< Deuteronomy 26 >

1 Nígbà tí ìwọ bá wọ ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fi fún ọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìní tí ìwọ sì ti jogún, tí ìwọ sì ti ń gbé níbẹ̀,
Gdy wejdziesz do ziemi, którą PAN, twój Bóg, daje ci w dziedzictwo, gdy posiądziesz ją i zamieszkasz w niej;
2 mú díẹ̀ nínú ohun tí o pèsè láti inú erùpẹ̀ ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fi fún ọ, kó wọn sínú agbọ̀n. Nígbà náà kí o lọ sí ibi tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò yàn gẹ́gẹ́ bí ibi tí orúkọ rẹ̀ yóò máa gbé.
Wtedy weźmiesz pierwociny ze wszystkich owoców ziemi, które złożysz w ofierze ze swojej ziemi danej ci przez PANA, twojego Boga, i włożysz je do kosza, i udasz się na miejsce, które wybierze PAN, twój Bóg, na mieszkanie dla swego imienia.
3 Kí o sì sọ fun àlùfáà tí ó wà ní ibi iṣẹ́ ní àsìkò náà, pé, “Mo sọ ọ́ di mí mọ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pé mo ti wá sí ilẹ̀ tí Olúwa búra fún àwọn baba wa.”
I przyjdziesz do kapłana, który w tym czasie będzie pełnić służbę, i powiesz do niego: Wyznaję dziś PANU, twemu Bogu, że wszedłem do ziemi, którą PAN poprzysiągł naszym ojcom, że nam ją da.
4 Àlùfáà yóò gbé agbọ̀n náà kúrò ní ọwọ́ rẹ, yóò sì gbé e kalẹ̀ níwájú pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Wtedy kapłan weźmie kosz z twojej ręki i postawi go przed ołtarzem PANA, twego Boga.
5 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní iwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ pé, “Baba mi jẹ́ alárìnkiri ará Aramu, ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí Ejibiti pẹ̀lú ènìyàn díẹ̀, ó sì ń gbé níbẹ̀, ó sì wá di orílẹ̀-èdè olókìkí, alágbára, tí ó kún fún ọ̀pọ̀ ènìyàn.
I odezwiesz się, i powiesz przed PANEM, swoim Bogiem: Mój ojciec [był] Syryjczykiem bliskim śmierci, zstąpił do Egiptu, gdzie przebywał w nielicznej garstce i stał się tam wielkim narodem, potężnym i licznym.
6 Ṣùgbọ́n àwọn ará Ejibiti ṣe àìdára sí wa, wọ́n jẹ wá ní yà, wọ́n fún wa ní iṣẹ́ líle ṣe.
Lecz Egipcjanie źle nas traktowali, dręczyli nas i nakładali na nas ciężką pracę.
7 Nígbà náà ni a kégbe pe Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wa, Olúwa sì gbọ́ ohùn wa, ó sì rí ìrora, làálàá àti ìnira wa.
Wtedy wołaliśmy do PANA, Boga naszych ojców, i PAN wysłuchał naszego głosu, i wejrzał na nasze utrapienie, naszą pracę i nasz ucisk;
8 Nígbà náà ni Olúwa mú wa jáde wá láti Ejibiti pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà, pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá àti iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu.
I wywiódł nas PAN z Egiptu potężną ręką i wyciągniętym ramieniem wśród wielkiej grozy, znaków i cudów;
9 Ó mú wa wá síbí, ó sì fún wa ní ilẹ̀ yìí, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin;
I przyprowadził nas na to miejsce, i dał nam tę ziemię, ziemię opływającą mlekiem i miodem.
10 àti pé ní báyìí, mo mú àkọ́so ilẹ̀ tí ìwọ Olúwa ti fún mi wá.” Ìwọ yóò gbé agbọ̀n náà síwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí o sì wólẹ̀ níwájú u rẹ̀.
Teraz oto przyniosłem pierwociny z owoców ziemi, którą mi dałeś, PANIE. I położysz je przed PANEM, swoim Bogiem, i oddasz pokłon przed PANEM, swoim Bogiem;
11 Ìwọ àti àwọn ọmọ Lefi àti àjèjì láàrín yín yóò máa yọ̀ nínú gbogbo oore tí Olúwa ti fi fún ọ àti fún àwọn ará ilé rẹ.
I będziesz się radował ze wszystkich dóbr, które PAN, twój Bóg, dał tobie i twemu domowi, ty, Lewita i przybysz, który jest pośród ciebie.
12 Nígbà tí ìwọ bá ṣetán láti ya ìdámẹ́wàá gbogbo ohun tí o ti mú jáde ní ọdún kẹta sọ́tọ̀ sí apá kan. Ọdún ìdámẹ́wàá, ìwọ yóò fi fún ọmọ Lefi, àjèjì, aláìní baba àti opó, kí wọn kí ó lè jẹ ní àwọn ìlú rẹ, kí wọn sì yó.
A gdy zakończysz składanie wszystkich dziesięcin swoich zbiorów w trzecim roku, roku dziesięcin, gdy oddasz je Lewicie, przybyszowi, sierocie oraz wdowie, aby najedli się do syta w twoich bramach;
13 Nígbà náà ní kí o wí fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pé, “Èmi ti mú ohun mímọ́ kúrò nínú ilé mi, èmi sì ti fi fún àwọn Lefi, àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba àti àwọn opó, gẹ́gẹ́ bí ohun gbogbo tí ìwọ ti pàṣẹ. Èmi kò yípadà kúrò nínú àṣẹ rẹ bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbàgbé ọ̀kankan nínú wọn.
Wtedy powiesz przed PANEM, swoim Bogiem: Wziąłem z domu to, co jest poświęcone, i dałem też z tego Lewicie, przybyszowi, sierocie oraz wdowie zgodnie ze wszystkimi twoimi przykazaniami, które mi nakazałeś. Nie przekroczyłem twoich przykazań ani nie zapomniałem ich.
14 Èmi kò jẹ lára ohun mímọ́ ní ìgbà tí mo ń ṣọ̀fọ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mu nínú wọn ní ìgbà tí mo wà ní àìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò fi nínú wọn fún òkú. Èmi ti ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run mi, èmi sì ti ṣe gbogbo ohun tí ó pàṣẹ fún mi.
Nie jadłem z tego w czasie żałoby, niczego z tego nie odjąłem do użytku pospolitego, ani też nic z tego nie dałem dla zmarłych. Usłuchałem głosu PANA, mojego Boga, uczyniłem wszystko, co mi nakazałeś.
15 Wo ilẹ̀ láti ọ̀run wá, ibùgbé mímọ́ rẹ, kí o sì bùkún fún àwọn ènìyàn Israẹli, àti fún ilẹ̀ náà tí ìwọ ti fi fún wa, bí ìwọ ti búra fún àwọn baba ńlá wa, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti fún oyin.”
Spójrz ze swego świętego przybytku z nieba, i błogosław swemu ludowi Izraela oraz ziemi, którą nam dałeś, tak jak poprzysiągłeś naszym ojcom, ziemi mlekiem i miodem płynącej.
16 Olúwa Ọlọ́run rẹ pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa tẹ̀lé àwọn ìlànà àti òfin, kí o sì máa ṣe wọ́n pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ àti gbogbo àyà rẹ.
Dziś PAN, twój Bóg, nakazuje ci wypełnić te ustawy i prawa. Przestrzegaj ich więc i wypełniaj je z całego swego serca i całą swoją duszą.
17 Ìwọ jẹ́wọ́ Olúwa ní òní pé Olúwa ni Ọlọ́run rẹ, àti pé ìwọ yóò máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, àti pé ìwọ yóò máa pa ìlànà rẹ̀, àṣẹ rẹ̀ àti òfin rẹ̀ mọ́, àti pé ìwọ yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí i.
Dziś oświadczyłeś, że PAN jest twoim Bogiem, że będziesz chodził jego drogami, przestrzegał jego ustaw, przykazań i praw oraz że będziesz słuchał jego głosu.
18 Ní òní ni Olúwa jẹ́wọ́ rẹ pé ìwọ ni ènìyàn òun, ilé ìṣúra rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí, àti pé ìwọ yóò máa pa gbogbo àṣẹ rẹ̀ mọ́.
PAN zaś oświadczył dziś, że będziesz jego szczególnym ludem, jak ci obiecał, i że masz przestrzegać wszystkich jego przykazań;
19 Òun sì jẹ́wọ́ pé, òun yóò gbé ọ sókè ju gbogbo orílẹ̀-èdè tí òun ti dá lọ, ní ìyìn, ní òkìkí àti ní ọlá; kí ìwọ kí ó le jẹ́ ènìyàn mímọ́ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí.
Że wywyższy cię ponad wszystkie narody, które uczynił, w chwale, w sławie i we czci, i że masz być ludem świętym dla PANA, swego Boga, tak jak powiedział.

< Deuteronomy 26 >