< 2 Kings 5 >

1 Naamani jẹ́ olórí ogun ọba Aramu. Ó jẹ́ ènìyàn ńlá níwájú ọ̀gá rẹ̀, wọ́n sì bu ọlá fún un, nítorí nípasẹ̀ rẹ̀ ni Olúwa ti fi ìṣẹ́gun fún Aramu. Òun jẹ́ alágbára, akọni ọkùnrin ṣùgbọ́n, ó dẹ́tẹ̀.
Naaman, dowódca króla Syrii, był człowiekiem bardzo poważanym u swego pana i osobą czcigodną. Przez niego bowiem PAN dał wybawienie Syryjczykom. Był on także dzielnym wojownikiem, [ale] trędowatym.
2 Nísinsin yìí ẹgbẹgbẹ́ láti Aramu ti jáde lọ láti mú ọmọ obìnrin kékeré kan ní ìgbèkùn láti Israẹli, ó sì sin ìyàwó Naamani.
Gdy pewnego razu Syryjczycy wyszli w gromadach, uprowadzili z ziemi Izraela małą dziewczynkę, a ona służyła żonie Naamana.
3 Ó sọ fún ọ̀gá rẹ̀ obìnrin pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ọ̀gá mi lè rí wòlíì tí ó wà ní Samaria! Yóò wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
Powiedziała do swojej pani: O gdyby mój pan udał się do proroka, który jest w Samarii! Ten na pewno uzdrowiłby go z trądu.
4 Naamani lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ̀ ó sì wí fún un ohun tí ọmọbìnrin Israẹli ti sọ.
[Naaman] poszedł więc i oznajmił to swemu panu: Tak a tak powiedziała dziewczynka, która jest z ziemi Izraela.
5 “Ní gbogbo ọ̀nà, lọ,” ọba Aramu dá a lóhùn pé, “Èmi yóò fi ìwé ránṣẹ́ sí ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni Naamani lọ, ó sì mú pẹ̀lú rẹ̀ tálẹ́ǹtì fàdákà mẹ́wàá, ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ìwọ̀n wúrà àti ìpààrọ̀ aṣọ mẹ́wàá.
Na to król Syrii odpowiedział: Idź, jedź tam, a poślę list do króla Izraela. Wyruszył więc i wziął ze sobą dziesięć talentów srebra, sześć tysięcy [syklów] złota i dziesięć szat na zmianę.
6 Ìwé tí ó mú lọ sọ́dọ̀ ọba Israẹli kà pé, “Pẹ̀lú ìwé yìí èmi ń rán ìránṣẹ́ mi Naamani sí ọ pé o lè wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
I przyniósł list do króla Izraela o następującej treści: Kiedy ten list do ciebie dojdzie, wiedz, że posyłam do ciebie Naamana, swego sługę, abyś go uzdrowił z trądu.
7 Bí ọba Israẹli ti ka ìwé náà ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wí pé, “Èmi ha jẹ́ Ọlọ́run? Ǹjẹ́ èmi le pa kí n sì mú wá sí ààyè padà? Kí ni ó dé tí eléyìí rán ènìyàn sí mi láti wo ààrùn ẹ̀tẹ̀ rẹ sàn, kí ẹ wo bí ó ti ń wá ọ̀nà láti wá ìjà pẹ̀lú mi!”
A gdy król Izraela przeczytał list, rozdarł swoje szaty i powiedział: Czy ja jestem Bogiem, abym mógł uśmiercać i ożywiać, że ten posyła do mnie, abym uzdrowił człowieka z trądu? Zauważcie, proszę, i zobaczcie, że szuka on zaczepki ze mną.
8 Nígbà tí Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run gbọ́ pé ọba Israẹli ti ya aṣọ rẹ̀, ó sì rán iṣẹ́ yìí sí i pé, “Kí ni ó dé tí o fi fa aṣọ rẹ ya? Jẹ́ kí ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi. Òun yóò sì mọ̀ pé wòlíì wà ní Israẹli.”
Kiedy Elizeusz, mąż Boży, usłyszał, że król Izraela rozdarł swoje szaty, posłał do króla wiadomość: Czemu rozdarłeś swoje szaty? Niech on przyjdzie do mnie, a dowie się, że jest prorok w Izraelu.
9 Bẹ́ẹ̀ ni Naamani sì lọ pẹ̀lú ẹṣin rẹ̀ àti kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Eliṣa.
Naaman przybył więc ze swymi końmi i swym rydwanem i stanął przed drzwiami domu Elizeusza.
10 Eliṣa rán ìránṣẹ́ láti lọ sọ fún un pé, “Lọ, wẹ̀ ara rẹ ní ìgbà méje ní odò Jordani, ẹran-ara rẹ yóò sì tún padà bọ̀ sípò, ìwọ yóò sì mọ́.”
Elizeusz zaś wysłał do niego posłańca z tymi słowami: Idź i umyj się siedem razy w Jordanie, a twoje ciało powróci do [zdrowia] i będziesz czysty.
11 Ṣùgbọ́n Naamani lọ pẹ̀lú ìbínú ó sì wí pé, “Mo lérò pé yóò sì dìde jáde wá nítòótọ́ sí mi, yóò sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run, fi ọwọ́ rẹ̀ lórí ibẹ̀ kí ó sì wo ẹ̀tẹ̀ mi sàn.
Lecz Naaman rozgniewał się i odszedł, mówiąc: Oto myślałem sobie, że na pewno wyjdzie, stanie [przy mnie], wezwie imienia PANA, swego Boga, poruszy swoją ręką nad miejscem [trądu] i uzdrowi trędowatego.
12 Abana àti Fapari, odò Damasku kò ha dára ju gbogbo omi Israẹli lọ? Ṣé èmi kò le wẹ̀ nínú wọn kí n sì mọ́?” Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà, ó sì lọ pẹ̀lú ìrunú.
Czyż Abana i Parpar, rzeki Damaszku, nie są lepsze od wszystkich wód Izraela? Czy nie mógłbym się w nich obmyć i być czysty? Odwrócił się więc i odjechał w gniewie.
13 Ìránṣẹ́ Naamani lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ó sì wí pé, “Baba mi, tí wòlíì bá ti sọ fún ọ láti ṣe ohun ńlá kan, ṣé ìwọ kì bá ti ṣe, mélòó mélòó nígbà náà, nígbà tí ó sọ fún ọ pé, ‘Wẹ̀ kí o sì mọ́’!”
Lecz jego słudzy podeszli i powiedzieli do niego: Mój ojcze, gdyby ten prorok rozkazał ci [zrobić] coś wielkiego, czy byś tego nie uczynił? Tym bardziej gdy ci powiedział: Obmyj się, a będziesz czysty.
14 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ ó sì tẹ ara rẹ̀ bọ inú odò Jordani ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run ti sọ fún un, ẹran-ara rẹ̀ sì tún padà sí mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọkùnrin kékeré.
Poszedł więc i zanurzył się w Jordanie siedem razy, według słowa męża Bożego. I jego ciało stało się jak ciało małego dziecka, i został oczyszczony.
15 Nígbà náà Naamani àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ padà lọ sí ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run. Ó sì dúró níwájú rẹ̀ ó sì wí pé, “Nísinsin yìí èmi mọ̀ pé kò sí Ọlọ́run ní gbogbo àgbáyé àyàfi ní Israẹli nìkan. Jọ̀wọ́ gba ẹ̀bùn láti ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ.”
Potem wrócił do męża Bożego wraz z całym swoim orszakiem, a gdy przybył, stanął przed nim i powiedział: Oto teraz poznałem, że nie ma Boga na całej ziemi poza Izraelem. Przyjmij więc, proszę, dar od swego sługi.
16 Wòlíì náà dáhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ẹni tí mo ń sìn, èmi kò nígbà ohun kan,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Naamani rọ̀ ọ́ láti gbà á, ó kọ̀.
Lecz on powiedział: Jak żyje PAN, przed którego obliczem stoję, nic nie wezmę. [Tamten] nalegał na niego, aby wziął, ale odmówił.
17 Naamani wí pé, “Tí o kò bá nígbà, jọ̀wọ́ jẹ́ kí a fi fún èmi ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ ẹrù erùpẹ̀ tí ìbáaka méjì le rù, nítorí láti òní lọ ìránṣẹ́ rẹ kì yóò rú ẹbọ sísun àti rú ẹbọ sí ọ̀kan lára àwọn ọlọ́run mìíràn mọ́ bí kò ṣe sí Olúwa.
Wtedy Naaman powiedział: Proszę więc, niech dadzą twemu słudze tyle ziemi, ile udźwignie para mułów. Twój sługa bowiem nie będzie już składał ani całopalenia, ani [innych] ofiar obcym bogom, tylko PANU.
18 Ṣùgbọ́n kí Olúwa kí ó dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún nǹkan yìí. Nígbà tí ọ̀gá mi wọ inú ilé Rimoni láti fi orí balẹ̀ tí ó sì fi ara ti ọwọ́ mi tí mo sì tẹ ara mi ba pẹ̀lú níbẹ̀. Nígbà tí èmi tẹ ara mi ba ní ilé Rimoni, kí Olúwa dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún èyí.”
[Jednak] w tej sprawie niech PAN przebaczy twemu słudze: gdy mój pan wchodzi do świątyni Rimmona, aby tam oddać pokłon, a opiera się na moim ramieniu, wtedy i ja kłaniam się w świątyni Rimmona. Gdy więc ja się kłaniam w świątyni Rimmona, niech PAN przebaczy twemu słudze w tej sprawie.
19 Eliṣa wí pé, “Máa lọ ní àlàáfíà.” Lẹ́yìn ìgbà tí Naamani tí rin ìrìnàjò tí ó jìnnà,
Odpowiedział mu: Idź w pokoju. A gdy odjechał od niego kawałek drogi;
20 Gehasi, ìránṣẹ́ Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run, ó wí fún ara rẹ̀ pé, “Ọ̀gá mi jẹ́ ẹni tí ó rọ́nú lórí Naamani, ará Aramu, nípa pé kò gba ohunkóhun ní ọwọ́ rẹ̀ ohun tí ó mú wá, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, èmi yóò sá tẹ̀lé e èmi yóò sì gba ohun kan ní ọwọ́ rẹ̀.”
Gehazi, sługa Elizeusza, męża Bożego, powiedział: Oto mój pan oszczędził tego Naamana, Syryjczyka, nie przyjmując z jego rąk tego, co przywiózł. Jak żyje PAN, pobiegnę za nim i wezmę coś od niego.
21 Bẹ́ẹ̀ ni Gehasi sáré tẹ̀lé Naamani. Nígbà tí Naamani rí i tí ó ń sáré tẹ̀lé e, ó sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ̀. “Ṣé gbogbo nǹkan wà dáradára?” ó béèrè.
Gehazi więc pobiegł za Naamanem. Kiedy Naaman zobaczył, że biegnie za nim, zszedł z rydwanu i wyszedł mu naprzeciw, i zapytał: Czy [wszystko] jest dobrze?
22 “Gbogbo nǹkan wà dáradára,” Gehasi dá a lóhùn. “Ọ̀gá mi rán mi láti sọ wí pé, ‘Àwọn ọ̀dọ́ ọmọkùnrin méjì láti ọ̀dọ̀ ọmọ wòlíì wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi láti orí òkè ìlú ti Efraimu. Jọ̀wọ́ fún wọn ní ẹ̀bùn fàdákà àti ìpààrọ̀ aṣọ méjì.’”
Odpowiedział: Dobrze. Mój pan posłał mnie, abym ci powiedział: Oto dopiero teraz przyszli do mnie dwaj młodzieńcy z góry Efraim spośród synów proroków. Daj im, proszę, talent srebra i dwie szaty na zmianę.
23 Naamani wí pé, “Ní gbogbo ọ̀nà, mú ẹ̀bùn méjì.” Ó sì rọ Gehasi láti gbà wọ́n, ó sì di ẹ̀bùn méjì náà ti fàdákà ní inú àpò méjì, pẹ̀lú ìpààrọ̀ aṣọ méjì, ó sì fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ méjì, wọ́n sì kó wọn lọ sọ́dọ̀ Gehasi.
Naaman odpowiedział: Racz wziąć dwa talenty. Nalegał na niego i zawiązał dwa talenty srebra w dwóch workach oraz dwie szaty na zmianę, i włożył na dwóch jego sług, którzy [je] nieśli przed nim.
24 Nígbà tí Gehasi sì dé ibi ilé ìṣọ́, ó gbà wọ́n lọ́wọ́ wọn, ó sì tó wọ́n sínú ilé, ó sì jọ̀wọ́ àwọn ọkùnrin náà lọ́wọ́ lọ, wọ́n sì jáde lọ.
A gdy przyszedł do twierdzy, wziął [to] z ich rąk i złożył w domu. Potem odprawił mężczyzn, a oni odeszli.
25 Nígbà náà ó sì wọlé wá ó sì dúró níwájú ọ̀gá rẹ̀ Eliṣa. “Níbo ni o ti wà Gehasi?” Eliṣa béèrè. “Ìránṣẹ́ rẹ kò lọ sí ibìkan kan.” Gehasi dá a lóhùn.
Sam zaś wszedł i stanął przed swoim panem. Elizeusz zapytał go: Skąd [wracasz], Gehazi? Odpowiedział: Twój sługa nigdzie nie chodził.
26 Ṣùgbọ́n Eliṣa wí fún un pé, “Ẹ̀mí mi kò ha wà pẹ̀lú rẹ nígbà tí ọkùnrin náà sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ? Ṣé àsìkò tí ó yẹ láti gba owó nìyìí, tàbí láti gba aṣọ, ọgbà olifi, ọgbà àjàrà, àgùntàn, màlúù tàbí ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin?
Lecz powiedział mu: Czy moje serce nie szło [z tobą], kiedy tamten człowiek odwrócił się na swym rydwanie na twoje spotkanie? Czy to był czas przyjmowania srebra, przyjmowania szat, sadów oliwnych, winnic, owiec, wołów, sług i służących?
27 Ẹ̀tẹ̀ Naamani yóò lẹ̀ mọ́ ọ àti sí irú-ọmọ rẹ títí láé.” Nígbà náà Gehasi kúrò níwájú Eliṣa, ó sì di adẹ́tẹ̀, ó sì funfun gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gbọ̀n òwú.
Dlatego też trąd Naamana przylgnie do ciebie i do twojego potomstwa na wieki. I wyszedł od niego trędowaty, [biały] jak śnieg.

< 2 Kings 5 >