< Ecclesiastes 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Oniwaasu, ọmọ Dafidi, ọba Jerusalẹmu:
Słowa Kaznodziei, syna Dawida, króla w Jerozolimie.
2 “Asán inú asán!” Oníwàásù náà wí pé, “Asán inú asán! Gbogbo rẹ̀ asán ni.”
Marność nad marnościami – mówi Kaznodzieja – marność nad marnościami. Wszystko jest marnością.
3 Kí ni ènìyàn rí jẹ ní èrè lórí gbogbo iṣẹ́ rẹ̀, lórí èyí tí ó ń ṣe wàhálà sí lábẹ́ oòrùn?
Jaki pożytek ma człowiek z całego swego trudu, który podejmuje pod słońcem?
4 Bí ìran kan ti wá ni ìran mìíràn ń kọjá lọ, síbẹ̀ ayé dúró títí láé.
Jedno pokolenie przemija, [drugie] pokolenie przychodzi, lecz ziemia trwa na wieki.
5 Oòrùn ń ràn, oòrùn sì ń wọ̀, ó sì sáré padà sí ibi tí ó ti yọ.
Słońce wschodzi i słońce zachodzi, i spieszy do swego miejsca, z którego znów wschodzi.
6 Afẹ́fẹ́ ń fẹ́ lọ sí ìhà gúúsù, Ó sì ń fẹ́ yípo sí ìhà àríwá, a sì tún padà sí ọ̀nà rẹ̀.
Wiatr idzie na południe i zawraca na północ, krąży nieustannie i znowu wraca na drogę swego krążenia.
7 Gbogbo odò ń sàn sí inú Òkun, síbẹ̀síbẹ̀ Òkun kò kún. Níbi tí àwọn odò ti wá, níbẹ̀ ni wọ́n tún padà sí.
Wszystkie rzeki płyną do morza, lecz morze się nie przepełnia; do miejsca, z którego rzeki płyną, [znowu] wracają.
8 Ohun gbogbo ni ó ń mú àárẹ̀ wá, ju èyí tí ẹnu le è sọ. Ojú kò tí ì rí ìrírí tí ó tẹ́ ẹ lọ́rùn, bẹ́ẹ̀ ni, etí kò tí ì kún fún gbígbọ́.
Wszystkie rzeczy [są] pełne trudu, a człowiek nie zdoła tego wyrazić. Oko nie nasyci się patrzeniem ani ucho nie napełni się słuchaniem.
9 Ohun tí ó ti wà tẹ́lẹ̀ náà ni yóò sì máa wà, ohun tí a ti ṣe sẹ́yìn òun ni a ó tún máa ṣe padà kò sí ohun tuntun lábẹ́ oòrùn.
To, co było, jest tym, co będzie; a to, co się stało, jest tym, co się stanie. I nie ma nic nowego pod słońcem.
10 Ǹjẹ́ ohun kan wà tí ẹnìkan le è sọ wí pé, “Wò ó! Ohun tuntun ni èyí”? Ó ti wà tẹ́lẹ̀ rí ní ọjọ́ tó ti pẹ́, o ti wà ṣáájú tiwa.
Czy jest coś, o czym można by powiedzieć: Patrz, to jest coś nowego? I to już było w dawnych czasach, które były przed nami.
11 Kò sí ìrántí ohun ìṣáájú bẹ́ẹ̀ ni ìrántí kì yóò sí fún ohun ìkẹyìn tí ń bọ̀ lọ́dọ̀ àwọn tí ń bọ̀ ní ìgbà ìkẹyìn.
Nie ma pamięci o dawnych rzeczach; także o tych, które będą, nie będzie pamięci u tych, którzy potem nastaną.
12 Èmi, Oniwaasu ti jẹ ọba lórí Israẹli ní Jerusalẹmu rí.
Ja, Kaznodzieja, byłem królem nad Izraelem w Jerozolimie.
13 Mo fi àsìkò mi sílẹ̀ láti kọ́ àti láti ṣe àwárí pẹ̀lú ọgbọ́n, gbogbo ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ ọ̀run. Háà! Ẹrù wúwo tí Ọlọ́run ti gbé lé àwọn ènìyàn.
I przyłożyłem się w swoim sercu [do tego], aby mądrością szukać wszystkiego i wybadać wszystko, co się dzieje pod niebem. To uciążliwe zadanie Bóg dał synom ludzkim, aby się nim trudzili.
14 Èmi ti rí ohun gbogbo tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ oòrùn, gbogbo rẹ̀ kò ní ìtumọ̀ bí ẹní gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.
Widziałem wszystkie sprawy, jakie się dzieją pod słońcem, a oto wszystko jest marnością i utrapieniem ducha.
15 Ohun tí ó ti wọ́ kò le è ṣe é tọ́ mọ́, ohun tí kò sí kò le è ṣe é kà.
Tego, co krzywe, nie da się wyprostować, a tego, czego brak, nie da się policzyć.
16 Mo rò nínú ara mi, “Wò ó, mo ti dàgbà, ọgbọ́n mi sì ti pọ̀ ju ti ẹnikẹ́ni tí ó ti ṣe alákòóso Jerusalẹmu síwájú mi lọ, mo ti ní ìrírí púpọ̀ nípa ọgbọ́n àti ìmọ̀.”
Tak więc pomyślałem w swoim sercu: Oto wzbogaciłem się i dano mi więcej mądrości niż wszystkim, którzy byli przede mną w Jerozolimie. I moje serce doświadczyło wielkiej mądrości i wiedzy.
17 Nígbà náà ni mo fi ara jì láti ní ìmọ̀ nípa ọgbọ́n, àti pàápàá àìgbọ́n àti òmùgọ̀, ṣùgbọ́n mo rí, wí pé èyí pẹ̀lú bí ẹni ń gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.
I przyłożyłem się w swoim sercu [do tego], aby poznać mądrość, a także by poznać szaleństwo i głupotę. [Ale] poznałem, że i to jest utrapieniem ducha.
18 Nítorí pé ọgbọ́n púpọ̀ ìbànújẹ́ púpọ̀ ní ń mú wá, bí ìmọ̀ bá sì ṣe pọ̀ tó náà ni ìbànújẹ́ ń pọ̀ tó.
Gdzie bowiem jest wiele mądrości, [tam] jest wiele smutku. A kto przysparza wiedzy, przysparza i cierpienia.

< Ecclesiastes 1 >