< Yeremiya 9 >

1 Ah, méning béshim suning béshi, Közüm yashning buliqi bolsiidi! Undaqta xelqimning qizi arisidiki öltürülgenler üchün kéche-kündüz yighlayttim!
Háà! Orí ìbá jẹ́ orísun omi kí ojú mi sì jẹ́ orísun omijé! Èmi yóò sì sọkún tọ̀sán tòru nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.
2 Ah, men üchün chöl-bayawanda yoluchilar chüshkidek bir turalghu bolsiidi! Undaqta xelqimni tashlap, ulardin ayrilghan bolattim! Chünki ularning hemmisi zinaxorlar, Munapiqlarning bir jamaitidur!»
Háà, èmi ìbá ní ni aginjù ilé àgbàwọ̀ fún àwọn arìnrìn-àjò, kí n ba à lè fi àwọn ènìyàn mi sílẹ̀ kí n sì lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn: nítorí gbogbo wọn jẹ́ panṣágà àjọ aláìṣòótọ́ ènìyàn.
3 — Ular oqyachi leshkerler oqyayini égildürgendek tilini yalghanchiliqqa égildürüshke teyyarlighan; ular zéminda üstünlük qazan’ghan, biraq bu semimiylik bilen bolghan emes; ular rezillik üstige rezillik qilghan, Méni héch tonup bilmigen» — deydu Perwerdigar.
Wọ́n ti pèsè ahọ́n wọn sílẹ̀ bí ọfà láti fi pa irọ́; kì í ṣe nípa òtítọ́ ni wọ́n fi borí ní ilẹ̀ náà. Wọ́n ń lọ láti inú ẹ̀ṣẹ̀ kan sí òmíràn; wọn kò sì náání mi, ní Olúwa wí.
4 — Herbiringlar öz yéqininglardin hézi bolunglar, qérindashliringlargha héch tayanmanglar; chünki herbir qérindash peqetla aldighuchi, xalas, herbir yéqinliring bolsa töhmetxorluqta yürmekte.
“Ṣọ́ra fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ; má ṣe gbẹ́kẹ̀lé àwọn arákùnrin rẹ. Nítorí pé oníkálùkù arákùnrin jẹ́ atannijẹ, oníkálùkù ọ̀rẹ́ sì jẹ́ abanijẹ́.
5 Ular herbiri öz yéqinlirigha aldamchiliq qilmaqta, héchkim heqiqetni sözlimeydu; ular öz tilini yalghan sözleshke ögitidu, ular qebihlikte özlirini upritidu.
Ọ̀rẹ́ ń dalẹ̀ ọ̀rẹ́. Kò sì ṣí ẹni tó sọ òtítọ́, wọ́n ti kọ́ ahọ́n wọn láti máa purọ́. Wọ́n sọ ara wọn di onírẹ̀wẹ̀sì pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀
6 Ular jebir-zulum üstige jebir-zulum qilmaqta, aldamchiliqtin yene bir aldamchiliqqa ötmekte; ular Méni tonushni ret qilidu, — deydu Perwerdigar.
Ó ń gbé ní àárín ẹ̀tàn; wọ́n kọ̀ láti mọ̀ mí nínú ẹ̀tàn wọn,” ni Olúwa wí.
7 Shunga samawi qoshunlarning Serdari bolghan Perwerdigar mundaq deydu: — Mana, Men ularni éritip tawlap sinaymen; xelqimning qizining rezillikige Manga bashqa yol qalmidimu?
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí: “Wò ó, èmi dán wọn wo; nítorí pé kí ni èmi tún le è ṣe? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi?
8 Ularning tili ejel oqidur; u aldamchiliqni sözleydu; herbir éghiz sözide yéqini bilen tinch-amanliqni sözleydu, lékin könglide qiltaq teyyarlaydu.
Ahọ́n wọn dàbí ọfà olóró; ó ń sọ ẹ̀tàn. Oníkálùkù sì ń fi ẹnu rẹ̀ sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí aládùúgbò rẹ̀, ní inú ọkàn rẹ̀, ó dẹ tàkúté sílẹ̀.
9 Bu ishlar tüpeylidin ularni jazalimay qoyamdim? — deydu Perwerdigar, — Méning jénim mushundaq bir eldin qisas almay qoyamdu?
Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n nítorí èyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò ha gbẹ̀san ara mi lórí irú orílẹ̀-èdè yìí bí?”
10 «Taghlardiki yaylaqlar üchün yigha we nale-peryad kötürimen, Daladiki otlaqlar üchün mersiye oquymen; Chünki ular köyüp kettiki, héchkim u yerdin ötmeydu; Kalilarning hörkireshliri anglanmaydu; Hem asmandiki uchar-qanatlar hem haywanatlarmu qéchip, Shu yerdin ketti!».
Èmi yóò sì sọkún, pohùnréré ẹkún fún àwọn òkè àti ẹkún ìrora lórí pápá oko aginjù wọ̀n-ọn-nì. Nítorí wọ́n di ahoro, wọn kò sì kọjá ní ibẹ̀. A kò sì gbọ́ igbe ẹran ọ̀sìn. Àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ti sálọ, bẹ́ẹ̀ náà ni àwọn ẹranko sì ti lọ.
11 — Men Yérusalémni xarablashqan top-top döwe, chilbörilerning bir turalghusi qilimen; Yehuda sheherlirini adem turmaydighan derijide wayrane qilimen.
“Èmi yóò sì sọ Jerusalẹmu di òkìtì àlàpà àti ihò àwọn ìkookò. Èmi ó sì sọ ìlú Juda di ahoro tí ẹnikẹ́ni kò sì ní le è gbé.”
12 — Kim bu ishlarni chüshinishke danishmen bolidu? Kim Perwerdigarning aghzidin söz élip bularni chüshendüreleydu? Némishqa zémin weyrane, héchkim ötmigüdek, köyüp chöl-bayawandek bolup ketti?
Ta ni ẹni náà tí ó ní ọgbọ́n láti mòye nǹkan wọ̀nyí? Ta ni Olúwa ti sọ èyí fún, tí ó sì lè ṣàlàyé rẹ̀? Èéṣe tí ilẹ̀ náà fi ṣègbé bí aginjù, tí ẹnìkankan kò sì le là á kọjá?
13 Perwerdigar deydu, — Chünki ular Men ular aldigha qoyghan Tewrat-qanunni tashliwetken, Méning awazimgha qulaq salmighan we uningda mangmighan,
Olúwa sì wí pé, nítorí pé wọ́n ti kọ òfin mi sílẹ̀, èyí tí mo gbé kalẹ̀ níwájú wọn, wọn ṣe àìgbọ́ràn sí wọn, wọn kò sì rìn nínú òfin mi.
14 Belki öz qelbidiki jahilliqqa egeshken, ata-bowiliri ulargha ögetkendek Baallarning keynige egiship ketken,
Dípò èyí, wọ́n ti tẹ̀lé agídí ọkàn wọn, wọ́n ti tẹ̀lé Baali gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe kọ́ wọn.
15 Shunga samawi qoshunlarning Serdari bolghan Perwerdigar, Israilning Xudasi mundaq deydu: — Mana, Men bu xelqqe kekrini yégüzimen, ulargha öt süyini ichküzimen,
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, “Wò ó, Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí jẹ oúnjẹ kíkorò àti láti mu omi májèlé.
16 ularni ular yaki ata-bowiliri ilgiri héch tonumaydighan eller arisigha tarqitimen; Men ularni yoqatquche ularning keynidin qoghlashqa qilichni ewetimen.
Èmi yóò sì tú wọn ká láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, nínú èyí tí àwọn tàbí àwọn baba wọn kò mọ̀. Èmi yóò sì lépa wọn pẹ̀lú idà títí èmi yóò fi pa wọ́n run.”
17 Samawi qoshunlarning Serdari bolghan Perwerdigar mundaq deydu: — Köngül qoyunglar, matemchi ayallarni kélishke chaqiringlar, yighlashqa eng usta bolghan qiz-ayallarni chaqirip kélishke adem ewetinglar!
Èyí sì ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí: “Sá à wò ó nísinsin yìí! Ké sí obìnrin ti ń ṣọ̀fọ̀ nì kí ó wá; sì ránṣẹ́ pe àwọn tí ó mòye nínú wọn.
18 — Berheq, ular téz kelsun, biz üchün zor yigha kötürsunki, bizning közlirimizdinmu yashlar taramlap tökülsun, chanaqlirimizdinmu yash tamchiliri aqsun —
Jẹ́ kí wọn wá kíákíá, kí wọn wá pohùnréré ẹkún lé wa lórí títí ojú wa yóò fi sàn fún omijé tí omi yóò sì máa sàn àwọn ìpéǹpéjú wa.
19 chünki Ziondin yigha awazi anglinip: — «Biz qanchilik bulang-talang qilinduq! Qanchilik shermende bolduq! Ular turalghulirimizni örüwetti, biz zéminimizni tashliduq!» — déyilidu.
A gbọ́ igbe ìpohùnréré ẹkún ní Sioni: ‘Àwa ti ṣègbé tó! A gbọdọ̀ fi ilẹ̀ wa sílẹ̀, nítorí pé àwọn ilé wa ti parun.’”
20 Perwerdigarning sözini anglanglar, i ayallar, Uning aghzidiki sözge qulaq sélinglar; Qizinglargha yighlashni ögitinglar, Herbiringlar yéqininglargha mersiye oqutunglar;
Nísinsin yìí, ẹ̀yin obìnrin ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa; ṣí etí yín sí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ. Kọ́ àwọn ọmọbìnrin yín ní ìpohùnréré ẹkún, kí ẹ sì kọ́ ara yín ní arò.
21 Chünki ölüm bolsa dérizilirimizdin yamiship kirgen, Orda-istihkamlirimizghimu kirgen; U balilarni kochilardin, Yigitlerni reste-meydanlardin yulup tashlighan.
Ikú ti gba ojú fèrèsé wa wọlé ó sì ti wọ odi alágbára wa ó ti ké àwọn ọmọ kúrò ní àdúgbò àti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò ní gbọ̀ngàn ìta gbangba.
22 [Yéqinliringlargha] uqturup: «Perwerdigar mundaq deydu: — Berheq, jesetler dalada tézektek yiqilidu; Ular ormichining orghiqining astigha yiqilghan, Lékin héchkim yighmaydighan bashaqtek yerge chéchilidu!» — denglar!
Sọ pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Òkú àwọn ènìyàn yóò ṣubú bí ààtàn ní oko gbangba àti bí ìbùkúnwọ́ lẹ́yìn olùkórè láìsí ẹnìkankan láti kó wọn jọ.’”
23 Perwerdigar mundaq deydu: — Dana kishi danaliqi bilen, küchlük kishi küchlükliki bilen, bay bayliqliri bilen pexirlinip maxtanmisun;
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Má ṣe jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n yangàn nítorí agbára ọgbọ́n rẹ̀, tàbí alágbára nítorí agbára rẹ̀, tàbí ọlọ́rọ̀ nítorí ọrọ̀ rẹ̀.
24 pexirlinip maxtighuchi bolsa shuningdin, yeni Méni, yer yüzide méhir-muhebbet, adalet we heqqaniyliqni yürgüzgüchi Men Perwerdigarni tonup yetkenlikidin pexirlinip maxtansun; chünki Méning xursenlikim del mushu ishlardindur, — deydu Perwerdigar.
Ẹ jẹ́ kí ẹni tí ń ṣògo nípa èyí nì wí pé: òun ní òye, òun sì mọ̀ mí wí pé, Èmi ni Olúwa tí ń ṣe òtítọ́, ìdájọ́ àti òdodo ní ayé, nínú èyí ni mo ní inú dídùn sí,” Olúwa wí.
25 Mana, shundaq künler kéliduki, — deydu Perwerdigar, — Men xetne qilmighanlarni xetne qilin’ghanlar bilen bille jazalaymen;
“Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò fi ìyà jẹ gbogbo àwọn tí a kọ ilà fún nínú ara nìkan.
26 yeni Misir, Yehuda, Édom, Ammoniylar we Moabiylar, jümlidin chöl-bayawanda turuwatqan, chéke chachlirini chüshürüwetken ellerni jazalaymen; chünki bu ellerning hemmisi xetnisizdur; Israilning barliq jemetimu könglide xetnisizdur.
Ejibiti, Juda, Edomu, Ammoni, Moabu àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní ọ̀nà jíjìn réré ní aginjù. Nítorí pé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jẹ́ aláìkọlà gbogbo àwọn ará ilé Israẹli sì jẹ́ aláìkọlà ọkàn.”

< Yeremiya 9 >