< 1 Kings 12 >

1 Rehoboamu sì lọ sí Ṣekemu, nítorí gbogbo Israẹli ti lọ síbẹ̀ láti fi í jẹ ọba.
Rehoboam loe Shekem ah caeh; Israel kaminawk boih loe anih to siangpahrang ah sak hanah caeh o.
2 Nígbà tí Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó wà ní Ejibiti síbẹ̀ gbọ́, nítorí tí ó ti sá kúrò níwájú Solomoni ọba, ó sì wà ní Ejibiti.
(To tamthang to Solomon siangpahrang khae hoi kacawn, ) Nabat capa Jeroboam mah a ohhaih ahmuen, Izip prae hoiah thaih naah, Izip prae hoi amlaem let.
3 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jeroboamu, òun àti gbogbo ìjọ Israẹli sì lọ sọ́dọ̀ Rehoboamu, wọ́n sì wí fún un pé,
Israel kaminawk mah Jeroboam to kawk hanah kami to patoeh o; Jeroboam hoi Israel kaminawk loe Rehoboam khaeah nawnto caeh o moe,
4 “Baba rẹ sọ àjàgà wa di wúwo, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú kí ìsìn baba rẹ̀ tí ó le, àti àjàgà rẹ̀ tí ó wúwo, tí ó fi sí wa ní ọrùn kí ó fẹ́rẹ̀ díẹ̀, àwa yóò sì sìn ọ́.”
nampa mah kaicae hae paroeai hmuen kazih ang phawhsak; nampa khae hoi kazit parai ka phawh o ih hmuen, kaicae nuiah koeng ih hmuen kazit hae nang mah loe anghoepsak kue lai ah, to tiah nahaeloe na tok to kang sak pae o han, tiah a naa o.
5 Rehoboamu sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ná títí di ọjọ́ mẹ́ta, nígbà náà ni kí ẹ padà tọ̀ mí wá.” Àwọn ènìyàn náà sì lọ.
Rehoboam mah, Amlaem oh loe, ni thumto pacoengah kai khaeah angzo o let ah, tiah a naa. To pongah to ih kaminawk loe amlaem o let.
6 Nígbà náà ni Rehoboamu ọba fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn àgbàgbà tí ń dúró níwájú Solomoni baba rẹ̀ nígbà tí ó wà láààyè. Ó sì béèrè pé, “Ìmọ̀ràn wo ni ẹ̀yin yóò gbà mí láti dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí lóhùn?”
Rehoboam siangpahrang mah, ampa Solomon hing naah, a hmaa ah angdoe poekhaih kahoih paekkung, kacoehtanawk khaeah, Hae kaminawk hae kawbangmaw ka pathim han? tiah a dueng.
7 Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ yóò bá jẹ́ ìránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí lónìí, kí o sì sìn wọ́n, àti kí o sì sọ ọ̀rọ̀ rere sí wọn nígbà tí ìwọ bá ń dá wọn lóhùn, wọn yóò máa ṣe ìránṣẹ́ rẹ títí láé.”
Nihcae mah, Nang loe vaihniah hae kaminawk ih tamna ah na oh moe, nihcae koehhaih to na paroi pae, nihcae han kahoih ah lok na pathim nahaeloe, hae kaminawk loe dungzan khoek to na tamna ah om o tih, tiah a naa o.
8 Ṣùgbọ́n Rehoboamu kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un, ó sì fi ọ̀rọ̀ náà lọ àwọn ọmọdé tí wọ́n dàgbà pẹ̀lú rẹ̀, tí wọ́n sì ń sìn ín.
Toe anih loe kacoehtanawk mah, thuih ih lok to tiah doeh sah ai, angmah hoi nawnto kaqoeng tahang, a hmaa ah toksah kaminawk to dueng lat.
9 Ó sì bi wọ́n pé, “Kí ni ìmọ̀ràn yín? Báwo ni a ó ṣe dá àwọn ènìyàn yí lóhùn, tí wọ́n wí fún mi pé, ‘Ṣé kí àjàgà tí baba rẹ fi sí wa lọ́rùn kí ó fúyẹ́ díẹ̀’?”
Siangpahrang mah nihcae khaeah, Hae kaminawk mah, kai khaeah, Nampa mah kaicae nuiah phawhsak ih hmuen kazit hae anghoepsak kue lai ah, tiah ang naa o, hae tiah thui kaminawk hae, kawbangmaw ka pathim han, tiah a naa.
10 Àwọn ọmọdé tí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Sọ fún àwọn ènìyàn tí wọ́n wí fún ọ pé, ‘Baba rẹ̀ mú kí àjàgà wa wúwo ṣùgbọ́n ìwọ mú kí ó fúyẹ́ díẹ̀ fún wa’; sọ fún wọn pé, ìka ọwọ́ mi kékeré nípọn ju ẹ̀gbẹ́ baba mi lọ.
Angmah hoi huihto kaqoeng thendoengnawk mah anih khaeah, Nampa mah kaicae nuiah phawhsak ih hmuen kazit to, nang mah anghoepsak kue lai ah, tiah kathui hae kaminawk khaeah, Ka banpazung loe kampa ih kaeng pongah len kue tih.
11 Baba mi ti gbé àjàgà wúwo lé e yín; Èmi yóò sì fi kún àjàgà yín. Baba mi ti fi pàṣán nà yín, Èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
Kampa mah ang phawh o sak ih kazit hmuen pongah kazit kue hmuen to kang phawh o sak han; kampa mah quiboeng hoiah ang thuihtaek o, kai mah loe sataai hoiah kang thuihtaek o han, tiah pathim ah, tiah a naa o.
12 Jeroboamu àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wá sọ́dọ̀ Rehoboamu ní ọjọ́ kẹta, gẹ́gẹ́ bí ọba ti wí pé, “Ẹ padà tọ̀ mí wá ní ọjọ́ kẹta.”
Siangpahrang mah ni thumto pacoengah angzoh o let hanah a thuih pae baktih toengah, Ni thumto oh pacoengah loe Jeroboam hoi kaminawk boih to Rehoboam khaeah angzoh o let.
13 Ọba sì fi ohùn líle dá àwọn ènìyàn lóhùn, ó sì kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un,
To naah siangpahrang loe kacoehtanawk mah thuih ih loknawk tiah doeh sah pae ai, to ih kaminawk khaeah kanaa parai ah lok to pathim pae;
14 Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọmọdé, ó sì wí pé, “Baba mí sọ àjàgà yín di wúwo, èmi yóò sì jẹ́ kí ó wúwo sí i, baba mi fi pàṣán nà yín èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
thendoengnawk mah thuih o ih lok baktih toengah, to kaminawk khaeah, Kampa mah ang phawh o sak ih hmuen kazit pong kazit kue ah, kang phawh o sak han; kampa mah quiboeng hoiah ang boh o, toe kai mah loe sataai hoiah kang boh o han, tiah a naa.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fi etí sí ti àwọn ènìyàn, nítorí tí ọ̀ràn náà ti ọwọ́ Olúwa wá láti mú ọ̀rọ̀ tí ó sọ fún Jeroboamu ọmọ Nebati láti ẹnu Ahijah ará Ṣilo ṣẹ.
Tipongah siangpahrang mah prae kaminawk ih lok tahngaih han koeh ai tih nahaeloe, Angraeng mah Shiloh kami Ahijah patohhaih rang hoiah, Nebat capa Jeroboam khaeah Angraeng mah thuih ih lok akoepsak han ih ni hae tiah hmuen hae oh.
16 Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i pé ọba kọ̀ láti gbọ́ ti àwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn pé, “Ìpín wo ni àwa ní nínú Dafidi, ìní wo ni àwa ní nínú ọmọ Jese? Padà sí àgọ́ rẹ, ìwọ Israẹli! Bojútó ilé ara rẹ, ìwọ Dafidi!” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Israẹli padà sí ilé wọn.
Siangpahrang mah nihcae ih lok tahngai pae ai, tiah Israel kaminawk boih mah panoek o naah, siangpahrang khaeah; David khaeah taham timaw ka tawnh o moe, Jesse capa khaeah qawktoep han koi timaw ka tawnh o? Aw Israel kaminawk, nangmacae kahni im ah amlaem oh; Aw David, na im hae nang mah toep lai ah, tiah a naa o. To pongah Israel kaminawk loe angmacae im ah amlaem o.
17 Ṣùgbọ́n fún ti àwọn ọmọ Israẹli tí ń gbé nínú ìlú Juda, Rehoboamu jẹ ọba lórí wọn síbẹ̀.
Toe Judah vangpuinawk thungah kaom Israel kaminawk loe Rehoboam mah ni uk vop.
18 Ọba Rehoboamu rán Adoniramu jáde, ẹni tí ó wà ní ìkáwọ́ iṣẹ́ onírúurú, ṣùgbọ́n gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa. Ọba Rehoboamu, gbìyànjú láti dé inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì sálọ sí Jerusalẹmu.
Rehoboam siangpahrang mah tamut kokhaih bangah zaehoikung Adoram to patoeh, toe anih to Israel kaminawk boih mah thlung hoiah vah o maat. Rehoboam siangpahrang angmah to loe, angmah ih hrang lakok nuiah karangah angthueng moe, Jerusalem vangpui ah cawnh.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí ilé Dafidi títí di òní yìí.
To pongah Israel kaminawk loe, David imthung takoh nuiah vaihni ni khoek to misa ah oh o.
20 Nígbà tí gbogbo Israẹli sì gbọ́ pé Jeroboamu ti padà dé, wọ́n ránṣẹ́, wọ́n sì pè é wá sí àjọ, wọ́n sì fi jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli. Kò sí ẹnìkan tí ó tọ ilé Dafidi lẹ́yìn bí kò ṣe kìkì ẹ̀yà Juda nìkan.
Jeroboam amlaem let boeh, tiah Israel kaminawk boih mah thaih o naah, rangpui amkhuenghaih ahmuen ah anih to kawk o moe, Israel kaminawk boih ukkung siangpahrang ah suek o; Judah acaeng khue ai ah loe, David ih imthung takoh hnukbang kami midoeh om ai.
21 Nígbà tí Rehoboamu sì dé sí Jerusalẹmu, ó kó gbogbo ilé Juda jọ, àti ẹ̀yà Benjamini; ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ènìyàn tí a yàn, tí wọ́n ń ṣe ológun, láti bá ilé Israẹli jà àti láti mú ìjọba náà padà bọ̀ sọ́dọ̀ Rehoboamu, ọmọ Solomoni.
Rehoboam Jerusalem vangpui ah phak naah, Israel kaminawk loe misa to tuk moe, prae to Solomon capa Rehoboam ban thungah phaksak let hanah, Judah imthung takoh kaminawk hoi Benjamin imthung takoh kaminawk boih ahmuen maeto ah amkhuengsak; a qoih ih misatuh thaih kami sang cumvaito pacoeng, sang quitazetto oh o.
22 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Ṣemaiah ènìyàn Ọlọ́run wá wí pé,
Toe Sithaw ih kami Shemaiah khaeah Sithaw ih lok hae tiah angzoh,
23 “Sọ fún Rehoboamu, ọmọ Solomoni, ọba Juda àti fún gbogbo ilé Juda àti ti Benjamini, àti fún àwọn ènìyàn tókù wí pé,
Solomon capa, Judah siangpahrang khaeah, Judah hoi Benjamin imthung takohnawk boih, kanghmat kaminawk boih khaeah,
24 ‘Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ má ṣe gòkè lọ láti bá àwọn arákùnrin yín jà, àwọn ènìyàn Israẹli. Kì olúkúlùkù yín padà sí ilé rẹ̀, nítorí nǹkan yìí láti ọ̀dọ̀ mi wá ni.”’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, wọ́n sì tún padà sí ilé wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
Angraeng mah hae tiah thuih; Nam nawkamya Israel kaminawk tuk hanah caeh o tahang hmah; kami boih angmah im ah amlaem o nasoe; kaimah ni hae hmuennawk hae ka sak, tiah thui pae oh, tiah a naa. To pongah nihcae mah Angraeng ih lok to tahngaih o moe, Angraeng mah thuih ih lok baktih toengah, angmacae im ah amlaem o let.
25 Nígbà náà ni Jeroboamu kọ́ Ṣekemu ní òkè Efraimu, ó sì ń gbé inú rẹ̀. Láti ibẹ̀ ó sì jáde lọ, ó sì kọ́ Penieli.
To pacoengah Jeroboam mah Ephraim mae nuiah, Shekem vangpui to sak moe, to vangpui thungah oh; to vangpui hoiah caeh moe, Penuel vangpui to a sak.
26 Jeroboamu rò nínú ara rẹ̀ pé, “Ìjọba náà yóò padà nísinsin yìí sí ilé Dafidi.
Jeroboam mah siangpahrang ukhaih prae loe David imthung takoh khaeah paek let tih boeh;
27 Bí àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá gòkè lọ láti ṣe ìrúbọ ní ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, wọn yóò tún fi ọkàn wọn fún Olúwa wọn, Rehoboamu ọba Juda. Wọn yóò sì pa mí, wọn yóò sì tún padà tọ Rehoboamu ọba Juda lọ.”
hae kaminawk mah angbawnhaih paek hanah, Angraeng ih im ohhaih Jerusalem ah caeh o nahaeloe, hae kaminawk loe angmacae ih angraeng, Judah siangpahrang, Rehoboam khaeah amlaem o let tih; kai hae na hum o ueloe, Rehoboam siangpahrang khaeah amlaem o let tih, tiah palung thungah a poek.
28 Lẹ́yìn tí ó ti gba ìmọ̀ràn, ọba sì yá ẹgbọrọ màlúù wúrà méjì. Ó sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ó ti pọ̀jù fún yín láti máa gòkè lọ sí Jerusalẹmu. Àwọn Ọlọ́run yín nìyìí, Israẹli, tí ó mú yín láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
To pongah kaminawk khaeah lokdueng pacoengah, Siangpahrang mah sui hoiah maitaw caa krang hnetto a sak; to pacoengah anih mah kaminawk khaeah, Jerusalem vangpui ah na caeh o haih pop parai boeh; Aw Israel kaminawk, Izip prae thung hoiah nangcae zaehoikung sithaw hnik loe, hae ah oh hoi boeh, tiah a naa.
29 Ó sì gbé ọ̀kan kalẹ̀ ní Beteli, àti èkejì ní Dani.
Maeto loe Bethel ah suek moe, kalah maeto loe Dan ah a suek.
30 Nǹkan yìí sì di ẹ̀ṣẹ̀; àwọn ènìyàn sì lọ títí dé Dani láti sin èyí tí ó wà níbẹ̀.
Hae tiah a sak ih hmuen loe zae haih ah oh; kaminawk loe to ah kaom sithaw to bok hanah, Dan karoek to caeh o.
31 Jeroboamu sì kọ́ ojúbọ sórí ibi gíga, ó sì yan àwọn àlùfáà láti inú àwọn ènìyàn bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn kì í ṣe inú àwọn ọmọ Lefi.
Jeroboam loe hmuensang ah bokhaih imnawk to sak moe, Levi acaeng na ai, kahnaem koek kami rumram to qaima ah a suek.
32 Jeroboamu sì dá àsè sílẹ̀ ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ gẹ́gẹ́ bí àsè tí ó wà ní Juda, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ. Ó ṣe èyí ní Beteli, ó rú ẹbọ sí àwọn ọmọ màlúù tí ó ṣe. Ó sì fi àwọn àlùfáà sí ibi gíga tí ó ti ṣe sí Beteli.
Judah prae ah sak o ih poih baktih toengah, khrah tazetto haih ni hatlaipangato naah, hmaicam pongah angbawnhaih to a sak. Bethel ah doeh to tiah sak ih maitaw caa krang khaeah angbawnhaih to a sak; hmuensang ah toksak hanah tokpaek ih qaimanawk to, Bethel ah a suek.
33 Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ, oṣù tí ó rò ní ọkàn ara rẹ̀, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí ó kọ́ ní Beteli. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì dá àsè sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, ó sì gun orí pẹpẹ náà lọ láti rú ẹbọ.
A poekhaih baktiah a qoih ih khrah tazetto haih ni hatlaipangato naah, Bethel ah a sak ih hmaicam pongah, angbawnhaih to sak; to tiah Israelnawk hanah poih to a sak pae pacoengah, hmaicam nuiah angbawnhaih to sak moe, hmuihoih doeh a thlaek.

< 1 Kings 12 >