< 2 Chronicles 5 >

1 Nígbà tí gbogbo iṣẹ́ tí Solomoni ti ṣe fún tẹmpili Olúwa ti parí, ó kó gbogbo àwọn nǹkan tí Dafidi baba rẹ̀ ti yà sọ́tọ̀: wúrà àti fàdákà àti gbogbo ohun èlò ọ̀ṣọ́, ó sì fi wọ́n sínú ìṣúra ilé Ọlọ́run.
Et ainsi fut terminé tout l'ouvrage exécuté par Salomon pour le Temple de l'Éternel, et Salomon introduisit ce que David, son père, avait consacré; et l'argent et l'or et tout le mobilier, il le mit dans le Trésor de la Maison de Dieu.
2 Nígbà náà ni Solomoni pe àwọn àgbàgbà Israẹli jọ sí Jerusalẹmu, gbogbo àwọn olórí ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan àti àwọn olóyè àwọn ìdílé Israẹli, kí wọn kí ó gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá láti Sioni ìlú Dafidi.
Alors Salomon assembla les Anciens d'Israël et tous les chefs des Tribus, les princes des maisons patriarcales des enfants d'Israël, à Jérusalem pour transférer l'Arche d'Alliance de l'Éternel de la Cité de David, c'est-à-dire, de Sion.
3 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli péjọ sí ọ̀dọ̀ ọba ní àkókò àjọ àgọ́.
Et auprès du roi s'assemblèrent tous les hommes d'Israël à la Fête (c'était le septième mois).
4 Gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli sì wá, àwọn ọmọ Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa.
Et vinrent tous les Anciens d'Israël, et les Lévites portèrent l'Arche.
5 Wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí náà gòkè àti àgọ́ ìpàdé àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi ni ó mú wọn gòkè wá.
Et ils apportèrent l'Arche et la Tente du Rendez-vous et tout le mobilier sacré qui était dans la Tente, ces objets furent apportés par les Prêtres, les Lévites.
6 Nígbà náà ni ọba Solomoni àti gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, wà níwájú àpótí ẹ̀rí náà wọ́n sì fi àgùntàn àti màlúù tí a kò le è kà tán rú ẹbọ, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è mọ iye wọn tán nítorí bí wọ́n ti pọ̀ tó.
Et le roi Salomon et toute l'Assemblée d'Israël qui s'était réunie auprès de lui, devant l'Arche sacrifièrent des brebis et des bœufs qui ne pouvaient se nombrer, ni se compter, tant il y en avait.
7 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀, sí ibi inú lọ́hùn ún ilé Olúwa, Ibi Mímọ́ Jùlọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.
Et les Prêtres introduisirent l'Arche d'Alliance de l'Éternel à sa place, dans le Sanctuaire de l'édifice, dans le Lieu Très-Saint au-dessous des ailes des Chérubins.
8 Àwọn Kérúbù na ìyẹ́ wọn bo ibi àpótí ẹ̀rí náà àti àwọn ọ̀pá tí ó gbé e ró.
Et les Chérubins avaient les ailes étendues sur l'emplacement de l'Arche, et les Chérubins couvraient l'Arche et ses barres d'en haut.
9 Àwọn ọ̀pá rẹ̀ náà gùn tó bẹ́ẹ̀ tí a fi rí orí àwọn ọ̀pá náà láti ibi àpótí ẹ̀rí náà níwájú Ibi Mímọ́ náà, ṣùgbọ́n a kò rí wọn lóde. Níbẹ̀ ni ó sì wà títí di òní yìí.
Et les barres étaient assez longues pour que de l'Arche devant le Sanctuaire on pût en voir les extrémités, mais du dehors on ne les apercevait pas, et elle y a été jusqu'à ce jour.
10 Kò sí ohun kan nínú àpótí ẹ̀rí náà bí kò ṣe wàláà méjì tí Mose fi sínú rẹ̀ ní Horebu, ní ìgbà tí Olúwa fi bá àwọn ọmọ Israẹli dá májẹ̀mú lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti.
Il n'y avait rien dans l'Arche que les deux Tables qu'y avait mises Moïse en Horeb, quand l'Éternel fit alliance avec les enfants d'Israël à leur sortie de l'Egypte.
11 Lẹ́yìn náà ni àwọn àlùfáà jáde wá láti Ibi Mímọ́. Gbogbo àwọn àlùfáà tí ó wà níbẹ̀ ni ó ya ara wọn sí mímọ́ láìbìkítà fún ìpín wọn.
Et lorsque les Prêtres sortirent du Lieu-Saint, (car tous les Prêtres présents s'étaient mis en état de sainteté, sans égard à la distinction des classes)
12 Gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n jẹ́ akọrin: Asafu, Hemani, Jedutuni àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn ẹbí wọn, wọ́n dúró ní igun ìlà-oòrùn pẹpẹ náà wọ́n wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ tuntun wọ́n ń lo kimbali, dùùrù àti ohun èlò orin olókùn. Ìwọ̀n ọgọ́fà àwọn àlùfáà tí wọ́n ń fun ìpè ni wọ́n tẹ̀lé wọn.
et lorsque les Lévites, les Chantres, eux tous, savoir Asaph, Heiman et Jeduthun, et leurs fils et leurs frères, vêtus de byssus et munis de cymbales, de harpes et de luths furent debout, au côté oriental de l'autel accompagnés de cent vingt Prêtres sonnant des trompettes,
13 Àwọn afùnpè àti àwọn akọrin pa ohùn wọn pọ̀ sí ọ̀kan ṣoṣo, láti fi ìyìn àti ọpẹ́ fun Olúwa. Wọ́n fi ìpè, kimbali àti àwọn ohun èlò orin mìíràn mọ́ ọn, wọ́n gbé ohùn wọn sókè láti fi yin Olúwa, wọ́n ń kọrin pé, “Ó dára; ìfẹ́ rẹ̀ wà títí láéláé.” Nígbà náà ni ìkùùkuu ojú ọ̀run kún inú tẹmpili Olúwa,
et lorsque, comme un seul homme, les trompettes et les chantres entonnèrent tout d'une voix la louange de l'Éternel et l'action de grâces à l'Éternel, et lorsqu'ils poussèrent leur voix au bruit des trompettes et des cymbales et des instruments à cordes et louant l'Éternel de ce qu'il est bon et sa miséricorde éternelle, alors l'édifice, le temple de l'Éternel se remplit d'une nuée,
14 tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn àlùfáà kò le è ṣiṣẹ́ ìsìn wọn nítorí ìkùùkuu náà, nítorí ògo Olúwa kún inú tẹmpili Ọlọ́run.
et les Prêtres ne pouvaient y tenir pour faire leur service, par l'effet de la nuée, caria gloire de l'Éternel avait rempli la Maison de Dieu.

< 2 Chronicles 5 >