< Amos 1 >

1 Àwọn ọ̀rọ̀ Amosi, ọ̀kan lára àwọn olùṣọ́-àgùntàn Tekoa; ohun tí o rí nípa Israẹli ní ọdún méjì ṣáájú ilẹ̀-rírì, nígbà tí Ussiah ọba Juda àti Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi jẹ́ ọba ní ilẹ̀ Israẹli.
Słowa Amosa, który był [jednym] spośród pasterzy z Tekoa, które widział o Izraelu za dni Uzjasza, króla Judy, i za dni Jeroboama, syna Joasza, króla Izraela, dwa lata przed trzęsieniem ziemi.
2 Ó wí pé, “Olúwa yóò bú jáde láti Sioni, ohùn rẹ̀ yóò sì sán bí àrá láti Jerusalẹmu wá; ibùgbé àwọn olùṣọ́-àgùntàn yóò sì ṣọ̀fọ̀, orí òkè Karmeli yóò sì rọ.”
I powiedział: PAN zagrzmi z Syjonu, z Jerozolimy wyda swój głos; mieszkania pasterzy będą lamentować, a wyschnie szczyt Karmelu.
3 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Damasku, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn fi ohun èlò ìpakà pa Gileadi. Pẹ̀lú ohun èlò irin tí ó ní eyín mímú,
Tak mówi PAN: Z powodu trzech występków Damaszku i z powodu czterech nie przepuszczę mu, ponieważ młócili Gilead narzędziami z żelaza.
4 Èmi yóò rán iná sí ilé Hasaeli, èyí ti yóò jó àwọn ààfin Beni-Hadadi run.
Ale ześlę ogień na dom Chazaela, który strawi pałace Ben-Hadada.
5 Èmi yóò ṣẹ́ ọ̀pá ìdábùú Damasku; Èmi yóò sì pa ọba tí ó wà ní àfonífojì Afeni run àti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé mú ní Beti-Edeni. Àwọn ará a Aramu yóò lọ sí ìgbèkùn sí Kiri,” ni Olúwa wí.
Połamię też rygiel Damaszku i wykorzenię mieszkańca z doliny Awen i tego, który trzyma berło z domu Eden. I lud Syrii pójdzie do niewoli do Kir, mówi PAN.
6 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Gasa, àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Gẹ́gẹ́ bí í oníṣòwò ẹrú, ó kó gbogbo àwọn ènìyàn mi ní ìgbèkùn. Ó sì tà wọ́n fún Edomu,
Tak mówi PAN: Z powodu trzech występków Gazy i z powodu czterech nie przepuszczę im, ponieważ uprowadzili wszystkich jeńców, aby ich wydać Edomowi.
7 Èmi yóò rán iná sí ara odi Gasa tí yóò jó gbogbo ààfin rẹ̀ run.
Ale ześlę ogień na mur Gazy, który strawi jej pałace.
8 Èmi yóò ké àwọn olùgbé Aṣdodu kúrò, ti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé ní Aṣkeloni mú. Èmi yóò yí ọwọ́ mi sí Ekroni títí tí ìyókù Filistini yóò fi ṣègbé,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
Wykorzenię też mieszkańca z Aszdodu i tego, który trzyma berło z Aszkelonu, i zwrócę swoją rękę przeciwko Ekronowi, i zginie resztka Filistynów, mówi Pan BÓG.
9 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Tire àní nítorí mẹ́rin, Èmi kì yóò yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọ́n ta gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ìgbèkùn fún Edomu. Wọn kò sì náání májẹ̀mú ọbàkan,
Tak mówi PAN: Z powodu trzech występków Tyru i z powodu czterech nie przepuszczę mu, ponieważ wydali wszystkich jeńców Edomowi, a nie pamiętali o braterskim przymierzu;
10 Èmi yóò rán iná sí ara odi Tire, tí yóò jó gbogbo àwọn ààfin rẹ̀ run.”
Ale ześlę ogień na mur Tyru, który strawi jego pałace.
11 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Edomu, àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí òhun fi idà lépa arákùnrin rẹ̀, Ó sì gbé gbogbo àánú sọnù, ìbínú rẹ̀ sì ń faniya títí, ó sì pa ìbínú rẹ̀ bí èéfín mọ́,
Tak mówi PAN: Z powodu trzech występków Edomu i z powodu czterech nie przepuszczę mu, ponieważ prześladował mieczem swego brata, tłumiąc w sobie wszelaką litość, a nieustannie pałał gniewem, swoją zapalczywość chował na zawsze.
12 Èmi yóò rán iná sí orí Temani, tí yóò jó gbogbo ààfin Bosra run.”
Ale ześlę ogień na Teman i strawi pałace Bosry.
13 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Ammoni, àní mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn ti la inú àwọn aboyún Gileadi kí wọ́n ba à lè fẹ ilẹ̀ wọn sẹ́yìn.
Tak mówi PAN: Z powodu trzech występków synów Ammona i z powodu czterech nie przepuszczę im, ponieważ rozcinali brzemienne w Gileadzie tylko po to, by rozszerzyć swoje granice.
14 Èmi yóò rán iná sí ara odi Rabba èyí tí yóò jó àwọn ààfin rẹ̀ run pẹ̀lú ìhó ayọ̀ ní ọjọ́ ogun, pẹ̀lú ìjì líle ni ọjọ́ àjà.
Ale rozniecę ogień na murze Rabby, który strawi jego pałace wśród krzyku w dzień bitwy, podczas wichru w dzień burzy.
15 Ọba wọn yóò sì lọ sí ìgbèkùn, òun àti àwọn ọmọ-aládé rẹ̀ lápapọ̀,” ni Olúwa wí.
I pójdzie ich król do niewoli, on i jego książęta razem z nim, mówi PAN.

< Amos 1 >