< Rut 1 >

1 På den tid då domarna regerade uppstod hungersnöd i landet. Då drog en man från Bet-Lehem i Juda åstad med sin hustru och sina båda söner för att bosätta sig i Moabs land under någon tid.
Ní ìgbà tí àwọn onídàájọ́ ń ṣe àkóso ilẹ̀ Israẹli, ìyàn kan mú ní ilẹ̀ náà, ọkùnrin kan láti Bẹtilẹhẹmu ti Juda, òun àti aya rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjì lọ láti máa gbé ní ilẹ̀ Moabu fún ìgbà díẹ̀.
2 Mannen hette Elimelek, hans hustru Noomi, och hans båda söner Mahelon och Kiljon; och de voro efratiter, från Bet-Lehem i Juda. Så kommo de nu till Moabs land och vistades där.
Orúkọ ọkùnrin náà ń jẹ́ Elimeleki, orúkọ ìyàwó rẹ̀ ni Naomi, orúkọ àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì sì ni Maloni àti Kilioni àwọn ará Efrata, ti Bẹtilẹhẹmu ti Juda. Wọ́n sì lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọ́n ń gbé níbẹ̀.
3 Och Elimelek, Noomis man, dog; men hon levde kvar med sina båda söner.
Ní àsìkò tí wọ́n ń gbé ibẹ̀, Elimeleki, ọkọ Naomi kú, ó sì ku òun pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì.
4 Dessa skaffade sig moabitiska hustrur; den ena hette Orpa och den andra Rut.
Wọ́n sì fẹ́ àwọn ọmọbìnrin ará Moabu méjì, orúkọ ọ̀kan ń jẹ́ Oripa, èkejì sì ń jẹ́ Rutu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti gbé níbẹ̀ fún bí ọdún mẹ́wàá,
5 Och sedan de hade bott där vid pass tio år, dogo också de båda, Mahelon och Kiljon; men kvinnan levde kvar efter sina båda söner och sin man.
Maloni àti Kilioni náà sì kú, Naomi sì wà láìsí ọkọ tàbí ọmọ kankan fún un mọ́.
6 Då stod hon upp med sina sonhustrur för att vända tillbaka från Moabs land; ty hon hade hört i Moabs land att HERREN hade sett till sitt folk och givit det bröd.
Nígbà tí Naomi gbọ́ ní Moabu tí ó wà wí pé Olúwa ti bẹ àwọn ènìyàn rẹ̀ wò nípa fífún wọn ní ọ̀pọ̀ oúnjẹ. Ó sì dìde pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì láti padà sí ìlú rẹ̀.
7 Så begav hon sig, jämte sina båda sonhustrur, från det ställe där hon hade vistats. Men när de nu gingo sin väg fram, för att komma tillbaka till Juda land,
Òun pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì ni wọ́n jọ fi ibi tí ó ń gbé sílẹ̀ tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà sí ilẹ̀ Juda.
8 sade Noomi till sina båda sonhustrur: "Vänden om och gå hem igen, var och en till sin moder.
Ṣùgbọ́n ní ojú ọ̀nà, Naomi wí fún àwọn aya ọmọ rẹ̀ méjèèjì pé, “Kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín padà sí ilé ìyá rẹ̀. Kí Olúwa ṣe àánú fún yín bí ẹ ti ṣe sí èmi àti àwọn ọkọ yín tí ó kú.
9 HERREN bevise godhet mot eder, såsom I haven gjort mot de båda döda och mot mig. HERREN give eder att I mån finna ro, var i sin mans hus." Därefter kysste hon dem. Men de brusto ut i gråt
Kí Olúwa kí ó fi yín lọ́kàn balẹ̀ ní ilé ọkọ mìíràn.” Naomi sì fi ẹnu kò wọ́n ní ẹnu wí pé “Ó dìgbà,” wọ́n sì sọkún kíkankíkan.
10 och sade till henne: "Nej, vi vilja följa med dig tillbaka till ditt folk."
Wọ́n sì wí fún un pé, “Rárá, a ó bà ọ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ.”
11 Men Noomi svarade: "Vänden om, mina döttrar. Varför skullen I gå med mig? Kan väl jag ännu en gång få söner i mitt liv, vilka kunna bliva män åt eder?
Ṣùgbọ́n Naomi dáhùn wí pé, “Ẹ padà sílé ẹ̀yin ọmọ mi. Nítorí kí ni ẹ fi fẹ́ wá pẹ̀lú mi? Ṣé mo tún le bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn ni, tí ó le ṣe ọkọ yin?
12 Vänden om, mina döttrar, och gån hem, ty jag är nu för gammal att överlämna mig åt en man. Och om jag än kunde tänka: 'Jag har ännu hopp', ja, om jag ock redan i natt överlämnade mig åt en man och så verkligen födde söner,
Ẹ padà sílé, ẹ̀yin ọmọ mi, nítorí èmi ti di arúgbó jù láti ní ọkọ mìíràn. Bí èmí wí pé, èmí ní ìrètí, bí èmí tilẹ̀ ní ọkọ mìíràn ní alẹ́ yìí, tí èmí sì bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn,
13 icke skullen I därför vänta, till dess att de hade blivit fullvuxna, icke skullen I därför stänga eder inne och förbliva utan män? Bort det, mina döttrar! Jag känner redan bedrövelse nog för eder skull, eftersom HERRENS hand så har drabbat mig."
ẹ̀yin ha le è dúró dìgbà tí wọ́n yóò fi dàgbà? Ẹ̀yin ó le è dúró dè wọ́n láì fẹ́ ọkọ mìíràn? Rárá, ẹ̀yin ọmọbìnrin mi, nítorí pé inú mi bàjẹ́ gidigidi ju tiyín lọ, nítorí tí ọwọ́ Olúwa fi jáde sí mi!”
14 Då brusto de åter ut i gråt. Och Orpa kysste sin svärmoder till avsked, men Rut höll sig alltjämt intill henne.
Wọ́n sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì tún sọkún. Nígbà náà ní Oripa fi ẹnu ko ìyá ọkọ rẹ̀ ní ẹnu wí pé ó dìgbà, ṣùgbọ́n Rutu dì mọ́ ọn síbẹ̀.
15 Då sade hon: "Se, din svägerska har vänt tillbaka till sitt folk och till sin gud; vänd ock du tillbaka och följ din svägerska."
Naomi wí pé, “Wò ó, arábìnrin rẹ ti padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀ àti òrìṣà rẹ̀, ìwọ náà padà pẹ̀lú rẹ̀.”
16 Men Rut svarade: "Sök icke intala mig att övergiva dig och vända tillbaka ifrån dig. Ty dit du går vill ock jag gå, och där du stannar vill ock jag stanna. Ditt folk är mitt folk, och din Gud är min Gud.
Ṣùgbọ́n Rutu dáhùn wí pé, “Má ṣe rọ̀ mí láti fi ọ́ sílẹ̀ tàbí láti padà lẹ́yìn rẹ. Ibi tí ìwọ bá lọ ní èmi yóò lọ, ibi ti ìwọ bá dúró ni èmi yóò dúró, àwọn ènìyàn rẹ ni yóò jẹ́ ènìyàn mi, Ọlọ́run rẹ ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run mi.
17 Där du dör vill ock jag dö, och där vill jag bliva begraven. HERREN straffe mig nu och framgent, om något annat än döden kommer att skilja mig från dig."
Níbi tí ìwọ bá kú sí ni èmi yóò kú sí, níbẹ̀ ni wọn yóò sì sin mí sí. Kí Olúwa jẹ mí ní ìyà tí ó lágbára, bí ohunkóhun bí kò ṣe ikú bá yà wá.”
18 Då hon nu såg att denna stod fast i sitt beslut att gå med henne, upphörde hon att tala därom med henne.
Nígbà tí Naomi rí i wí pé Rutu ti pinnu láti tẹ̀lé òun kò rọ̀ láti padà mọ́.
19 Så gingo de båda med varandra, till dess att de kommo till Bet-Lehem. Och när de kommo till Bet-Lehem, kom hela staden i rörelse för deras skull, och kvinnorna sade: "Detta är ju Noomi!"
Àwọn méjèèjì sì ń lọ títí wọ́n fi dé ìlú Bẹtilẹhẹmu. Nígbà tí wọ́n dé ibẹ̀, ariwo ìpadàbọ̀ wọn gba ìlú kan, àwọn obìnrin ibẹ̀ sì kígbe ní ohùn rara wí pé, “Naomi ni èyí bí?”
20 Men hon sade till dem: "Kallen mig icke Noomi, utan kallen mig Mara, ty den Allsmäktige har låtit mycken bedrövelse komma över mig.
Naomi sì dáhùn wí pé, “Ẹ má ṣe pè mí ní Naomi mọ́, ẹ pè mí ní Mara, nítorí wí pé Olódùmarè ti mú kí ayé mi di kíkorò.
21 Rik drog jag härifrån, och tomhänt har HERREN låtit mig komma tillbaka. Varför kallen I mig då Noomi, när HERREN har vittnat emot mig, när den Allsmäktige har låtit det gå mig så illa?"
Mo jáde ní kíkún, ṣùgbọ́n Olúwa mú mi padà ní òfo. Nítorí náà kín ló dé tí ẹ fi ń pè mí ní Naomi, nígbà tí Olódùmarè ti kọ̀ mí sílẹ̀, tí ó sì mú ìdààmú bá mi?”
22 Så kom då Noomi tillbaka med sin sonhustru, moabitiskan Rut, i det hon vände tillbaka från Moabs land. Och de kommo till Bet-Lehem, när kornskörden begynte.
Báyìí ni Naomi ṣe padà láti Moabu pẹ̀lú Rutu, ará Moabu ìyàwó ọmọ rẹ̀. Wọ́n gúnlẹ̀ sí Bẹtilẹhẹmu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìkórè ọkà barle.

< Rut 1 >