< 1 Kings 14 >

1 Ní àkókò náà Abijah ọmọ Jeroboamu sì ṣàìsàn,
W tym czasie zachorował Abiasz, syn Jeroboama.
2 Jeroboamu sì wí fún aya rẹ̀ pé, “Lọ, sì pa ara rẹ dà, kí wọn kí ó má ba à mọ̀ ọ́n ní aya Jeroboamu. Nígbà náà ni kí o lọ sí Ṣilo. Ahijah wòlíì wà níbẹ̀; ẹni tí ó sọ fún mi pé, èmi yóò jẹ ọba lórí àwọn ènìyàn yìí.
I Jeroboam powiedział do swojej żony: Wstań teraz, przebierz się, aby nie poznano, że jesteś żoną Jeroboama, i idź do Szilo. [Jest] tam prorok Achiasz, który mi powiedział, że będę królem nad tym ludem.
3 Mú ìṣù àkàrà mẹ́wàá pẹ̀lú rẹ̀, àti àkàrà wẹ́wẹ́ àti ìgò oyin, kí o sì lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Òun yóò sì sọ fún ọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọkùnrin náà.”
Weź ze sobą dziesięć chlebów, placki i dzban miodu i idź do niego. On ci oznajmi, co się stanie z dzieckiem.
4 Bẹ́ẹ̀ ni aya Jeroboamu sì ṣe bí ó ti wí, ó sì lọ sí ilé Ahijah ní Ṣilo. Ahijah kò sì ríran; ojú rẹ̀ ti fọ́ nítorí ogbó rẹ̀.
Żona Jeroboama tak uczyniła. Wstała i poszła do Szilo, i przybyła do domu Achiasza. Lecz Achiasz już nie widział, gdyż jego oczy osłabły z powodu jego starości.
5 Ṣùgbọ́n Olúwa ti sọ fún Ahijah pé, “Kíyèsi i, aya Jeroboamu ń bọ̀ wá béèrè nípa ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ, nítorí tí ó ṣàìsàn, báyìí báyìí ni kí ìwọ kí ó wí fún un. Nígbà tí ó bá dé, yóò ṣe ara rẹ̀ bí ẹlòmíràn.”
A PAN powiedział do Achiasza: Oto żona Jeroboama nadchodzi, aby dowiedzieć się czegoś od ciebie o swoim synu, gdyż jest chory. Powiesz jej tak i tak, bo gdy wejdzie, będzie udawała kogoś innego.
6 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì rí, nígbà tí Ahijah sì gbọ́ ìró ẹsẹ̀ rẹ̀ ní ẹnu-ọ̀nà, ó sì wí pé, “Wọlé wá, aya Jeroboamu. Kí ló dé tí ìwọ fi ṣe ara rẹ bí ẹlòmíràn? A ti fi iṣẹ́ búburú rán mi sí ọ.
Gdy więc Achiasz usłyszał odgłos jej kroków, gdy wchodziła przez drzwi, powiedział: Wejdź, żono Jeroboama. Dlaczego udajesz kogoś innego? Zostałem posłany do ciebie z przykrą nowiną.
7 Lọ, sọ fún Jeroboamu pé báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Èmi sì gbé ọ ga láti inú àwọn ènìyàn, mo sì fi ọ́ jẹ olórí lórí Israẹli ènìyàn mi.
Idź, powiedz Jeroboamowi: Tak mówi PAN, Bóg Izraela: Mimo że wywyższyłem cię spośród ludu i ustanowiłem cię księciem nad moim ludem Izraelem;
8 Mo fa ìjọba náà ya kúrò ní ilé Dafidi, mo sì fi fún ọ ṣùgbọ́n, ìwọ kò dàbí Dafidi ìránṣẹ́ mi, tí ó pa àṣẹ mi mọ́, tí ó sì tọ̀ mí lẹ́yìn tọkàntọkàn rẹ̀, láti ṣe kìkì èyí tí ó tọ́ ní ojú mi.
Wyrwałem domowi Dawida królestwo i dałem je tobie, ty jednak nie byłeś jak mój sługa Dawid, który przestrzegał moich przykazań i który chodził za mną całym swym sercem, czyniąc tylko to, co jest prawe w moich oczach;
9 Ìwọ sì ti ṣe búburú ju gbogbo àwọn tí ó ti wà ṣáájú rẹ lọ. Ìwọ sì ti ṣe àwọn ọlọ́run mìíràn fún ara rẹ, àwọn òrìṣà tí a gbẹ́; o sì ti mú mi bínú, o sì ti gbé mi sọ sí ẹ̀yìn rẹ.
Lecz postępowałeś gorzej niż wszyscy, którzy byli przed tobą. Ty bowiem poszedłeś i uczyniłeś sobie obcych bogów i odlane posągi, aby mnie pobudzić do gniewu, mnie zaś rzuciłeś za plecy.
10 “‘Nítorí èyí, Èmi yóò mú ibi wá sí ilé Jeroboamu. Èmi yóò ké gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò lọ́dọ̀ Jeroboamu, àti ọmọ ọ̀dọ̀ àti òmìnira ní Israẹli. Èmi yóò mú ilé Jeroboamu kúrò bí ènìyàn ti ń kó ìgbẹ́ kúrò, títí gbogbo rẹ̀ yóò fi tán.
Dlatego sprowadzę nieszczęście na dom Jeroboama i wytępię z Jeroboama każdego, aż do najmniejszego szczenięcia, każdego więźnia i opuszczonego w Izraelu, i usunę ostatki domu Jeroboama, jak usuwa się gnój, aż do końca.
11 Ajá yóò jẹ ẹni Jeroboamu tí ó bá kú ní ìlú, àti ẹni tí ó bá kú ní igbó ni àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ. Olúwa ti sọ ọ́!’
Tego, kto [z domu] Jeroboama umrze w mieście, zjedzą psy, a tego, kto umrze na polu, zjedzą powietrzne ptaki, ponieważ tak powiedział PAN.
12 “Ní ti ìwọ, padà lọ ilé, nígbà tí o bá sì fi ẹsẹ̀ rẹ tẹ ìlú, ọmọ náà yóò kú.
Ty zaś wstań i idź do swego domu, [a] gdy wejdziesz do miasta, dziecko umrze.
13 Gbogbo Israẹli yóò sì ṣọ̀fọ̀ fún un, wọn yóò sì sin ín. Òun nìkan ni a ó sì sin nínú ẹni tí ń ṣe ti Jeroboamu, nítorí lọ́dọ̀ rẹ̀ nìkan ni a ti rí ohun rere díẹ̀ sípa Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ní ilé Jeroboamu.
I cały Izrael będzie je opłakiwał, i pogrzebie je, bo jedynie ono [z domu] Jeroboama zejdzie do grobu, gdyż w nim znalazło się [coś] dobrego względem PANA, Boga Izraela, w domu Jeroboama.
14 “Olúwa yóò gbé ọba kan dìde fúnra rẹ̀ lórí Israẹli tí yóò ké ilé Jeroboamu kúrò. Ọjọ́ náà nìyìí! Kí ni? Àní nísinsin yìí.
PAN zaś ustanowi sobie króla nad Izraelem, który wytępi dom Jeroboama w tym samym dniu. A co [mówię, wzbudzi]? I owszem, już [wzbudził].
15 Olúwa yóò kọlu Israẹli, yóò sì dàbí koríko ti ń mì nínú omi. Yóò sì fa Israẹli tu kúrò ní ilẹ̀ rere yìí, tí ó ti fi fún àwọn baba wọn, yóò sì fọ́n wọn ká kọjá odò Eufurate, nítorí wọ́n ti rú ìbínú Olúwa nípa ṣíṣe ère Aṣerah.
I PAN uderzy Izraela [tak], że [się zachwieje], jak się chwieje trzcina w wodzie, i wykorzeni Izraela z tej dobrej ziemi, którą dał ich ojcom, i rozproszy ich za rzeką za to, że uczynili sobie gaje, pobudzając PANA do gniewu.
16 Yóò sì kọ Israẹli sílẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jeroboamu ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Israẹli ṣẹ̀.”
I tak porzuci on Izraela z powodu grzechów Jeroboama, który grzeszył i skłonił Izraela do grzechu.
17 Nígbà náà ni aya Jeroboamu sì dìde, ó sì lọ, ó sì lọ sí Tirsa. Bí ó sì ti fi ẹsẹ̀ tẹ ìloro ilé, ọmọdé náà sì kú.
Wtedy żona Jeroboama wstała, wyruszyła i przybyła do Tirsy. Gdy przekroczyła próg domu, dziecko umarło.
18 Wọ́n sì sin ín, gbogbo Israẹli sì ṣọ̀fọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí láti ẹnu ìránṣẹ́ rẹ̀, Ahijah wòlíì.
I pogrzebali je, i cały Izrael je opłakiwał zgodnie ze słowem PANA, które zapowiedział przez swego sługę, proroka Achiasza.
19 Ìyókù ìṣe Jeroboamu, bí ó ti jagun, àti bí ó ti jẹ ọba, ni a kọ sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli.
Pozostałe zaś dzieje Jeroboama, jak walczył i jak królował, są zapisane w kronikach o królach Izraela.
20 Jeroboamu sì jẹ ọba fún ọdún méjìlélógún, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Nadabu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
A czas, który królował Jeroboam, wynosił dwadzieścia dwa lata. Potem zasnął ze swoimi ojcami, a jego syn Nadab królował w jego miejsce.
21 Rehoboamu ọmọ Solomoni sì jẹ ọba ní Juda. Ó jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógún nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ní ọdún mọ́kànlélógún ní Jerusalẹmu, ìlú tí Olúwa ti yàn nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Naama, ará Ammoni.
Roboam zaś, syn Salomona, królował w Judzie. Roboam [miał] czterdzieści jeden lat, gdy zaczął królować, a królował siedemnaście lat w Jerozolimie, w mieście, które PAN wybrał spośród wszystkich pokoleń Izraela, aby tam przebywało jego imię. Jego matka miała na imię Naama, [była] Ammonitką.
22 Juda sì ṣe búburú níwájú Olúwa nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn tí wọ́n ti dá, wọ́n sì mú u jowú ju gbogbo èyí tí baba wọn ti ṣe lọ.
I Juda czynił to, co złe w oczach PANA, i swoimi grzechami, które popełniali, pobudzali go do zazdrości bardziej niż to wszystko, co czynili ich ojcowie.
23 Wọ́n sì tún kọ́ ibi gíga fún ara wọn, àti ère òkúta àti òpó Aṣerah lórí gbogbo òkè gíga, àti lábẹ́ gbogbo igi tútù.
Pobudowali sobie bowiem wyżyny, posągi i gaje na każdym wysokim wzgórzu i pod każdym zielonym drzewem.
24 Àwọn tí wọn jẹ́ ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà wà ní ilẹ̀ náà, àwọn ènìyàn náà sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun ìríra àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde kúrò níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
Byli też w tej ziemi sodomici. Postępowali oni według wszystkich obrzydliwości pogan, których PAN wypędził sprzed synów Izraela.
25 Ó sì ṣe ní ọdún karùn-ún Rehoboamu, Ṣiṣaki ọba Ejibiti kọlu Jerusalẹmu.
A w piątym roku króla Roboama, przeciw Jerozolimie nadciągnął Sziszak, król Egiptu.
26 Ó sì kó ìṣúra ilé Olúwa lọ àti ìṣúra ilé ọba. Gbogbo rẹ̀ ni ó kó lọ, pẹ̀lú asà wúrà tí Solomoni ti ṣe.
I zabrał skarby domu PANA oraz skarby domu królewskiego, zabrał wszystko. Zabrał też wszystkie złote tarcze, które wykonał Salomon.
27 Rehoboamu ọba sì ṣe asà idẹ ní ipò wọn, ó sì fi wọ́n sí ọwọ́ olórí àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ ìlẹ̀kùn ilé ọba.
Zamiast nich król Roboam wykonał spiżowe tarcze i powierzył je dowódcy straży przybocznej, która strzegła drzwi domu królewskiego.
28 Nígbàkígbà tí ọba bá sì lọ sí ilé Olúwa, wọ́n á rù wọ́n, wọ́n á sì mú wọn padà sínú yàrá olùṣọ́.
Ilekroć król wchodził do domu PANA, straż je nosiła, a potem odnosiła do wartowni.
29 Ní ti ìyókù ìṣe Rehoboamu, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ǹjẹ́ a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda bí?
A pozostałe dzieje Roboama i wszystko, co czynił, czyż nie są zapisane w kronikach królów Judy?
30 Ogun sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu ní ọjọ́ wọn gbogbo.
I trwała wojna między Roboamem a Jeroboamem po wszystkie dni.
31 Rehoboamu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú Dafidi. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Naama; ará Ammoni. Abijah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Potem Roboam zasnął ze swoimi ojcami i został pogrzebany z nimi w mieście Dawida. A jego matka miała na imię Naama, [była] Ammonitką. I jego syn Abijam królował w jego miejsce.

< 1 Kings 14 >