< Exodus 23 >

1 “Ìwọ kò gbọdọ̀ tan ìròyìn èké kalẹ̀. Ìwọ kò gbọdọ̀ ran ènìyàn búburú lọ́wọ́ láti jẹ́rìí èké.
Nie będziesz rozgłaszał fałszywych wieści. Nie wchodź w spółkę z bezbożnym, by być fałszywym świadkiem.
2 “Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọ̀pọ̀ ènìyàn láti ṣe aburú. Nígbà tí ìwọ bá jẹ́rìí sí ẹjọ́, ìwọ kò gbọdọ̀ yí ìdájọ́ po nípa gbígbé lẹ́yìn ọ̀pọ̀ ènìyàn.
Nie idź za większością, aby wyrządzić zło, i nie zeznawaj w sprawie, ulegając [zdaniu] większości, by naginać [sąd].
3 Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúsàájú sí tálákà nínú ẹjọ́ rẹ̀.
I nie okazuj przychylności ubogiemu w jego sprawie.
4 “Bí ìwọ bá ṣe alábàápàdé akọ màlúù tàbí akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ọ̀tá rẹ tí ó ṣìnà lọ, rí i dájú pé o mú un padà wá fún un.
Jeśli napotkasz błądzącego wołu swego wroga lub jego osła, musisz odprowadzić go do niego.
5 Bí ìwọ bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹnìkan tí ó kórìíra rẹ tí ẹrù ṣubú lé lórí, má ṣe fi í sílẹ̀ bẹ́ẹ̀; rí i dájú pé o ran án lọ́wọ́ nípa rẹ.
Jeśli zobaczysz, że osioł tego, który cię nienawidzi, leży pod swoim ciężarem, nie odmówisz mu pomocy. Owszem, masz mu z nim pomóc.
6 “Ìwọ kò gbọdọ̀ du aláìní ní ìdájọ́ òdodo.
Nie naginaj sądu twego ubogiego w jego sprawie.
7 Má ṣe lọ́wọ́ nínú ẹ̀sùn èké, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ pa aláìṣẹ̀ tàbí olódodo ènìyàn, nítorí Èmi kò ní dá ẹlẹ́bi láre.
Trzymaj się z dala od nieuczciwej sprawy. Nie zabijaj niewinnego i sprawiedliwego, bo nie usprawiedliwię bezbożnego.
8 “Ìwọ kò gbọdọ̀ gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀, nítorí pé àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ń fọ́ ojú ọlọ́gbọ́n, ó sì ń ba ọ̀rọ̀ olódodo jẹ́.
Nie będziesz też brać darów, ponieważ dar zaślepia mądrych i wypacza słowa sprawiedliwych.
9 “Ìwọ kò gbọdọ̀ pọ́n àjèjì kan lójú, ẹ̀yin sa ti mọ inú àjèjì, nítorí ẹ̀yin náà ti jẹ́ àjèjì ní ilẹ̀ Ejibiti.
Nie uciskaj również przybysza, bo sami wiecie, jak się czuje przybysz, gdyż byliście przybyszami w ziemi Egiptu.
10 “Ní ọdún mẹ́fà ni ìwọ yóò gbin oko rẹ, ìwọ yóò sì kóre èso rẹ̀.
Przez sześć lat będziesz obsiewał swoją ziemię i zbierał jej plony;
11 Ṣùgbọ́n ní ọdún keje, jẹ́ kí ilẹ̀ náà wà ní àìkọ àti ní àìlò, jẹ́ kí ilẹ̀ náà kí ó sinmi. Nígbà náà ni tálákà láàrín yín yóò rí oúnjẹ láti ibẹ̀. Ẹranko igbó yóò sì jẹ èyí tí wọ́n fi sílẹ̀. Ìwọ ṣe bákan náà pẹ̀lú ọgbà àjàrà rẹ àti ọgbà olifi rẹ.
A w siódmym [roku] zostawisz ją odłogiem, żeby odpoczęła, aby jedli ubodzy twego ludu, a co zostanie po nich, zjedzą zwierzęta polne. Tak też postąpisz ze swoją winnicą i swoim sadem oliwnym.
12 “Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò ṣe iṣẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì sinmi ní ọjọ́ keje, kí akọ màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ bá à lè ní ìsinmi, kí a sì tú ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti àlejò ti ń gbé ni ilé rẹ lára.
Przez sześć dni będziesz wykonywać swoją pracę, ale siódmego dnia odpoczniesz, aby odpoczął twój wół i twój osioł i [żeby] odetchnął syn twojej niewolnicy i przybysz.
13 “Ẹ máa ṣọ́ra, kí ẹ sì ṣe ohun gbogbo tí mo wí fún un yín. Ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà, kí a má ṣe gbọ́ orúkọ wọn ní ẹnu yín.
A we wszystkim, co wam powiedziałem, bądźcie ostrożni. Nie wspominajcie też imienia obcych bogów, niech nie będzie słyszane z twoich ust.
14 “Ní ìgbà mẹ́ta ni ìwọ yóò ṣe àjọ fún mi nínú ọdún.
Trzy razy w roku będziesz obchodzić dla mnie święto.
15 “Ṣe àjọ àkàrà àìwú; jẹ àkàrà ti kò ní ìwúkàrà fún ọjọ́ méje, bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ. Ṣe èyí ní àkókò tí a ti yàn ní oṣù Abibu, nítorí ni oṣù yìí ni ìwọ jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá sí iwájú mi ní ọwọ́ òfo.
Będziesz obchodzić Święto Przaśników. Siedem dni będziesz jeść przaśniki, jak ci nakazałem, w miesiącu Abib, bo w nim wyszedłeś z Egiptu. Nie pokażecie się przede mną z pustymi rękami.
16 “Ṣe àjọ ìkórè pẹ̀lú èso àkọ́so ọ̀gbìn oko rẹ. “Ṣe àjọ àkójọ oko rẹ ní òpin ọdún, nígbà tí ìwọ bá kó ìre oko rẹ jọ tan.
I Święto Żniw, pierwocin twojej pracy, tego, co posiałeś na polu. I także Święto Zbiorów pod koniec roku, gdy zbierzesz z pola [owoce] swojej pracy.
17 “Ní ìgbà mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni àwọn ọkùnrin yín yóò máa wá fi ara hàn ní iwájú Olúwa Olódùmarè.
Trzy razy w roku wszyscy twoi mężczyźni mają się pokazać przed Panem BOGIEM.
18 “Ìwọ kò gbọdọ̀ rú ẹbọ ẹ̀jẹ̀ sí mi ti òun ti àkàrà tó ní ìwúkàrà. “Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rá ẹbọ àjọ mi ni kò gbọdọ̀ kù títí di òwúrọ̀.
Nie będziesz ofiarował krwi mojej ofiary z chlebem kwaszonym, a tłuszcz mojej ofiary nie zostanie przez noc aż do poranka.
19 “Mú àkọ́ká èso ilẹ̀ rẹ tí ó dára jùlọ wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ. “Ìwọ kò gbọdọ̀ bọ ọmọ ewúrẹ́ nínú omi ọmú ìyá rẹ̀.
Przyniesiesz do domu PANA, twego Boga, pierwociny z pierwszych plonów swojej ziemi. Nie będziesz gotował koźlęcia w mleku jego matki.
20 “Kíyèsi èmi rán angẹli kan lọ ní iwájú rẹ, láti ṣọ́ ọ ni ọ̀nà àti láti mú ọ dé ibi ti mo ti pèsè sílẹ̀ fún.
Oto posyłam Anioła przed tobą, aby cię strzegł w drodze i doprowadził do miejsca, które przygotowałem.
21 Fi ara balẹ̀, kí o sì fetísílẹ̀ sí i, kí o sì gba ohùn rẹ̀ gbọ́; má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí i, nítorí kò ní fi àìṣedéédéé yín jì yín, orúkọ mi wà lára rẹ̀.
Zważaj na niego i słuchaj jego głosu; nie pobudzaj go do gniewu, bo nie przebaczy waszych przestępstw, gdyż moje imię jest w nim.
22 Bí ìwọ bá fetísílẹ̀ dáradára sí ohùn rẹ̀ tí ẹ sì ṣe ohun gbogbo ti mo ní kí ẹ ṣe, èmi yóò jẹ́ ọ̀tá àwọn ọ̀tá yín. Èmi yóò sì fóòro àwọn tí ń fóòro yín.
Bo jeśli będziesz pilnie słuchać jego głosu i uczynisz wszystko, co powiem, będę wrogiem twoich wrogów i będę dręczyć tych, którzy cię dręczyli.
23 Angẹli mi yóò lọ níwájú rẹ, yóò sì mú ọ dé ọ̀dọ̀ àwọn ará: Amori, Hiti, Peresi, Kenaani, Hifi àti Jebusi, èmi a sì gé wọn kúrò.
Mój Anioł bowiem pójdzie przed tobą i wprowadzi cię do Amorytów, Chetytów, Peryzzytów, Kananejczyków, Chiwwitów i Jebusytów, i wytracę ich.
24 Ìwọ kò gbọdọ̀ foríbalẹ̀ fún òrìṣà wọn, bẹ́ẹ̀ ni, ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n, tàbí kí ẹ tẹ̀lé ìṣe wọn. Kí ìwọ kí ó si wó wọn lulẹ̀, kí ìwọ kí ó sì fọ́ ère òkúta wọ́n túútúú.
Nie będziesz oddawał pokłonu ich bogom ani nie będziesz im służył, ani nie postępuj według ich czynów, ale do gruntu zburz ich i doszczętnie pokrusz ich posągi.
25 Ẹ̀yin yóò sí máa sin Olúwa Ọlọ́run yin, òun yóò si bùsi oúnjẹ rẹ. Èmi yóò mú àìsàn kúrò láàrín rẹ.
Będziecie służyć PANU, waszemu Bogu, a on będzie błogosławić twój chleb i twoją wodę; i oddalę od ciebie chorobę.
26 Oyún kò ní bàjẹ́ lára obìnrin kan, bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan kì yóò yàgàn ni ilẹ̀ rẹ. Èmi yóò fún ọ ní ẹ̀mí gígùn.
Nie będzie w twojej ziemi roniącej ani niepłodnej. Dopełnię liczbę twoich dni.
27 “Èmi yóò rán ẹ̀rù mi lọ ṣáájú rẹ, ìdàrúdàpọ̀ yóò sì wà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ bá da ojú kọ. Èmi yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ yí ẹ̀yìn padà sí ọ, kí wọn sì sá ní iwájú rẹ.
Poślę mój strach przed tobą i strwożę wszelki lud, przeciw któremu pójdziesz, i sprawię, że wszyscy twoi wrogowie uciekną przed tobą.
28 Èmi yóò rán oyin ṣáájú rẹ láti lé àwọn ará: Hifi, Kenaani àti Hiti kúrò ni ọ̀nà rẹ.
Poślę też przed tobą szerszenie, które wypędzą Chiwwitów, Kananejczyków i Chetytów sprzed twego oblicza.
29 Ṣùgbọ́n, Èmi kò ni lé gbogbo wọn jáde ni ọdún kan ṣoṣo, ki ilẹ̀ náà má ba à di ahoro, àwọn ẹranko búburú yóò sì ti pọ̀jù fún ọ.
Nie wypędzę ich sprzed twojego oblicza w jednym roku, by ziemia nie zmieniła się w pustynię i nie namnożył się przeciwko tobie dziki zwierz.
30 Díẹ̀díẹ̀ ni èmi yóò máa lé wọn jáde kúrò ní iwájú rẹ, títí ìwọ yóò fi pọ̀ tó láti gba gbogbo ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí ìní.
Pomału będę ich wypędzał sprzed twego oblicza, aż się rozmnożysz i posiądziesz ziemię.
31 “Èmi yóò fi ìdí òpin ààlà ilẹ̀ rẹ lélẹ̀ láti etí Òkun Pupa títí dé òkun àwọn ara Filistini, láti aṣálẹ̀ títí dé etí odò Eufurate, Èmi yóò fa àwọn ènìyàn ti ń gbé ilẹ̀ náà lé ọ lọ́wọ́, ìwọ yóò sì lé wọn jáde kúrò ní iwájú rẹ.
A ustanowię twoje granice od Morza Czerwonego aż do Morza Filistynów, od pustyni aż do rzeki. Oddam bowiem w wasze ręce mieszkańców tej ziemi, a ty wypędzisz ich sprzed twego oblicza.
32 Ìwọ kò gbọdọ̀ dá májẹ̀mú kankan pẹ̀lú wọn tàbí pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn.
Nie zawrzesz przymierza z nimi ani z ich bogami.
33 Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́ kí wọn gbé ni ilẹ̀ rẹ, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, wọn yóò mú ọ dẹ́ṣẹ̀ sí mi: nítorí bí ìwọ bá sin òrìṣà wọn, èyí yóò jẹ́ ìdẹ̀kùn fun ọ nítòótọ́.”
Nie wolno im mieszkać w twojej ziemi, by cię nie doprowadzili do grzechu przeciwko mnie. Jeśli bowiem będziesz służył ich bogom, będzie to dla ciebie sidłem.

< Exodus 23 >