< Exodus 16 >

1 Ìjọ àwọn ọmọ Israẹli mú ọ̀nà wọn pọ̀n kúrò ni Elimu, wọ́n dé sí ijù Sini tí ó wà láàrín Elimu àti Sinai, ni ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kejì tí wọ́n jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
Potem wyruszyli z Elim i całe zgromadzenie synów Izraela przybyło na pustynię Sin, która [leży] między Elim a Synajem, piętnastego dnia drugiego miesiąca po ich wyjściu z ziemi Egiptu.
2 Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sì ń kùn sí Mose àti Aaroni ní ijù náà.
I całe zgromadzenie synów Izraela szemrało przeciw Mojżeszowi i Aaronowi na pustyni.
3 Àwọn ọmọ Israẹli wí fún wọn pé, “Àwa ìbá ti ọwọ́ Olúwa kú ni Ejibiti! Níbi tí àwa ti jókòó ti ìkòkò ẹran ti a sì ń jẹ ohun gbogbo tí a fẹ́ ni àjẹyó, ṣùgbọ́n ẹ̀yin mú wa wá sí inú ijù yìí láti fi ebi pa wá tí a ó fi kú.”
Synowie Izraela mówili do nich: Obyśmy pomarli z ręki PANA w ziemi Egiptu, gdy siadaliśmy nad garncami mięsa, gdy najadaliśmy się chleba do syta! Bo wyprowadziliście nas na tę pustynię, by całą tę rzeszę zamorzyć głodem.
4 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Èmi yóò rọ òjò oúnjẹ láti ọ̀run wá fún yín. Àwọn ènìyàn yóò sì máa jáde lọ ni ọjọ́ kọ̀ọ̀kan láti kó ìwọ̀nba oúnjẹ ti ó tó fún oúnjẹ òòjọ́ wọn. Ní ọ̀nà yìí ni, èmi yóò fi dán wọn wò láti mọ bóyá wọn yóò máa tẹ̀lé ìlànà mi.
Wtedy PAN powiedział do Mojżesza: Oto spuszczę wam jak deszcz chleb z nieba. Lud będzie wychodził i każdego dnia będzie zbierał według potrzeby dziennej, abym mógł go wystawić na próbę, czy będzie postępował zgodnie z moim prawem, czy nie.
5 Ní ọjọ́ kẹfà, ki wọn kó ìlọ́po méjì èyí tiwọn ń ko ni ojoojúmọ́ tẹ́lẹ̀.”
A szóstego dnia przyrządzą [to], co przyniosą, a będzie tego dwa razy tyle, co zbierają codziennie.
6 Mose àti Aaroni sọ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ní ìrọ̀lẹ́, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ni ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá.
Mojżesz i Aaron mówili do wszystkich synów Izraela: Wieczorem poznacie, że PAN wyprowadził was z ziemi Egiptu;
7 Ní òwúrọ̀, ẹ̀yin yóò ri ògo Olúwa, nítorí òun ti gbọ́ kíkùn tí ẹ kùn sí i. Ta ni àwa ti ẹ̀yin yóò máa kùn sí wa?”
A rano ujrzycie chwałę PANA, usłyszał bowiem wasze szemrania przeciw PANU. A my, czym jesteśmy, że szemrzecie przeciwko nam?
8 Mose tún wí pé, “Ẹ̀yin yóò mọ pé Olúwa ni, nígbà ti ó bá fún un yín ni ẹran ni ìrọ̀lẹ́ àti gbogbo oúnjẹ ti ẹ̀yin ń fẹ́ ni òwúrọ̀, nítorí kíkùn ti ẹ̀yin ń kùn sí i. Ta ni àwa? Ẹ̀yin kò kùn sí àwa, Olúwa ni ẹ̀yin kùn sí i.”
Mojżesz mówił dalej: PAN da wam wieczorem mięso do jedzenia, a rano chleb do syta. PAN bowiem usłyszał wasze szemrania, które podnosicie przeciw niemu. A my, czym jesteśmy? Wasze szemrania nie [są] przeciwko nam, ale przeciwko PANU.
9 Nígbà náà ni Mose sọ fún Aaroni pe, “Sọ fún gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli pe, ‘Ẹ wá sí iwájú Olúwa, nítorí òun ti gbọ́ kíkùn yín.’”
Mojżesz powiedział do Aarona: Powiedz całemu zgromadzeniu synów Izraela: Zbliżcie się przed oblicze PANA, gdyż usłyszał wasze szemranie.
10 Ó sì ṣe bí Aaroni ti ń bá gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, wọn si bojú wo ìhà ijù, sì kíyèsi ògo Olúwa si farahàn ni àwọsánmọ̀.
Gdy Aaron mówił do całego zgromadzenia synów Izraela, spojrzeli w stronę pustyni, a oto chwała PANA ukazała się w obłoku.
11 Olúwa sọ fún Mose pé,
Potem PAN powiedział do Mojżesza:
12 “Èmi ti gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli. Sọ fun wọn, ‘Ní àṣálẹ́, ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, àti ni òwúrọ̀ ni ẹ̀yin yóò jẹ oúnjẹ. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
Usłyszałem szemranie synów Izraela. Powiedz do nich: Pod wieczór będziecie jeść mięso, a rano będziecie nasyceni chlebem. I poznacie, że ja jestem PAN, wasz Bóg.
13 Ní àṣálẹ́ ọjọ́ náà ni àwọn àparò fò dé, wọ́n sì bo àgọ́ mọ́lẹ̀, ní òwúrọ̀ ìrì sì sẹ̀ yí gbogbo àgọ́ náà ká.
Wieczorem stało się tak, że zleciały się przepiórki i pokryły obóz, a rano dokoła obozu leżała rosa;
14 Nígbà tí ìrì tí ó sẹ̀ bo ilẹ̀ ti lọ, kíyèsi i, ohun tí ó dì, tí ó sì ń yooru bí i yìnyín wà lórí ilẹ̀.
A gdy warstwa rosy się uniosła, ukazało się na [powierzchni] pustyni [coś] bardzo małego, okrągłego, drobnego jak szron na ziemi.
15 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli rí i, wọ́n bi ara wọn léèrè pé, “Kí ni èyí?” Nítorí pé wọn kò mọ ohun tí i ṣe. Mose sì wí fún wọn pé, “Èyí ni oúnjẹ tí Olúwa fi fún un yín láti jẹ.
Gdy synowie Izraela to zobaczyli, mówili jeden do drugiego: To manna, gdyż nie wiedzieli, co to było. I Mojżesz powiedział do nich: To [jest] chleb, który PAN dał wam do jedzenia.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa ti pàṣẹ, ‘Kí olúkúlùkù máa kó èyí ti ó tó fún un láti jẹ. Ẹ mú òsùwọ̀n omeri kan fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ti ó wà nínú àgọ́ yín.’”
Oto co PAN rozkazał: Niech każdy zbiera z niego tyle, ile trzeba do jedzenia, omer na osobę, [według] liczby osób. Niech każdy zbiera dla tych, którzy są w jego namiocie.
17 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bí a ti sọ fún wọn; àwọn kan kó púpọ̀, àwọn kan kó kékeré.
I synowie Izraela tak uczynili, i zbierali jedni więcej, drudzy mniej.
18 Nígbà tí wọ́n fi òsùwọ̀n omeri wọ̀n-ọ́n, ẹni tí ó kó púpọ̀ kò ní púpọ̀ jù, bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó kó ìwọ̀nba kò ní kéré jù. Ẹnìkọ̀ọ̀kan kó ìwọ̀nba ti ó tó fún un.
A gdy [to] mierzyli omerem, to [ten], kto nazbierał więcej, nie miał nadmiaru, [temu] zaś, kto nazbierał mało, nie zabrakło. Każdy zbierał według tego, co mógł zjeść.
19 Mose sì wí fún wọ́n pé, “Kí ẹnikẹ́ni ó má ṣe kó pamọ́ lára rẹ̀ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì.”
Mojżesz mówił też do nich: Niech nikt nie pozostawia z tego nic do rana.
20 Ṣùgbọ́n, àwọn kan nínú wọn kò fetí sí Mose, wọ́n kó lára rẹ̀ pamọ́ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ohun ti wọ́n kó pamọ́ kún fún ìdin, ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní rùn. Nítorí náà Mose bínú sí wọn.
Jednak nie usłuchali Mojżesza i zostawili niektórzy z tego aż do rana, i zamieniło się w robaki, i cuchnęło. I Mojżesz rozgniewał się na nich.
21 Ní òwúrọ̀, ni ojoojúmọ́ ni ẹnìkọ̀ọ̀kan ń lọ kó ìwọ̀nba ti ó tó fún un láti jẹ, bí oòrùn bá sì mú, a sì yọ́.
Zbierali to więc każdego ranka, każdy według [tego], co mógł zjeść. A gdy słońce zaczynało grzać, topniało.
22 Ní ọjọ́ kẹfà, wọ́n kó ìlọ́po méjì èyí tiwọn ń kó tẹ́lẹ̀: òsùwọ̀n omeri méjì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan; àwọn olórí ìjọ ènìyàn sì wá, wọ́n sì sọ èyí fún Mose.
A gdy nastał szósty dzień, zbierali dwa razy więcej chleba, po dwa omery na każdego. I wszyscy przełożeni zgromadzenia przyszli i powiedzieli o tym Mojżeszowi.
23 Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ: ‘Ọ̀la jẹ́ ọjọ́ ìsinmi, ìsinmi mímọ́ fún Olúwa. Ẹ yan èyí ti ẹ̀yin ní yan, kí ẹ sì bọ èyí ti ẹ̀yin ní bọ̀. Ẹ tọ́jú èyí ti ó kù sílẹ̀, kí ẹ pa á mọ́ di òwúrọ̀.’”
On zaś powiedział im: Oto co PAN mówił: Jutro [będzie] odpoczynek, święty szabat dla PANA. Upieczcie, co macie upiec, ugotujcie, co macie ugotować, a co zostanie, zostawcie sobie i zachowajcie do jutra.
24 Wọ́n sì tọ́jú rẹ̀ di òwúrọ̀ bí Mose ti pàṣẹ; kò sì rùn bẹ́ẹ̀ ni kò sì ní ìdin.
Zostawili więc to do rana, jak Mojżesz rozkazał, i nie cuchnęło ani nie było w tym robaków.
25 Mose sì wí fún wọn pé, “Ẹ jẹ ẹ́ ní òní nítorí òní jẹ́ ọjọ́ ìsinmi Olúwa. Ẹ̀yin kò ni rí i ni orí ilẹ̀ ní ọjọ́ òní.
I Mojżesz powiedział: Jedzcie to dziś, bo dziś jest szabat dla PANA. Dziś nie znajdziecie tego na polu.
26 Ní ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi kó o, ṣùgbọ́n ni ọjọ́ keje ọjọ́ ìsinmi, kò ní sí i fún un yín ni ọjọ́ náà.”
Przez sześć dni będziecie to zbierać, a w siódmym dniu jest szabat, w nim tego nie będzie.
27 Síbẹ̀síbẹ̀ àwọn ènìyàn kan jáde lọ ní ọjọ́ keje láti kó o, ṣùgbọ́n wọn kò ri nǹkan kan kó.
A siódmego dnia [niektórzy] z ludu wyszli, aby zbierać, ale nic nie znaleźli.
28 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Yóò ti pẹ́ tó ti ẹ ó kọ̀ láti pa àṣẹ mi àti ìlànà mi mọ́?
Wtedy PAN powiedział do Mojżesza: Jak długo będziecie się wzbraniać przed przestrzeganiem moich przykazań i moich praw?
29 Wò ó? Olúwa ti fún un yín ni ọjọ́ ìsinmi, nítorí náà, ni ọjọ́ kẹfà, ó fún un yín ni oúnjẹ ọjọ́ méjì; kí ẹnìkọ̀ọ̀kan dúró ni ibi tí ó gbé wà; kí ẹ má ṣe kúrò ni ibi tí ẹ wà ni ọjọ́ keje.”
Patrzcie, PAN dał wam szabat, dlatego w szóstym dniu daje wam chleb na dwa dni. Niech każdy zostanie na swoim miejscu, niech nikt nie wychodzi ze swego miejsca w siódmym dniu.
30 Nítorí náà, àwọn ènìyàn sinmi ní ọjọ́ keje.
Odpoczywał więc lud siódmego dnia.
31 Àwọn ènìyàn Israẹli sì pe oúnjẹ náà ní manna. Ó funfun bí irúgbìn korianderi, ó sì dùn bí àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ ti a fi oyin ṣe.
I dom Izraela nadał temu [pokarmowi] nazwę manna. Była jak nasienie kolendry, biała, o smaku placków z miodem.
32 Mose wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ, ‘Ẹ mú òsùwọ̀n omeri manna kí ẹ sì pa á mọ́ de àwọn ìran ti ń bọ̀, kí wọn kí ó lè rí oúnjẹ ti èmi fi fún un yín jẹ ní ijù, nígbà tí mo mú un yín jáde ni ilẹ̀ Ejibiti.’”
Mojżesz powiedział: Tak rozkazał PAN: Napełnij nim omer na przechowanie dla waszych [przyszłych] pokoleń, aby widziały ten chleb, którym was karmiłem na pustyni, gdy wyprowadziłem was z ziemi Egiptu.
33 Nígbà náà ni Mose sọ fún Aaroni pe, “Mú ìkòkò kan, kí o sì kó manna tí ó kún òsùwọ̀n omeri kan sí inú rẹ̀, kí o sì gbé e kalẹ̀ ni iwájú Olúwa láti tọ́jú rẹ̀ pamọ́ de àwọn ìran ti ń bọ̀.”
Potem Mojżesz powiedział do Aarona: Weź naczynie, wsyp do niego pełen omer manny i postaw je przed PANEM na przechowanie dla waszych [przyszłych] pokoleń.
34 Bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, Aaroni gbé manna sí iwájú ẹ̀rí láti pa á mọ́.
Jak PAN przykazał Mojżeszowi, tak Aaron postawił je przed Świadectwem na przechowanie.
35 Àwọn ará Israẹli jẹ manna fún ogójì ọdún títí wọ́n fi dé ilẹ̀ Kenaani ni ibi ti èso ti wà fún wọn láti jẹ, wọ́n jẹ manna títí tí wọ́n fi dé ilẹ̀ agbègbè Kenaani.
A synowie Izraela jedli mannę przez czterdzieści lat, aż przybyli do ziemi zamieszkałej. Jedli mannę, aż przybyli do granic ziemi Kanaan.
36 (Òsùwọ̀n omeri kan sì jẹ́ ìdákan nínú ìdámẹ́wàá efa.)
A omer to dziesiąta część efy.

< Exodus 16 >