< Deuteronomy 3 >

1 Lẹ́yìn èyí ní a yípadà tí a sì kọrí sí ọ̀nà tí ó lọ sí Baṣani, Ogu ọba Baṣani àti gbogbo jagunjagun rẹ̀ ṣígun wá pàdé wa ní Edrei.
Bashan longpuei la n'hooi uh tih n'caeh uh vaengah khaw Bashan manghai Oga neh a pilnam pum loh caemtloek neh mamih doe ham Edrei ah ha pawk.
2 Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀. Kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
Te vaengah BOEIPA loh kai te, 'Anih neh a pilnam pum khaw, a khohmuen khaw, na kut ah kam paek coeng. Anih te rhih boeh. Heshbon ah aka ngol Amori manghai Sihon taengkah na saii bangla anih taengah saii,’ a ti.
3 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Ọlọ́run wa fi Ogu ọba Baṣani àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lé wa lọ́wọ́. A kọlù wọ́n títí kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè.
Bashan manghai Oga neh a pilnam boeih te khaw mamih kut dongah mamih kah Pathen BOEIPA loh m'paek van coeng dongah rhaengnaeng a om pawt hil anih te n'tloek uh.
4 Ní ìgbà náà ní a gba gbogbo àwọn ìlú rẹ̀. Kò sí ọ̀kankan tí a kò gbà nínú àwọn ọgọta ìlú tí wọ́n ní, gbogbo agbègbè Argobu, lábẹ́ ìjọba Ogu ní Baṣani.
Te vaeng tue ah a khopuei rhoek boeih te n'buem uh tih amih taeng lamloh n'loh mueh khorha pakhat khaw om pawh. Bashan ah Oga ram Argob paeng boeih he khopuei sawmrhuk lo.
5 Gbogbo ìlú wọ̀nyí ní a mọ odi gíga yíká pẹ̀lú àwọn ìlẹ̀kùn àti irin. Ọ̀pọ̀ àwọn ìlú kéékèèké tí a kò mọ odi yíká sì tún wà pẹ̀lú.
Tekah khopuei boeih kah vongtung tah cak tih thohkhaih neh thohkalh khaw sang. Khopuei khat bueng lamloh vangcahlang khaw muep ping.
6 Gbogbo wọn ni a parun pátápátá gẹ́gẹ́ bí á ti ṣe sí Sihoni ọba Heṣboni, tí a pa gbogbo ìlú wọn run pátápátá: tọkùnrin tobìnrin àti àwọn ọmọ wọn.
Heshbon manghai Sihon taengkah n'saii uh bangla amih te khaw n'thup uh tih khopuei takuem kah huta tongpa neh camoe khaw n'thup uh.
7 Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú wọn, fún ara wa.
Tedae rhamsa boeih neh khopuei rhoek kah kutbuem te tah mamih ham ni m'poelyoe uh.
8 Ní ìgbà náà ni a ti gba ilẹ̀ tí ó wà ní Jordani láti odò Arnoni, títí dé orí òkè Hermoni lọ́wọ́ àwọn ọba Amori méjèèjì wọ̀nyí.
Te vaengah Jordan rhalvang Arnon soklong lamkah Hermon tlang duela aka om Amori manghai rhoi kut lamkah khohmuen te n'loh uh.
9 (Àwọn ará Sidoni ń pe Hermoni ní Sirioni. Àwọn Amori sì ń pè é ní Seniri).
Hermon te Sidoni rhoek loh Sirion a ti uh tih Amori rhoek loh Senir a ti uh.
10 Gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè olórí títẹ́ náà ni a gbà àti gbogbo Gileadi, àti gbogbo Baṣani, títí dé Saleka, àti Edrei, ìlú àwọn ọba Ogu ní ilẹ̀ Baṣani.
Tlangkol khopuei rhoek boeih neh Gilead boeih khaw, Bashan boeih Salkhah due khaw, Bashan ah Oga ram khopuei rhoek khuikah Edrei khaw n'lohuh.
11 (Ogu tí í ṣe ọba Baṣani nìkan ni ó ṣẹ́kù nínú àwọn ará Refaimu. Ibùsùn rẹ̀ ni a fi irin ṣe, ó sì gùn ju ẹsẹ̀ bàtà mẹ́tàlá lọ ní gígùn àti ẹsẹ̀ bàtà mẹ́fà ní ìbú. Èyí sì wà ní Rabba ti àwọn Ammoni.)
Te dongah Bashan manghai Oga bueng ni Rapha hlangrhuel la aka sueng. Te vaengah anih kah soengca thi soengca aih te hlang kah a dong la a daang te dong li neh a yun dong ko la Ammon koca rhoek kah Rabbah hmuen ah om pawt het a?
12 Nínú àwọn ilẹ̀ tí a gbà ní ìgbà náà, mo fún àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, ní ilẹ̀ tí ó wà ní àríwá Aroeri níbi odò Arnoni, pọ̀ mọ́ ìdajì ilẹ̀ òkè Gileadi pẹ̀lú gbogbo ìlú wọn.
Te vaeng tue kah khohmuen m'pang te Arnon soklong kah Aroer neh Gilead tlang a rhakthuem neh khopuei rhoek te Reuben koca neh Gad koca taengah ka paek coeng.
13 Gbogbo ìyókù Gileadi àti gbogbo Baṣani, ní ilẹ̀ ọba Ogu ni mo fún ìdajì ẹ̀yà Manase. (Gbogbo agbègbè Argobu ni Baṣani tí a mọ̀ sí ilẹ̀ àwọn ará Refaimu.
Gilead kah a coih neh Oga ram Bashan pum te Manasseh koca rhakthuem taengah ka paek coeng. Bashan pum kah Argob paeng boeih he Rapha khohmuen la a tkhue.
14 Jairi ọ̀kan nínú àwọn ìran Manase gba gbogbo agbègbè Argobu títí dé ààlà àwọn ará Geṣuri àti àwọn ará Maakati; a sọ ibẹ̀ ní orúkọ rẹ̀ torí èyí ni Baṣani fi ń jẹ́ Hafoti-Jairi títí di òní.)
Manasseh capa Jair loh Argob paeng pum te Geshuri neh Maakathi khorhi duela a loh. Te dongah te rhoek te anih ming neh tihnin due, Bashan vangca, Jair a sui.
15 Mo sì fi Gileadi fún Makiri,
Makir te khaw Gilead ka paek coeng.
16 ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Reubeni àti ọmọ Gadi ni mo fún ní ilẹ̀ láti Gileadi lọ dé odò Arnoni (àárín odò náà sì jẹ́ ààlà) títí ó fi dé odò Jabbok. Èyí tí i ṣe ààlà àwọn ará Ammoni.
Tedae Gilead lamkah Arnon soklong due, khorhi soklong bangli neh Ammon koca rhoek kah khorhi Jabbok soklong duela,
17 Pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah pẹ̀lú, àti Jordani gẹ́gẹ́ bí òpin ilẹ̀ rẹ̀, láti Kinnereti lọ títí dé Òkun pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah, àní Òkun Iyọ̀, ní ìsàlẹ̀ àwọn orísun Pisga ní ìhà ìlà-oòrùn.
kolken neh Jordan khorhi khaw, Kinnereth lamkah kolken tuili, lungkaeh li neh khocuk Pisgah kah tuibah hmui rhoek khaw Reuben koca neh Gad koca taengah ka paek coeng.
18 Mo pàṣẹ fún un yín ní ìgbà náà pé, “Olúwa Ọlọ́run yín ti fi ilẹ̀ yìí fún un yín láti ní i. Ṣùgbọ́n, gbogbo àwọn ọkùnrin yín tí ó lera tí wọ́n sì ti dira ogun, gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín: ará Israẹli.
Te vaeng tue ah ni nangmih te kang uen tih, 'Na BOEIPA Pathen loh nangmih taengah m'paek khohmuen he pang hamla pumcum uh laeh. Israel ca rhoek tatthai hlang boeih long tah na manuca rhoek kah mikhmuh ah lan phai uh laeh,’ ka ti.
19 Àwọn ẹ̀yà a yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ohun ọ̀sìn in yín (mo mọ̀ pé ẹ ti ní ohun ọ̀sìn púpọ̀) lè dúró ní àwọn ìlú tí mo fi fún un yín,
Tedae na yuu na ca rhoek neh na boiva te tah ka ming vanbangla boiva khaw muep a yet oeh pueng dongah nangmih ham kam paek na khopuei rhoek ah te om uh mai saeh.
20 títí di ìgbà tí Olúwa yóò fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi bí ó ti fún un yín, àti ìgbà tí àwọn náà yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún wọn ní ìhà kejì Jordani. Nígbà náà ni ọ̀kọ̀ọ̀kan yín tó lè padà lọ sí ìní rẹ̀ tí mo fún un.”
Nangmih bangla na manuca rhoek te BOEIPA loh a duem sak duela na BOEIPA Pathen loh amih taengah khohmuen a paek te amih loh Jordan rhalvang khaw a pang uh thil van coeng. Te dongah hlang he nangmih taengah kam paek vanbangla a rho taengla mael saeh.
21 Nígbà náà ni mo pàṣẹ fún Joṣua pé, “Ìwọ tí fi ojú rẹ rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ṣe sí àwọn ọba méjèèjì wọ̀nyí. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò ṣe sí àwọn ilẹ̀ ọba tí ẹ̀yin n lọ.
Joshua khaw amah te vaeng tue ah ka uen tih, 'Hekah manghai rhoi taengah na BOEIPA Pathen loh a saii boeih te na mik loh a hmuh coeng. Nang loh na kun thil ham ram boeih te khaw BOEIPA loh a saii ni.
22 Ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, Olúwa Ọlọ́run yín tìkára rẹ̀ ni yóò jà fún un yín.”
Nangmih hamla na BOEIPA Pathen loh a vathoh thil coeng dongah amih te rhih boeh,’ ka ti nah.
23 Nígbà náà ni mo bẹ Olúwa wí pé,
Amah te vaeng tue ah BOEIPA taengla ka bih tih,
24 “Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí bẹ̀rẹ̀ sí fi títóbi rẹ àti ọwọ́ agbára rẹ han ìránṣẹ́ rẹ. Ọlọ́run wo ló tó bẹ́ẹ̀ láyé àti lọ́run tí ó lè ṣe àwọn iṣẹ́ agbára ńlá tí o ti ṣe?
'Aw Boeipa, Yahovah nang loh na boeilennah neh na tlungluen kut te na sal taengah tueng sak hamla na tawn coeng. Nang kah bibi neh na thayung thamal bangla vaan neh diklai dongah mebang pathen long nim a saii thai bal.
25 Jẹ́ kí n kọjá lọ wo ilẹ̀ rere ti ìkọjá Jordani, ilẹ̀ òkè dídára nì àti Lebanoni.”
Jordan rhalvang la bet ka lan mai saeh lamtah khohmuen then Lebanon tlang then te khaw ka hmu laem eh,’ ka ti nah.
26 Ṣùgbọ́n torí i tiyín, Olúwa Ọlọ́run bínú sí mi kò sì gbọ́ tèmi. Olúwa sọ wí pé, “Ó tó gẹ́ẹ́, ìwọ kò gbọdọ̀ sọ ohunkóhun lórí ọ̀rọ̀ yìí sí mi mọ́.
Tedae nangmih kongah BOEIPA te kai taengah lungoe tih ka ol hnatun pawh. Te vaenagah BOEIPA loh kai taengah, 'Temah saeh ne nang te, hebang olka he kai taengah koep thui ham khoep boeh.
27 Gòkè lọ sí orí òkè Pisga, sì wò yíká ìwọ̀-oòrùn, ìlà-oòrùn, àríwá àti gúúsù. Fi ojú ara rẹ wo ilẹ̀ náà níwọ̀n bí ìwọ kò tí ní kọjá Jordani yìí.
Pisgah som la luei lamtah tuitunli neh tlangpuei khaw, tuithim neh khocuk khaw na mik neh dan mai. Jordan he na mik neh na hmuh cakhaw na kat mahpawh.
28 Ṣùgbọ́n yan Joṣua, kí o sì gbà á níyànjú, mú un lọ́kàn le, torí pé òun ni yóò síwájú àwọn ènìyàn wọ̀nyí kọjá, yóò sì jẹ́ kí wọn jogún ilẹ̀ náà tí ìwọ yóò rí.”
Tedae Joshua te uen lamtah talong khaw talong, duel khaw duel. Anih tah pilnam kah mikhmuh ah kat phai vetih na hmuh ham khohmuen te a pang ni, ' a ti.
29 Báyìí ni a dúró ní àfonífojì ní ẹ̀bá Beti-Peori.
Te dongah ni Bethpeor imdan kah kolrhawk ah kho n'sakuh.

< Deuteronomy 3 >