< Lukas 10 >

1 Därefter utsåg Herren sjuttiotvå andra och sände ut dem framför sig, två och två, till var stad och ort dit han själv tänkte komma
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Olúwa sì yan méjìléláàádọ́rin ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn pẹ̀lú, ó sì rán wọn ní méjì méjì lọ ṣáájú rẹ̀, sí gbogbo ìlú àti ibi tí òun tìkára rẹ̀ yóò sì dé.
2 "Skörden är mycken, men arbetarna äro få. Bedjen fördenskull skördens Herre att han sänder ut arbetare till sin skörd.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ìkórè pọ̀, ṣùgbọ́n àwọn alágbàṣe kò tó nǹkan, nítorí náà ẹ bẹ Olúwa ìkórè, kí ó lè rán àwọn alágbàṣe sínú ìkórè rẹ̀.
3 Gån åstad. Se, jag sänder eder såsom lamm mitt in ibland ulvar.
Ẹ mú ọ̀nà yín pọ̀n: sá wò ó, èmi rán yín lọ bí ọ̀dọ́-àgùntàn sáàrín ìkookò.
4 Bären ingen penningpung, ingen ränsel, inga skor, och hälsen icke på någon under vägen.
Ẹ má ṣe mú àpò, ẹ má ṣe mú àpamọ́wọ́, tàbí bàtà: ẹ má sì ṣe kí ẹnikẹ́ni lọ́nà.
5 Men när I kommen in i något hus, så sägen först: 'Frid vare över detta hus.'
“Ní ilékílé tí ẹ̀yin bá wọ̀, kí ẹ kọ́ wí pé, ‘Àlàáfíà fún ilé yìí!’
6 Om då någon finnes därinne, som är frid värd, så skall den frid I tillönsken vila över honom; varom icke, så skall den vända tillbaka över eder själva.
Bí ọmọ àlàáfíà bá sì wà níbẹ̀, àlàáfíà yín yóò bà lé e: ṣùgbọ́n bí kò bá sí, yóò tún padà sọ́dọ̀ yín.
7 Och stannen kvar i det huset, och äten och dricken vad de hava att giva, ty arbetaren är värd sin lön. Gån icke ur hus i hus.
Ẹ dúró sínú ilé náà, kí ẹ máa jẹ, kí ẹ sì máa mu ohunkóhun tí wọ́n bá fi fún yín, nítorí ọ̀yà alágbàṣe tọ́ sí i. Ẹ má ṣe lọ láti ilé dé ilé.
8 Och när I kommen in i någon stad där man tager emot eder, så äten vad som sättes fram åt eder,
“Ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá wọ̀, tí wọ́n bá sì gbà yín, ẹ jẹ ohunkóhun tí a bá gbé ka iwájú yín.
9 och boten de sjuka som finnas där, och sägen till dem: 'Guds rike är eder nära.'
Ẹ sì mú àwọn aláìsàn tí ń bẹ nínú rẹ̀ láradá, kí ẹ sì wí fún wọn pé, ‘Ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀ sí yín!’
10 Men när I kommen in i någon stad där man icke tager emot eder, så gån ut på dess gator och sägen:
Ṣùgbọ́n ní ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá sì wọ̀, tí wọn kò bá sì gbà yín, nígbà tí ẹ̀yin bá sì jáde ní ìgboro ìlú náà, kí ẹ̀yin sì wí pé,
11 'Till och med det stoft som låder vid våra fötter ifrån eder stad skaka vi av oss åt eder. Men det mån I veta, att Guds rike är nära.'
‘Eruku ìlú yín tí ó kù sí wa lẹ́sẹ̀, a gbọ̀n ọ́n sílẹ̀ fún yín! Ṣùgbọ́n ẹ mọ èyí pé, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀.’
12 Jag säger eder att det för Sodom skall på 'den dagen' bliva drägligare än för den staden.
Ṣùgbọ́n mo wí fún yín, yóò sàn fún Sodomu ní ọjọ́ náà, ju fún ìlú náà lọ.
13 Ve dig, Korasin! Ve dig, Betsaida! Ty om de kraftgärningar som äro gjorda i eder hade blivit gjorda i Tyrus och Sidon, så skulle de för länge sedan hava suttit i säck och aska och gjort bättring.
“Ègbé ni fún ìwọ, Korasini! Ègbé ni fún ìwọ Betisaida! Nítorí ìbá ṣe pé a ti ṣe iṣẹ́ agbára tí a ṣe nínú yín, ní Tire àti Sidoni, wọn ìbá ti ronúpìwàdà lọ́jọ́ pípẹ́ sẹ́yìn, wọn ìbá sì jókòó nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti nínú eérú.
14 Men också skall det vid domen bliva drägligare för Tyrus och Sidon än för eder.
Ṣùgbọ́n yóò sàn fún Tire àti Sidoni nígbà ìdájọ́ jù fún yín lọ.
15 Och du. Kapernaum, skall väl du bliva upphöjt till himmelen? Nej, ned till dödsriket måste du fara. -- (Hadēs g86)
Àti ìwọ, Kapernaumu, a ó ha gbé ọ ga dé òkè ọ̀run? A ó rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ dé isà òkú. (Hadēs g86)
16 Den som hör eder, han hör mig, och den som förkastar eder, han förkastar mig; men den som förkastar mig, han förkastar honom som har sänt mig."
“Ẹni tí ó bá gbọ́ tiyín, ó gbọ́ tèmi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ yín, ó kọ̀ mi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ mi, ó kọ ẹni tí ó rán mi.”
17 Och de sjuttiotvå kommo tillbaka, uppfyllda av glädje, och sade: "Herre, också de onda andarna äro oss underdåniga genom ditt namn."
Àwọn àádọ́rin náà sì fi ayọ̀ padà, wí pé, “Olúwa, àwọn ẹ̀mí èṣù tilẹ̀ foríbalẹ̀ fún wa ní orúkọ rẹ.”
18 Då sade han till dem: "Jag såg Satan falla ned från himmelen såsom en ljungeld.
Ó sì wí fún wọn pé, “Èmí rí Satani ṣubú bí mọ̀nàmọ́ná láti ọ̀run wá.
19 Se, jag har givit eder makt att trampa på ormar och skorpioner och att förtrampa all ovännens härsmakt, och han skall icke kunna göra eder någon skada.
Kíyèsi i, èmí fún yín ní àṣẹ láti tẹ ejò àti àkéekèe mọ́lẹ̀, àti lórí gbogbo agbára ọ̀tá, kò sì ṣí ohun kan bí ó ti wù tí ó ṣe, tí yóò pa yín lára.
20 Dock, glädjens icke över att änglarna äro eder underdåniga, utan glädjens över att edra namn äro skrivna i himmelen."
Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe yọ̀ nítorí èyí pé, àwọn ẹ̀mí ń foríbalẹ̀ fún yín; ṣùgbọ́n ẹ kúkú yọ̀, pé; a kọ̀wé orúkọ yín ní ọ̀run!”
21 I samma stund uppfylldes han av fröjd genom den helige Ande och sade: "Jag prisar dig, Fader, du himmelens och jordens Herre, för att du väl har dolt detta för de visa och kloka, men uppenbarat det för de enfaldiga. Ja, Fader; så har ju varit ditt behag.
Ní wákàtí kan náà Jesu yọ̀ nínú Ẹ̀mí mímọ́ ó sì wí pé, “Mo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, Baba, Olúwa ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ pa nǹkan wọ̀nyí mọ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n àti amòye, ìwọ sì fi wọ́n hàn fún àwọn ọmọ ọwọ́. Bẹ́ẹ̀ ni, Baba, bẹ́ẹ̀ ni ó sá à yẹ ní ojú rẹ.
22 Allt har av min Fader blivit för trott åt mig. Och ingen känner vem Sonen är utom Fadern, ej heller vem Fadern är, utom Sonen och den för vilken Sonen vill göra honom känd."
“Ohun gbogbo ni a ti fi fún mi láti ọ̀dọ̀ Baba mi; kò sì ṣí ẹni tí ó mọ ẹni tí ọmọ jẹ́, bí kò ṣe Baba, àti ẹnikẹ́ni tí ó bá sì wu ọmọ láti fi í hàn fún.”
23 Sedan vände han sig till lärjungarna, när han var allena med dem och sade: "Saliga äro de ögon som se det I sen.
Ó sì yípadà sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ní apá kan. Ó ní, “Ìbùkún ni fún ojú tí ń rí ohun tí ẹ̀yin ń rí.
24 Ty jag säger eder: Många profeter och konungar ville se det som I sen men fingo dock icke se det, och höra det som I hören, men fingo dock icke höra det."
Nítorí mo wí fún yín, ọ̀pọ̀ àwọn wòlíì àti àwọn ọba ni ó ń fẹ́ láti rí ohun tí ẹ̀yin ń rí, wọn kò sì rí wọn, àti láti gbọ́ ohun tí ẹ̀yin ń gbọ́, wọn kò sì gbọ́ wọn.”
25 Men en lagklok stod upp och ville snärja honom och sade: "Mästare, vad skall jag göra för att få evigt liv till arvedel?" (aiōnios g166)
Sì kíyèsi i amòfin kan dìde, ó ń dán an wò, ó ní, “Olùkọ́, kín ni èmi ó ṣe kí èmi lè jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios g166)
26 Då sade han till honom: "Vad är skrivet i lagen? Huru läser du?"
Ó sì bi í pé, “Kí ni a kọ sínú ìwé òfin? Báwo ni ìwọ sì ti kà á?”
27 Han svarade och sade: "'Du skall älska Herren, din Gud, av allt ditt hjärta och av all din själ och av all din kraft och av allt ditt förstånd och din nästa såsom dig själv.'"
Ó sì dáhùn wí pé, “‘Kí ìwọ fi gbogbo àyà rẹ, àti gbogbo ọkàn rẹ, àti gbogbo agbára rẹ, àti gbogbo inú rẹ fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ’; àti, ‘Ẹnìkejì rẹ bí ara rẹ.’”
28 Han sade till honom: "Rätt svarade du. Gör det, så får du leva,
Ó sì wí fún un pé, “Ìwọ́ dáhùn rere. Ṣe èyí, ìwọ ó sì yè.”
29 Då ville han rättfärdiga sig och sade till Jesus: "Vilken är då min nästa?"
Ṣùgbọ́n ó ń fẹ́ láti da ara rẹ̀ láre, ó wí fún Jesu wí pé, “Ta ha sì ni ẹnìkejì mi?”
30 Jesus svarade och sade: "En man begav sig från Jerusalem ned till Jeriko, men råkade ut för rövare, som togo ifrån honom hans kläder och därtill slogo honom; därefter gingo de sin väg och läto honom ligga där halvdöd.
Jesu sì dáhùn ó wí pé, “Ọkùnrin kan ń ti Jerusalẹmu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Jeriko, ó sì bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà; wọ́n gbà á ní aṣọ, wọ́n sá a lọ́gbẹ́, wọ́n sì fi sílẹ̀ lọ ní àìpatán.
31 Så hände sig att en präst färdades samma väg; och när han fick se honom, gick han förbi.
Ní kòńgẹ́ àkókò yìí ni àlùfáà kan sì ń sọ̀kalẹ̀ lọ lọ́nà náà. Nígbà tí ó sì rí i ó kọjá lọ níhà kejì.
32 Likaledes ock en levit: när denne kom till det stället och fick se honom, gick han förbi.
Bẹ́ẹ̀ náà sì ni ọmọ Lefi kan pẹ̀lú, nígbà tí ó dé ibẹ̀, tí ó sì rí i, ó kọjá lọ níhà kejì.
33 Men en samarit, som färdades samma väg, kom också dit där han låg; och när denne fick se honom, ömkade han sig över honom
Ṣùgbọ́n ará Samaria kan, bí ó ti ń re àjò, ó dé ibi tí ó gbé wà; nígbà tí ó sì rí i, àánú ṣe é.
34 och gick fram till honom och göt olja och vin i hans sår och förband dem. Sedan lyfte han upp honom på sin åsna och förde honom till ett härbärge och skötte honom.
Ó sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì di ọgbẹ́ rẹ̀, ó da òróró àti ọtí wáìnì sí i, ó sì gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ti òun tìkára rẹ̀, ó sì mú un wá sí ilé èrò, a sì ń ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
35 Morgonen därefter tog han fram två silverpenningar och gav dem åt värden och sade: 'Sköt honom och vad du mer kostar på honom skall jag betala dig, när jag kommer tillbaka.' --
Nígbà tí ó sì lọ ní ọjọ́ kejì, ó fi owó idẹ méjì fún olórí ilé èrò ó sì wí fún un pé, ‘Máa tọ́jú rẹ̀; ohunkóhun tí ìwọ bá sì ná kún un, nígbà tí mo bá padà dé, èmi ó san án fún ọ.’
36 Vilken av dessa tre synes dig nu hava visat sig vara den mannens nästa, som hade fallit i rövarhänder?"
“Nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí, ta ni ìwọ rò pé ó jẹ́ ẹnìkejì ẹni tí ó bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà?”
37 Han svarade: "Den som bevisade honom barmhärtighet." Då sade Jesus till honom: "Gå du och gör sammalunda."
Ó sì dáhùn wí pé, “Ẹni tí ó ṣàánú fún un ni.” Jesu sì wí fún un pé, “Lọ, kí o ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́!”
38 När de nu voro på vandring, gick han in i en by, och en kvinna, vid namn Marta, tog emot honom i sitt hus.
Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń lọ, o wọ ìletò kan, obìnrin kan tí a ń pè ní Marta sì gbà á sí ilé rẹ̀.
39 Och hon hade en syster, som hette Maria; denna satte sig ned vid Herrens fötter och hörde på hans ord.
Ó sì ní arábìnrin kan tí a ń pè ní Maria tí ó sì jókòó lẹ́bàá ẹsẹ̀ Olúwa, tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀.
40 Men Marta var upptagen av mångahanda bestyr för att tjäna honom. Och hon gick fram och sade: "Herre, frågar du icke efter att min syster har lämnat alla bestyr åt mig allena? Säg nu till henne att hon hjälper mig."
Ṣùgbọ́n Marta ń ṣe ìyọnu ohun púpọ̀, ó sì tọ̀ ọ́ wá, ó wí pé, “Olúwa, ìwọ kò sì bìkítà sí ti arábìnrin mi pé ó fi mí sílẹ̀ láti máa nìkan ṣe ìránṣẹ́? Wí fún un kí ó ràn mí lọ́wọ́.”
41 Då svarade Herren och sade till henne: "Marta, Marta, du gör dig bekymmer och oro för mångahanda,
Ṣùgbọ́n Olúwa sì dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Marta, Marta, ìwọ ń ṣe àníyàn àti làálàá nítorí ohun púpọ̀.
42 men allenast ett är nödvändigt. Maria har utvalt den goda delen, och den skall icke tagas ifrån henne."
Ṣùgbọ́n ohun kan ni a kò lè ṣe aláìní, Maria sì ti yan ipa rere náà tí a kò lè gbà lọ́wọ́ rẹ̀.”

< Lukas 10 >