< Job 7 >

1 En stridsmans liv lever ju människan på jorden, och hennes dagar äro såsom dagakarlens dagar.
“Ṣé ìjà kò ha si fún ènìyàn lórí ilẹ̀? Ọjọ́ rẹ̀ pẹ̀lú kò ha dàbí ọjọ́ alágbàṣe?
2 Hon är lik en träl som flämtar efter skugga, lik en dagakarl som får bida efter sin lön.
Bí ọmọ ọ̀dọ̀ tí máa ń kánjú bojú wo òjìji, àti bí alágbàṣe ti í kánjú wo ọ̀nà owó iṣẹ́ rẹ̀.
3 Så har jag fått till arvedel månader av elände; nätter av vedermöda hava blivit min lott.
Bẹ́ẹ̀ ni a mú mi ní ìbànújẹ́ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oṣù, òru ìdáni-lágara ni a sì là sílẹ̀ fún mi.
4 Så snart jag har lagt mig, är min fråga: "När skall jag då få stå upp?" Ty aftonen synes mig så lång; jag är övermätt av oro, innan morgonen har kommit.
Nígbà ti mo dùbúlẹ̀, èmi wí pé, ‘Nígbà wo ni èmi ó dìde?’ Tí òru yóò sì kọjá, ó sì tó fún mi láti yí síyìn-ín yí sọ́hùn-ún, títí yóò fi di àfẹ̀mọ́júmọ́.
5 Med förruttnelsens maskar höljes min kropp, med en skorpa lik jord; min hud skrymper samman och faller sönder.
Kòkòrò àti ògúlùtu erùpẹ̀ ni á fi wọ̀ mi ni aṣọ, awọ ara mi bù, o sì di bíbàjẹ́.
6 Mina dagar fly snabbare än vävarens spole; de försvinna utan något hopp.
“Ọjọ́ mi yára jù ọkọ̀ ìhunṣọ lọ, o sì di lílò ní àìní ìrètí.
7 Tänk därpå att mitt liv är en fläkt, att mitt öga icke mer skall få se någon lycka.
Háà! Rántí pé afẹ́fẹ́ ni ẹ̀mí mi; ojú mi kì yóò padà rí rere mọ́.
8 Den nu ser mig, hans öga skall ej vidare skåda mig; bäst din blick vilar på mig, är jag icke mer.
Ojú ẹni tí ó rí mi, kì yóò rí mi mọ́; ojú rẹ̀ tẹ̀ mọ́ra mi, èmi kò sí mọ́.
9 Såsom ett moln som har försvunnit och gått bort, så är den som har farit ned i dödsriket; han kommer ej åter upp därifrån. (Sheol h7585)
Bí ìkùùkuu tí i túká, tí í sì fò lọ, bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sí ipò òkú tí kì yóò padà wa mọ́. (Sheol h7585)
10 Aldrig mer vänder han tillbaka till sitt hus, och hans plats vet icke av honom mer.
Kì yóò padà sínú ilé rẹ̀ mọ́, bẹ́ẹ̀ ní ipò rẹ̀ kì yóò mọ̀ ọn mọ́.
11 Därför vill jag nu icke lägga band på min mun, jag vill taga till orda i min andes ångest, jag vill klaga i min själs bedrövelse.
“Nítorí náà èmi kì yóò pa ẹnu mi mọ́, èmi yóò máa sọ nínú ìrora ọkàn mi, èmi yóò máa ṣe ìráhùn nínú kíkorò ọkàn mi.
12 Icke är jag väl ett hav eller ett havsvidunder, så att du måste sätta ut vakt mot mig?
Èmi a máa ṣe Òkun tàbí ẹ̀mí búburú, tí ìwọ fi ń yan olùṣọ́ tì mi?
13 När jag hoppas att min bädd skall trösta mig, att mitt läger skall lindra mitt bekymmer,
Nígbà tí mo wí pé, ibùsùn mi yóò tù mí lára, ìtẹ́ mi yóò mú ara mi fúyẹ́ pẹ̀lú.
14 då förfärar du mig genom drömmar, och med syner förskräcker du mig.
Nígbà náà ni ìwọ fi àlá da yọ mi lénu bò mi, ìwọ sì fi ìran òru dẹ́rùbà mí.
15 Nej, hellre vill jag nu bliva kvävd, hellre dö än vara blott knotor!
Bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mí yàn láti fún pa àti ikú ju kí ń wà láààyè ní ipò tí ara mí wà yìí lọ.
16 Jag är led vid detta; aldrig kommer jag åter till liv. Låt mig vara; mina dagar äro ju fåfänglighet.
O sú mi, èmi kò le wà títí: jọ̀wọ́ mi jẹ́, nítorí pé asán ni ọjọ́ mi.
17 Vad är då en människa, att du gör så stor sak av henne, aktar på henne så noga,
“Kí ni ènìyàn tí ìwọ o máa kókìkí rẹ̀? Àti tí ìwọ ìbá fi gbé ọkàn rẹ lé e?
18 synar henne var morgon, prövar henne vart ögonblick?
Àti ti ìwọ ó fi máa wá í bẹ̀ ẹ́ wò ni òròòwúrọ̀, ti ìwọ o sì máa dán an wò nígbàkígbà!
19 Huru länge skall det dröja, innan du vänder din blick ifrån mig, lämnar mig i fred ett litet andetag?
Yóò ti pẹ́ tó kí ìwọ kí ó tó fi mí sílẹ̀ lọ, tí ìwọ o fi mí sílẹ̀ jẹ́ẹ́ títí èmi yóò fi lè dá itọ́ mi mì.
20 Om jag än har syndar, vad skadar jag därmed dig, du människornas bespejare? Varför har du satt mig till ett mål för dina angrepp och låtit mig bliva en börda för mig själv?
Èmi ti ṣẹ̀, ki ní èmi ó ṣe sí ọ. Ìwọ Olùsójú ènìyàn? Èéṣe tí ìwọ fi fi mí ṣe àmì itasi níwájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi sì di ẹrẹ̀ wíwo fún ọ?
21 Varför vill du icke förlåta mig min överträdelse, icke tillgiva mig min missgärning? Nu måste jag ju snart gå till vila i stoftet; om du söker efter mig, så är jag icke mer.
Èéṣe tí ìwọ kò sì dárí ìrékọjá mi jìn, kí ìwọ kí ó sì mú àìṣedéédéé mi kúrò? Ǹjẹ́ nísinsin yìí ni èmi ìbá sùn nínú erùpẹ̀, ìwọ ìbá sì wá mi kiri ní òwúrọ̀, èmi kì bá tí sí.”

< Job 7 >