< 1 Chronicles 11 >

1 Gbogbo àwọn Israẹli kó ara wọn jọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní Hebroni, wọ́n sì wí pé, “Ẹran-ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ ni àwa í ṣe.
Wtedy cały Izrael zebrał się przy Dawidzie w Hebronie, mówiąc: Oto jesteśmy twoją kością i twoim ciałem.
2 Ní àtijọ́, kódà nígbà tí Saulu jẹ ọba, ìwọ ni ẹni tí ó darí Israẹli ní ojú ogun wọn. Olúwa Ọlọ́run rẹ sì wí fún ọ pé, ‘Ìwọ yóò sì jẹ́ olùṣọ́ Israẹli ènìyàn mi, ìwọ yóò sì jẹ́ olórí fún wọn.’”
Już przedtem, gdy jeszcze Saul był królem, wyprowadzałeś i wprowadzałeś Izraela. I PAN, twój Bóg, powiedział ci: Ty będziesz pasł mój lud Izraela i ty będziesz wodzem nad moim ludem, Izraelem.
3 Nígbà tí gbogbo àwọn ìjòyè Israẹli tí wọ́n ti wá sọ́dọ̀ ọba Dafidi ni Hebroni. Ó sì ṣe májẹ̀mú pẹ̀lú wọn ní Hebroni níwájú Olúwa, wọ́n sì fi òróró yan Dafidi ní ọba lórí Israẹli, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa láti ọwọ́ Samuẹli.
Przyszli więc wszyscy starsi Izraela do króla do Hebronu i Dawid zawarł z nimi przymierze w Hebronie przed PANEM. Namaścili Dawida na króla nad Izraelem zgodnie ze słowem PANA, [które wypowiedział] przez Samuela.
4 Dafidi àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jáde lọ sí Jerusalẹmu (tí ṣe Jebusi). Àwọn Jebusi ara ilẹ̀ náà ń gbé níbẹ̀.
I Dawid wyruszył wraz z całym Izraelem do Jerozolimy, to jest Jebus; mieszkańcami tej ziemi byli Jebusyci.
5 Àwọn ará ìlú Jebusi sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ kò sì gbọdọ̀ wọ ìhín yìí wá.” Ṣùgbọ́n Dafidi kó ìlú odi Sioni—èyí tí í ṣe ìlú Dafidi.
Wtedy mieszkańcy Jebus powiedzieli do Dawida: Nie wejdziesz tutaj. Dawid jednak zdobył twierdzę Syjon, to [jest] miasto Dawida.
6 Dafidi ti wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá tètè kọlu àwọn ará Jebusi ni yóò di olórí àti balógun.” Joabu ọmọ Seruiah sì kọ́kọ́ gòkè lọ, bẹ́ẹ̀ ni ó sì gba olórí.
Potem Dawid powiedział: Kto pierwszy pokona Jebusytów, będzie wodzem i naczelnikiem. Wystąpił więc jako pierwszy Joab, syn Serui, i został wodzem.
7 Dafidi sì ń gbé inú ìlú odi, nítorí náà ni wọ́n fi ń pè é ni ìlú Dafidi.
I Dawid zamieszkał w twierdzy, dlatego nazwano ją miastem Dawida.
8 Ó sì kọ́ àwọn ìlú náà yíkákiri; láti Millo yíkákiri; Joabu sì tún ìyókù àwọn ìlú náà ṣe.
Rozbudował miasto wokoło, od Millo, a Joab odbudował resztę miasta.
9 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi ń ga, ó sì pọ̀ sí i, nítorí pé Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú rẹ̀.
A Dawid stawał się coraz potężniejszy, ponieważ PAN zastępów [był] z nim.
10 Àwọn wọ̀nyí sì ni ìjòyè alágbára ọkùnrin Dafidi, àwọn pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì fún ìjọba rẹ̀ ní àtìlẹ́yìn tó lágbára láti mú un tàn káàkiri gbogbo ilẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣèlérí.
Oto naczelnicy spośród dzielnych wojowników, których miał Dawid i którzy dzielnie starali się z nim o jego królestwo wraz z całym Izraelem, aby uczynić go królem zgodnie ze słowem PANA o Izraelu.
11 Èyí sì ni iye àwọn akọni ọkùnrin Dafidi: Jaṣobeamu ọmọ Hakumoni, òun sì ni olórí nínú àwọn ìjòyè, ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè lórí àwọn ọ̀ọ́dúnrún ènìyàn, àwọn ẹni tí ó pa ní ogun ẹ̀ẹ̀kan.
A oto spis dzielnych wojowników, których miał Dawid: Jaszobeam, syn Chakmoniego, naczelnik dowódców. On to podniósł swoją włócznię przeciw trzystu i pobił ich za jednym razem.
12 Lẹ́yìn rẹ̀ sì ni Eleasari ọmọ Dodo àwọn ará Ahohi, ọ̀kan lára àwọn mẹ́ta ọkùnrin alágbára.
Po nim Eleazar, syn Dodo, Achochita, jeden spośród trzech dzielnych.
13 Ó sì wà pẹ̀lú Dafidi ní Pasi-Dammimu nígbà tí àwọn ará Filistini kó ara wọn jọ láti jagun, níbi tí ilẹ̀ kan wà tí ó kún fún ọkà barle. Àwọn ènìyàn sì sálọ kúrò níwájú Filistini.
Był on z Dawidem w Pas-Dammim, gdzie Filistyni zebrali się do walki. Było tam pole pełne jęczmienia, a lud uciekał przed Filistynami.
14 Ṣùgbọ́n wọ́n mú ìdúró wọn ní àárín pápá náà. Wọ́n sì gbà a wọ́n sì gún àwọn ará Filistini mọ́lẹ̀, Olúwa sì mú ìgbàlà ńlá fún wọn.
I stanęli na środku tego pola, obronili je i pobili Filistynów. Tak dokonał PAN wielkiego wybawienia.
15 Mẹ́ta nínú àwọn ọgbọ̀n ìjòyè sọ̀kalẹ̀ tọ́ Dafidi wá lọ sí orí àpáta nínú ihò Adullamu, nígbà tí àwọn ẹgbẹ́ Filistini sì dúró ní àfonífojì ní orí òkè Refaimu.
A trzej spośród trzydziestu dowódców zeszli po skale do Dawida, do jaskini Adullam, podczas gdy wojsko Filistynów obozowało w dolinie Rafaim.
16 Ní àsìkò náà Dafidi sì ń bẹ nínú ìlú odi, ẹgbẹ́ ogun àwọn ará Filistini sì ń bẹ ní Bẹtilẹhẹmu.
Dawid bowiem [przebywał] w tym czasie w miejscu obronnym, a załoga Filistynów [znajdowała się] wtedy w Betlejem.
17 Dafidi sí pòǹgbẹ fún omi ó sì wí pé, “Háà, ẹnìkan yóò ha bu omi láti inú kànga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-bodè Bẹtilẹhẹmu fún un mu?”
Dawid poczuł wówczas pragnienie i powiedział: Oby ktoś dał mi się napić wody ze studni w Betlejem, która jest przy bramie!
18 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn mẹ́ta náà sì là láti ogun ará Filistini, ó sì fa omi jáde láti inú kànga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-bodè Bẹtilẹhẹmu ó sì gbé padà tọ Dafidi wá. Ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti mu ú: dípò, ó sì tú jáde níwájú Olúwa.
Wtedy ci trzej przebili się przez wojsko Filistynów i zaczerpnęli wody ze studni w Betlejem, która jest przy bramie. Zabrali ją i przynieśli do Dawida. Dawid jednak nie chciał jej pić, ale wylał ją [na ofiarę] dla PANA.
19 “Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí èmi ó má ṣe ṣe èyí!” ó wí pé. “Ṣé kí èmi kí ó mú ẹ̀jẹ̀ ọkùnrin yí ẹni tí ó fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu?” Nítorí wọ́n fi ẹ̀mí wọn wéwu láti mú padà wá, Dafidi kò ní mu ú. Nǹkan wọ̀nyí ni àwọn akọni mẹ́ta ọkùnrin náà ṣe ohun ìyanu ńlá.
I powiedział: Niech PAN mnie strzeże [od tego], abym miał to uczynić. Czy mam pić krew tych ludzi, którzy narażali swoje życie? Przynieśli bowiem [wodę] z narażeniem swego życia. I nie chciał jej pić. Tych [dzieł] dokonali ci trzej najdzielniejsi.
20 Abiṣai arákùnrin Joabu ìjòyè àwọn mẹ́ta. Ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè lórí àwọn ọ̀ọ́dúnrún àwọn ènìyàn, àwọn ẹni tí ó pa, bẹ́ẹ̀ ni ó sì di olókìkí gẹ́gẹ́ bí àwọn mẹ́ta.
A Abiszaj, brat Joaba, stał na czele tych trzech. On to podniósł swoją włócznię przeciw trzystu i pobił [ich], i miał sławę wśród tych trzech.
21 Ó sì gba ìlọ́po ọlá lórí àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta ó sì di olórí wọn, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a kò ka kún ara wọn.
Wśród tych trzech był on sławniejszy od pozostałych dwóch i był ich dowódcą. Nie dorównał jednak [tamtym] trzem.
22 Benaiah ọmọ Jehoiada ó sì jẹ́ akọni oníjà láti Kabṣeeli, ẹni tí ó ṣe iṣẹ́ agbára ńlá. Ó sì pa àwọn ọmọ Arieli méjì ti Moabu, ó sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí inú ihò lákokò yìnyín dídì, ó sì pa kìnnìún kan
Benajasz, syn Jehojady, syn walecznego męża z Kabseela, który dokonał wielu czynów, zabił dwóch wojowników z Moabu. On też zszedł do jamy i zabił lwa w śnieżnym dniu.
23 Ó sì pa ara Ejibiti ẹni tí ó ga ní ìwọ̀n ẹsẹ̀ méje àti ààbọ̀ ṣùgbọ́n àwọn ará Ejibiti wọn ní ọ̀kọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìdábùú igi ahunṣọ àti ọ̀pá ní ọwọ́ rẹ̀, Benaiah sọ̀kalẹ̀ lórí rẹ̀ pẹ̀lú kùmọ̀. Ó sì gba ọ̀kọ̀ náà láti ọwọ́ ará Ejibiti ó sì pa á pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀.
Zabił również Egipcjanina, człowieka o wzroście pięciu łokci. Egipcjanin miał w ręku włócznię, [grubą] jak wał tkacki. On zaś zszedł do niego z kijem, wyrwał włócznię z ręki Egipcjanina i zabił go jego własną włócznią.
24 Nǹkan wọ̀nyí sì ní ìwà akin Benaiah ọmọ Jehoiada; ohun náà pẹ̀lú sì di olókìkí gẹ́gẹ́ bí àwọn akọni ọkùnrin mẹ́ta.
Tego dokonał Benajasz, syn Jehojady, i miał sławę wśród tych trzech dzielnych.
25 Ó sì ní ọlá púpọ̀ ju àwọn ọgbọ̀n lọ, ṣùgbọ́n a kò kà á láàrín àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta. Dafidi sì fi sí ìkáwọ́ àwọn ẹ̀ṣọ́.
Wśród trzydziestu był on sławny, ale nie dorównał tamtym trzem. I Dawid postawił go na czele swojej straży przybocznej.
26 Àwọn akọni ọkùnrin náà nìyí: Asaheli arákùnrin Joabu, Elhanani ọmọ Dodo láti Bẹtilẹhẹmu,
Dzielnymi wojownikami wojska [byli]: Asahel, brat Joaba, Elchanan, syn Dodo z Betlejem;
27 Ṣamotu ará Harori, Helesi ará Peloni
Szammot z Harodi, Cheles Pelonita;
28 Ira ọmọ Ikẹsi láti Tekoa, Abieseri láti Anatoti,
Ira, syn Ikkesza, Tekoitczyk, Abiezer Anatotczyk;
29 Sibekai ará Huṣati, láti ará Ahohi
Sibbekaj Chuszatyta, Ilaj Achochita;
30 Maharai ará Netofa, Heledi ọmọ Baanah ará Netofa,
Maharaj Netofatyta, Cheled, syn Baany, Netofatyta;
31 Itai ọmọ Ribai láti Gibeah ní Benjamini, Benaiah ará Piratoni,
Itaj, syn Ribaja, z Gibea synów Beniamina, Benajasz Piratończyk;
32 Hurai láti àfonífojì Gaaṣi, Abieli ará Arbati,
Churaj z potoków Gaasz, Abiel Arbatczyk;
33 Asmafeti ará Bahurimu Eliaba ará Ṣaalboni.
Azmawet Bacharumczyk, Eliachba Szaalbończyk;
34 Àwọn ọmọ Haṣemu ará Gisoni Jonatani ọmọ Ṣage ará Harari.
Synowie Chaszema Gisończyka, Jonatan, syn Szagiego, Hararyta;
35 Ahiamu ọmọ Sakari ará Harari, Elifali ọmọ Uri
Achiam, syn Sakara, Hararyta, Elifal, syn Ura;
36 Heferi ará Mekerati, Ahijah ará Peloni,
Chefer Mekeratyta, Achiasz Pelonita;
37 Hesro ará Karmeli Naarai ọmọ Esbai,
Chesro Karmelita, Naaraj, syn Ezbaja;
38 Joẹli arákùnrin Natani Mibari ọmọ Hagari,
Joel, brat Natana, Mibchar, syn Hagriego;
39 Seleki ará Ammoni, Naharai ará Beroti ẹni tí ó jẹ́ ẹni tí n ru ìhámọ́ra Joabu ọmọ Seruiah.
Selek Ammonita, Nacharaj Berotczyk, giermek Joaba, syna Serui;
40 Ira ará Itri, Garebu ará Itri,
Ira Jitryta, Gareb Jitryta;
41 Uriah ará Hiti Sabadi ọmọ Ahlai.
Uriasz Chetyta, Zabad, syn Achlaja;
42 Adina ọmọ Ṣisa ará Reubeni, ẹni tí ó jẹ́ ìjòyè ará Reubeni, àti pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀.
Adina, syn Szizy, Rubenita, naczelnik Rubenitów, a wraz z nim trzydziestu;
43 Hanani ọmọ Maaka. Jehoṣafati ará Mitini.
Chanan, syn Maaki, Joszafat Mitnita;
44 Ussia ará Asiterati, Ṣama àti Jeieli àwọn ọmọ Hotami ará Aroeri,
Uziasz Aszteratczyk, Szama i Jejel, synowie Chotamy Aroerczyka;
45 Jediaeli ọmọ Ṣimri, àti arákùnrin Joha ará Tisi
Jediael, syn Szimriego, i jego brat Jocha, Tizyta;
46 Elieli ará Mahafi Jeribai àti Joṣafia àwọn ọmọ Elnaamu, Itimah ará Moabu,
Eliel Machawita, Jeribaj i Joszawiasz, synowie Elnaama, Jitma Moabita;
47 Elieli, Obedi àti Jaasieli ará Mesoba.
Eliel, Obed i Jaasiel Mezobata.

< 1 Chronicles 11 >