< 1 Samuel 1 >

1 Ọkùnrin kan wà, láti Ramataimu-Sofimu, láti ìlú olókè Efraimu, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Elkana, ọmọ Jerohamu, ọmọ Elihu, ọmọ Tohu, ọmọ Sufu, ará Efrata.
Był pewien człowiek z Ramataim-Sofim, z góry Efraim, imieniem Elkana, syn Jerochama, syna Elihu, syna Tochu, syna Sufa Efratejczyka.
2 Ó sì ní ìyàwó méjì, orúkọ wọn ni Hana àti Penina: Penina ní ọmọ, ṣùgbọ́n Hana kò ní.
Miał on dwie żony, jednej było na imię Anna, a drugiej – Peninna. Peninna miała dzieci, Anna zaś była bezdzietna.
3 Ní ọdọọdún, ọkùnrin yìí máa ń gòkè láti ìlú rẹ̀ láti lọ sìn àti láti ṣe ìrúbọ sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun jùlọ ní Ṣilo, níbi tí àwọn ọmọkùnrin Eli méjèèjì, Hofini àti Finehasi ti jẹ́ àlùfáà Olúwa.
Człowiek ten co roku udawał się ze swego miasta, aby oddać cześć i złożyć ofiarę PANU zastępów w Szilo. Tam byli dwaj synowie Helego, Chofni i Pinchas, kapłani PANA.
4 Nígbàkígbà tí ó bá kan Elkana láti ṣe ìrúbọ, òun yóò bù lára ẹran fún aya rẹ̀ Penina àti fún gbogbo àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin.
A gdy nadszedł dzień, w którym Elkana składał ofiarę, dał swojej żonie Peninnie oraz wszystkim jej synom i córkom części [z ofiary];
5 Ṣùgbọ́n ó máa ń pín ìlọ́po fun Hana nítorí pé ó fẹ́ràn rẹ̀ àti pé Olúwa ti sé e nínú.
Ale Annie dał jedną wyborną część, gdyż miłował Annę, choć PAN zamknął jej łono.
6 Nítorí pé Olúwa ti sé e nínú, orogún rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ní fín níràn láti lè mú kí ó bínú.
Jej przeciwniczka zaś bardzo jej dokuczała, aby tylko ją rozgniewać z tego powodu, że PAN zamknął jej łono.
7 Eléyìí sì máa ń ṣẹlẹ̀ ní ọdọọdún. Nígbàkígbà tí Hana bá gòkè lọ sí ilé Olúwa, orogún rẹ̀ a máa fín níràn títí tí yóò fi máa sọkún tí kò sì ní lè jẹun.
I tak [Elkana] czynił każdego roku, a ilekroć [Anna] przychodziła do domu PANA, w ten sposób [Peninna] jej dokuczała. Ta zaś płakała i nie jadła.
8 Elkana ọkọ rẹ̀ yóò sọ fún un pé, “Hana èéṣe tí ìwọ fi ń sọkún? Èéṣe tí ìwọ kò fi jẹun? Èéṣe tí ìwọ fi ń ba ọkàn jẹ́? Èmi kò ha ju ọmọ mẹ́wàá lọ fún ọ bí?”
Wtedy Elkana, jej mąż, powiedział do niej: Anno, czemu płaczesz? Dlaczego nie jesz? Czemu tak smuci się twoje serce? Czy ja nie jestem dla ciebie lepszy niż dziesięciu synów?
9 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti jẹ, tí wọ́n tún mu tán ní Ṣilo, Hana dìde wá síwájú Olúwa. Nígbà náà, Eli àlùfáà wà lórí àga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ní ibi tí ó máa ń jókòó.
I gdy najedli się, i napili w Szilo, Anna wstała. A kapłan Heli siedział na krześle przy odrzwiach świątyni PANA.
10 Pẹ̀lú ẹ̀dùn ọkàn Hana sọkún gidigidi, ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
A ona, z goryczą w duszy, modliła się do PANA i strasznie płakała.
11 Ó sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, jùlọ tí ìwọ bá le bojú wo ìránṣẹ́bìnrin rẹ kí ìwọ sì rántí rẹ̀, tí ìwọ kò sì gbàgbé ìránṣẹ́ rẹ ṣùgbọ́n tí ìwọ yóò fún un ní ọmọkùnrin, nígbà náà èmi yóò sì fi fún Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀ a kì yóò sì fi abẹ kàn án ní orí.”
I złożyła ślub, mówiąc: PANIE zastępów, jeśli wejrzysz na utrapienie swojej służącej i wspomnisz na mnie, i nie zapomnisz swojej służącej, ale dasz swej służącej męskiego potomka, wtedy oddam go PANU na wszystkie dni jego życia, a brzytwa nie dotknie jego głowy.
12 Bí ó sì ṣe ń gbàdúrà sí Olúwa, Eli sì kíyèsi ẹnu rẹ̀.
A gdy długo modliła się przed PANEM, Heli przypatrywał się jej ustom.
13 Hana ń gbàdúrà láti inú ọkàn rẹ̀, ṣùgbọ́n ètè rẹ̀ ni ó ń mì, a kò gbọ́ ohùn rẹ̀. Eli rò wí pé ó ti mu ọtí yó.
Lecz Anna mówiła w swym sercu i tylko jej wargi się poruszały, ale jej głosu nie było słychać. Heli sądził więc, że jest pijana.
14 Eli sì wí fún un pé, “Yóò ti pẹ́ fún ọ tó tí ìwọ yóò máa yó? Mú ọtí wáìnì rẹ̀ kúrò.”
I Heli powiedział do niej: Jak długo będziesz pijana? Wytrzeźwiej od swego wina.
15 Hana dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, Olúwa mi, èmi ni obìnrin oníròbìnújẹ́. Èmi kò mu ọtí wáìnì tàbí ọtí líle; èmi ń tú ọkàn mi jáde sí Olúwa ni.
Anna zaś odpowiedziała: Nie, mój panie. Jestem kobietą utrapionego ducha. Nie piłam ani wina, ani mocnego napoju, lecz wylałam swoją duszę przed PANEM.
16 Má ṣe mú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí obìnrin búburú. Èmi ti ń gbàdúrà níhìn-ín nínú ìrora ọkàn àti ìbànújẹ́ mi.”
Nie uważaj swojej służącej za kobietę Beliala, gdyż z nadmiaru troski i smutku aż dotąd mówiłam.
17 Eli dáhùn pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, kí Ọlọ́run Israẹli fi ohun tí ìwọ ti béèrè ní ọwọ́ rẹ̀ fún ọ.”
Wtedy Heli odpowiedział: Idź w pokoju, a niech Bóg Izraela spełni twoją prośbę, którą zaniosłaś do niego.
18 Ó wí pé, “Kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ rí oore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà bá tirẹ̀ lọ, ó sì jẹun, kò sì fa ojú ro mọ́.
I powiedziała: Niech twoja służąca znajdzie łaskę w twoich oczach. I ta kobieta poszła swoją drogą, i jadła, a jej twarz już nie była [smutna].
19 Wọ́n sì dìde ni kùtùkùtù òwúrọ̀, wọn wólẹ̀ sìn níwájú Olúwa, wọn padà wa sí ilé wọn ni Rama: Elkana si mọ Hana aya rẹ̀: Olúwa sì rántí rẹ̀.
Nazajutrz wstali wcześnie rano, pokłonili się przed PANEM, wrócili się i przybyli do swego domu w Rama. I Elkana obcował z Anną, swoją żoną, a PAN wspomniał na nią.
20 Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ rẹ̀ pé, lẹ́yìn ìgbà tí Hana lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Samuẹli, pé, “Nítorí tí mo béèrè rẹ̀ lọ́wọ́ Olúwa.”
I gdy się wypełniły dni potem, jak Anna poczęła, urodziła syna i nadała mu imię Samuel, gdyż [mówiła]: Uprosiłam go u PANA.
21 Ọkùnrin náà Elkana, àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, gòkè lọ láti rú ẹbọ ọdún sí Olúwa, àti láti sán ẹ̀jẹ́ rẹ̀.
Potem ten człowiek, Elkana, wraz z całym swoim domem udał się, aby złożyć PANU doroczną ofiarę oraz [wypełnić] swój ślub.
22 Ṣùgbọ́n Hana kò gòkè lọ; nítorí tí ó sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ó di ìgbà tí mo bá gba ọmú lẹ́nu ọmọ náà, nígbà náà ni èmi yóò mú un lọ, kí òun lè fi ara hàn níwájú Olúwa, kí ó sí máa gbé ibẹ̀ títí láé.”
Lecz Anna nie poszła, bo mówiła swemu mężowi: [Nie pójdę], aż dziecko będzie odstawione od piersi, potem je zaprowadzę, żeby ukazało się przed PANEM i zostało tam na zawsze.
23 Elkana ọkọ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ. Dúró títí ìwọ yóò fi gba ọmú lẹ́nu rẹ̀; ṣùgbọ́n kí Olúwa sá à mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà sì jókòó, ó sì fi ọmú fún ọmọ rẹ̀ títí ó fi gbà á lẹ́nu rẹ̀.
Jej mąż Elkana odpowiedział: Czyń to, co ci [się wydaje] słuszne; pozostań, aż go odstawisz. Niech tylko PAN utwierdzi swoje słowo. Kobieta pozostała więc i karmiła piersią swego syna, aż do odstawienia go od piersi.
24 Nígbà tí ó sì gba ọmú lẹ́nu rẹ̀, ó sì mú un gòkè lọ pẹ̀lú ara rẹ̀. Pẹ̀lú ẹgbọrọ màlúù mẹ́ta, àti ìyẹ̀fun efa kan, àti ìgò ọtí wáìnì kan, ó sì mú un wá sí ilé Olúwa ní Ṣilo: ọmọ náà sì wà ní ọmọdé.
A gdy go odstawiła, wzięła go ze sobą wraz z trzema cielcami, z jedną efą mąki i bukłakiem wina i przyprowadziła go do domu PANA w Szilo; a dziecko [było] małe.
25 Wọ́n pa ẹgbọrọ màlúù, wọ́n sì mú ọmọ náà tọ Eli wá.
I zabili cielca, i przyprowadzili dziecko do Heliego.
26 Hana sì wí pé, “Olúwa mi, bí ọkàn rẹ ti wà láààyè, Olúwa mi, èmi ni obìnrin náà tí ó dúró lẹ́bàá ọ̀dọ̀ rẹ níhìn-ín tí ń tọrọ lọ́dọ̀ Olúwa.
A ona powiedziała: Proszę, mój panie! Jak żyje twoja dusza, mój panie, to ja [jestem] tą kobietą, która stała tu przy tobie, modląc się do PANA.
27 Ọmọ yìí ni mo ń tọrọ; Olúwa sì fi ìdáhùn ìbéèrè tí mo béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀ fún mi.
Prosiłam o to dziecko i PAN spełnił moją prośbę, którą zaniosłam do niego.
28 Nítorí náà pẹ̀lú, èmi fi í fún Olúwa; ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀: nítorí tí mo ti béèrè rẹ̀ fún Olúwa.” Wọn si wólẹ̀ sin Olúwa níbẹ̀.
Dlatego też oddaję je PANU. Na wszystkie dni jego życia zostaje oddane PANU. I oddał tam pokłon PANU.

< 1 Samuel 1 >