< 1 Kings 2 >

1 Nígbà tí ọjọ́ ikú Dafidi súnmọ́ etílé, ó pàṣẹ fún Solomoni ọmọ rẹ̀.
A gdy zbliżał się czas śmierci Dawida, rozkazał Salomonowi, swemu synowi:
2 Ó sì wí pé, “Èmi ti fẹ́ lọ sí ọ̀nà gbogbo ayé, nítorí náà jẹ́ alágbára kí o sì fi ara rẹ hàn bí ọkùnrin,
Idę drogą całej ziemi. [Ty] umacniaj się i okaż się mężczyzną;
3 kí o sì wòye ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ béèrè, rìn ní ọ̀nà rẹ̀, kí o sì pa àṣẹ àti òfin rẹ̀ mọ́, àti ìdájọ́ rẹ, àti ẹ̀rí rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé òfin Mose, nítorí kí ìwọ kí ó le è máa ṣe rere ní ohun gbogbo tí ìwọ ṣe, àti ní ibikíbi tí ìwọ bá lọ,
Zachowuj nakaz PANA, swego Boga, abyś chodził jego drogami i przestrzegał jego ustaw, jego przykazań, jego praw i jego świadectw, jak jest napisane w Prawie Mojżesza, aby ci się wiodło we wszystkim, co będziesz czynił, i wszędzie, dokądkolwiek się zwrócisz;
4 kí Olúwa kí ó lè pa ìlérí rẹ̀ tí ó sọ nípa tèmi mọ́ pé, ‘Bí àwọn ọmọ rẹ bá kíyèsi ọ̀nà wọn, tí wọ́n bá sì fi gbogbo àyà wọn àti ọkàn wọn rìn níwájú mi ní òtítọ́, o kì yóò sì kùnà láti ní ọkùnrin kan lórí ìtẹ́ Israẹli.’
Aby PAN spełnił swoje słowo, które zapowiedział o mnie: Jeśli twoi synowie będą strzec swej drogi, postępując przede mną w prawdzie, z całego swego serca i z całej swej duszy, to wtedy nie zabraknie [ci] mężczyzny na tronie Izraela.
5 “Ìwọ pẹ̀lú sì mọ ohun tí Joabu ọmọ Seruiah ṣe sí mi àti ohun tí ó ṣe sí balógun méjì nínú àwọn ológun Israẹli, sí Abneri ọmọ Neri àti sí Amasa ọmọ Jeteri. Ó sì pa wọ́n, ó sì ta ẹ̀jẹ̀ wọn sílẹ̀ ní ìgbà àlàáfíà bí í ti ojú ogun ó sì fi ẹ̀jẹ̀ náà sí ara àmùrè rẹ̀ tí ń bẹ ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, àti sí ara sálúbàtà rẹ̀ tí ń bẹ ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
Ty wiesz także, co uczynił mi Joab, syn Serui, co uczynił dwom dowódcom wojska Izraela, Abnerowi, synowi Nera, i Amasie, synowi Jetery, których zabił i przelał krew w czasie pokoju jak na wojnie, i zbroczył tą krwią wojny swój pas na biodrach i swoje obuwie na nogach.
6 Ṣe sí í gẹ́gẹ́ bí ọgbọ́n rẹ̀, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí ewú orí rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí isà òkú ní àlàáfíà. (Sheol h7585)
Uczynisz więc według swojej mądrości, jednak nie dopuść, aby w sędziwym wieku zstąpił w pokoju do grobu. (Sheol h7585)
7 “Ṣùgbọ́n fi inú rere hàn sí àwọn ọmọ Barsillai, ti Gileadi, jẹ́ kí wọn wà lára àwọn tí ó ń jẹun lórí tábìlì rẹ̀. Wọ́n dúró tì mí nígbà tí mo sá kúrò níwájú Absalomu arákùnrin rẹ.
Lecz synom Barzillaja Gileadczyka okaż łaskę i niech należą do tych, którzy jadają przy twoim stole. Oni bowiem przyszli do mnie, kiedy uciekałem przed twoim bratem Absalomem.
8 “Àti kí o rántí, Ṣimei ọmọ Gera ẹ̀yà Benjamini tí Bahurimu wà pẹ̀lú rẹ̀, tí ó bú mi ní èébú tí ó korò ní ọjọ́ tí mo lọ sí Mahanaimu. Nígbà tí ó sọ̀kalẹ̀ wá pàdé mi ní Jordani, mo fi Olúwa búra fún un pé, ‘Èmi kì yóò fi idà pa ọ́.’
Oto jest też u ciebie Szimei, syn Gery, Beniaminita z Bachurim, który złorzeczył mi ostro w tym dniu, kiedy szedłem do Machanaim. Lecz wyszedł mi na spotkanie nad Jordanem i przysiągłem mu na PANA: Nie zabiję cię mieczem.
9 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, má ṣe kíyèsi í gẹ́gẹ́ bí aláìlẹ́ṣẹ̀, ọkùnrin ọlọ́gbọ́n ni ìwọ ṣe; ìwọ yóò mọ ohun tí ìwọ yóò ṣe sí i. Mú ewú orí rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sínú isà òkú pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀.” (Sheol h7585)
Teraz jednak nie daruj mu [tego]. Jesteś bowiem człowiekiem mądrym i będziesz wiedział, co masz mu uczynić, by posłać go w sędziwym wieku [zbroczonego] krwią do grobu. (Sheol h7585)
10 Nígbà náà ni Dafidi sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi.
Potem Dawid zasnął ze swymi ojcami i został pogrzebany w mieście Dawida.
11 Dafidi ti jẹ ọba lórí Israẹli ní ogójì ọdún, ọdún méje ni Hebroni àti ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu.
A czas panowania Dawida nad Izraelem [wynosił] czterdzieści lat. W Hebronie królował siedem lat, a w Jerozolimie królował trzydzieści trzy lata.
12 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi baba rẹ̀, ìjọba rẹ̀ sì fi ìdí múlẹ̀ gidigidi.
Zasiadł więc Salomon na tronie Dawida, swego ojca, i jego królestwo zostało mocno utwierdzone.
13 Wàyí, Adonijah ọmọ Haggiti tọ Batṣeba, ìyá Solomoni wá. Batṣeba sì bi í pé, “Àlàáfíà ni o bá wa bí?” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àlàáfíà ni.”
Potem przyszedł Adoniasz, syn Chaggity, do Batszeby, matki Salomona. [Ta] go zapytała: Czy twoje przyjście oznacza pokój? A [on] odpowiedział: Pokój.
14 Nígbà náà ni ó sì fi kún un pé, “Mo ní ohun kan láti sọ fún ọ.” Batṣeba sì wí pé, “Máa wí.”
Następnie dodał: Mam do ciebie sprawę. Odpowiedziała: Mów.
15 Ó wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí o ti mọ̀, ti tèmi ni ìjọba náà. Gbogbo Israẹli ti wò mí bí ọba wọn. Ṣùgbọ́n nǹkan yípadà, ìjọba náà sì ti lọ sí ọ̀dọ̀ arákùnrin mi, nítorí ó ti wá sọ́dọ̀ rẹ̀ láti ọwọ́ Olúwa wá.
Wtedy powiedział: Ty wiesz, że do mnie należało królestwo i że cały Izrael patrzył na mnie i chciał, abym królował. Królestwo jednak uległo zmianie i dostało się memu bratu, bo przypadło mu ono od PANA.
16 Nísinsin yìí mo ní ìbéèrè kan láti bi ọ́, má ṣe kọ̀ fún mi.” Ó wí pé, “O lè wí.”
Teraz mam więc do ciebie jedną prośbę, nie odmawiaj mi tego. Odpowiedziała: Mów.
17 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì tẹ̀síwájú pé, “Mo bẹ̀ ọ́, jọ̀wọ́ sọ fún Solomoni ọba (òun kì yóò kọ̀ fún ọ́) kí ó fún mi ní Abiṣagi ará Ṣunemu ní aya.”
Wtedy powiedział: Powiedz, proszę, do Salomona, króla – bo wiem, że tobie nie odmówi – aby dał mi Abiszag Szunamitkę za żonę.
18 Batṣeba sì dáhùn pé, “Ó dára èmi yóò bá ọba sọ̀rọ̀ nítorí rẹ̀.”
Batszeba odpowiedziała: Dobrze, przemówię za tobą do króla.
19 Nígbà tí Batṣeba sì tọ Solomoni ọba lọ láti bá a sọ̀rọ̀ nítorí Adonijah, ọba sì dìde láti pàdé rẹ̀, ó sì tẹríba fún un, ó sì jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀. Ó sì tẹ́ ìtẹ́ kan fún ìyá ọba, ó sì jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún rẹ̀.
Poszła więc Batszeba do króla Salomona, aby przemówić do niego za Adoniaszem. I król wstał na jej spotkanie, pokłonił się jej i usiadł na swym tronie. Kazał też postawić krzesło swojej matce, a ona usiadła po jego prawicy.
20 Ó sì wí pé, “Mo ní ìbéèrè kékeré kan láti béèrè lọ́wọ́ rẹ, má ṣe kọ̀ fún mi.” Ọba sì dáhùn wí pé, “Béèrè, ìyá mi; èmi kì yóò kọ̀ ọ́.”
I powiedziała: Mam do ciebie jedną małą prośbę, nie odmawiaj mi. Król odpowiedział jej: Proś, moja matko, bo ci nie odmówię.
21 Nígbà náà ni ó wí pé, “Jẹ́ kí a fi Abiṣagi ará Ṣunemu fún Adonijah arákùnrin rẹ ní aya.”
Wtedy powiedziała: Niech Abiszag Szunamitka będzie dana za żonę twemu bratu, Adoniaszowi.
22 Solomoni ọba sì dá ìyá rẹ̀ lóhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ fi béèrè Abiṣagi ará Ṣunemu fún Adonijah! Ìwọ ìbá sì béèrè ìjọba fún un pẹ̀lú nítorí ẹ̀gbọ́n mi ní í ṣe, fún òun pàápàá àti fún Abiatari àlùfáà àti fun Joabu ọmọ Seruiah!”
Król Salomon odpowiedział swojej matce: A dlaczego prosisz o Abiszag Szunamitkę dla Adoniasza? Poproś także dla niego o królestwo. Jest bowiem moim starszym bratem i ma za sobą kapłana Abiatara i Joaba, syna Serui.
23 Nígbà náà ni Solomoni ọba fi Olúwa búra pé, “Kí Ọlọ́run ki ó jẹ mí ní yà, àti jù bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú, bí Adonijah kò bá ní fi ẹ̀mí rẹ̀ san ìbéèrè yìí!
I król Salomon przysiągł na PANA: Niech Bóg mi to uczyni i tamto dorzuci, jeśli Adoniasz nie wypowiedział tych słów przeciwko własnemu życiu.
24 Àti nísinsin yìí, bí ó ti dájú pé Olúwa wà láààyè, ẹni tí ó ti mú mi jókòó lórí ìtẹ́ baba mi Dafidi, àti tí ó sì ti kọ́ ilé fún mi bí ó ti ṣèlérí, lónìí ni a ó pa Adonijah!”
A teraz, jak żyje PAN, który mnie ustanowił i posadził na tronie Dawida, mego ojca, i który zbudował mi dom, jak obiecał, Adoniasz dziś zostanie zabity.
25 Solomoni ọba sì pàṣẹ fún Benaiah ọmọ Jehoiada, ó sì kọlu Adonijah, ó sì kú.
Wtedy król Salomon posłał Benajasza, syna Jehojady, i ten zadał mu cios, tak że umarł.
26 Ọba sì wí fún Abiatari àlùfáà pé, “Padà lọ sí pápá rẹ ni Anatoti, ó yẹ fún ọ láti kú, ṣùgbọ́n èmi kì yóò pa ọ́ nísinsin yìí, nítorí o ti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa Olódùmarè níwájú Dafidi baba mi, o sì ti ní ìpín nínú gbogbo ìyà tí baba mi jẹ.”
A do kapłana Abiatara król powiedział: Idź do Anatot, do swojej posiadłości, gdyż zasłużyłeś na śmierć. Dziś jednak nie zabiję cię, ponieważ nosiłeś arkę PANA przed Dawidem, moim ojcem, i ponieważ wycierpiałeś wszystko, co mój ojciec wycierpiał.
27 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni yọ Abiatari kúrò nínú iṣẹ́ àlùfáà Olúwa, kí ó lè mú ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti sọ nípa ilé Eli ní Ṣilo ṣẹ.
I Salomon usunął Abiatara, by nie był kapłanem PANA, aby spełniło się słowo PANA, które wypowiedział o domu Helego w Szilo.
28 Nígbà tí ìròyìn sì dé ọ̀dọ̀ Joabu, ẹni tí ó ti dìtẹ̀ pẹ̀lú Adonijah bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kò wà pẹ̀lú Absalomu, ó sì sálọ sínú àgọ́ Olúwa, ó sì di ìwo pẹpẹ mú.
Gdy wieść o tym doszła do Joaba – Joab bowiem dołączył do Adoniasza, chociaż do Absaloma nie dołączył – Joab uciekł do namiotu PANA i uchwycił się rogów ołtarza.
29 A sì sọ fún Solomoni ọba pé Joabu ti sálọ sínú àgọ́ Olúwa àti pé ó wà ní ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ. Nígbà náà ni Solomoni pàṣẹ fún Benaiah ọmọ Jehoiada pé, “Lọ, kí o sì kọlù ú.”
I doniesiono królowi Salomonowi o tym, że Joab uciekł do namiotu PANA i jest przy ołtarzu. Wtedy Salomon posłał Benajasza, syna Jehojady, mówiąc: Idź, zabij go.
30 Benaiah sì wọ inú àgọ́ Olúwa, ó sì wí fún Joabu pé, “Ọba sọ wí pé, ‘Jáde wá.’” Ṣùgbọ́n ó dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, èmi yóò kú níhìn-ín.” Benaiah sì mú èsì fún ọba, “Báyìí ni Joabu ṣe dá mi lóhùn.”
Benajasz przyszedł więc do namiotu PANA i powiedział do niego: Tak mówi król: Wyjdź. Ten odpowiedział: Nie wyjdę, ale tu umrę. Benajasz przekazał odpowiedź królowi: Tak mówił Joab i tak mi odpowiedział.
31 Ọba sì pàṣẹ fún Benaiah pé, “Ṣe bí ó ti wí. Kọlù ú, kí o sì sin ín, kí o sì mú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi àti kúrò lọ́dọ̀ ilé baba mi, tí Joabu ti ta sílẹ̀.
I król mu polecił: Uczyń, jak powiedział. Zabij go i pogrzeb go, a oczyścisz mnie i dom mego ojca z niewinnej krwi, którą przelał Joab.
32 Olúwa yóò sì san ẹ̀jẹ̀ tí ó ti ta sílẹ̀ padà fún un, nítorí tí ó kọlu ọkùnrin méjì, ó sì fi idà rẹ̀ pa wọ́n, Dafidi baba mi kò sì mọ̀. Àwọn méjèèjì ni Abneri ọmọ Neri olórí ogun Israẹli, àti Amasa ọmọ Jeteri olórí ogun Juda, wọ́n jẹ́ olódodo, wọ́n sì sàn ju òun fúnra rẹ̀ lọ.
A PAN sprowadzi jego krew na jego własną głowę, ponieważ zadał cios dwom mężczyznom sprawiedliwszym i lepszym niż on sam i zabił ich mieczem bez wiedzy mego ojca Dawida – Abnera, syna Nera, dowódcę wojska Izraela, i Amasę, syna Jetery, dowódcę wojska Judy.
33 Kí ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ wọn wá sórí Joabu àti sórí irú-ọmọ rẹ̀ títí láé. Ṣùgbọ́n sórí Dafidi àti irú-ọmọ rẹ̀, sí ilé rẹ̀ àti sí ìtẹ́ rẹ̀, ni kí àlàáfíà Olúwa wà títí láé.”
Ich krew spadnie na głowę Joaba i na głowę jego potomstwa na wieki. Dla Dawida zaś i jego potomstwa, jego domu i jego tronu niech będzie pokój od PANA na wieki.
34 Bẹ́ẹ̀ ni Benaiah ọmọ Jehoiada sì gòkè lọ, ó sì kọlu Joabu, ó sì pa á, a sì sin ín ní ilẹ̀ ibojì ara rẹ̀ ní aginjù.
Benajasz, syn Jehojady, poszedł więc, rzucił się na niego i zabił go. I został pogrzebany w swoim domu na pustyni.
35 Ọba sì fi Benaiah ọmọ Jehoiada jẹ olórí ogun ní ipò Joabu àti Sadoku àlùfáà ní ipò Abiatari.
Król na jego miejsce postawił na czele wojska Benajasza, syna Jehojady, a kapłana Sadoka król postawił na miejsce Abiatara.
36 Nígbà náà ni ọba ránṣẹ́ sí Ṣimei, ó sì wí fún un pé, “Kọ́ ilé fún ara rẹ ní Jerusalẹmu, kí o sì máa gbé ibẹ̀, ṣùgbọ́n kí o má sì ṣe lọ sí ibòmíràn.
Potem król posłał po Szimejego i przyzwał go, i powiedział mu: Zbuduj sobie dom w Jerozolimie i zamieszkaj tam, i nigdy stamtąd nie wychodź.
37 Ọjọ́ tí ìwọ bá jáde, tí o sì kọjá àfonífojì Kidironi, kí ìwọ kí ó mọ̀ dájúdájú pé ìwọ yóò kú; ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò sì wà lórí ara rẹ.”
Tego dnia bowiem, w którym wyjdziesz i przekroczysz potok Cedron, wiedz dobrze, że na pewno umrzesz. Twoja krew spadnie na twoją głowę.
38 Ṣimei sì dá ọba lóhùn pé, “Ohun tí ìwọ sọ dára. Ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe bí olúwa mi ọba ti wí.” Ṣimei sì gbé ní Jerusalẹmu fún ìgbà pípẹ́.
Wtedy Szimei powiedział do króla: Dobre jest to słowo. Jak mój pan, król, powiedział, tak twój sługa uczyni. I mieszkał Szimei w Jerozolimie przez wiele dni.
39 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ọdún mẹ́ta, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ Ṣimei méjì sì sálọ sọ́dọ̀ Akiṣi ọmọ Maaka, ọba Gati, a sì sọ fún Ṣimei pé, “Àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ méjì wà ní Gati.”
I zdarzyło się po trzech latach, że dwaj słudzy Szimejego uciekli do Akisza, syna Maaki, króla Gat. I dano znać Szimejemu: Oto twoi słudzy [są] w Gat.
40 Fún ìdí èyí, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ní gàárì, ó sì lọ sọ́dọ̀ Akiṣi ní Gati láti wá àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni Ṣimei sì lọ, ó sì mú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ padà bọ̀ láti Gati.
Szimei wstał więc, osiodłał swego osła i wyruszył do Gat, do Akisza, aby szukać swoich sług. Potem Szimei wrócił i przyprowadził swe sługi z Gat.
41 Nígbà tí a sì sọ fún Solomoni pé Ṣimei ti lọ láti Jerusalẹmu sí Gati, ó sì ti padà.
I doniesiono Salomonowi, że Szimei poszedł z Jerozolimy do Gat i powrócił.
42 Ọba pe Ṣimei lẹ́jọ́, ó wí fún un pé, “Ǹjẹ́ èmi kò ti mú ọ búra ní ti Olúwa, èmi sì ti kìlọ̀ fún ọ pé, ‘Ní ọjọ́ tí ìwọ bá kúrò láti lọ sí ibikíbi, kí o mọ̀ dájú pé ìwọ yóò kú.’ Nígbà náà ni ìwọ sì sọ fún mi pé, ‘Ohun tí ìwọ sọ dára. Èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn.’
Wtedy król posłał po Szimejego i wezwał go, i powiedział mu: Czy nie przysiągłem na PANA i nie oświadczyłem ci, mówiąc: Tego dnia, w którym wyjdziesz, wiedz dobrze, że na pewno umrzesz? I odpowiedziałeś mi: Dobre to słowo, [które] słyszałem.
43 Èéṣe, nígbà náà tí ìwọ kò pa ìbúra Olúwa mọ́, àti kí o sì ṣe ìgbọ́ràn sí àṣẹ tí mo pa fún ọ?”
Dlaczego więc nie przestrzegałeś przysięgi PANA i nakazu, który ci dałem?
44 Ọba sì tún wí fún Ṣimei pé, “Ìwọ mọ̀ ní ọkàn rẹ gbogbo búburú tí ìwọ ti ṣe sí Dafidi baba mi. Báyìí, Olúwa yóò san gbogbo ìṣe búburú rẹ padà fún ọ.
Następnie król powiedział do Szimejego: Znasz całe zło, którego jest świadome twoje serce, a które wyrządziłeś memu ojcu Dawidowi. PAN sprowadzi więc twoje zło na twoją głowę.
45 Ṣùgbọ́n a ó sì bùkún fún Solomoni ọba, ìtẹ́ Dafidi yóò sì wà láìfòyà níwájú Olúwa títí láéláé.”
A król Salomon będzie błogosławiony i tron Dawida zostanie utwierdzony przed PANEM na wieki.
46 Nígbà náà ni ọba pàṣẹ fún Benaiah ọmọ Jehoiada, ó sì jáde lọ, ó sì kọlu Ṣimei, ó sì pa á. Ìjọba náà sì wá fi ìdí múlẹ̀ ní ọwọ́ Solomoni.
Tak więc król wydał rozkaz Benajaszowi, synowi Jehojady; i ten wyszedł, zadał mu cios i zabił go. I tak królestwo zostało utwierdzone w ręce Salomona.

< 1 Kings 2 >