< 1 Kings 16 >

1 Ó sì ṣe, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jehu ọmọ Hanani wá sí Baaṣa pé,
Wtedy słowo PANA doszło do Jehu, syna Chananiego, przeciw Baszy:
2 “Èmi ti gbé ọ ga láti inú erùpẹ̀ wá, mo sì fi ọ́ ṣe olórí Israẹli ènìyàn mi, ṣùgbọ́n ìwọ sì rìn ní ọ̀nà Jeroboamu, ó sì mú kí Israẹli ènìyàn mi dẹ́ṣẹ̀, láti mú mi bínú nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Ponieważ wywyższyłem cię z prochu i ustanowiłem cię wodzem nad swoim ludem Izraelem, a ty poszedłeś drogą Jeroboama i skłoniłeś do grzechu mój lud, Izraela, aby mnie pobudzić do gniewu jego grzechami;
3 Nítorí náà, èmi yóò mú Baaṣa àti ilé rẹ̀ kúrò, èmi yóò sì ṣe ilé rẹ̀ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati.
Oto zgładzę potomstwo Baszy i potomstwo jego domu i postąpię z twoim domem jak z domem Jeroboama, syna Nebata.
4 Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Baaṣa tí ó bá kú ní ìlú, ẹyẹ ojú ọ̀run yóò sì jẹ àwọn tí ó kú ní oko.”
Tego, kto [z rodu] Baszy umrze w mieście, zjedzą psy, a tego, kto umrze na polu, zjedzą powietrzne ptaki.
5 Àti ìyókù ìṣe Baaṣa, ohun tí ó ṣe àti agbára rẹ̀, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
A pozostałe dzieje Baszy i to, co czynił, i jego potęga, czyż nie są zapisane w kronikach królów Izraela?
6 Baaṣa sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní Tirsa. Ela ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Potem Basza zasnął ze swoimi ojcami i został pogrzebany w Tirsie, a jego syn Ela królował w jego miejsce.
7 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì wá nípa ọwọ́ Jehu wòlíì ọmọ Hanani pẹ̀lú sí Baaṣa àti ilé rẹ̀, nítorí gbogbo búburú tí ó ti ṣe níwájú Olúwa, ní mímú un bínú nípa ohun tó ti ṣe àti wíwà bí ilé Jeroboamu, àti nítorí tí ó pa á run pẹ̀lú.
Ponownie przez proroka Jehu, syna Chananiego, doszło słowo PANA przeciw Baszy i przeciw jego domowi za całe zło, które czynił w oczach PANA, pobudzając go do gniewu czynami swoich rąk, stając się podobnym do domu Jeroboama, i za to, że go zabił.
8 Ní ọdún kẹrìndínlọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, Ela ọmọ Baaṣa bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba ní Israẹli, ó sì jẹ ọba ní Tirsa ní ọdún méjì.
W dwudziestym szóstym roku Asy, króla Judy, nad Izraelem w Tirsie zaczął królować Ela, syn Baszy, i [królował] dwa lata.
9 Simri, ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, olórí ìdajì kẹ̀kẹ́ rẹ̀, dìtẹ̀ sí i. Ela sì wà ní Tirsa nígbà náà, ó sì mu àmupara ní ilé Arsa, ìríjú ilé rẹ̀ ni Tirsa.
A jego sługa Zimri, dowódca połowy rydwanów, uknuł spisek przeciw niemu, gdy w Tirsie Ela oddawał się pijaństwu w domu Arsy, szafarza domu [królewskiego] w Tirsie.
10 Simri sì wọlé, ó sì kọlù ú, ó sì pa á ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n Asa, ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Zimri wszedł tam, uderzył go i zabił – w dwudziestym siódmym roku Asy, króla Judy, i królował w jego miejsce.
11 Bí ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba, bí ó sì ti jókòó lórí ìtẹ́, ó lu gbogbo ilé Baaṣa pa, kò ku ọkùnrin kan sílẹ̀, bóyá ìbátan tàbí ọ̀rẹ́.
A gdy tylko zaczął królować i zasiadł na swoim tronie, wymordował cały dom Baszy. Nie pozostawił z niego nikogo – ani z jego krewnych, ani przyjaciół – aż do najmniejszego szczenięcia.
12 Bẹ́ẹ̀ ni Simri pa gbogbo ilé Baaṣa run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ sí Baaṣa nípa ọwọ́ Jehu wòlíì:
W ten sposób Zimri wytracił cały dom Baszy zgodnie ze słowem PANA, które wypowiedział przeciw Baszy przez proroka Jehu;
13 nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí Baaṣa àti Ela ọmọ rẹ̀ ti ṣẹ̀ àti tí wọ́n ti mú Israẹli ṣẹ̀, tí wọ́n fi mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú, wọ́n mú u bínú nípa òrìṣà asán wọn.
Z powodu wszystkich grzechów Baszy i grzechów jego syna Eli, które popełnili i którymi doprowadzili Izraela do grzechu, pobudzając PANA, Boga Izraela, do gniewu swymi marnościami.
14 Ìyókù ìṣe Ela àti gbogbo ohun tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
A pozostałe dzieje Eli i wszystko, co czynił, czyż nie są zapisane w kronikach królów Izraela?
15 Ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, ni Simri jẹ ọba ọjọ́ méje ní Tirsa. Àwọn ọmọ-ogun sì dó ti Gibetoni, ìlú àwọn ará Filistini.
W dwudziestym siódmym roku Asy, króla Judy, Zimri królował siedem dni w Tirsie. Lud oblegał wtedy Gibbeton, który należy do Filistynów.
16 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli tí ó dó tì gbọ́ wí pé Simri ti dìtẹ̀ sí ọba, ó sì ti pa á, wọ́n kéde Omri, olórí ogun, bí ọba lórí Israẹli ní ọjọ́ náà ní ibùdó.
A gdy lud oblegający [miasto] usłyszał wieść: Zimri uknuł spisek i zabił króla, wtedy cały Izrael w tym samym dniu w obozie ustanowił królem Omriego, który był dowódcą wojska Izraela.
17 Nígbà náà ni Omri àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀ kúrò ní Gibetoni, wọ́n sì dó ti Tirsa.
Wtedy Omri wyruszył spod Gibbeton wraz z całym Izraelem i oblegli Tirsę.
18 Nígbà tí Simri sì ri pé a ti gba ìlú, ó sì wọ inú ààfin ilé ọba lọ, ó sì tẹ iná bọ ilé ọba lórí ara rẹ̀, ó sì kú,
A gdy Zimri zobaczył, że miasto zostało zdobyte, wszedł do pałacu domu królewskiego i podpalił nad sobą dom królewski, i umarł.
19 nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó ti ṣẹ̀, ní ṣíṣe búburú níwájú Olúwa àti ní rírìn ní ọ̀nà Jeroboamu àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó ti ṣe àti tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀.
[Stało się tak] z powodu jego grzechów, których się dopuścił, czyniąc to, co złe w oczach PANA, idąc drogą Jeroboama i w jego grzechu – którego się dopuszczał i do którego skłonił Izraela.
20 Ní ti ìyókù ìṣe Simri, àti ọ̀tẹ̀ rẹ̀ tí ó dì, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
A pozostałe dzieje Zimriego i spisek, który uknuł, czyż nie są zapisane w kronikach królów Izraela?
21 Nígbà náà ní àwọn ènìyàn Israẹli dá sí méjì; apá kan wọn ń tọ Tibni ọmọ Ginati lẹ́yìn, láti fi í jẹ ọba, apá kan tókù sì ń tọ Omri lẹ́yìn.
Wtedy lud Izraela podzielił się na dwie części: połowa ludu szła za Tibnim, synem Ginata, aby go obwołać królem, a połowa szła za Omrim.
22 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn tí ń tọ Omri lẹ́yìn borí àwọn tí ń tọ Tibni ọmọ Ginati lẹ́yìn. Bẹ́ẹ̀ ni Tibni kú, Omri sì jẹ ọba.
Lecz lud, który był za Omrim, przemógł lud, który był za Tibnim, synem Ginata. I umarł Tibni, a królował Omri.
23 Ní ọdún kọkànlélọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, Omri bẹ̀rẹ̀ sí ń jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì jẹ ọba ní ọdún méjìlá, ọdún mẹ́fà ní Tirsa.
W trzydziestym pierwszym roku Asy, króla Judy, nad Izraelem zaczął królować Omri [i panował] dwanaście lat. W Tirsie królował sześć lat.
24 Ó sì ra òkè Samaria lọ́wọ́ Ṣemeri ní tálẹ́ǹtì méjì fàdákà, ó sì kọ́ ìlú sórí rẹ̀, ó sì pe ìlú náà ní Samaria, nípa orúkọ Ṣemeri, orúkọ ẹni tí ó kọ́kọ́ ni òkè náà.
I kupił wzgórze Samarii od Szemera za dwa talenty srebra, i pobudował na tym wzgórzu, a miasto, które zbudował, nazwał Samarią, od imienia właściciela wzgórza, Szemera.
25 Ṣùgbọ́n Omri sì ṣe búburú níwájú Olúwa, Ó sì ṣe búburú ju gbogbo àwọn tí ó wà ṣáájú rẹ̀ lọ.
Lecz Omri czynił to, co złe w oczach PANA, i dopuszczał się gorszych rzeczy niż wszyscy, którzy [byli] przed nim.
26 Ó rìn ní gbogbo ọ̀nà Jeroboamu ọmọ Nebati àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀, láti fi ohun asán wọn mú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli bínú.
Chodził bowiem wszystkimi drogami Jeroboama, syna Nebata, i w jego grzechu, do którego przywiódł Izraela, pobudzając PANA, Boga Izraela, do gniewu swymi marnościami.
27 Ìyókù ìṣe àti ohun tí Omri ṣe, àti agbára rẹ tí ó fihàn, a kò ha kọ, wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
A pozostałe dzieje Omriego, których dokonał, i jego potęga, którą pokazywał, czyż nie są zapisane w kronikach królów Izraela?
28 Omri sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín ní Samaria. Ahabu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
I Omri zasnął ze swoimi ojcami, i został pogrzebany w Samarii. A jego syn Achab królował w jego miejsce.
29 Ní ọdún kejìdínlógójì Asa ọba Juda, Ahabu ọmọ Omri jẹ ọba ní Israẹli, o si jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria ní ọdún méjìlélógún.
W trzydziestym ósmym roku Asy, króla Judy, nad Izraelem zaczął królować Achab, syn Omriego. Achab, syn Omriego, królował nad Izraelem w Samarii dwadzieścia dwa lata.
30 Ahabu ọmọ Omri sì ṣe búburú ní ojú Olúwa ju gbogbo àwọn tí ó wà ṣáájú rẹ̀ lọ.
I Achab, syn Omriego, czynił to, co złe w oczach PANA, bardziej niż wszyscy, którzy byli przed nim.
31 Ó sì ṣe bí ẹni pé ó ṣe ohun kékeré fún un láti máa rìn nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, ó sì mú Jesebeli, ọmọbìnrin Etibaali, ọba àwọn ará Sidoni ní aya, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ń sin Baali, ó sì bọ ọ́.
A jakby nie wystarczyło mu popełnianie grzechów Jeroboama, syna Nebata, to jeszcze pojął za żonę Jezabel, córkę Etbaala, króla Sydończyków, i zaczął służyć Baalowi i oddawać mu pokłon.
32 Ó sì tẹ́ pẹpẹ kan fún Baali nínú ilé Baali tí ó kọ́ sí Samaria.
I wzniósł ołtarz dla Baala w domu Baala, który zbudował w Samarii.
33 Ahabu sì túnṣe ère òrìṣà Aṣerah, ó sì ṣe púpọ̀ láti mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú ju èyí tí gbogbo ọba Israẹli tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀ ti ṣe lọ.
Achab zasadził też gaj. Achab czynił więcej, by pobudzać PANA, Boga Izraela, do gniewu niż wszyscy królowie Izraela, którzy byli przed nim.
34 Ní ìgbà ayé Ahabu, Hieli ará Beteli kọ́ Jeriko. Ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé ilẹ̀ ní Abiramu, àkọ́bí rẹ, ó sì gbé àwọn ìlẹ̀kùn ibodè rẹ̀ kọ́ ní Segubu àbíkẹ́yìn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Joṣua ọmọ Nuni sọ.
Za jego czasów Chiel z Betel odbudował Jerycho. Założył fundamenty na Abiramie, swoim pierworodnym, a na Segubie, swoim najmłodszym [synu], postawił jego bramy – według słowa PANA, które wypowiedział przez Jozuego, syna Nuna.

< 1 Kings 16 >