< 2 Samuel 6 >

1 Dafidi sì tún kó gbogbo àwọn akọni ọkùnrin ní Israẹli jọ, wọ́n sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún.
I Dawid ponownie zebrał wszystkich doborowych [mężczyzn] z Izraela, trzydzieści tysięcy.
2 Dafidi sì dìde, ó sì lọ àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ń bẹ́ lọ́dọ̀ rẹ́, láti Baalahi ní Juda wá, láti mú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run tí ibẹ̀ wá, èyí tí a ń pe orúkọ rẹ̀ ní orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí ó jókòó láàrín àwọn kérúbù.
Potem Dawid wraz z całym ludem, który z nim był, powstał i wyruszył z Baali judzkiej, aby przenieść stamtąd arkę Boga, która nosi imię PANA zastępów zasiadającego [między] cherubinami.
3 Wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run náà gun kẹ̀kẹ́ tuntun kan, wọ́n sì mú un láti ilé Abinadabu wá, èyí tí ó wà ní Gibeah: Ussa àti Ahio, àwọn ọmọ Abinadabu sì ń dá kẹ̀kẹ́ tuntun náà.
I umieścili arkę Boga na nowym wozie, i wywieźli ją z domu Abinadaba położonego w Gibea. A Uzza i Achio, synowie Abinadaba, prowadzili ten nowy wóz.
4 Wọ́n sì mú un láti ilé Abinadabu jáde wá, tí ó wà ní Gibeah, pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, Ahio sì ń rìn níwájú àpótí ẹ̀rí náà.
I wyprowadzili go z domu Abinadaba położonego w Gibea wraz z arką Boga. A Achio szedł przed arką.
5 Dafidi àti gbogbo ilé Israẹli sì ṣiré níwájú Olúwa lára gbogbo onírúurú ohun èlò orin tí a fi igi arère ṣe àti lára ìlù haapu, ní ara tambori, sisitirumu àti lára kimbali.
Dawid zaś i cały Izrael grali przed PANEM na wszelkich [instrumentach] z drewna jodłowego: na harfach, cytrach, bębnach, piszczałkach i cymbałach.
6 Nígbà tí wọ́n dé sí ilẹ̀ ìpakà Nakoni, Ussa sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, ó sì dìímú, nítorí tí màlúù kọsẹ̀.
A [gdy] przybyli do klepiska Nachona, Uzza wyciągnął [rękę] do arki Boga i pochwycił ją, gdyż woły ją szarpnęły.
7 Ìbínú Olúwa sì ru sí Ussa; Ọlọ́run sì pa á níbẹ̀ nítorí ìṣísẹ̀ rẹ̀; níbẹ̀ ni ó sì kù ní ẹ̀bá àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run.
I zapłonął gniew PANA przeciwko Uzzie, i Bóg zabił go za uchybienie. I umarł tam przy arce Boga.
8 Inú Dafidi sì bàjẹ́ nítorí tí Olúwa gé Ussa kúrò, ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Peresi-Usa títí ó fi di òní yìí.
I Dawid był wielce niezadowolony, że PAN tak srogo poraził Uzzę, i nazwał to miejsce Peres-Uzza, i tak jest do dziś.
9 Dafidi sì bẹ̀rù Olúwa ní ọjọ́ náà, ó sì wí pé, “Àpótí ẹ̀rí Olúwa yóò ti ṣe tọ̀ mí wá?”
Dawid zląkł się PANA tego dnia i powiedział: Jakże ma przyjść do mnie arka PANA?
10 Dafidi kò sì fẹ́ mú àpótí ẹ̀rí Olúwa sọ́dọ̀ rẹ̀ sí ìlú Dafidi; ṣùgbọ́n Dafidi sì mú un yà sí ilé Obedi-Edomu ará Gitti.
Dlatego Dawid nie chciał sprowadzić arki PANA do siebie, do swego miasta, lecz wprowadził ją do domu Obed-Edoma, Gittyty.
11 Àpótí ẹ̀rí Olúwa sì gbé ní ilé Obedi-Edomu ará Gitti ní oṣù mẹ́ta; Olúwa sì bùkún fún Obedi-Edomu, àti gbogbo ilé rẹ̀.
I arka PANA pozostała w domu Obed-Edoma, Gittyty, przez trzy miesiące. A PAN błogosławił Obed-Edomowi i całemu jego domowi.
12 A sì rò fún Dafidi ọba pé, “Olúwa ti bùkún fún ilé Obedi-Edomu, àti gbogbo èyí tí í ṣe tirẹ̀, nítorí àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run.” Dafidi sì lọ, ó sì mú àpótí ẹ̀rí náà gòkè láti ilé Obedi-Edomu wá sí ìlú Dafidi pẹ̀lú ayọ̀.
A doniesiono królowi Dawidowi: PAN błogosławi domowi Obed-Edoma i wszystkiemu, co posiada, ze względu na arkę Boga. Dawid poszedł więc i sprowadził z wielką radością arkę Boga z domu Obed-Edoma do miasta Dawida.
13 Ó sì ṣe nígbà tí àwọn ènìyàn tí ó ru àpótí ẹ̀rí Olúwa bá sì ṣí ẹsẹ̀ mẹ́fà, òun a sì fi màlúù àti ẹran àbọ́pa rú ẹbọ.
A gdy ci, którzy nieśli arkę PANA, zrobili sześć kroków, składał w ofierze woły i tuczne [zwierzęta].
14 Dafidi sì fi gbogbo agbára rẹ̀ jó níwájú Olúwa; Dafidi sì wọ efodu ọ̀gbọ̀.
I Dawid tańczył przed PANEM z całych sił; był przepasany lnianym efodem.
15 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti gbogbo ilé Israẹli sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá, pẹ̀lú ìhó ayọ̀, àti pẹ̀lú ìró ìpè.
Tak Dawid i cały dom Izraela sprowadzili arkę PANA z okrzykami i przy dźwiękach trąby.
16 Bí àpótí ẹ̀rí Olúwa sì ti wọ ìlú Dafidi wá; Mikali ọmọbìnrin Saulu sì wo láti ojú fèrèsé, ó sì rí Dafidi ọba ń fò sókè ó sì ń jó níwájú Olúwa; òun sì kẹ́gàn rẹ̀ ní ọkàn rẹ̀.
A gdy arka PANA weszła do miasta Dawida, Mikal, córka Saula, wyglądała przez okno i zobaczyła króla Dawida, jak skakał i tańczył przed PANEM, i wzgardziła nim w swoim sercu.
17 Wọ́n sì mú àpótí ẹ̀rí Olúwa náà wá, wọ́n sì gbé e kalẹ̀ sípò rẹ̀ láàrín àgọ́ náà tí Dafidi pa fún un. Dafidi sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ìrẹ́pọ̀ níwájú Olúwa.
Sprowadzili więc arkę PANA i ustawili ją na swoim miejscu w środku namiotu, który rozpiął dla niej Dawid. I Dawid złożył przed PANEM całopalenia i ofiary pojednawcze.
18 Dafidi sì parí ìṣe ẹbọ sísun àti ẹbọ ìrẹ́pọ̀ náà, ó sì súre fún àwọn ènìyàn náà ní orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
A gdy Dawid skończył składać całopalenia i ofiary pojednawcze, błogosławił ludowi w imię PANA zastępów.
19 Ó sì pín fún gbogbo àwọn ènìyàn náà, àní fún gbogbo ọ̀pọ̀ ènìyàn Israẹli, àti ọkùnrin àti obìnrin; fún olúkúlùkù ìṣù àkàrà kan àti ekìrí ẹran kan, àti àkàrà díndín kan. Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì túká lọ, olúkúlùkù sí ilé rẹ̀.
I rozdał wśród całego ludu i całego zgromadzenia Izraela, zarówno mężczyznom, jak i kobietom, każdemu po jednym bochenku chleba, po jednym kawałku mięsa i po jednym bukłaku [wina]. Potem cały lud odszedł, każdy do swojego domu.
20 Dafidi sì yípadà láti súre fún àwọn ará ilé rẹ̀, Mikali ọmọbìnrin Saulu sì jáde láti wá pàdé Dafidi, ó sì wí pé, “Báwo ni ọba Israẹli ṣe ṣe ara rẹ̀ lógo bẹ́ẹ̀ lónìí, tí ó bọ́ ara rẹ̀ sílẹ̀ lónìí lójú àwọn ìránṣẹ́bìnrin àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn lásán tí ń bọ́ra rẹ̀ sílẹ̀.”
Potem Dawid wrócił, aby pobłogosławić swój dom. I Mikal, córka Saula, wyszła naprzeciw Dawidowi, i powiedziała: O jakże wspaniały był dziś król Izraela, który się obnażył dziś na oczach służących swych sług, tak jak się obnaża jakiś niepoważny [człowiek]!
21 Dafidi sì wí fún Mikali pé, “Níwájú Olúwa ni, ẹni tí ó yàn mí fẹ́ ju baba rẹ lọ, àti ju gbogbo ìdílé rẹ lọ, láti fi èmi ṣe olórí àwọn ènìyàn Olúwa, àní lórí Israẹli, èmi ó sì súre níwájú Olúwa.
Wtedy Dawid powiedział do Mikal: [Grałem] przed PANEM, który wybrał raczej mnie niż twego ojca i niż cały jego dom, aby ustanowić mnie wodzem nad ludem PANA, nad Izraelem. Będę więc grał przed PANEM.
22 Èmi ó sì tún rẹ ara mi sílẹ̀ jú bẹ́ẹ̀ lọ, èmi ó sì ṣe aláìníyìn lójú ara mi, àti lójú àwọn ìránṣẹ́bìnrin náà ti ìwọ wí, lọ́dọ̀ wọn náà ni èmi ó sì ní ògo.”
I poniżę się jeszcze bardziej niż dotąd, i będę jeszcze bardziej godny pogardy w swoich oczach, lecz u służących, o których mi mówiłaś, będę poważany.
23 Mikali ọmọbìnrin Saulu kò sì bí ọmọ, títí o fi di ọjọ́ ikú rẹ̀ nítorí tí ó sọ̀rọ̀-òdì yìí sí Dafidi.
Mikal, córka Saula, nie miała więc dzieci aż do dnia swej śmierci.

< 2 Samuel 6 >