< 2 Samuel 23 >

1 Wọ̀nyí sì ni ọ̀rọ̀ ìkẹyìn Dafidi. “Dafidi ọmọ Jese, àní ọkùnrin tí a ti gbéga, ẹni àmì òróró Ọlọ́run Jakọbu, àti olórin dídùn Israẹli wí pé,
E estas são as últimas palavras de David: Diz David, filho de Jessé, e diz o homem que foi levantado em altura, o ungido do Deus de Jacob, e o suave em salmos de Israel:
2 “Ẹ̀mí Olúwa sọ ọ̀rọ̀ nípa mi, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ń bẹ ní ahọ́n mi.
O espírito do Senhor falou por mim, e a sua palavra esteve em minha boca.
3 Ọlọ́run Israẹli ni, àpáta Israẹli sọ fún mi pé, ‘Ẹnìkan ti ń ṣe alákòóso ènìyàn lódodo, tí ń ṣàkóso ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
Disse o Deus de Israel, a Rocha de Israel a mim me falou: Haverá um justo que domine sobre os homens, que domine no temor de Deus.
4 Yóò sì dàbí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ nígbà tí oòrùn bá là, òwúrọ̀ tí kò ní ìkùùkuu, nígbà tí koríko tútù bá hù wá láti ilẹ̀ lẹ́yìn òjò.’
E será como a luz da manhã, quando sai o sol, da manhã sem nuvens, quando pelo seu resplandor e pela chuva a erva brota da terra.
5 “Lóòtítọ́ ilé mi kò rí bẹ́ẹ̀ níwájú Ọlọ́run, ṣùgbọ́n ó ti bá mi dá májẹ̀mú àìnípẹ̀kun, tí a túnṣe nínú ohun gbogbo, tí a sì pamọ́; nítorí pé gbogbo èyí ni ìgbàlà, àti gbogbo ìfẹ́ mi, ilé mi kò lè ṣe kí ó má dàgbà.
Ainda que a minha casa não seja tal para com Deus, contudo estabeleceu comigo um concerto eterno, que em tudo será bem ordenado e guardado, pois toda a minha salvação e todo o meu prazer está nele, apesar de que ainda não o faz brotar.
6 Ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọ Beliali yóò dàbí ẹ̀gún ẹ̀wọ̀n tí a ṣá tì, nítorí pé a kò lè fi ọwọ́ kó wọn.
Porém os filhos de Belial todos serão como os espinhos que se lançam fora, porque se lhes não pode pegar com a mão.
7 Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí yóò tọ́ wọn yóò fi irin àti ọ̀pá ọ̀kọ̀ ṣagbára yí ara rẹ̀ ká; wọ́n ó jóná lúúlúú níbìkan náà.”
Mas qualquer que os tocar se armará de ferro e da haste de uma lança; e a fogo serão totalmente queimados no mesmo lugar.
8 Wọ̀nyí sì ni orúkọ àwọn akọni ọkùnrin tí Dafidi ní: Joṣebu-Basṣebeti ará Takemoniti ni olórí àwọn balógun, òun sì ni akọni rẹ̀ tí ó pa ẹgbẹ̀rin ènìyàn lẹ́ẹ̀kan náà.
Estes são os nomes dos valentes que David teve: Joseb-bashebeth, filho de Tachemoni, o principal dos capitães: este era Adino, o esnita, que se oppozera a oitocentos, e os feriu de uma vez.
9 Ẹni tí ó tẹ̀lé e ni Eleasari ọmọ Dodo ará Ahohi, ọ̀kan nínú àwọn alágbára ọkùnrin mẹ́ta ti ó wà pẹ̀lú Dafidi, nígbà tí wọ́n pe àwọn Filistini ní ìjà, àwọn ọkùnrin Israẹli sì ti lọ kúrò.
E depois dele Eleazar, filho de Dodó, filho de Ahohi, entre os três valentes que estavam com David quando provocaram os philisteus que ali se ajuntaram à peleja, e quando de Israel os homens subiram.
10 Òun sì dìde, ó sì kọlu àwọn Filistini títí ọwọ́ fi kún un, ọwọ́ rẹ̀ sì lẹ̀ mọ́ idà; Olúwa sì ṣiṣẹ́ ìgbàlà ńlá lọ́jọ́ náà, àwọn ènìyàn sì padà bọ̀ lẹ́yìn rẹ̀ láti kó ìkógun.
Este se levantou, e feriu os philisteus, até lhe cançar a mão e ficar a mão pegada à espada: e naquele dia o Senhor obrou um grande livramento; e o povo voltou atráz dele, somente a tomar o despojo.
11 Ẹni tí ó tẹ̀lé e ni Ṣamma ọmọ Agee ará Harari, àwọn Filistini sì kó ara wọn jọ láti piyẹ́, oko kan sì wà níbẹ̀ tí ó kún fun lẹntili, àwọn ọmọ-ogun Israẹli sì sá kúrò níwájú àwọn Filistini.
E depois dele Samma, filho de Agé, o hararita, quando os philisteus se ajuntaram numa multidão, onde havia um pedaço de terra cheio de lentilhas, e o povo fugira de diante dos philisteus.
12 Ṣamma sì dúró láàrín méjì ilẹ̀ náà, ó sì gbà á sílẹ̀, ó sì pa àwọn Filistini Olúwa sì ṣe ìgbàlà ńlá.
Este pois se pôs no meio daquele pedaço de terra, e o defendeu, e feriu os philisteus: e o Senhor obrou um grande livramento.
13 Mẹ́ta nínú àwọn ọgbọ̀n ìjòyè sọ̀kalẹ̀, wọ́n sì tọ Dafidi wá ní àkókò ìkórè nínú ihò Adullamu, ọ̀wọ́ àwọn Filistini sì dó sí àfonífojì Refaimu.
Também três dos trinta cabeças desceram, e vieram no tempo da sega a David, à caverna de Adullam: e a multidão dos philisteus acampara no vale de Rephaim.
14 Dafidi sì wà nínú odi, ibùdó àwọn Filistini sì wà ní Bẹtilẹhẹmu nígbà náà.
David estava então num lugar forte, e a guarnição dos philisteus estava então em Beth-lehem.
15 Dafidi sì ń pòǹgbẹ, ó wí báyìí pé, “Ta ni yóò fún mi mu nínú omí kànga tí ń bẹ ní Bẹtilẹhẹmu, èyí tí ó wà ní ìhà ẹnu-bodè.”
E teve David desejo, e disse: Quem me dera beber da água da cisterna de Beth-lehem, que está junto à porta!
16 Àwọn ọkùnrin alágbára mẹ́ta sì la ogún àwọn Filistini lọ, wọ́n sì fa omi láti inú kànga Bẹtilẹhẹmu wá, èyí tí ó wà ní ìhà ẹnu-bodè, wọ́n sì mú tọ Dafidi wá, òun kò sì fẹ́ mu nínú rẹ̀, ṣùgbọ́n ó tú u sílẹ̀ fún Olúwa.
Então aqueles três valentes romperam pelo arraial dos philisteus, e tiraram água da cisterna de Beth-lehem, que está junto à porta, e a tomaram, e a trouxeram a David; porém ele não a quis beber, mas derramou-a perante o Senhor,
17 Òun sì wí pé, “Kí a má rí, Olúwa, tí èmi ó fi ṣe èyí; ṣé èyí ni ẹ̀jẹ̀ àwọn ọkùnrin tí ó lọ tí àwọn tí ẹ̀mí wọn lọ́wọ́?” Nítorí náà òun kò sì fẹ́ mú un. Nǹkan wọ̀nyí ni àwọn ọkùnrin alágbára mẹ́tẹ̀ẹ̀ta yìí ṣe.
E disse: Guarda-me, ó Senhor, de que tal faça; beberia eu o sangue dos homens que foram a risco da sua vida? De maneira que não a quis beber: isto fizeram aqueles três valentes.
18 Abiṣai, arákùnrin Joabu, ọmọ Seruiah, òun náà ni pàtàkì nínú àwọn mẹ́ta. Òun ni ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè sí ọ̀ọ́dúnrún ènìyàn, ó sì pa wọ́n, ó sì ní orúkọ nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta.
Também Abisai, irmão de Joab, filho de Zeruia, era cabeça de três; e este alçou a sua lança contra trezentos feridos: e tinha nome entre os três.
19 Ọlọ́lá jùlọ ni òun jẹ́ nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta, ó sì jẹ́ olórí fún wọn, ṣùgbọ́n òun kò tó àwọn mẹ́ta ìṣáájú.
Porventura este não era o mais nobre dentre estes três? pois era o primeiro deles; porém aos primeiros três não chegou.
20 Benaiah, ọmọ Jehoiada, ọmọ akọni ọkùnrin kan tí Kabṣeeli, ẹni tí ó pọ̀ ní iṣẹ́ agbára, òun pa àwọn ọmọ Arieli méjì ti Moabu; ó sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú ó sì pa kìnnìún kan nínú ihò lákoko òjò-dídì.
Também Benaia, filho de Joiada, filho dum homem valoroso de Cabseel, grande em obras, este feriu dois fortes leões de Moab; e desceu ele, e feriu um leão no meio de uma cova, no tempo da neve.
21 Ó sì pa ará Ejibiti kan, ọkùnrin tí ó dára láti wò, ará Ejibiti náà sì ní ọ̀kọ̀ kan ní ọwọ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n Benaiah sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ lọ, pẹ̀lú ọ̀pá ní ọwọ́, ó sì gba ọ̀kọ̀ náà lọ́wọ́ ará Ejibiti náà, ó sì fi ọ̀kọ̀ rẹ̀ pa á.
Também este feriu um homem egípcio, homem de respeito: e na mão do egípcio havia uma lança, porém ele desceu a ele com um cajado, e arrancou a lança da mão do egípcio, e o matou com a sua própria lança.
22 Nǹkan wọ̀nyí ní Benaiah ọmọ Jehoiada ṣe, ó sì ní orúkọ nínú àwọn ọkùnrin alágbára mẹ́ta náà.
Estas coisas fez Benaia, filho de Joiada, pelo que teve nome entre três valentes.
23 Nínú àwọn ọgbọ̀n náà, òun ní ọlá jùlọ, ṣùgbọ́n òun kò tó àwọn mẹ́ta ti ìṣáájú. Dafidi sì fi í ṣe ìgbìmọ̀ rẹ̀.
Dentre os trinta ele era o mais nobre, porém aos três primeiros não chegou: e David o pôs sobre os seus guardas.
24 Ọ̀kan nínú àwọn ọgbọ̀n náà: Asaheli arákùnrin Joabu sì Jásí Elhanani ọmọ Dodo ti Bẹtilẹhẹmu;
Asael, irmão de Joab, estava entre os trinta, que eram: El-hanan, filho de Dodó, de Beth-lehem,
25 Ṣamma ará Haroditi, Elika ará Harodi.
Samma, harodita, Elika, harodita,
26 Helesi ará Palti, Ira ọmọ Ikẹsi ará Tekoa;
Heles, paltita, Ira, filho de Ikkes, tekoita,
27 Abieseri ará Anatoti, Sibekai ará Huṣati;
Abiezer, anathothita, Mebunnai, hsathita,
28 Salmoni ará Ahohi, Maharai ará Netofa;
Zalmon, ahohita, Maharai, netophathita,
29 Heledi ọmọ Baanah, ará Netofa, Ittai ọmọ Ribai to Gibeah ti àwọn ọmọ Benjamini;
Heleb, filho de Baena, netophathita, Ittai, filho de Ribai, de Gibeah dos filhos de Benjamin,
30 Benaiah ará Piratoni, Hiddai ti àfonífojì Gaaṣi,
Benaia, pirathonita, Hiddai, do ribeiro de Gaás,
31 Abi-Alboni ará Arbati, Asmafeti Barhumiti;
Abi-albon, arbathita, Azmaveth, barhumita,
32 Eliaba ará Ṣaalboni, àwọn ọmọ Jaṣeni, Jonatani;
Eliaba, saalbonita, os filhos de Jasen e Jonathan,
33 ọmọ Ṣamma ará Harari, Ahiamu ọmọ Ṣarari ará Harari;
Samma, hararita, Ahiam, filho de Sarar, ararita,
34 Elifeleti ọmọ Ahasbai, ọmọ ará Maakati, Eliamu ọmọ Ahitofeli ará Giloni;
Eliphelet, filho de Ahasbai, filho dum maacathita, Eliam, filho de Achitophel, gilonita,
35 Hesro ará Karmeli, Paarai ará Arba;
Hesrai, carmelita, Paarai, arbita,
36 Igali ọmọ Natani ti Soba, Bani ará Gadi;
Ighal. filho de Nathan, de Zoba, Bani, gadita,
37 Seleki ará Ammoni, Naharai ará Beeroti, ẹni tí ń ru ìhámọ́ra Joabu ọmọ Seruiah;
Zelek, amonita, Naharai, beerothita, o que trazia as armas de Joab, filho de Zeruia,
38 Ira ará Itri, Garebu ará Itri.
Ira, jethrita, Gareb, jethrita,
39 Uriah ará Hiti. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́tàdínlógójì.
Urias, hetheu: trinta e sete por todos.

< 2 Samuel 23 >