< Exodus 19 >

1 Ní oṣù kẹta tí àwọn Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti, ni ọjọ́ náà gan an ni wọ́n dé aginjù Sinai.
W trzecim miesiącu od wyjścia synów Izraela z ziemi Egiptu, w tym samym dniu, przyszli na pustynię Synaj.
2 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n gbéra kúrò ní Refidimu, wọ́n wọ ijù Sinai, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀, níbẹ̀ ni Israẹli sì dó sí ní iwájú òkè ńlá.
Bo wyruszyli z Refidim i po przybyciu na pustynię Synaj rozbili obóz na pustyni; tam Izrael obozował naprzeciw góry.
3 Mose sì gòkè tọ Ọlọ́run lọ. Olúwa sì ké pè é láti orí òkè náà wá pé, “Èyí ni ìwọ yóò sọ fún ilé Jakọbu àti ohun tí ìwọ yóò sọ fún àwọn ọmọ Israẹli:
A Mojżesz wstąpił do Boga i PAN zawołał do niego z góry: Tak powiesz domowi Jakuba i oznajmisz synom Izraela:
4 ‘Ẹ̀yin ti rí ohun tí mo ti ṣe sí àwọn ará Ejibiti, àti bí mo ti gbé e yín ní apá ìyẹ́ idì.
Widzieliście, co uczyniłem Egipcjanom i jak niosłem was na skrzydłach orłów, i przyprowadziłem was do siebie.
5 Nísinsin yìí, bí ẹ̀yin bá ṣe ìgbọ́ràn sí mi dé ojú àmì, tí ẹ sì pa májẹ̀mú mi mọ́, nígbà náà ni ẹ̀yin ó jẹ́ ìṣúra fún mi ju gbogbo orílẹ̀-èdè yòókù lọ. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé gbogbo ayé ni tèmi.
Dlatego teraz, jeśli posłuchacie mego głosu i będziecie przestrzegać mojego przymierza, będziecie moją szczególną własnością ponad wszystkie narody, bo do mnie należy cała ziemia.
6 Ẹ̀yin yóò sì máa jẹ́ ilẹ̀ ọba àwọn àlùfáà fún mi, orílẹ̀-èdè mímọ́.’ Ìwọ̀nyí ni ọ̀rọ̀ ti ìwọ yóò sọ fún àwọn ọmọ Israẹli.”
A wy będziecie mi królestwem kapłanów i narodem świętym. To są słowa, które będziesz mówić do synów Izraela.
7 Mose sì tọ àwọn ènìyàn wá, ó sí pe àwọn àgbàgbà láàrín àwọn ènìyàn jọ. Ó sì gbé gbogbo ọ̀rọ̀ ti Olúwa pàṣẹ fún un láti sọ ní iwájú wọn.
Wtedy Mojżesz przyszedł i zwołał starszych ludu, i wyłożył im wszystkie te słowa, które mu PAN nakazał.
8 Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì pa ohùn wọn pọ̀ wọ́n sì dáhùn wí pé, “Àwa yóò ṣe ohun gbogbo ti Olúwa wí.” Mose sì mú ìdáhùn wọn padà tọ Olúwa lọ.
Cały lud odpowiedział wspólnie: Uczynimy wszystko, co PAN powiedział. I Mojżesz zaniósł słowa ludu do PANA.
9 Olúwa sọ fún Mose pé, “Èmi yóò tọ̀ ọ́ wá nínú ìkùùkuu ṣíṣú dudu, kí àwọn ènìyàn lè gbọ́ ohùn mi nígbà ti mo bá ń bá ọ sọ̀rọ̀, kí wọn kí ó lè máa gbà ọ́ gbọ́.” Nígbà náà ni Mose sọ ohun tí àwọn ènìyàn wí fún Olúwa.
PAN powiedział do Mojżesza: Oto przyjdę do ciebie w gęstym obłoku, aby lud słyszał, gdy będę z tobą rozmawiał, i uwierzył ci na zawsze. A Mojżesz przekazał PANU słowa ludu.
10 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Tọ àwọn ènìyàn lọ kí o sì yà wọ́n sí mímọ́ ni òní àti ni ọ̀la. Jẹ́ kí wọn kí ó fọ aṣọ wọn.
PAN zaś mówił do Mojżesza: Idź do ludu i uświęć ich dziś i jutro, i niech wypiorą swoje szaty.
11 Kí wọn kí ó sì múra di ọjọ́ kẹta, nítorí ni ọjọ́ náà ni Olúwa yóò sọ̀kalẹ̀ sí orí òkè Sinai ni ojú gbogbo àwọn ènìyàn.
Niech będą gotowi na trzeci dzień. Trzeciego dnia bowiem PAN zstąpi na oczach całego ludu na górę Synaj.
12 Kí ìwọ kí ó ṣe ààlà fún àwọn ènìyàn, kí ìwọ kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Ẹ kíyèsí ara yín, kí ẹ má ṣe gun orí òkè lọ, kí ẹ má tilẹ̀ fi ọwọ́ ba etí rẹ̀; ẹnikẹ́ni tí ó bá fi ọwọ́ kan òkè náà, ó dájú, pípa ni a ó pa á.
I wyznaczysz ludowi granice dokoła, mówiąc: Strzeżcie się, abyście nie wstępowali na górę ani nie dotykali jej podnóża. Każdy, kto dotknie góry, poniesie śmierć.
13 A ó sọ ọ́ ní òkúta tàbí kí a ta á ní ọfà, ọwọ́kọ́wọ́ kò gbọdọ̀ kàn án. Ìbá à ṣe ènìyàn tàbí ẹranko, òun kì yóò wà láààyè.’ Nígbà ti ìpè bá dún nìkan ni kí wọn ó gun òkè wá.”
Nie dotknie go ręka, ale ukamienują [go] albo przeszyją strzałami; czy to zwierzę, czy człowiek, nie będzie żyć. Gdy przeciągle będą trąbić, niech podejdą do góry.
14 Mose sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà wá sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn, ó yà wọ́n sí mímọ́, wọ́n sì fọ aṣọ wọn.
Mojżesz zstąpił więc z góry do ludu i uświęcił lud, a oni uprali swoje szaty.
15 Ó sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ múra sílẹ̀ di ọjọ́ kẹta; ẹ má ṣe bá aya yín lòpọ̀.”
I mówił do ludu: Bądźcie gotowi na trzeci dzień, nie zbliżajcie się do żon.
16 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kẹta, àrá àti mọ̀nàmọ́ná sì wà pẹ̀lú ìkùùkuu tí ó ṣú dudu ní orí òkè, ìpè ńlá sì dún kíkankíkan tó bẹ́ẹ̀ tí gbogbo àwọn tí ó wà ni ibùdó wárìrì.
Trzeciego dnia o poranku pojawiły się grzmoty i błyskawice, i gęsty obłok nad górą, i bardzo potężny głos trąby, tak że cały lud, który był w obozie, zadrżał.
17 Mose sì kó àwọn ènìyàn tí ó jáde láti ibùdó wá pàdé Ọlọ́run, wọ́n dúró nítòsí òkè.
I Mojżesz wyprowadził lud z obozu na spotkanie z Bogiem, i stanęli u stóp góry.
18 Èéfín sì bo òkè Sinai nítorí Olúwa sọ̀kalẹ̀ sí orí rẹ̀ nínú iná. Èéfín náà sì ń ru sókè bí èéfín iná ìléru, gbogbo òkè náà sì mì tìtì.
A góra Synaj cała dymiła, gdyż PAN zstąpił na nią w ogniu. Dym unosił się z niej jak dym z pieca i cała góra bardzo się trzęsła.
19 Ohùn ìpè sì ń rinlẹ̀ dòdò. Mose sọ̀rọ̀, Ọlọ́run sì fi àrá dá a lóhùn.
A gdy głos trąby się przeciągał i coraz bardziej się rozlegał, Mojżesz mówił, a Bóg odpowiadał mu głosem.
20 Olúwa sọ̀kalẹ̀ sí orí òkè Sinai, o sì pe Mose wá sí orí òkè náà. Mose sì gun orí òkè.
I PAN zstąpił na górę Synaj, na szczyt góry. Wtedy PAN wezwał Mojżesza na szczyt góry i Mojżesz [tam] wstąpił.
21 Olúwa sọ fún Mose pé, “Sọ̀kalẹ̀, kí ó sì kìlọ̀ fún àwọn ènìyàn, kí wọn má ṣe fi tipátipá wá ọ̀nà láti wo Olúwa, bí wọn bá ṣe bẹ́ẹ̀, ọ̀pọ̀ wọn yóò ṣègbé.
Potem PAN powiedział do Mojżesza: Zejdź, przestrzeż lud, by nie przekroczył granicy, aby zobaczyć PANA, i aby wielu z nich nie zginęło.
22 Kódà àwọn àlùfáà tí ó ń wá síwájú Olúwa gbọdọ̀ ya ara wọn sí mímọ́ bí bẹ́ẹ̀ kọ́. Olúwa yóò kọlù wọ́n.”
Nawet kapłani, którzy zbliżają się do PANA, niech się uświęcą, by ich PAN nie wytracił.
23 Mose wí fún Olúwa pé, “Àwọn ènìyàn kì yóò lè wá sí orí òkè Sinai, nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ti kìlọ̀ fún wa pé, ‘Ṣe ààlà yí òkè ká, kí o sì yà á sí mímọ́.’”
I Mojżesz powiedział do PANA: Lud nie może wejść na górę Synaj, ponieważ ty nas przestrzegłeś, mówiąc: Wyznacz granice wokół góry i uświęć ją.
24 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ, mú Aaroni gòkè wá pẹ̀lú rẹ. Ṣùgbọ́n kí àwọn àlùfáà àti àwọn ènìyàn má ṣe fi tipátipá gòkè tọ Olúwa. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ yóò kọlù wọ́n.”
PAN powiedział do niego: Idź, zejdź, a [potem] wstąpisz ty i Aaron z tobą. Lecz kapłani i lud niech nie przekraczają [granicy], by wstąpić do PANA, aby ich nie wytracił.
25 Mose sọ̀kalẹ̀ tọ àwọn ènìyàn lọ. Ó sì sọ ohun tí Olúwa wí fún wọn.
Mojżesz zszedł więc do ludu i powiedział im to.

< Exodus 19 >