< 1 Corinthians 15 >

1 Ǹjẹ́ ará, èmi ń sọ ìyìnrere náà dí mí mọ̀ fún un yín, tí mo ti wàásù fún un yín, èyí tí ẹ̀yin pẹ̀lú ti gbá, nínú èyí tí ẹ̀yin sì dúró.
A oznajmiam wam, bracia, ewangelię, którą wam głosiłem, a którą przyjęliście i w której trwacie;
2 Nípasẹ̀ ìyìnrere yìí ni a fi ń gbà yín là pẹ̀lú, bí ẹ̀yin bá di ọ̀rọ̀ ti mo ti wàásù fún yín mú ṣinṣin. Bí bẹ́ẹ̀ kọ̀, ẹ̀yin kàn gbàgbọ́ lásán.
Przez którą też dostępujecie zbawienia, jeśli pamiętacie to, co wam głosiłem, chyba że uwierzyliście na próżno.
3 Nítorí èyí tí mo rí gbà ṣáájú ohun gbogbo ní èmi pẹ̀lú ti fi lé e yín lọ́wọ́, bí Kristi ti kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bí ìwé mímọ́ tí wí.
Najpierw bowiem przekazałem wam to, co i ja otrzymałem, że Chrystus umarł za nasze grzechy, zgodnie z Pismem;
4 Àti pé a sìnkú rẹ̀, àti pé ó jíǹde ní ọjọ́ kẹta gẹ́gẹ́ bí Ìwé Mímọ́ tí wí;
Że został pogrzebany, że zmartwychwstał trzeciego dnia, zgodnie z Pismem;
5 àti pé ó farahàn Peteru, lẹ́yìn èyí, àwọn méjìlá.
I że ukazał się Kefasowi, a potem tym dwunastu.
6 Lẹ́yìn èyí, ó farahàn àwọn ará tí o jú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta lọ lẹ́ẹ̀kan náà; ọ̀pọ̀ nínú wọn wà títí fi di ìsinsin yìí, ṣùgbọ́n àwọn díẹ̀ ti sùn.
Potem ukazał się więcej niż pięciuset braciom naraz, z których większość żyje aż dotąd, a niektórzy zasnęli.
7 Lẹ́yìn èyí ni ó farahan Jakọbu; lẹ́yìn náà fún gbogbo àwọn aposteli.
Potem ukazał się Jakubowi, potem wszystkim apostołom.
8 Àti níkẹyìn gbogbo wọn ó farahàn mí pẹ̀lú, bí ẹni tí a bí ṣáájú àkókò rẹ̀.
A ostatniemu ze wszystkich ukazał się i mnie, jak poronionemu płodowi.
9 Nítorí èmi ni ẹni tí ó kéré jùlọ nínú àwọn aposteli, èmi ẹni tí kò yẹ láti pè ní aposteli, nítorí tí mo ṣe inúnibíni sí ìjọ ènìyàn Ọlọ́run.
Ja bowiem jestem najmniejszym z apostołów i nie jestem godny nazywać się apostołem, bo prześladowałem kościół Boży.
10 Ṣùgbọ́n nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run mo rí bí mo ti rí: oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ tí a fi fún mi kò sì jẹ́ asán; ṣùgbọ́n mó ṣiṣẹ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ jú gbogbo wọn lọ, ṣùgbọ́n kì í ṣe èmi, bí kò ṣe oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run tí ó wà pẹ̀lú mi.
Lecz z łaski Boga jestem tym, czym jestem, a jego łaska względem mnie nie okazała się daremna, ale pracowałem więcej od nich wszystkich, jednak nie ja, lecz łaska Boga, która [jest] ze mną.
11 Nítorí náà ìbá à ṣe èmí tàbí àwọn ni, èyí ní àwa wàásù, èyí ní ẹ̀yin sì gbàgbọ́.
Czy więc ja, czy oni, tak głosimy i tak uwierzyliście.
12 Ǹjẹ́ bí a bá wàásù Kristi pé ó tí jíǹde kúrò nínú òkú, èéha tí ṣe tí àwọn mìíràn nínú yín fi wí pé, àjíǹde òkú kò sí.
A jeśli się o Chrystusie głosi, że został wskrzeszony z martwych, jak [mogą] niektórzy pośród was mówić, że nie ma zmartwychwstania?
13 Ṣùgbọ́n bí àjíǹde òkú kò sí, ǹjẹ́ Kristi kò jíǹde.
Jeśli bowiem nie ma zmartwychwstania, to i Chrystus nie został wskrzeszony.
14 Bí Kristi kò bá sì jíǹde, ǹjẹ́ asán ni ìwàásù wà, asán sì ni ìgbàgbọ́ yín pẹ̀lú.
A jeśli Chrystus nie został wskrzeszony, to daremne [jest] nasze głoszenie, daremna też wasza wiara.
15 Ṣùgbọ́n jù bẹ́ẹ̀ lọ, a mú wa ni ẹlẹ́rìí èké fún Ọlọ́run; nítorí ti àwa jẹ́rìí Ọlọ́run pé ó jí Kristi dìde kúrò nínú òkú: ẹni tí òun kò jí dìde bí ó bá ṣe pé àwọn òkú kò jíǹde?
I okazuje się, że jesteśmy fałszywymi świadkami Boga, bo świadczyliśmy o Bogu, że wskrzesił Chrystusa, którego nie wskrzesił, jeśli umarli nie są wskrzeszani.
16 Nítorí pé bi á kò bá jí àwọn òkú dìde, ǹjẹ́ a kò jí Kristi dìde,
Jeśli bowiem umarli nie są wskrzeszani, to i Chrystus nie został wskrzeszony.
17 bí a kò bá sì jí Kristi dìde, asán ní ìgbàgbọ́ yín; ẹ̀yin wà nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín síbẹ̀.
A jeśli Chrystus nie został wskrzeszony, daremna [jest] wasza wiara i nadal jesteście w swoich grzechach.
18 Ǹjẹ́ àwọn pẹ̀lú tí ó sùn nínú Kristi ṣègbé.
Tak więc i ci, którzy zasnęli w Chrystusie, poginęli.
19 Bí ó bá ṣe pé kìkì ayé yìí nìkan ní àwa ní ìrètí nínú Kristi, àwa jásí òtòṣì jùlọ nínú gbogbo ènìyàn.
Jeśli tylko w tym życiu mamy nadzieję w Chrystusie, jesteśmy ze wszystkich ludzi najbardziej nieszczęśliwi.
20 Ǹjẹ́ nísinsin yìí Kristi tí jíǹde kúrò nínú òkú, ó sì dí àkọ́bí nínú àwọn tí ó sùn.
Tymczasem jednak Chrystus został wskrzeszony z martwych i stał się pierwszym plonem tych, którzy zasnęli.
21 Nítorí ìgbà tí ó jẹ́ pé nípa ènìyàn ní ikú ti wá, nípa ènìyàn ní àjíǹde òkú sì ti wá pẹ̀lú.
Skoro bowiem śmierć [przyszła] przez człowieka, przez człowieka [przyszło] też zmartwychwstanie umarłych.
22 Nítorí bí gbogbo ènìyàn ti kú nínú Adamu, bẹ́ẹ̀ ní a ó sì sọ gbogbo ènìyàn dí alààyè nínú Kristi.
Jak bowiem w Adamie wszyscy umierają, tak też w Chrystusie wszyscy zostaną ożywieni.
23 Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ènìyàn ní ipá tirẹ̀: Kristi àkọ́bí; lẹ́yìn èyí àwọn tí ó jẹ́ tí Kristi ni wíwá rẹ̀.
Ale każdy w swojej kolejności, Chrystus jako pierwszy plon, potem ci, którzy należą do Chrystusa, w [czasie] jego przyjścia.
24 Nígbà náà ni òpin yóò dé, nígbà tí ó bá ti fi ìjọba fún Ọlọ́run Baba, nígbà tí ó bá pa gbogbo àṣẹ àti gbogbo ọlá àti agbára run.
A potem będzie koniec, gdy przekaże królestwo Bogu i Ojcu, gdy zniszczy wszelką zwierzchność oraz wszelką władzę i moc.
25 Nítorí ti òun gbọdọ̀ ti jẹ ọba kí òun to fi gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.
Bo on musi królować, aż położy wszystkich wrogów pod swoje stopy.
26 Ikú ní ọ̀tá ìkẹyìn tí a ó parun.
A ostatni wróg, który zostanie zniszczony, to śmierć.
27 “Nítorí ó ti fi ohun gbogbo sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.” Ṣùgbọ́n nígbà tí ó wí pé, “Ohun gbogbo ni á fi sí abẹ́ rẹ̀,” o dájú pé Ọlọ́run nìkan ṣoṣo ní kò sí ní abẹ́ rẹ̀, Òun ní ó fi ohun gbogbo sí abẹ́ àkóso Kristi.
Wszystko bowiem poddał pod jego stopy. A gdy mówi, że wszystko jest [mu] poddane, [jest] jasne, że oprócz tego, który mu wszystko poddał.
28 Nígbà tí a bá sì fi ohun gbogbo sí abẹ́ rẹ̀ tán, nígbà náà ni á ó fi ọmọ tìkára rẹ̀ pẹ̀lú sábẹ́ ẹni tí ó fi ohun gbogbo sí abẹ́ rẹ̀, kí Ọlọ́run lè jásí ohun gbogbo nínú ohun gbogbo.
Gdy zaś wszystko zostanie mu poddane, wtedy i sam Syn będzie poddany temu, który mu poddał wszystko, aby Bóg był wszystkim we wszystkich.
29 Ní báyìí, bí kò bá sí àjíǹde, kín ní ète àwọn ènìyàn tí wọn ń tẹ bọ omi nítorí òkú? Bí àwọn òkú kò bá jíǹde rárá, nítorí kín ni a ṣe ń bamitiisi wọn nítorí wọn?
Bo inaczej co zrobią ci, którzy przyjmują chrzest za zmarłych, jeśli umarli w ogóle nie są wskrzeszani? Po co przyjmują chrzest za zmarłych?
30 Nítorí kín ní àwa sì ṣe ń bẹ nínú ewu ni wákàtí gbogbo?
Po co i my każdej godziny narażamy się na niebezpieczeństwo?
31 Mo sọ nípa ayọ̀ tí mo ní lórí yín nínú Kristi Jesu Olúwa wá pé, èmi ń kú lójoojúmọ́.
[Zapewniam was] przez chlubę, którą mam z was w Jezusie Chrystusie, naszym Panu, że każdego dnia umieram.
32 Kí a wí bí ènìyàn, bí mo bá ẹranko jà ní Efesu, àǹfààní kín ni ó jẹ́ fún mi? Bí àwọn òkú kò bá jíǹde, “Ẹ jẹ́ kí a máa jẹ, kí á máa mú; nítorí ní ọlá ni àwa ó kú.”
Jeśli na sposób ludzki walczyłem z bestiami w Efezie, jaki z tego mam pożytek, jeśli umarli nie są wskrzeszani? Jedzmy i pijmy, bo jutro pomrzemy.
33 Kí a má tàn yín jẹ́, “Ẹgbẹ́ búburú bá ìwà rere jẹ́.”
Nie łudźcie się. Złe rozmowy psują dobre obyczaje.
34 Ẹ jí ìjí òdodo, kí ẹ má sì dẹ́ṣẹ̀; nítorí àwọn ẹlòmíràn kò ni imọ̀ Ọlọ́run, mo sọ èyí kí ojú ba à lè tiyín.
Ocknijcie się ku sprawiedliwości i nie grzeszcie; niektórzy bowiem nie mają poznania Boga. Mówię to ku waszemu zawstydzeniu.
35 Ṣùgbọ́n ẹnìkan yóò wí pé, “Báwo ni àwọn òkú yóò ṣe jíǹde? Irú ara wó ni wọn ó padà sí?”
Lecz powie ktoś: Jak umarli są wskrzeszani i w jakim ciele przychodzą?
36 Ìwọ aláìmòye, ohun tí ìwọ fúnrúgbìn kì í yè bí kò ṣe pé ó ba kú,
Głupcze! To, co siejesz, nie ożyje, jeśli nie obumrze.
37 àti èyí tí ìwọ fúnrúgbìn, kì í ṣe ara tí ń bọ̀ ni ìwọ fúnrúgbìn, ṣùgbọ́n èso lásán ni, ìbá à ṣe alikama, tàbí irú mìíràn.
I to, co siejesz, to nie ciało, które ma powstać, ale gołe ziarno, na przykład pszeniczne lub jakieś inne.
38 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run fún ún ni ara bí o tí wù ú, àti fún olúkúlùkù irúgbìn ara tirẹ̀.
Bóg zaś daje mu ciało, jakie chce, a każdemu z ziaren właściwe jemu ciało.
39 Gbogbo ẹran-ara kì í ṣe ẹran-ara kan náà, ṣùgbọ́n ọ̀tọ̀ ni ẹran-ara ti ènìyàn, ọ̀tọ̀ ni ẹran-ara ti ẹranko, ọ̀tọ̀ ní ti ẹja, ọ̀tọ̀ sì ní tí ẹyẹ.
Nie każde ciało jest jednakowe, ale inne jest ciało ludzi, a inne ciało zwierząt, inne ryb, a inne ptaków.
40 Ará ti òkè ọ̀run ń bẹ, ara ti ayé pẹ̀lú sì ń bẹ, ṣùgbọ́n ògo ti òkè ọ̀run ọ̀tọ̀, àti ògo ti ayé ọ̀tọ̀.
Są też ciała niebieskie i ciała ziemskie, lecz inna jest chwała [ciał] niebieskich, a inna ziemskich.
41 Ọ̀tọ̀ ni ògo ti oòrùn, ọ̀tọ̀ ni ògo ti òṣùpá, ọ̀tọ̀ sì ni ògo ti ìràwọ̀; ìràwọ̀ ṣá yàtọ̀ sí ìràwọ̀ ni ògo.
Inna chwała słońca, inna chwała księżyca, a inna chwała gwiazd. Gwiazda bowiem od gwiazdy różni się jasnością.
42 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sí ni àjíǹde òkú. A gbìn ín ní ìdíbàjẹ́; a sí jì í dìde ni àìdíbàjẹ́.
Tak też jest ze zmartwychwstaniem umarłych. Sieje się [ciało] w zniszczalności, a jest wskrzeszane w niezniszczalności;
43 A gbìn ín ni àìní ọlá, a sí jí i dìde ni ògo; a gbìn ín ni àìlera, a sì jí í dìde ní agbára.
Sieje się w niesławie, a jest wskrzeszane w chwale, sieje się w słabości, a jest wskrzeszane w mocy;
44 A gbìn ín ni, ara ẹran a sì jí i dìde ni ara ti ẹ̀mí. Bí ara ẹran bá ń bẹ, ara ẹ̀mí náà sì ń bẹ.
Sieje się ciało cielesne, a jest wskrzeszane ciało duchowe. Jest ciało cielesne, jest też ciało duchowe.
45 Bẹ́ẹ̀ ní a si kọ ọ́ pé, “Adamu ọkùnrin ìṣáájú, alààyè ọkàn ni a dá a”; Adamu ìkẹyìn ẹ̀mí ìsọnidààyè.
Tak też jest napisane: Stał się pierwszy człowiek, Adam, duszą żyjącą, [a] ostatni Adam duchem ożywiającym.
46 Ṣùgbọ́n èyí tí í ṣe tí ẹ̀mí kọ ní ó kọ́kọ́ ṣáájú, bí kò ṣe èyí tí í ṣe tí ara ọkàn, lẹ́yìn náà èyí ti í ṣe ti ẹ̀mí.
Jednak pierwsze nie jest to, co duchowe, ale to, co cielesne, potem duchowe.
47 Ọkùnrin ìṣáájú ti inú erùpẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bí ẹni erùpẹ̀: ọkùnrin èkejì láti ọ̀run wá ni.
Pierwszy człowiek z ziemi – ziemski, drugi człowiek – [sam] Pan z nieba.
48 Bí ẹni erùpẹ̀ ti rí, irú bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn tí í ṣe erùpẹ̀: bí ẹni tí ọ̀run ti rí, irú bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn tí í ṣe tí ọ̀run.
Jaki jest ten ziemski, tacy i ziemscy; a jaki jest niebieski, tacy i niebiescy.
49 Bí àwa ti rú àwòrán ẹni erùpẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àwa ó sì rú àwòrán ẹni ti ọ̀run.
A jak nosiliśmy obraz ziemskiego, tak będziemy nosili obraz niebieskiego.
50 Ará, ǹjẹ́ èyí ní mo wí pé, ara àti ẹ̀jẹ̀ kò lè jogún ìjọba Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ìdíbàjẹ́ kò lé jogún àìdíbàjẹ́.
To zaś mówię, bracia, że ciało i krew nie mogą odziedziczyć królestwa Bożego ani to, co zniszczalne, nie odziedziczy tego, co niezniszczalne.
51 Kíyèsi í, ohun ìjìnlẹ̀ ni mo sọ fún un yín, gbogbo wá kì yóò sùn, ṣùgbọ́n gbogbo wá ní a ó paláradà.
Oto oznajmiam wam tajemnicę: Nie wszyscy zaśniemy, ale wszyscy będziemy przemienieni;
52 Lọ́gán, ni ìṣẹ́jú kan, nígbà ìpè ìkẹyìn: nítorí ìpè yóò dún, a ó sì jí àwọn òkú dìde ní àìdíbàjẹ́, a ó sì pa wá láradà.
W jednej chwili, w mgnieniu oka, na ostatnią trąbę. Zabrzmi bowiem [trąba], a umarli zostaną wskrzeszeni niezniszczalni, a my zostaniemy przemienieni.
53 Nítorí pé ara ìdíbàjẹ́ yìí kò lè ṣàìgbé ìdíbàjẹ́ wọ̀, àti ara kíkú yìí kò lè ṣàìgbé ara àìkú wọ̀.
To bowiem, co zniszczalne, musi przyodziać się w to, co niezniszczalne, a to, co śmiertelne, przyoblec się w nieśmiertelność.
54 Ṣùgbọ́n nígbà tí ará ìdíbàjẹ́ yìí bá ti gbé àìdíbàjẹ́ wọ̀, ti ara kíkú yìí bá sí ti gbé àìkú wọ̀ bẹ́ẹ̀ tan, nígbà náà ni ọ̀rọ̀ ti a kọ yóò ṣẹ pé, “A gbé ikú mí ní ìṣẹ́gun.”
A gdy to, co zniszczalne, przyoblecze się w niezniszczalność, a to, co śmiertelne, przyoblecze się w nieśmiertelność, wtedy wypełni się to słowo, które [jest] napisane: Połknięta jest śmierć w zwycięstwie.
55 “Ikú, oró rẹ dà? Ikú, ìṣẹ́gun rẹ́ dà?” (Hadēs g86)
Gdzież [jest], o śmierci, twoje żądło? Gdzież jest, o piekło, twoje zwycięstwo? (Hadēs g86)
56 Oró ikú ni ẹ̀ṣẹ̀; àti agbára ẹ̀ṣẹ̀ ni òfin.
Żądłem zaś śmierci [jest] grzech, a siłą grzechu prawo.
57 Ṣùgbọ́n ọpẹ́ ní fún Ọlọ́run ẹni tí ó fì ìṣẹ́gun fún wá nípa Olúwa wá Jesu Kristi!
Lecz dzięki [niech będą] Bogu, który nam dał zwycięstwo przez naszego Pana Jezusa Chrystusa.
58 Nítorí náà ẹ̀yin ará mi olùfẹ́ ẹ máa dúró ṣinṣin, láìyẹsẹ̀, kí ẹ máa pọ̀ si í ní iṣẹ́ Olúwa nígbà gbogbo, ní ìwọ̀n bí ẹ̀yin ti mọ̀ pé iṣẹ́ yin kì í ṣe asán nínú Olúwa.
A tak, moi mili bracia, bądźcie stali, niezachwiani, zawsze obfitujący w dziele Pana, wiedząc, że wasza praca nie jest daremna w Panu.

< 1 Corinthians 15 >