< 2 Chronicles 16 >

1 Ní ọdún kẹrìndínlógójì ìjọba Asa, Baaṣa ọba Israẹli gòkè wá sí Juda ó sì kọlu Rama, láti ma bá a jẹ́ kí ẹnikẹ́ni lè jáde tàbí wọlé tọ Asa ọba Juda lọ.
W trzydziestym szóstym roku panowania Asy nadciągnął przeciw Judzie Basza, król Izraela, i zbudował Rama, aby [nikt] nie mógł wychodzić od Asy, króla Judy, i wchodzić do niego.
2 Nígbà náà ni Asa mú wúrà àti fàdákà jáde nínú ilé ìṣúra ilé Olúwa àti ààfin ọba ó sì ránṣẹ́ sí Beni-Hadadi ọba Siria, ẹni tí ń gbé ní Damasku, ó wí pé,
Wtedy Asa wziął srebro i złoto ze skarbców domu PANA i domu królewskiego i posłał [je] do Ben-Hadada, króla Syrii, który mieszkał w Damaszku, mówiąc:
3 “Májẹ̀mú kan wà láàrín èmi àti ìrẹ, bí ó ti wà láàrín baba mi àti baba rẹ. Ẹ wò ó, mo fi wúrà àti fàdákà ránṣẹ́ sí ọ; lọ, ba májẹ̀mú tí o bá Baaṣa ọba Israẹli dá jẹ́, kí ó lè lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.”
[Trwa] przymierze między mną a tobą, j[ak było] między moim ojcem a twoim ojcem. Oto posyłam ci srebro i złoto. Idź i zerwij swoje przymierze z Baszą, królem Izraela, aby odstąpił ode mnie.
4 Beni-Hadadi sì gbọ́ ti Asa ọba, ó sì rán àwọn olórí ogun rẹ̀ lọ sí àwọn ìlú Israẹli, wọ́n sì kọlu Ijoni, Dani, Abeli-Maimu, àti gbogbo ìlú ìṣúra Naftali.
I Ben-Hadad posłuchał króla Asy, i posłał dowódców swoich wojsk przeciwko miastom Izraela. Uderzyli na Ijjon, Dan i Abelmaim oraz wszystkie miasta spichlerze Neftalego.
5 Nígbà tí Baaṣa gbọ́ èyí, ó sì dá kíkọ́ Rama dúró, ó sì dá iṣẹ́ rẹ̀ dúró.
Kiedy Basza o tym usłyszał, przestał budować Rama i przerwał swoje roboty.
6 Nígbà náà ní ọba Asa kó gbogbo àwọn ènìyàn Juda jọ, wọ́n sì kó òkúta àti igi Rama lọ èyí ti Baaṣa ń fi kọ́lé; ó sì fi kọ́ Geba àti Mispa.
Wtedy król Asa wziął ze sobą cały lud Judy i zabrali z Rama kamienie i drewno, z którego budował Basza, a zbudował z niego Geba i Mispę.
7 Ní àkókò náà wòlíì Hanani wá sí ọ̀dọ̀ Asa ọba Juda, ó sì wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ọba Siria, ìwọ kò sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run rẹ, nítorí náà ni ogún ọba Siria ṣe bọ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ.
A w tym czasie widzący Chanani przyszedł do Asy, króla Judy, i powiedział mu: Ponieważ polegałeś na królu Syrii, a nie na PANU, swoim Bogu, wojsko króla Syrii uszło ci z ręki.
8 Àwa kì í ṣe ará Etiopia àti àwọn ará Libia àwọn alágbára ogun pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹlẹ́ṣin? Síbẹ̀ nígbà tí ìwọ bá gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò sì fi wọ́n lé ọwọ́ rẹ.
Czyż Etiopczycy i Libijczycy nie mieli ogromnego wojska z mnóstwem rydwanów i jeźdźców? A jednak, ponieważ polegałeś na PANU, oddał ich w twoją rękę.
9 Nítorí ojú Olúwa yí gbogbo ayé ká láti fi agbára fún àwọn ẹni tí ó ní ọkàn pípé sí i. Ìwọ ti ṣe ohun aṣiwèrè, láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ yóò wà lójú ogun.”
Oczy PANA przebiegają bowiem całą ziemię, aby pokazywał on swoją moc dla tych, których serce [jest] doskonałe wobec niego. Głupio postąpiłeś; z tego powodu odtąd będziesz miał wojny.
10 Asa sì bínú pẹ̀lú sí wòlíì nítorí èyí, ó sì mú un bínú gidigidi tí ó sì fi mú un sínú túbú. Ní àkókò náà Asa sì ni díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn náà lára.
Wtedy Asa rozgniewał się na widzącego i wtrącił go do więzienia, bo był tym wzburzony. W tym czasie Asa uciskał także [niektórych] z ludu.
11 Àwọn iṣẹ́ ìjọba Asa, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni akọ sínú ìwé ọba Juda àti Israẹli.
Ale pozostałe dzieje Asy, od pierwszych do ostatnich, są zapisane w księdze królów Judy i Izraela.
12 Ní ọdún kọkàndínlógójì ìjọba rẹ̀, Asa sì ṣe àìsàn pẹ̀lú ààrùn nínú ẹsẹ̀ rẹ̀. Bi ó tilẹ̀ jẹ pé ààrùn rẹ̀ lágbára, síbẹ̀ kódà nínú àìsàn rẹ̀ kò wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ àwọn oníṣègùn nìkan.
I w trzydziestym dziewiątym roku swojego panowania Asa rozchorował się na nogi, a choroba była bardzo ciężka. Jednak w swojej chorobie nie szukał PANA, lecz lekarzy.
13 Nígbà náà tí ó pé ọdún kọ́kànlélógójì rẹ̀, Asa kú, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn ìjọba baba rẹ̀,
I tak Asa zasnął ze swoimi ojcami, i umarł w czterdziestym pierwszym roku swojego panowania.
14 wọ́n sì sin ín sínú isà òkú tí ó ti gbẹ́ jáde fún ara rẹ̀ ní ìlú Dafidi. Wọ́n sì tẹ sí orí àkéte tí ó fi òórùn dídùn kún, àti onírúurú tùràrí tí a fi ọgbọ́n pèsè, wọ́n sì da iná ńlá nítorí rẹ̀.
I pogrzebano go w jego grobie, który sobie przygotował w mieście Dawida. Położono go na łożu wypełnionym wonnościami i rozmaitymi maściami przygotowanymi według sztuki aptekarskiej. I rozpalono mu wielki ogień.

< 2 Chronicles 16 >