< 1 Samuel 7 >

1 Nígbà náà àwọn ará Kiriati-Jearimu wá, wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa. Wọ́n gbé e lọ sí ilé Abinadabu lórí òkè, wọ́n sì ya Eleasari ọmọ rẹ̀ sí mímọ́ láti ṣọ́ àpótí ẹ̀rí Olúwa.
Przyszli więc ludzie z Kiriat-Jearim, zabrali arkę PANA i wnieśli ją do domu Abinadaba na wzgórzu. Eleazara zaś, jego syna, poświęcili, aby strzegł arki PANA.
2 Ó sì jẹ́ ní ìgbà pípẹ́, ogún ọdún ni àpótí ẹ̀rí Olúwa fi wà ní Kiriati-Jearimu. Gbogbo ilé Israẹli ṣọ̀fọ̀ wọ́n sì pohùnréré ẹkún sí Olúwa.
A od dnia przybycia arki do Kiriat-Jearim upłynęło dużo czasu, to jest dwadzieścia lat, a cały dom Izraela płakał za PANEM.
3 Samuẹli sọ fún gbogbo ilé Israẹli pé, “Tí ẹ bá ń padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín, ẹ yẹra kúrò lọ́dọ̀ ọlọ́run àjèjì àti Aṣtoreti kí ẹ sì fi ara yín jì fún Olúwa kí ẹ sì sin òun nìkan ṣoṣo, òun yóò sì gbà yín kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Filistini.”
I Samuel powiedział do całego domu Izraela: Jeśli z całego swego serca nawrócicie się do PANA, wyrzućcie spośród siebie obcych bogów oraz Asztarty i przygotujcie swoje serce PANU, i służcie tylko jemu. Wtedy wybawi was z ręki Filistynów.
4 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Israẹli yẹra fún Baali àti Aṣtoreti, wọ́n sì sin Olúwa nìkan ṣoṣo.
Synowie Izraela usunęli więc Baalów i Asztarty i służyli tylko PANU.
5 Nígbà náà ni, Samuẹli wí pé, “Ẹ kó gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jọ sí Mispa, èmi yóò bẹ̀bẹ̀ fún un yín lọ́dọ̀ Olúwa.”
Wtedy Samuel powiedział: Zgromadźcie całego Izraela w Mispie, a ja będę modlił się za wami do PANA.
6 Nígbà tí wọ́n sì ti péjọpọ̀ ní Mispa, wọ́n pọn omi, wọ́n sì dà á sílẹ̀ níwájú Olúwa. Ní ọjọ́ náà, wọ́n gbààwẹ̀, wọ́n sì jẹ́wọ́ pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí Olúwa.” Samuẹli sì jẹ́ olórí àwọn ọmọ Israẹli ní Mispa.
Zgromadzili się więc w Mispie i czerpali wodę, którą wylewali przed PANEM. Pościli tam tego dnia i mówili: Zgrzeszyliśmy przeciw PANU. A Samuel sądził synów Izraela w Mispie.
7 Nígbà tí àwọn Filistini gbọ́ pé àwọn Israẹli ti péjọ ní Mispa, àwọn aláṣẹ Filistini gòkè wá láti kọlù wọ́n. Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ èyí, ẹ̀rù bà wọ́n nítorí àwọn Filistini.
A [gdy] Filistyni usłyszeli, że synowie Izraela zgromadzili się w Mispie, wyruszyli książęta filistyńscy przeciw Izraelowi. Kiedy usłyszeli o tym synowie Izraela, zlękli się Filistynów.
8 Wọ́n sọ fún Samuẹli pé, “Má ṣe dákẹ́ kíké pe Olúwa Ọlọ́run wa fún wa, ké pè é kí ó lè gbà wá kúrò lọ́wọ́ àwọn Filistini.”
I synowie Izraela powiedzieli do Samuela: Nie przestawaj wołać za nami do PANA, naszego Boga, aby nas wybawił z ręki Filistynów.
9 Nígbà náà ni Samuẹli mú ọ̀dọ́-àgùntàn tí ó jẹ́ ọmọ ọmú, ó sì fi rú ẹbọ sísun sí Olúwa. Ó sí ké pe Olúwa nítorí ilé Israẹli, Olúwa sì dá a lóhùn.
Samuel wziął więc jedno jagnię ssące i złożył je PANU w ofierze całopalnej. I Samuel wołał do PANA za Izraelem, a PAN go wysłuchał.
10 Nígbà tí Samuẹli ń ṣe ìrúbọ ẹbọ sísun, àwọn Filistini súnmọ́ tòsí láti bá Israẹli ja ogun. Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà, Olúwa sán àrá ńlá lu àwọn Filistini, ó sì mú jìnnìjìnnì bá wọn, a sì lé wọn níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
A kiedy Samuel składał całopalenie, Filistyni nadciągnęli, aby walczyć z Izraelem. Lecz w tym dniu PAN zagrzmiał wielkim grzmotem nad Filistynami i rozproszył ich tak, że zostali pobici przed Izraelem.
11 Àwọn ọkùnrin Israẹli tú jáde láti Mispa. Wọ́n sì ń lépa àwọn Filistini, wọ́n sì pa wọ́n ní àpá rìn títí dé abẹ́ Beti-Kari.
A Izraelici wyruszyli z Mispy, gonili Filistynów i bili ich aż pod Bet-Kar.
12 Samuẹli mú òkúta kan ó sì fi lélẹ̀ láàrín Mispa àti Ṣeni, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Ebeneseri, wí pé, “Ibí ni Olúwa ràn wá lọ́wọ́ dé.”
Wtedy Samuel wziął kamień, ustawił go między Mispą a Szen i nazwał go Ebenezer, mówiąc: Aż dotąd pomagał nam PAN.
13 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣẹ́gun Filistini, wọn kò sì wá sí agbègbè àwọn ọmọ Israẹli mọ́. Ní gbogbo ìgbésí ayé Samuẹli, ọwọ́ Olúwa lòdì sí àwọn Filistini.
Tak zostali upokorzeni Filistyni i już nie przekraczali granic Izraela, a ręka PANA była przeciwko Filistynom po wszystkie dni Samuela.
14 Àwọn ìlú láti Ekroni dé Gati tí àwọn Filistini ti gbà lọ́wọ́ Israẹli ni ó ti gbà padà fún Israẹli, ó sì gba gbogbo ilẹ̀ agbègbè rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ìṣàkóso àwọn Filistini. Ìrẹ́pọ̀ sì wà láàrín Israẹli àti àwọn Amori.
Izraelowi zostały przywrócone miasta, które Filistyni zabrali Izraelowi, od Ekronu aż do Gat, a ich granice wyzwolił Izrael z ręki Filistynów. I pokój panował między Izraelem a Amorytami.
15 Samuẹli tẹ̀síwájú gẹ́gẹ́ bí adájọ́ lórí Israẹli. Ní ọjọ́ ayé e rẹ̀.
A Samuel sądził Izraela po wszystkie dni swego życia.
16 Láti ọdún dé ọdún, ó lọ yíká láti Beteli dé Gilgali dé Mispa, ó sì ń ṣe ìdájọ́ Israẹli ní gbogbo ibi wọ̀nyí.
Co roku chodził też i obchodził Betel, Gilgal i Mispę i sądził Izraela we wszystkich tych miejscach.
17 Ṣùgbọ́n ó máa ń padà sí ilé rẹ̀ ní Rama, níbí tí ilé rẹ̀ wà, ó sì túnṣe ìdájọ́ Israẹli níbẹ̀, ó sì kọ́ pẹpẹ kan síbẹ̀ fún Olúwa.
Potem wracał do Rama, ponieważ tam był jego dom. Tam sądził Izraela i tam też zbudował ołtarz PANU.

< 1 Samuel 7 >