< 1 Samuel 9 >

1 Ará Benjamini kan wà, ẹni tí ó jẹ́ aláàánú ọlọ́rọ̀, orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Kiṣi, ọmọ Abieli, ọmọ Serori, ọmọ Bekorati, ọmọ Afiah ti Benjamini.
Był pewien człowiek z [pokolenia] Beniamina, któremu na imię było Kisz – syn Abiela, syna Cerora, syna Bekorata, syna Afiacha, Beniaminita, dzielny mąż.
2 Ó ní ọmọkùnrin kan tí à ń pè ní Saulu, ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó yanjú, tí ó jẹ́ arẹwà, tí kò sí ẹni tó ní ẹwà jù ú lọ láàrín gbogbo àwọn ọmọ Israẹli—láti èjìká rẹ̀ lọ sí òkè, ó ga ju gbogbo àwọn ènìyàn tókù lọ.
Miał on syna imieniem Saul, urodziwego młodzieńca. Nie [było] nikogo spośród synów Izraela przystojniejszego niż on. Wzrostem o głowę przewyższał cały lud.
3 Nísinsin yìí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó jẹ́ ti Kiṣi baba Saulu sì sọnù. Nígbà náà, Kiṣi sọ fún Saulu ọmọ rẹ̀ pé, “Mú ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́ pẹ̀lú rẹ kí ẹ lọ láti wá àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà.”
A zaginęły oślice Kisza, ojca Saula. Wtedy Kisz powiedział do swego syna Saula: Weź teraz ze sobą jednego ze sług i wstań, idź, poszukaj oślic.
4 Bẹ́ẹ̀ ní ó kọjá láàrín àwọn ìlú olókè Efraimu, ó sì kọjá ní àyíká ilẹ̀ Ṣaliṣa, ṣùgbọ́n wọn kò rí wọn. Wọ́n sì kọjá lọ sí òpópó Ṣaalimu, ṣùgbọ́n àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kò sí níbẹ̀. Nígbà náà, ó kọjá ní agbègbè Benjamini, wọn kò sì rí wọn.
Przeszedł więc przez górę Efraim i przez ziemię Szalisza, lecz [ich] nie znaleźli. Przeszli także przez ziemię Szaalim, ale [ich] nie [znaleźli]. Przeszli też przez ziemię Beniamina i [ich] nie znaleźli.
5 Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Sufu, Saulu sọ fún ìránṣẹ́ tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí á padà sẹ́yìn, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, baba mi yóò dá ìrònú rẹ̀ dúró nípa àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ yóò sì bẹ̀rẹ̀ àníyàn nípa wa.”
Kiedy przyszli do ziemi Suf, Saul powiedział do swego sługi, który z nim był: Chodź, wracajmy, by czasem mój ojciec nie zaniechał [troski] o oślice i nie martwił się o nas.
6 Ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ náà fún un ní èsì pé, “Wò ó, ní inú ìlú yìí ọkùnrin ènìyàn Ọlọ́run kan wà; ó jẹ́ ẹni tí wọ́n ń bu ọlá fún, àti gbogbo ohun tí ó bá sọ ní ó máa ń jẹ́ òtítọ́. Jẹ́ kí á lọ síbẹ̀ nísinsin yìí, bóyá yóò sọ fún wá ọ̀nà tí a yóò gbà.”
Ten mu odpowiedział: Oto teraz w tym mieście [jest] mąż Boży, człowiek szanowany; wszystko, co mówi, spełnia się. Pójdźmy więc tam, może wskaże nam drogę, którą mamy iść.
7 Saulu sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀, “Tí àwa bá lọ, kín ni àwa lè fún ọkùnrin náà? Oúnjẹ inú àpò wa ti tán. A kò sì ní ẹ̀bùn láti mú lọ sọ́dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run. Kí ni a ní?”
Wtedy Saul odpowiedział swemu słudze: Jeśli pójdziemy, cóż przyniesiemy temu człowiekowi? Chleb bowiem wyczerpał się już w naszych torbach i nie mamy podarunku, który moglibyśmy przynieść mężowi Bożemu. Cóż mamy?
8 Ìránṣẹ́ sì dá a lóhùn lẹ́ẹ̀kan sí i. “Wò ó,” ó wí pé, “Mo ní ìdámẹ́rin ṣékélì fàdákà lọ́wọ́. Èmi yóò fún ènìyàn Ọlọ́run náà kí ó lè fi ọ̀nà hàn wá.”
Sługa znowu odpowiedział Saulowi: Oto mam przy sobie ćwierć srebrnego sykla. Dam to mężowi Bożemu, aby oznajmił nam naszą drogę.
9 (Tẹ́lẹ̀ ní Israẹli tí ọkùnrin kan bá lọ béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run, yóò wí pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì náà,” nítorí àwọn alásọtẹ́lẹ̀ ìsinsin yìí ni wọ́n ń pè ní wòlíì).
Dawniej w Izraelu, kiedy ktoś szedł poradzić się Boga, tak mówił: Chodźcie, pójdziemy do widzącego. Dzisiejszego proroka bowiem dawniej nazywano widzącym.
10 Saulu sọ fún ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀ pé ó dára, “Jẹ́ kí a lọ.” Wọ́n jáde lọ sí ìlú tí ènìyàn Ọlọ́run náà ń gbé.
Wtedy Saul powiedział do swego sługi: Słuszne [jest] twoje słowo, chodź, pójdziemy. I udali się do miasta, w którym był mąż Boży.
11 Bí wọ́n ṣe ń lọ ní orí òkè sí ìlú náà, wọ́n pàdé àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin tí ó ń jáde í bọ̀ láti wá pọn omí. Wọ́n sì bi wọ́n, “Ṣé wòlíì náà wà níbí?”
A gdy wchodzili na górę do miasta, spotkali dziewczęta, które wyszły naczerpać wody. I zapytali je: Czy jest tu widzący?
12 “Ó wà,” wọ́n dáhùn. “Ó ń bẹ níwájú u yín, múra nísinsin yìí, ó ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ wa lónìí ni, nítorí àwọn ènìyàn ní ẹbọ rírú ni ibi gíga.
One odpowiedziały im: Tak, oto jest przed tobą. Pośpiesz się, dziś bowiem przyszedł do miasta, gdyż dziś lud [składa] ofiary na wyżynie.
13 Kété tí ẹ bá ti wọ ìlú, ẹ ó rí i kí ó tó lọ sí ibi gíga láti lọ jẹun. Àwọn ènìyàn kò sì ní bẹ̀rẹ̀ sí jẹun títí tí yóò fi dé. Torí ó gbọdọ̀ bùkún ẹbọ náà; lẹ́yìn náà, àwọn tí a pè yóò jẹun. Gòkè lọ nísinsin yìí, ó yẹ kí ẹ rí i ní àkókò yìí.”
Gdy wejdziecie do miasta, znajdziecie go, zanim pójdzie na wyżynę na posiłek. Lud bowiem nie będzie jadł, dopóki [on] nie przyjdzie, gdyż on błogosławi ofiarę. Dopiero potem jedzą zaproszeni. Idźcie więc, bo właśnie teraz go spotkacie.
14 Wọ́n gòkè lọ sí ìlú náà, bí wọ́n ti ń wọlé, níbẹ̀ ni Samuẹli, ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ wọn bí ó ti ń lọ ibi gíga náà.
Ruszyli więc do miasta. A gdy wchodzili do miasta, oto Samuel wychodził im naprzeciw, udając się na wyżynę.
15 Olúwa ti sọ létí Samuẹli ní ọjọ́ kan kí Saulu ó tó dé pé,
A PAN wyjawił Samuelowi na dzień przed przybyciem Saula, mówiąc mu:
16 “Ní ìwòyí ọ̀la, èmi yóò ran ọmọkùnrin kan sí ọ láti ilẹ̀ Benjamini. Fi òróró yàn án gẹ́gẹ́ bí olórí lórí àwọn ọmọ Israẹli, yóò gba àwọn ènìyàn mi kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Filistini. Mo ti bojú wo àwọn ènìyàn mi, nítorí igbe wọn ti dé ọ̀dọ̀ mi.”
Jutro w tym czasie wyślę do ciebie człowieka z ziemi Beniamina. Jego namaścisz na wodza nad moim ludem Izraelem; a on wybawi mój lud z rąk Filistynów. Wejrzałem bowiem na swój lud, gdyż jego lament dotarł do mnie.
17 Nígbà tí Samuẹli fojúrí Saulu, Olúwa sọ fún un pé, “Èyí ni ọkùnrin tí mo sọ fún ọ nípa rẹ̀, yóò darí àwọn ènìyàn mi.”
A gdy Samuel zobaczył Saula, PAN mu powiedział: Oto człowiek, o którym ci powiedziałem. Właśnie on będzie panował nad moim ludem.
18 Saulu sì súnmọ́ Samuẹli ní ẹnu-ọ̀nà ìlú, ó sì wí pé, “Sọ fún mi èmi ń bẹ̀ ọ́ níbo ni ilé wòlíì náà wà.”
Wtedy Saul zbliżył się do Samuela w bramie i powiedział: Proszę, powiedz mi, gdzie jest dom widzącego?
19 Samuẹli dáhùn pé, “Èmi ni wòlíì náà. Ẹ máa gòkè lọ ṣáájú mi, ní ibi gíga, ẹ ó sì bá mi jẹun lónìí. Ní òwúrọ̀ ni èmi yóò tó jẹ́ kí ẹ lọ, gbogbo ohun tí ó wà ní ọkàn rẹ ní èmi yóò sọ fún ọ.
Samuel odpowiedział Saulowi: Ja jestem widzący. Idź przede mną na wyżynę. Dziś będziecie jeść ze mną, a jutro rano odprawię cię i powiem ci wszystko, co jest w twoim sercu.
20 Fún ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó sọnù fún ọjọ́ mẹ́ta sẹ́yìn, má ṣe dààmú nípa wọ́n: a ti rí wọn. Sí ta ni gbogbo ìfẹ́ Israẹli wà? Bí kì í ṣe sí ìwọ àti sí gbogbo ilé baba à rẹ.”
A co do oślic, które ci zaginęły trzy dni temu, nie martw się, bo już się znalazły. I na kogo jest zwrócone wszelkie pragnienie Izraela? Czy nie na ciebie i na cały dom twego ojca?
21 Saulu dáhùn pé, “Ṣùgbọ́n èmi kì í há ṣe ẹ̀yà Benjamini? Kékeré nínú ẹ̀yà Israẹli. Ìdílé mi kò ha rẹ̀yìn jùlọ nínú gbogbo ẹ̀yà Benjamini? Èéṣì ti ṣe tí ìwọ sọ̀rọ̀ yìí sí mi?”
Saul odpowiedział: Czyż nie jestem Beniaminitą – z najmniejszego pokolenia Izraela? I czyż moja rodzina nie jest najmniejsza ze wszystkich rodzin pokolenia Beniamina? Dlaczego więc mówisz do mnie takie słowa?
22 Nígbà náà ni Samuẹli mú Saulu pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ̀ wọ inú gbọ̀ngán, ó sì mú wọn jókòó sí iwájú àwọn tí a pè—tí wọn tó ọgbọ̀n.
I Samuel zabrał Saula i jego sługę, zaprowadził ich do sali i dał im pierwsze miejsce wśród zaproszonych, a było ich około trzydziestu ludzi.
23 Samuẹli sọ fún alásè pé, “Mú ìpín ẹran tí mo fún ọ wá, èyí tí mo sọ fún ọ pé kí o yà sọ́tọ̀.”
Wtedy Samuel powiedział do kucharza: Podaj tę część, którą ci dałem i o której ci mówiłem: Zatrzymaj ją u siebie;
24 Alásè náà sì gbé ẹsẹ̀ náà pẹ̀lú ohun tí ó wà lórí i rẹ̀, ó sì gbé e síwájú Saulu. Samuẹli wí pé, “Èyí ni ohun tí a fi pamọ́ fún ọ. Jẹ, nítorí a yà á sọ́tọ̀ fún ọ, fún ìdí yìí, láti ìgbà tí mo ti wí pé, ‘Mo ní àlejò tí a pè.’” Saulu sì jẹun pẹ̀lú Samuẹli ní ọjọ́ náà.
Kucharz przyniósł łopatkę i to, co było na niej, i położył przed Saulem, a [Samuel] powiedział: Oto co zostało, połóż to przed sobą i jedz, bo [kiedy] powiedziałem: Wezwałem lud – zostało [to] zachowane dla ciebie na tę chwilę. I Saul jadł razem z Samuelem tego dnia.
25 Lẹ́yìn ìgbà tí wọn ti sọ̀kalẹ̀ láti ibí gíga náà wá sí inú ìlú, Samuẹli sì bá Saulu sọ̀rọ̀ lórí òrùlé ilé e rẹ̀.
A gdy zeszli z wyżyny do miasta, Samuel rozmawiał z Saulem na dachu.
26 Wọ́n sì dìde ní àfẹ̀mọ́júmọ́, ó pe Saulu sórí òrùlé pé, “Múra, èmi yóò rán ọ lọ.” Nígbà tí Saulu múra tán òun àti Samuẹli jọ jáde lọ síta.
Potem wstali wcześnie rano. I gdy zaczęło świtać, Samuel zawołał Saula na dach, mówiąc: Wstań, a wyprawię cię. Saul wstał więc i obaj wyszli z domu, on i Samuel.
27 Bí wọ́n ti ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìpẹ̀kun ìlú náà, Samuẹli wí fún Saulu pé, “Sọ fún ìránṣẹ́ náà kí ó máa lọ ṣáájú u wa,” ìránṣẹ́ náà sì ṣe bẹ́ẹ̀, “Ṣùgbọ́n kí ìwọ kí ó dúró díẹ̀, kí èmi kí ó lè sọ ọrọ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run fún ọ.”
A gdy schodzili ku granicy miasta, Samuel odezwał się do Saula: Powiedz słudze, aby poszedł przed nami. I gdy ten poszedł, [dodał]: Ty zaś zatrzymaj się na chwilę, abym ci oznajmił słowo Boże.

< 1 Samuel 9 >