< Yeşaya 27 >

1 O gün RAB Livyatan'ı, o kaçan yılanı, Evet Livyatan'ı, o kıvrıla kıvrıla giden yılanı Acımasız, kocaman, güçlü kılıcıyla cezalandıracak, Denizdeki canavarı öldürecek.
Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò fi idà rẹ̀ jẹ ni ní yà idà rẹ̀ a mú bí iná tí ó tóbi tí ó sì lágbára Lefitani ejò tí ń yọ̀ tẹ̀ẹ̀rẹ̀ n nì, Lefitani ejò tí ń lọ́ bìrìkìtì; Òun yóò sì pa ẹ̀mí búburú inú Òkun náà.
2 O gün RAB, “Sevdiğim bağ için ezgiler söyleyin” diyecek,
Ní ọjọ́ náà, “Kọrin nípa ọgbà àjàrà eléso kan.
3 “Ben RAB, bağın koruyucusuyum, Onu sürekli sularım. Kimse zarar vermesin diye Gece gündüz beklerim.
Èmi Olúwa ń bojútó o, Èmi ó bomirin ín láti ìgbàdégbà. Èmi ó ṣọ́ ọ tọ̀sán tòru kí ẹnikẹ́ni má ba à pa á lára.
4 Kızgın değilim. Keşke karşıma dikenli çalılar çıksa! Onların üzerine yürür, Tümünü ateşe verirdim.
Inú kò bí mi. Bí ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n bá dojú ìjà kọ mí! Èmi yóò dìde sí wọn ní ogun, Èmi yóò sì dáná sun gbogbo wọn.
5 Ya da koruyuculuğuma sarılsınlar, Barışsınlar benimle, Evet, benimle barışsınlar.”
Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, jẹ́ kí wọn wá sọ́dọ̀ mi fún ààbò; jẹ́ kí wọ́n wá àlàáfíà pẹ̀lú mi, bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí wọn wá àlàáfíà pẹ̀lú mi.”
6 Yakup soyu gelecekte kök salacak, İsrail filizlenip çiçeklenecek, Yeryüzünü meyvesiyle dolduracak.
Ní ọjọ́ iwájú Jakọbu yóò ta gbòǹgbò, Israẹli yóò tanná yóò sì rudi èso rẹ̀ yóò sì kún gbogbo ayé.
7 RAB İsrailliler'i, kendilerini cezalandıranları cezalandırdığı gibi cezalandırdı mı? Ya da İsrailliler'i başkalarını öldürdüğü gibi öldürdü mü?
Ǹjẹ́ Olúwa ti lù ú gẹ́gẹ́ bí ó ti lu àwọn tí ó lù ú bolẹ̀? Ǹjẹ́ a ti pa á gẹ́gẹ́ bí a ti pa àwọn tí ó pa á?
8 RAB onları yargıladı, Kovup sürgüne gönderdi. Doğu rüzgarının estiği gün Onları şiddetli soluğuyla savurdu.
Nípa ogun jíjà àti ìjìyà ti o le ni ó fi dojúkọ ọ́ pẹ̀lú ìjì gbígbóná ni ó lé e jáde, gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn fẹ́.
9 Böylece Yakup soyunun suçu bağışlanacak. Günahlarının kaldırılmasının sonucu şöyle olacak: Sunağın taşlarını tebeşir taşı gibi un ufak ettiklerinde Ne Aşera putu ne de buhur sunağı kalacak.
Nítorí èyí báyìí ni ètùtù yóò ṣe wà fún ẹ̀ṣẹ̀ Jakọbu, èyí ni yóò sì jẹ́ èso kíkún ti ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Nígbà tí ó bá mú kí àwọn òkúta pẹpẹ dàbí òkúta ẹfun tí a fọ́ sí wẹ́wẹ́, kì yóò sí ère Aṣerah tàbí pẹpẹ tùràrí tí yóò wà ní ìdúró.
10 Surlu kent terk edildi, Çöl kadar ıssız, sahipsiz bir yurt oldu. Dana orada otlayıp uzanacak, Filizlerini yiyip bitirecek.
Ìlú olódi náà ti dahoro, ibùdó ìkọ̀sílẹ̀, tí a kọ̀ tì gẹ́gẹ́ bí aginjù; níbẹ̀ ni àwọn ọmọ màlúù ti ń jẹ oko níbẹ̀ ni wọn ń sùn sílẹ̀; wọn sì jẹ gbogbo ẹ̀ka rẹ̀ tán.
11 Kuruyan dalları koparılacak, Kadınlar gelip bunları yakacaklar. Çünkü bu halk akıllı bir halk değil. Bu yüzden onları yaratan kendilerine acımayacak, Onlara biçim veren onları kayırmayacak.
Nígbà tí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ bá rọ, a ó ya wọn dànù àwọn obìnrin dé, wọ́n sì fi wọ́n dáná nítorí aláìlóye ènìyàn ni wọn jẹ́, nítorí náà ni ẹni tí ó dá wọn kì yóò ṣàánú fún wọn; bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó mọ wọn kì yóò sì fi ojúrere wò wọ́n.
12 Ey İsrailoğulları, o gün RAB gürül gürül akan Fırat ile Mısır Vadisi arasında harman döver gibi, sizi birer birer toplayacak.
Ní ọjọ́ náà Olúwa yóò sì kó oore láti ìṣàn omi odo Eufurate wá títí dé Wadi ti Ejibiti, àti ìwọ, ìwọ ọmọ Israẹli, ni a ó kójọ ní ọ̀kọ̀ọ̀kan.
13 Evet, o gün büyük bir boru çalınacak; Asur'da yitenlerle Mısır'a sürgün edilenler gelip kutsal dağda, Yeruşalim'de RAB'be tapınacaklar.
Àti ní ọjọ́ náà, a ó fun fèrè ńlá kan. Gbogbo àwọn tí ń ṣègbé lọ ní Asiria àti àwọn tí ń ṣe àtìpó ní Ejibiti yóò wá sin Olúwa ní òkè mímọ́ ní Jerusalẹmu.

< Yeşaya 27 >