła ani całopalenia, ani ofiary pokarmowej, nie będziecie też na nim składać ofiary z płynów.
10 Aaroni yóò sì máa ṣe ètùtù sórí àwọn ìwo rẹ̀ lẹ́ẹ̀kan lọ́dún. Òun yóò sì máa ṣe ètùtù ọdọọdún yìí pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ètùtù fún ìran tó ń bọ̀. Mímọ́ jùlọ ni sí Olúwa.”
Tylko raz do roku Aaron dokona na jego rogach przebłagania krwią z ofiary na przebłaganie grzechu. Raz do roku odprawi przebłaganie na nim przez wszystkie wasze pokolenia. Będzie to najświętsza rzecz dla PANA.
11 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Mose pé,
Potem PAN powiedział do Mojżesza:
12 “Nígbà tí ìwọ bá ka iye àwọn ọmọ Israẹli láti mọ iye wọn, ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn gbọdọ̀ mú ìràpadà ọkàn rẹ̀ wá fún Olúwa ní ìgbà tí o bá ka iye wọn. Nígbà náà ni àjàkálẹ̀-ààrùn kì yóò súnmọ́ wọn, nígbà tí o bá ń ka iye wọn.
Gdy przeliczysz synów Izraela podlegających spisowi, każdy da PANU okup za swą duszę podczas spisu, aby nie dotknęła ich plaga, gdy będą zliczeni.
13 Olúkúlùkù ẹrù tí ó bá kọjá lọ sọ́dọ̀ àwọn tí a ti kà yóò san ìdajì ṣékélì, gẹ́gẹ́ bí ṣékélì ibi mímọ́, èyí tí ó wọn ogún gera. Ìdajì ṣékélì yìí ní ọrẹ fún Olúwa.
To będzie dawać każdy, kto podlega spisowi: pół sykla według sykla świątynnego – sykl to dwadzieścia ger. Pół sykla wyniesie więc ofiara dla PANA.
14 Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá sínú àwọn tí a kà láti ẹni ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ, ni yóò fi ọrẹ fún Olúwa.
Każdy podległy spisowi, od dwudziestego roku życia wzwyż, odda PANU ofiarę.
15 Àwọn olówó kì yóò san ju ìdajì ṣékélì lọ, àwọn tálákà kò sì gbọdọ̀ dín ní ìdajì ṣékélì nígbà tí ẹ̀yin bá mú ọrẹ wá fún Olúwa láti ṣe ètùtù fún ọkàn yín.
Bogaty nie da więcej, a ubogi nie da mniej niż pół sykla, gdy będą dawać PANU ofiarę na przebłaganie za swoje dusze.
16 Ìwọ yóò sì gba owó ètùtù náà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Israẹli, ìwọ yóò sì fi lélẹ̀ fún ìsìn àgọ́ àjọ. Yóò jẹ́ ìrántí fún àwọn ọmọ Israẹli níwájú Olúwa, láti ṣe ètùtù fún ọkàn yín.”
A weźmiesz pieniądze przebłagania od synów Izraela i dasz je na służbę Namiotu Zgromadzenia. Będzie to dla synów Izraela pamiątką przed PANEM, na przebłaganie za wasze dusze.
17 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Mose pé,
Potem PAN powiedział do Mojżesza:
18 “Ìwọ yóò sì ṣe agbada idẹ kan, àti ẹsẹ̀ rẹ̀ idẹ, fún wíwẹ̀. Ìwọ yóò sì gbé e sí àárín àgọ́ àjọ àti pẹpẹ náà, ìwọ yóò sì pọn omi sínú rẹ̀.
Uczynisz też miedzianą kadź do obmywania i do niej miedzianą podstawę i postawisz ją między Namiotem Zgromadzenia a ołtarzem, i nalejesz do niej wody.
19 Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wẹ ọwọ́ àti ẹsẹ̀ wọn pẹ̀lú omi tí ó wà nínú rẹ̀.
Aaron i jego synowie będą w niej obmywać swoje ręce i nogi.
20 Nígbàkígbà tí wọ́n bá wọ inú àgọ́ àjọ, wọ́n yóò wẹ̀ pẹ̀lú omi nítorí kí wọ́n má ba à kú. Bákan náà, nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ ibi pẹpẹ láti ṣe ìsìn, láti mú ẹbọ ti a fi iná sun wá fún Olúwa,
Gdy będą wchodzić do Namiotu Zgromadzenia, obmyją się wodą, aby nie pomarli. Podobnie gdy będą przystępować do ołtarza, aby służyć i spalać ofiarę ogniową dla PANA;
21 wọn yóò sì wẹ ọwọ́ wọn àti ẹsẹ̀ wọn, nítorí kí wọn máa ba à kú. Èyí ni yóò jẹ́ ìlànà títí láé fún Aaroni àti irú àwọn ọmọ rẹ̀ fún ìrandíran wọn.”
Obmyją swoje ręce i nogi, aby nie pomarli. Będzie to dla nich wieczną ustawą, dla niego i jego potomstwa, przez wszystkie ich pokolenia.
22 Olúwa sọ fún Mose pé,
PAN powiedział jeszcze do Mojżesza:
23 “Ìwọ yóò mú ààyò tùràrí olóòórùn sí ọ̀dọ̀ rẹ; ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ṣékélì (kilogiramu mẹ́fà) tí òjìá ṣíṣàn, ìdajì bí ó bá yẹ àádọ́ta lé nígba ṣékélì tí kinamoni dídùn, àti kénì dídùn àádọ́ta lé nígba ṣékélì,
Weź sobie też najlepsze wonności: pięćset [syklów] najczystszej mirry, połowę tego, czyli dwieście pięćdziesiąt [syklów], wonnego cynamonu i dwieście pięćdziesiąt [syklów] ziela tataraku;
24 kasia ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ṣékélì gbogbo rẹ̀ ní ìlànà ṣékélì ibi mímọ́ àti hínì òróró olifi kan (lita mẹ́rin).
Pięćset [syklów] kasji według sykla świątynnego i hin oliwy z oliwek.
25 Ṣe ìwọ̀nyí ní òróró mímọ́ ìkunra, tí a pò gẹ́gẹ́ bí olùṣe òórùn dídùn tì í ṣe. Yóò jẹ òróró mímọ́ ìtasórí.
Uczynisz z tego święty olejek do namaszczenia, wyborną maść, dzieło zielarza. Będzie [to] święty olejek do namaszczenia.
26 Ìwọ yóò sì lò ó láti ya àgọ́ sí mímọ́ àti àpótí ẹ̀rí náà,
Namaścisz nim Namiot Zgromadzenia i arkę świadectwa;
27 tábìlì àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, ọ̀pá fìtílà àti ohun èlò rẹ̀, àti pẹpẹ tùràrí,
I stół wraz ze wszystkimi jego naczyniami, świecznik i jego przybory oraz ołtarz kadzenia;
28 pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, àti agbada pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀.
Ołtarz [do] całopalenia ze wszystkimi jego naczyniami i kadź z jej podstawą.
29 Ìwọ yóò sì sọ wọ́n di mímọ́, nítorí kí wọn lè jẹ́ mímọ́ jùlọ, àti ohunkóhun tí ó bá fi ọwọ́ kàn wọn yóò di mímọ́.
I poświęcisz je, aby stały się najświętsze. Ktokolwiek się ich dotknie, musi być poświęcony.
30 “Ìwọ yóò sì ta òróró sí orí Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, ìwọ yóò sì sọ wọ́n di mímọ́, nítorí kí wọn lè sìn mí bí àlùfáà.
Namaścisz też Aarona i jego synów i poświęcisz ich, aby mi sprawowali urząd kapłański.
31 Ìwọ yóò sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Èyí ni yóò ṣe òróró mímọ́ ìtasórí mi fún ìrandíran tó ń bọ̀.
Synom Izraela powiesz: To będzie dla mnie świętym olejkiem namaszczenia przez wszystkie wasze pokolenia;
32 Má ṣe dà á sí ara ènìyàn kí o má sì ṣe ṣe òróró kankan ni irú rẹ̀. Mímọ́ ni, ẹ̀yin sì gbọdọ̀ kà á sí mímọ́.
Nie wolno go wylewać na ciało człowieka i nie wolno sporządzić [innego] o podobnym składzie, [bo] jest święty i dla was będzie święty.
33 Ẹnikẹ́ni tí ó bá po irú rẹ̀, tàbí ẹnikẹ́ni tí ó bá fi sára àlejò yàtọ̀ sí àlùfáà, a ó gé e kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.’”
Ktokolwiek sporządzi podobny i namaści nim [kogoś] obcego, będzie wykluczony ze swego ludu.
34 Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú tùràrí olóòórùn dídùn sọ́dọ̀ rẹ, onika, àti galibanumu àti kìkì tùràrí dáradára, òsùwọ̀n kan fún gbogbo rẹ,
I PAN powiedział do Mojżesza: Weź sobie wonności: balsam, onychę, wonne galbanum i czyste kadzidło, wszystko o takiej samej wadze;
35 ṣe tùràrí olóòórùn dídùn tí a pò, iṣẹ́ àwọn olóòórùn, tí ó ní iyọ̀, ó dára, ó sì jẹ́ mímọ́.
I uczynisz z tego wonne kadzidło, dzieło zielarza, dobrze mieszane, czyste i święte.
36 Ìwọ yóò sì lọ díẹ̀ nínú rẹ̀ kúnná, ìwọ yóò sì gbé e síwájú ẹ̀rí ní àgọ́ àjọ, níbi tí èmi yóò ti pàdé yín. Yóò sì jẹ́ mímọ́ jùlọ fún yín.
[Część] z niego zetrzesz [na proszek] i będziesz go kłaść przed świadectwem w Namiocie Zgromadzenia, gdzie będę się z tobą spotykać. Będzie to najświętsze.
37 Ẹ má ṣe ṣe tùràrí kankan ní irú èyí fúnra yín; ẹ kà á ní mímọ́ sí Olúwa.
Kadzideł, które sporządzicie według tego składu, nie sporządzicie dla siebie. Będzie to święte dla PANA.
38 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe irú rẹ̀ láti máa gbádùn òórùn rẹ̀, òun ni a ó gé kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.”
Ktokolwiek by uczynił coś podobnego, aby rozkoszować się jego wonią, będzie wykluczony ze swego ludu.

< Exodus 30 >