< Samu'il 1 4 >

1 U waⱪitta Israil Filistiylǝr bilǝn jǝng ⱪilƣili qiⱪip Əbǝn-Əzǝrgǝ yeⱪin jayda bargaⱨ-qedirlarni tikti. Filistiylǝr bolsa Afǝk degǝn jayda bargaⱨ-qedirlarni tikti.
Ọ̀rọ̀ Samuẹli tọ gbogbo àwọn ọmọ Israẹli wá. Nísinsin yìí àwọn ọmọ Israẹli jáde láti lọ bá àwọn Filistini jà. Àwọn ọmọ Israẹli sì pàgọ́ sí Ebeneseri àti àwọn Filistini ní Afeki.
2 Filistiylǝr Israillar bilǝn soⱪuxⱪili sǝp tizip turdi. Jǝng kengǝygǝndǝ Israil Filistiylǝr aldida tarmar boldi; Filistiylǝr ularning jǝng sǝpliridin tɵt mingqǝ adǝmni ɵltürdi.
Àwọn Filistini mú ogun wọn sọ̀kalẹ̀ láti pàdé Israẹli, nígbà tí ogun náà bẹ̀rẹ̀, àwọn Filistini ṣẹ́gun Israẹli wọ́n pa ẹgbàajì ọkùnrin nínú ogun náà.
3 Halayiⱪ bargaⱨⱪa yenip kǝlgǝndǝ, Israilning aⱪsaⱪalliri: — Nemixⱪa Pǝrwǝrdigar bügün bizni Filistiylǝr tǝripidin tarmar ⱪildurdi? Biz Xiloⱨdin Pǝrwǝrdigarning ǝⱨdǝ sanduⱪini ⱪeximizƣa elip kelǝyli; u arimizda bolsa, bizni düxminimizning ⱪolidin ⱪutⱪuzidu, dedi.
Nígbà tí àwọn ọmọ-ogun náà padà sí ibùdó, àwọn àgbàgbà Israẹli sì béèrè pé, “Èéṣe ti Olúwa fi mú kí àwọn Filistini ṣẹ́gun wa lónìí? Ẹ jẹ́ kí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa láti Ṣilo wá, kí ó ba à le lọ pẹ̀lú wa kí ó sì gbà wá là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa.”
4 Xu gǝptin keyin halayiⱪ Xiloⱨƣa adǝm mangdurup, xu yǝrdin kerublarning otturisida olturƣan samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari Pǝrwǝrdigarning ǝⱨdǝ sanduⱪini elip kɵtürüp kǝldi. Xuningdǝk Əlining ikki oƣli Hofniy bilǝn Finiⱨasmu Hudaning ǝⱨdǝ sanduⱪi bilǝn billǝ kǝldi.
Nítorí náà a rán àwọn ènìyàn lọ sí Ṣilo, wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wá, ẹni tí ń wà láàrín àwọn Kérúbù àti àwọn ọmọ Eli méjèèjì Hofini àti Finehasi wà níbẹ̀ pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run.
5 Wǝ xundaⱪ boldiki, Pǝrwǝrdigarning ǝⱨdǝ sanduⱪi lǝxkǝrgaⱨⱪa elip kelingǝndǝ pütkül Israil yǝrni tǝwrǝtküdǝk küqlük bir quⱪan kɵtürüxti.
Nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ibùdó, gbogbo àwọn ọmọ Israẹli sì dìde láti kígbe tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ sì mì tìtì.
6 Filistiylǝr küqlük tǝntǝnǝ awazini anglap: — Ibraniylarning lǝxkǝrgaⱨidin anglanƣan bu küqlük quⱪan nemǝ wǝjidin qiⱪⱪandu, dǝp eytixti. Arⱪidinla ular Pǝrwǝrdigarning ǝⱨdǝ sanduⱪining ularning lǝxkǝrgaⱨiƣa kǝltürülginini bilip yǝtti.
Ní ìgbà tí àwọn Filistini gbọ́ ariwo náà wọ́n béèrè pé, “Kí ni gbogbo ariwo yìí ní ibùdó Heberu?” Nígbà tí wọ́n mọ̀ wí pé àpótí ẹ̀rí Olúwa ti wá sí ibùdó,
7 Xuning bilǝn Filistiylǝr ⱪorⱪup: — Ilaⱨlar ularning lǝxkǝrgaⱨiƣa kǝptu, ⱨalimizƣa way! Mundaⱪ ix bu waⱪitⱪiqǝ ⱨeq bolƣan ǝmǝs, deyixti.
àwọn Filistini sì bẹ̀rù pé, Ọlọ́run kékeré ti wọ ibùdó, wọ́n wí pé, “A wọ wàhálà, irú èyí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí.
8 Ⱨalimizƣa way! Bizni bu ⱪudrǝtlik ilaⱨlarning ⱪolidin kim ⱪutⱪuzidu? Mana bayawanda misirliⱪlarni türlük bala-wabalar bilǝn urƣan ilaⱨlar dǝl xulardur!
Àwa gbé! Ta ni yóò gbà wá kúrò lọ́wọ́ Ọlọ́run alágbára yìí? Àwọn ni Ọlọ́run tí ó fi ìpọ́njú pa àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo àjàkálẹ̀-ààrùn ní aginjù.
9 I Filistiylǝr, ɵzliringlarni jǝsur kɵrsitip ǝrkǝktǝk turunglar. Bolmisa, ibraniylar bizgǝ ⱪul bolƣandǝk biz ularƣa ⱪul bolimiz; ǝrkǝktǝk bolup jǝng ⱪilinglar! — dedi.
Ẹ jẹ́ alágbára Filistini, ẹ ṣe bí ọkùnrin, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ̀yin yóò di ẹrú àwọn Heberu, bí wọ́n ti jẹ́ sí i yín. Ẹ jẹ́ alágbára ọkùnrin, kí ẹ sì jagun!”
10 Xuning bilǝn Filistiylǝr Israillar bilǝn jǝng ⱪildi. Israil tarmar ⱪilinip, ⱨǝrbiri tǝrǝp-tǝrǝpkǝ ɵz qedirigǝ bǝdǝr ⱪaqti. Jǝngdǝ ⱪattiⱪ ⱪirƣinqiliⱪ bolup, Israildin ottuz ming piyadǝ ǝskǝr ɵltürüldi.
Nígbà náà àwọn Filistini jà, wọ́n sì ṣẹ́gun àwọn Israẹli olúkúlùkù sì sá padà sínú àgọ́ rẹ̀, wọ́n pa ọ̀pọ̀ ènìyàn, àwọn ará Israẹli tí ó kú sí ogun sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọmọ-ogun orí ilẹ̀.
11 Pǝrwǝrdigarning ǝⱨdǝ sanduⱪi olja bolup kǝtti wǝ Əlining ikki oƣli Hofniy bilǝn Finiⱨasmu ɵltürüldi.
Wọ́n gba àpótí ẹ̀rí Olúwa, àwọn ọmọkùnrin Eli méjèèjì sì kú, Hofini àti Finehasi.
12 Xu küni bir Binyaminliⱪ jǝng mǝydanidin ⱪeqip kiyim-keqǝkliri yirtiⱪ, üstibexi topa-qang ⱨalda Xiloⱨƣa yügürüp kǝldi.
Lọ́jọ́ kan náà tí ará Benjamini kan sá wá láti ojú ogun tí ó sì lọ sí Ṣilo, aṣọ rẹ̀ sì fàya pẹ̀lú eruku lórí rẹ̀.
13 U yetip kǝlgǝndǝ, mana Əli yolning qetidǝ ɵz orunduⱪida olturup taⱪiti-taⱪ bolup kütüwatatti; uning kɵngli Pǝrwǝrdigarning ǝⱨdǝ sanduⱪining ƣemidǝ pǝrixan idi. U kixi hǝwǝrni yǝtküzgili xǝⱨǝrgǝ kirgǝndǝ, pütkül xǝⱨǝr pǝryad-quⱪan kɵtürdi.
Nígbà tí ó sì dé, Eli sì jókòó sórí àga rẹ̀ ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà, ó ń wò, ọkàn rẹ̀ kò balẹ̀ nítorí àpótí ẹ̀rí Olúwa. Nígbà tí ọkùnrin náà wọ ìlú tí ó sì sọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀, gbogbo ìlú bẹ̀rẹ̀ sí sọkún.
14 Əli pǝryad sadasini anglap: — Bu zadi nemǝ warang-qurung? dǝp soridi. U kixi aldirap kelip ǝligǝ hǝwǝr bǝrdi
Eli gbọ́ ìró ohùn ẹkún náà ó sì béèrè pé, “Kí ni ìtumọ̀ ariwo yìí?” Ọkùnrin náà sì sáré tọ Eli wá
15 (Əli toⱪsan sǝkkiz yaxⱪa kirgǝn, kɵzliri ⱪetip ⱪalƣan bolup, kɵrmǝytti).
Eli sì di ẹni méjìdínlọ́gọ́run ọdún, tí ojú rẹ̀ di bàìbàì, kò sì ríran mọ́.
16 U kixi Əligǝ: — Mǝn jǝngdin ⱪaytip kǝlgǝn kiximǝn, bügün jǝng mǝydanidin ⱪeqip kǝldim, dedi. Əli: — I oƣlum, nemǝ ix yüz bǝrdi? — dǝp soridi.
Ọkùnrin náà sọ fún Eli, “Mo ṣẹ̀ṣẹ̀ dé láti ibi ogun náà ni: mo sá láti ibi ogun náà wá lónìí.” Eli sì béèrè pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀ ọmọ mi?”
17 Hǝwǝrqi jawab berip: — Israil Filistiylǝrning aldidin bǝdǝr ⱪaqti. Hǝlⱪ arisida ⱪattiⱪ ⱪirƣinqiliⱪ boldi! Sening ikki oƣlung, Hofniy bilǝn Finiⱨasmu ɵldi ⱨǝmdǝ Hudaning ǝⱨdǝ sanduⱪimu olja bolup kǝtti, dedi.
Ọkùnrin tí ó mú ìròyìn náà wá dáhùn pé, “Israẹli sá níwájú àwọn Filistini, ìṣubú àwọn ọmọ-ogun náà sì pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ méjèèjì, Hofini àti Finehasi, wọ́n kú, wọ́n sì ti gba àpótí ẹ̀rí Olúwa lọ.”
18 Wǝ xundaⱪ boldiki, hǝwǝrqi Hudaning ǝⱨdǝ sanduⱪini tilƣa alƣanda, Əli dǝrwazining yenidiki orunduⱪtin kǝynigǝ yiⱪilip qüxüp, boyni sunup ɵldi; qünki u ⱪerip, bǝdinimu eƣirlixip kǝtkǝnidi. U ⱪiriⱪ yil Israilning ⱨakimi bolƣanidi.
Nígbà tí ó dárúkọ àpótí ẹ̀rí Olúwa, Eli sì ṣubú sẹ́yìn kúrò lórí àga ní ẹ̀gbẹ́ bodè, ọrùn rẹ̀ ṣẹ́, ó sì kú, nítorí tí ó jẹ́ arúgbó ọkùnrin, ó sì tóbi, ó ti darí àwọn Israẹli fún ogójì ọdún.
19 Uning kelini, yǝni Finiⱨasning ayali ⱨamilidar bolup tuƣuxⱪa az ⱪalƣanidi. U Hudaning ǝⱨdǝ sanduⱪining olja bolup kǝtkǝnliki wǝ ⱪiyinatisi bilǝn eriningmu ɵlgǝnlik hǝwirini angliƣanda, birdinla ⱪattiⱪ tolƣaⱪ tutup, pükülüp balini tuƣdi.
Aya ọmọ rẹ̀, ìyàwó Finehasi, ó lóyún ó súnmọ́ àkókò àti bí. Nígbà tí ó gbọ́ ìròyìn náà wí pé wọ́n ti gba àpótí ẹ̀rí Olúwa lọ àti wí pé baba ọkọ rẹ̀ àti ọkọ rẹ̀ ti kú, ó rọbí ó sì bímọ, ó sì borí ìrora ìrọbí náà.
20 U ɵlǝy dǝp ⱪalƣanda, qɵrisidǝ turƣan ayallar: — Ⱪorⱪmiƣin, sǝn oƣul bala tuƣdung, dedi. Lekin u buningƣa jawabmu bǝrmidi ⱨǝm kɵngül bɵlmidi.
Bí ó ti ń kú lọ, obìnrin tí ó dúró tì í wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù; nítorí o ti bí ọmọ ọkùnrin.” Ṣùgbọ́n kò sọ̀rọ̀ tàbí kọ ibi ara sí i.
21 U: «Xan-xǝrǝp Israildin kǝtti» dǝp baliƣa «Ihabod» dǝp isim ⱪoydi; qünki Hudaning ǝⱨdǝ sanduⱪi olja bolup kǝtkǝn ⱨǝm ⱪeyinatisi bilǝn erimu ɵlgǝnidi.
Ó sì pe ọmọ náà ní Ikabodu, wí pé, “Kò sí ògo fún Israẹli mọ́,” nítorí tí wọ́n ti gba àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run àti ikú baba ọkọ rẹ̀ àti ti ọkọ rẹ̀.
22 U yǝnǝ: — Xan-xǝrǝp Israildin kǝtti; qünki Hudaning ǝⱨdǝ sanduⱪi olja bolup kǝtti! — dedi.
Ó si wí pé, “Ògo kò sí fún Israẹli mọ́, nítorí ti a ti gbá àpótí Ọlọ́run.”

< Samu'il 1 4 >