< Amos 3 >

1 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli nípa àwọn ìdílé tí mo mú jáde láti Ejibiti:
Słuchajcie tego słowa, które PAN mówi przeciwko wam, synowie Izraela, przeciwko całemu pokoleniu, które wyprowadziłem z ziemi Egiptu:
2 “Ìwọ nìkan ni ẹni tí mo yàn nínú gbogbo àwọn ìran ayé yìí; nígbà náà èmi ó jẹ ọ́ ní yà fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.”
Tylko was uznałem spośród wszystkich rodów ziemi, dlatego was ukarzę za wszystkie wasze nieprawości.
3 Ẹni méjì ha à le rìn pọ̀ láìjẹ́ pé wọ́n ti pinnu láti ṣe bẹ?
Czy dwóch może chodzić razem, jeśli się nie zgadzają?
4 Ǹjẹ́ Kìnnìún yóò ha bú ramúramù nínú igbó, bí kò bá ní ohun ọdẹ? Ọmọ kìnnìún yóò ha ké jáde nínú ìhó rẹ̀ bí kò bá rí ohun kan mú?
Czy lew zaryczy w lesie, gdy nie ma łupu? [Czy] młody lew wyda swój głos ze swojego legowiska, jeśli nic nie złowił?
5 Ǹjẹ́ ẹyẹ ṣubú sínú okùn ọdẹ lórí ilẹ̀ nígbà tí a kò dẹ okùn ọdẹ fún un? Okùn ọdẹ ha lè hù jáde lórí ilẹ̀ nígbà tí kò sí ohun tí yóò mú?
Czy ptak wpadnie w sidła na ziemi, jeśli nie ma pułapki? Czy podniesie się sidła z ziemi, jeśli nic nie schwytały?
6 Nígbà tí ìpè bá dún ní ìlú, àwọn ènìyàn kò ha bẹ̀rù? Tí ewu bá wa lórí ìlú kò ha ṣe Olúwa ni ó fà á?
Czy trąba zadmie w mieście, a lud się nie ulęknie? Czy w mieście zdarzy się nieszczęście, którego PAN by nie uczynił?
7 Nítòótọ́ Olúwa Olódùmarè kò ṣe ohun kan láìfi èrò rẹ̀ hàn fun àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
Doprawdy, Pan BÓG nic nie czyni, jeśli nie objawi swojej tajemnicy swym sługom, prorokom.
8 Kìnnìún ti bú ramúramù ta ni kì yóò bẹ̀rù? Olúwa Olódùmarè ti sọ̀rọ̀ ta ni le ṣe àìsọ àsọtẹ́lẹ̀?
Lew ryknął, któż się nie ulęknie? Pan BÓG przemówił, któż nie będzie prorokował?
9 Ẹ kéde ní ààfin Aṣdodu àti ní ààfin ní ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹ kó ara yín jọ sí orí òkè ńlá Samaria; kí ẹ sì wo ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láàrín rẹ̀ àti ìnilára láàrín àwọn ènìyàn rẹ.”
Głoście w pałacach w Aszdodzie i w pałacach ziemi Egiptu i mówcie: Zbierzcie się na górach Samarii i zobaczcie w niej wielkie zamieszanie oraz cierpiących w niej ucisk;
10 “Wọn kò mọ bí wọ́n ṣe ń ṣe rere,” ni Olúwa wí, “àwọn ẹni tí ó gba àwọn ìwà ipá àti olè sí ààfin rẹ̀.”
Nie umieją bowiem czynić tego, co jest prawe, mówi PAN. Zbierają w swoich pałacach skarby ze zdzierstwa i z grabieży.
11 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “Àwọn ọ̀tá yóò pa ilẹ̀ náà run; yóò wó ibi gíga yín palẹ̀ a ó sì ba ààfin rẹ̀ jẹ́.”
Dlatego tak mówi Pan BÓG: Wróg otoczy tę ziemię i pozbawi cię twojej siły, i twoje pałace zostaną ograbione.
12 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Bí olùṣọ́-àgùntàn ti ń gbà itan méjì kúrò ní ẹnu kìnnìún tàbí ẹ̀là etí kan bẹ́ẹ̀ ni a ó mú àwọn ọmọ Israẹli, tí ń gbé Samaria kúrò ní igun ibùsùn wọn ní orí àga ìrọ̀gbọ̀kú wọn ní Damasku.”
Tak mówi PAN: Jak pasterz wyrywa z lwiej paszczy dwie nogi lub kawałek ucha, tak zostaną wyrwani synowie Izraela, którzy mieszkają w Samarii na rogu łoża i w Damaszku na posłaniach.
13 “Gbọ́ èyí kí o sì jẹ́rìí nípa ilé Jakọbu,” ni Olúwa wí, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.
Słuchajcie i oświadczcie w domu Jakuba, mówi Pan BÓG, Bóg zastępów;
14 “Ní ọjọ́ tí mo fìyà jẹ Israẹli lórí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, Èmi yóò pa pẹpẹ Beteli run; ìwo pẹpẹ ni a ó ké kúrò yóò sì wó lulẹ̀.
Bo w tym dniu, w którym ukarzę Izraela za jego przestępstwa, ukarzę też ołtarze w Betel. I rogi ołtarza zostaną odcięte i upadną na ziemię.
15 Èmi yóò wó ilé òtútù lulẹ̀ pẹ̀lú ilé ooru; ilé tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ yóò ṣègbé a ó sì pa ilé ńlá náà run,” ni Olúwa wí.
I zburzę dom zimowy i dom letni, zginą domy z kości słoniowej i dla wielkich domów nastanie koniec, mówi PAN.

< Amos 3 >