< 1 Chronicles 10 >

1 Nísinsin yìí, àwọn ará Filistini dojú ìjà kọ Israẹli, àwọn ará Israẹli sì sálọ kúrò níwájú wọn, a sì pa ọ̀pọ̀ wọn sí orí òkè Gilboa.
Gdy Filistyni walczyli z Izraelem, Izraelici uciekli przed nimi i padli zabici na górze Gilboa.
2 Àwọn ará Filistini sí lépa Saulu gidigidi àti àwọn ọmọ rẹ̀. Wọ́n sì pa àwọn ọmọ rẹ̀. Jonatani, Abinadabu àti Malikiṣua.
I Filistyni ścigali Saula i jego synów, i zabili Jonatana, Abinadaba i Malkiszuę, synów Saula.
3 Ogun náà sí gbóná janjan fún Saulu, nígbà tí àwọn tafàtafà sì lé e bá, wọ́n sì ṣá a lọ́gbẹ́.
A gdy rozgorzała bitwa przeciw Saulowi, łucznicy trafili w niego i został przez nich ciężko zraniony.
4 Saulu sì sọ fún ẹni tí ó gbé ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Fa idà rẹ yọ, kí o sì fi gún mi, kí àwọn aláìkọlà wọ̀nyí má wá láti bú mi.” Ṣùgbọ́n ẹni tí ó ń gbé ìhámọ́ra rẹ̀ ń bẹ̀rù, kò sì le ṣe é, bẹ́ẹ̀ ni Saulu mú idà tirẹ̀ ó sì ṣubú lé e.
Wtedy Saul powiedział do swego giermka: Dobądź swój miecz i przebij mnie nim, aby nie przyszli ci nieobrzezani i nie znęcali się nade mną. Ale jego giermek nie chciał [tego zrobić], ponieważ bardzo się bał. Saul więc wziął miecz i sam rzucił się na niego.
5 Nígbà tí agbé-ìhámọ́ra rí pé Saulu ti kú, òhun pẹ̀lú ṣubú lórí idà tirẹ̀, ó sì kú.
A gdy jego giermek zobaczył, że Saul umarł, rzucił się i on na swój miecz i umarł.
6 Bẹ́ẹ̀ ni Saulu àti ọmọ rẹ̀ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta kú, gbogbo ilé rẹ̀ sì kú ṣọ̀kan, lọ́jọ́ kan náà.
Tak umarli Saul i jego trzej synowie, a cały jego dom zginął razem z nim.
7 Nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ rí wí pé àwọn ọmọ-ogun ti sálọ àti pé Saulu àti àwọn ọmọ rẹ̀ ti kú wọ́n kọ àwọn ìlú wọn sílẹ̀, wọ́n sì sálọ. Àwọn ará Filistini wá, wọ́n sì jókòó nínú wọn.
A gdy wszyscy Izraelici, którzy [mieszkali] w dolinie, zobaczyli, że [Izraelici] uciekli oraz że Saul i jego synowie umarli, opuścili swoje miasta i uciekli. Przyszli więc Filistyni i mieszkali w nich.
8 Ní ọjọ́ kejì, nígbà tí àwọn ará Filistini wá láti kó òkú, wọ́n rí Saulu àti àwọn ọmọ rẹ̀ tí wọ́n ṣubú sórí òkè Gilboa.
Kiedy nazajutrz Filistyni przyszli, aby złupić zabitych, znaleźli Saula i jego synów poległych na górze Gilboa.
9 Wọ́n bọ́ ní aṣọ, wọ́n sì gbé orí rẹ̀ àti ìhámọ́ra rẹ̀, wọ́n sì rán ìránṣẹ́ lọ káàkiri ilẹ̀ àwọn ará Filistini láti kéde ìròyìn náà láàrín àwọn òrìṣà wọn àti àwọn ènìyàn wọn.
Obdarli go więc [z szat], wzięli jego głowę i zbroję i rozesłali po całej ziemi filistyńskiej, aby ogłosić radosną wieść swoim bożkom i swojemu ludowi.
10 Wọ́n gbé ìhámọ́ra rẹ̀ sí inú ilé tí wọ́n kọ́ fún òrìṣà wọn, wọ́n sì fi orí rẹ̀ kọ́ sí inú ilé Dagoni.
Jego zbroję położyli w domu swoich bogów, a jego głowę powiesili w świątyni Dagona.
11 Nígbà tí gbogbo àwọn olùgbé Jabesi—Gileadi gbọ́ gbogbo ohun tí àwọn ará Filistini ṣe fún Saulu,
Kiedy wszyscy mieszkańcy Jabesz-Gilead usłyszeli o wszystkim, co Filistyni uczynili Saulowi;
12 gbogbo àwọn akọni ọkùnrin wọn lọ láti mú àwọn ará Saulu àti àwọn ọmọ rẹ̀, wọ́n sì kó wọn wá sí Jabesi. Nígbà náà, wọ́n sin egungun wọn sábẹ́ igi óákù ní Jabesi, wọ́n sì gbààwẹ̀ fún ọjọ́ méje.
Powstali wszyscy waleczni mężczyźni, wzięli ciało Saula oraz ciała jego synów, przynieśli [je] do Jabesz i pogrzebali ich kości pod dębem w Jabesz. Potem pościli przez siedem dni.
13 Saulu kú nítorí kò ṣe òtítọ́ sí Olúwa, kò pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́ pẹ̀lú, ó tọ abókùúsọ̀rọ̀ lọ fún ìtọ́sọ́nà.
Tak umarł Saul z powodu swojego przestępstwa, które popełnił przeciwko PANU i przeciwko słowu PANA, którego nie przestrzegał, oraz za to, że szukał rady czarownika;
14 Kò sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa pa á, Ó sì yí ìjọba náà padà sọ́dọ̀ Dafidi ọmọ Jese.
A nie radził się PANA. [PAN] zabił go więc i przeniósł królestwo na Dawida, syna Jessego.

< 1 Chronicles 10 >