< 1 Kings 22 >

1 Fún ọdún mẹ́ta kò sì sí ogun láàrín Aramu àti Israẹli.
A przez trzy lata nie było wojny między Syrią a Izraelem.
2 Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, Jehoṣafati ọba Juda sọ̀kalẹ̀ lọ láti rí ọba Israẹli.
I w trzecim roku Jehoszafat, król Judy, przyjechał do króla Izraela.
3 Ọba Israẹli sì ti wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ti wa ni Ramoti Gileadi, àwa sì dákẹ́ síbẹ̀, a kò sì gbà á padà lọ́wọ́ ọba Aramu?”
Wtedy król Izraela powiedział do swoich sług: Czy wiecie, że Ramot-Gilead należy do nas? A my zwlekamy z odebraniem go z ręki króla Syrii.
4 Ó sì béèrè lọ́wọ́ Jehoṣafati pé, “Ṣé ìwọ yóò bá mi lọ láti lọ bá Ramoti Gileadi jà?” Jehoṣafati sì dá ọba Israẹli lóhùn pé, “Èmi bí ìwọ, ènìyàn mi bí ènìyàn rẹ, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.”
Zapytał więc Jehoszafata: Czy wyruszysz ze mną na wojnę do Ramot-Gilead? Jehoszafat odpowiedział królowi Izraela: Ja tak, jak i ty, mój lud tak, jak i twój lud, moje konie, jak i twoje konie.
5 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati sì tún wí fún ọba Israẹli pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”
Jehoszafat powiedział jeszcze królowi Izraela: Zapytaj dziś, proszę, o słowo PANA.
6 Nígbà náà ni ọba Israẹli kó àwọn wòlíì jọ, bí irinwó ọkùnrin. Ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé kí n lọ sí Ramoti Gileadi lọ jagun, tàbí kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ̀?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Lọ, nítorí tí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
Król Izraela zebrał więc około czterystu proroków i zapytał ich: Czy mam wyruszyć na wojnę do Ramot-Gilead, czy mam [tego] zaniechać? Odpowiedzieli mu: Wyrusz, bo PAN wyda [je] w ręce króla.
7 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati béèrè pé, “Ǹjẹ́ wòlíì Olúwa kan kò sí níhìn-ín, tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”
Ale Jehoszafat zapytał: Czy nie ma tu jeszcze jakiegoś proroka PANA, abyśmy mogli go zapytać?
8 Ọba Israẹli dá Jehoṣafati lóhùn pé, “Ọkùnrin kan ṣì wà, lọ́dọ̀ ẹni tí àwa lè béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n mo kórìíra rẹ̀ nítorí kì í sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kan nípa mi, bí kò ṣe ibi. Mikaiah ọmọ Imla ni.” Jehoṣafati sì wí pé, “Kí ọba má ṣe sọ bẹ́ẹ̀.”
Król Izraela odpowiedział Jehoszafatowi: Jest jeszcze jeden człowiek, przez którego moglibyśmy radzić się PANA, ale ja go nienawidzę, bo nie prorokuje mi nic dobrego, tylko to, co złe. Jest to Micheasz, syn Jimli. Jehoszafat powiedział: Niech król tak nie mówi.
9 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli sì pe ìránṣẹ́ kan, ó sì wí pé, “Lọ yára mú Mikaiah, ọmọ Imla wá.”
Wtedy król Izraela zawołał pewnego dworzanina i polecił mu: Przyprowadź tu szybko Micheasza, syna Jimli.
10 Ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda jókòó lórí ìtẹ́ wọn, wọ́n wọ aṣọ ìgúnwà wọn ní ìta ẹnu ibodè Samaria, gbogbo àwọn wòlíì náà sì ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn.
Tymczasem król Izraela i Jehoszafat, król Judy, siedzieli na swoich tronach ubrani w królewskie szaty na placu przed wejściem do bramy Samarii, a przed nimi prorokowali wszyscy prorocy.
11 Sedekiah ọmọ Kenaana sì ṣe ìwo irin fún ara rẹ̀, ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Wọ̀nyí ni ìwọ yóò fi kan àwọn ará Aramu títí ìwọ yóò fi run wọ́n.’”
A Sedekiasz, syn Kenaany, sporządził sobie żelazne rogi i powiedział: Tak mówi PAN: Nimi będziesz bódł Syryjczyków, aż ich wytępisz.
12 Gbogbo àwọn wòlíì tókù sì ń sọtẹ́lẹ̀ ohun kan náà wí pé, “Kọlu Ramoti Gileadi, kí o sì ṣẹ́gun.” Wọ́n sì wí pé, “Nítorí tí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
Tak samo prorokowali wszyscy prorocy, mówiąc: Wyrusz do Ramot-Gilead, a poszczęści ci się. PAN bowiem wyda je w ręce króla.
13 Ìránṣẹ́ tí ó lọ pe Mikaiah wí fún un pé, “Wò ó, ẹnu kan náà ni ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì fi jẹ́ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ bá ti àwọn tókù mu, kí o sì sọ rere.”
Wtedy posłaniec, który poszedł, aby przywołać Micheasza, powiedział do niego: Oto teraz słowa proroków jednomyślnie przekazują królowi to, co dobre. Niech twoje słowo, proszę, będzie jak słowo jednego z nich i mów to, co dobre.
14 Ṣùgbọ́n Mikaiah wí pé, “Bí Olúwa ti wà, ohun tí Olúwa bá sọ fún mi ni èmi yóò sọ fún un.”
Micheasz odpowiedział: Jak żyje PAN, będę mówił to, co PAN mi powie.
15 Nígbà tí ó sì dé, ọba sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Mikaiah, ṣé kí a lọ bá Ramoti Gileadi jagun, tàbí kí a jọ̀wọ́ rẹ̀?” Ó sì dáhùn wí pé, “Lọ, kí o sì ṣẹ́gun, nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
A gdy przyszedł do króla, król powiedział do niego: Micheaszu, czy mamy wyruszyć na wojnę do Ramot-Gilead, czy mamy [tego] zaniechać? Odpowiedział: Wyrusz, a poszczęści ci się. PAN bowiem wyda je w ręce króla.
16 Ọba sì wí fún un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi yóò fi ọ bú pé kí o má ṣe sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”
I król powiedział do niego: Ileż razy mam cię zaprzysięgać, abyś mi nie mówił nic innego [jak tylko] prawdę w imieniu PANA?
17 Mikaiah sì dáhùn pé, “Mo rí gbogbo Israẹli túká kiri lórí àwọn òkè bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn wọ̀nyí kò ní olúwa. Jẹ́ kí olúkúlùkù padà sí ilé rẹ̀ ní àlàáfíà.’”
Powiedział więc: Widziałem całego Izraela rozproszonego po górach jak owce niemające pasterza. A PAN powiedział: Oni nie mają pana. Niech każdy wraca do swego domu w pokoju.
18 Ọba Israẹli sì wí fún Jehoṣafati pé, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún ọ pé kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ ìre kan sí mi rí bí kò ṣe ibi?”
Wtedy król Izraela powiedział do Jehoszafata: Czy nie mówiłem ci, że nie będzie mi prorokować nic dobrego, tylko to, co złe?
19 Mikaiah sì tún wí pé, “Nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Mo rí Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ogun ọ̀run dúró ní apá ọ̀tún àti ní apá òsì rẹ̀.
[Tamten] powiedział: Słuchaj więc słowa PANA: Widziałem PANA siedzącego na swoim tronie, a wszystkie zastępy niebieskie stojące po jego prawicy i lewicy.
20 Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Ahabu láti kọlu Ramoti Gileadi? Kí ó sì tọ ikú rẹ̀ lọ níbẹ̀?’ “Ẹnìkan wí báyìí, ẹlòmíràn sì sọ òmíràn.
I PAN zapytał: Kto zwiedzie Achaba, aby wyruszył do Ramot-Gilead i poległ tam? I jeden mówił tak, a drugi inaczej.
21 Ẹ̀mí kan sì jáde wá, ó sì dúró níwájú Olúwa, ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’
Wtedy wystąpił duch i stanął przed PANEM, mówiąc: Ja go zwiodę. PAN go zapytał: Jak?
22 “Olúwa sì béèrè pé, ‘Báwo?’ “Ó sì wí pé, ‘Èmi yóò jáde lọ, èmi yóò sì di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì rẹ̀.’ “Olúwa sì wí pé, ‘Ìwọ yóò tàn án, ìwọ yóò sì borí, jáde lọ, kí o sì ṣe bẹ́ẹ̀.’
Odpowiedział: Wyjdę i będę duchem kłamliwym w ustach wszystkich jego proroków. [PAN] mu powiedział: Zwiedziesz [go], na pewno ci się uda. Idź i tak uczyń.
23 “Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu gbogbo àwọn wòlíì rẹ wọ̀nyí. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”
Teraz więc PAN włożył ducha kłamliwego w usta tych wszystkich twoich proroków, gdyż PAN zapowiedział ci nieszczęście.
24 Nígbà náà ni Sedekiah ọmọ Kenaana sì dìde, ó sì gbá Mikaiah lójú, ó sì wí pé, “Ọ̀nà wo ni ẹ̀mí Olúwa gbà lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?”
Wtedy Sedekiasz, syn Kenaany, podszedł do Micheasza i uderzył go w policzek, mówiąc: Którędy odszedł ode mnie Duch PANA, aby mówić z tobą?
25 Mikaiah sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò ṣe ìwádìí ní ọjọ́ tí ìwọ yóò sá pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.”
Micheasz odpowiedział: Ty sam to zobaczysz tego dnia, kiedy wejdziesz do najskrytszej komnaty, aby się ukryć.
26 Ọba Israẹli sì pàṣẹ pé, “Ẹ mú Mikaiah, kí ẹ sì mú un padà sọ́dọ̀ Amoni, olórí ìlú, àti sọ́dọ̀ Joaṣi ọmọ ọba
Król Izraela powiedział: Weź Micheasza i zaprowadź go do Amona, namiestnika miasta, i do Joasza, syna króla.
27 kí ẹ sì wí pé, ‘Báyìí ni ọba wí: Ẹ fi eléyìí sínú túbú, kí ẹ sì fi oúnjẹ ìpọ́njú àti omi ìpọ́njú bọ́ ọ, títí èmi yóò fi padà bọ̀ ní àlàáfíà.’”
I powiesz: Tak mówi król: Wtrąćcie tego [człowieka] do więzienia i żywcie go chlebem utrapienia i wodą ucisku, aż wrócę w pokoju.
28 Mikaiah sì wí pé, “Bí ìwọ bá padà bọ̀ ní àlàáfíà, Olúwa kò ti ipa mi sọ̀rọ̀.” Ó sì tún wí pé, “Ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ mi, ẹ̀yin ènìyàn gbogbo!”
Ale Micheasz odpowiedział: Jeśli rzeczywiście wrócisz w pokoju, to PAN nie mówił przeze mnie. I dodał: Słuchajcie wszyscy ludzie.
29 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda gòkè lọ sí Ramoti Gileadi.
Tak więc król Izraela i Jehoszafat, król Judy, wyruszyli do Ramot-Gilead.
30 Ọba Israẹli sì wí fún Jehoṣafati pé, “Èmi yóò pa aṣọ dà, èmi yóò sì lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wọ aṣọ ìgúnwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pa aṣọ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.
I król Izraela powiedział do Jehoszafata: Przebiorę się i pójdę na bitwę, ty zaś ubierz się w swoje szaty. Następnie król Izraela przebrał się i poszedł na bitwę.
31 Ọba Aramu ti pàṣẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rẹ̀ méjìlélọ́gbọ̀n wí pé, “Ẹ má ṣe bá ẹnìkankan jà, ẹni kékeré tàbí ẹni ńlá, bí kò ṣe ọba Israẹli nìkan.”
A król Syrii rozkazał swoim trzydziestu dwom dowódcom rydwanów: Nie walczcie ani z małym, ani z wielkim, tylko z samym królem Izraela.
32 Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ sì rí Jehoṣafati, wọ́n sì wí pé, “Dájúdájú ọba Israẹli ni èyí.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yípadà láti bá a jà, ṣùgbọ́n nígbà tí Jehoṣafati sì kígbe sókè,
A gdy dowódcy rydwanów zobaczyli Jehoszafata, powiedzieli: Na pewno on jest królem Izraela. I zwrócili się przeciwko niemu, aby z nim walczyć, ale Jehoszafat wydał okrzyk.
33 àwọn olórí kẹ̀kẹ́ sì rí i pé kì í ṣe ọba Israẹli, wọ́n sì padà kúrò lẹ́yìn rẹ̀.
Kiedy dowódcy rydwanów zobaczyli, że on nie jest królem Izraela, odstąpili od niego.
34 Ṣùgbọ́n ẹnìkan sì fa ọrun rẹ̀ láìròtẹ́lẹ̀, ó sì ta ọba Israẹli láàrín ìpàdé ẹ̀wù irin. Ọba Israẹli sì wí fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ dà, kí o sì mú mi jáde kúrò nínú ogun. Èmi ti gbọgbẹ́.”
A pewien mężczyzna na ślepo naciągnął łuk i ugodził króla Izraela między spojenia pancerza. A ten powiedział swojemu woźnicy: Zawróć i wywieź mnie z pola bitwy, bo jestem ranny.
35 Ogun náà sì le ní ọjọ́ náà, a sì dá ọba dúró nínú kẹ̀kẹ́ kọjú sí àwọn ará Aramu. Ẹ̀jẹ̀ sì sàn jáde láti inú ọgbẹ́ rẹ̀ sí àárín kẹ̀kẹ́ náà, ó sì kú ní àṣálẹ́.
I bitwa wzmogła się tego dnia. Król stał w rydwanie naprzeciw Syryjczyków i wieczorem umarł, a krew spływała z [jego] rany na dno rydwanu.
36 A sì kéde la ibùdó já ní àkókò ìwọ̀-oòrùn wí pé, “Olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀ àti olúkúlùkù sí ilẹ̀ rẹ̀!”
O zachodzie słońca w obozie wydano rozkaz: Każdy do swego miasta i każdy do swojej ziemi.
37 Bẹ́ẹ̀ ni ọba kú, a sì gbé e wá sí Samaria, wọ́n sì sin ín ní Samaria.
Tak więc król umarł i przywieziono go do Samarii, i pogrzebano go w Samarii.
38 Wọ́n sì wẹ kẹ̀kẹ́ náà ní adágún Samaria, àwọn ajá sì lá ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, àwọn àgbèrè sì wẹ ara wọn nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti sọ.
A gdy myto rydwan w sadzawce Samarii, psy lizały jego krew, myto także jego zbroję, według słowa PANA, które zapowiedział.
39 Ní ti ìyókù ìṣe Ahabu, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, àti ilé eyín erin tí ó kọ́, àti gbogbo ìlú tí ó tẹ̀dó, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
A pozostałe sprawy Achaba i wszystko, co uczynił, oraz dom z kości słoniowej, który wzniósł, a także wszystkie miasta, które zbudował – czy nie są opisane w kronikach królów Izraela?
40 Ahabu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Ahasiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
I Achab zasnął ze swymi ojcami, a królował jego syn Achazjasz w jego miejsce.
41 Jehoṣafati ọmọ Asa, sì bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba lórí Juda ní ọdún kẹrin Ahabu ọba Israẹli.
A Jehoszafat, syn Asy, zaczął królować nad Judą w czwartym roku Achaba, króla Izraela.
42 Jehoṣafati sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ń jẹ ọba ní ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Asuba ọmọbìnrin Silihi.
Jehoszafat miał trzydzieści pięć lat, gdy zaczął królować, a dwadzieścia pięć lat królował w Jerozolimie. Jego matka [miała] na imię Azuba [i była] córką Szilchiego.
43 Ó sì rìn nínú gbogbo ọ̀nà Asa baba rẹ̀, kò sì yípadà kúrò nínú rẹ̀; ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa. Kìkì àwọn ibi gíga ni a kò mú kúrò, àwọn ènìyàn sì ń rú ẹbọ, wọ́n sì ń sun tùràrí níbẹ̀.
I szedł wszystkimi drogami Asy, swego ojca, i nie zboczył z nich, czyniąc to, co było dobre w oczach PANA. Jednak wyżyn nie usunięto. Lud bowiem jeszcze składał ofiary i palił kadzidło na wyżynach.
44 Jehoṣafati sì wà ní àlàáfíà pẹ̀lú ọba Israẹli.
Jehoszafat także zawarł pokój z królem Izraela.
45 Ní ti ìyókù ìṣe Jehoṣafati àti ìṣe agbára rẹ̀ tí ó ṣe, àti bí ó ti jagun sí, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda?
A pozostałe sprawy Jehoszafata i jego potęga, którą pokazywał, i to, jak walczył – czyż nie są zapisane w kronikach królów Judy?
46 Ó pa ìyókù àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà ní ọjọ́ Asa baba rẹ̀ run kúrò ní ilẹ̀ náà.
Usunął też z ziemi resztę sodomitów, którzy pozostali za dni Asy, jego ojca.
47 Nígbà náà kò sí ọba ní Edomu; adelé kan ni ọba.
W tym czasie nie [było] króla w Edomie. Królem był namiestnik.
48 Jehoṣafati kan ọkọ̀ Tarṣiṣi láti lọ sí Ofiri fún wúrà, ṣùgbọ́n wọn kò lọ, nítorí àwọn ọkọ̀ náà fọ́ ní Esioni-Geberi.
Jehoszafat zbudował okręty Tarszisz, aby płynęły do Ofiru po złoto. Lecz nie dopłynęły, bo okręty rozbiły się w Esjon-Geber.
49 Ní ìgbà náà Ahasiah ọmọ Ahabu wí fún Jehoṣafati pé, “Jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ mi bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ nínú ọkọ̀,” ṣùgbọ́n Jehoṣafati kọ̀.
Wtedy Achazjasz, syn Achaba, powiedział do Jehoszafata: Niech moi słudzy płyną na okrętach z twoimi sługami. Ale Jehoszafat nie chciał.
50 Nígbà náà ni Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi, baba rẹ. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
I Jehoszafat zasnął ze swymi ojcami, i został pogrzebany wraz z nimi w mieście Dawida, swego ojca. W jego miejsce królował jego syn Joram.
51 Ahasiah ọmọ Ahabu bẹ̀rẹ̀ sí jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria ní ọdún kẹtàdínlógún Jehoṣafati ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ọdún méjì lórí Israẹli.
Achazjasz, syn Achaba, zaczął królować nad Izraelem w Samarii w siedemnastym roku Jehoszafata, króla Judy, i królował nad Izraelem dwa lata.
52 Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, nítorí tí ó rìn ní ọ̀nà baba rẹ̀, àti ní ọ̀nà ìyá rẹ̀, àti ní ọ̀nà Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó mú Israẹli dẹ́ṣẹ̀.
Czynił to, co złe w oczach PANA, idąc drogą swego ojca, drogą swej matki i drogą Jeroboama, syna Nebata, który przywiódł Izraela do grzechu.
53 Ó sì sin Baali, ó sì ń bọ Baali, ó sì mú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli bínú, gẹ́gẹ́ bí i baba rẹ̀ ti ṣe.
Służył bowiem Baalowi, oddawał mu pokłon i pobudzał do gniewu PANA, Boga Izraela, według wszystkiego, co czynił jego ojciec.

< 1 Kings 22 >