< Jeremia 49 >

1 Om Ammons barn. Så säger HERREN: Har Israel nu inga barn, eller har han ingen arvinge mer? Eller varför har Malkam tagit arv, efter Gad, och varför bor hans folk i dess städer?
Nípa Ammoni. Báyìí ni Olúwa wí, “Israẹli kò ha ní ọmọkùnrin? Israẹli kò ha ní àrólé bí? Nítorí kí ni Malkomu ṣe jogún Gadi? Kí ló dé tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ń gbé ìlú rẹ̀?
2 Se, därför skola dagar komma, säger HERREN då jag skall låta höra ett härskri mot Rabba i Ammons barns land; och då skall det bliva en öde grushög, och dess lydstäder skola brännas upp i eld; och Israel skall då taga arv efter dem som hava tagit hans arv, säger HERREN.
Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí; “nígbà tí èmi yóò mú kí a gbọ́ ìdágìrì ogun ní Rabba tí Ammoni; yóò sì di òkìtì ahoro, gbogbo ìlú tí ó yí i ká ni a ó jó níná. Nígbà náà ni Israẹli yóò lé wọn, àwọn tí ó ti lé e jáde,” ni Olúwa wí.
3 Jämra dig, du Hesbon, ty Ai är förstört; ropen, I Rabbas döttrar. Höljen eder i sorgdräkt, klagen, och gån omkring i gårdarna; ty Malkam måste vandra bort i fångenskap, och hans präster och furstar med honom.
“Hu, ìwọ Heṣboni, nítorí Ai tí rún! Kígbe ẹ̀yin olùgbé Rabba! Ẹ wọ aṣọ ọ̀fọ̀ kí ẹ sì ṣọ̀fọ̀. Ẹ sáré sókè sódò nínú ọgbà, nítorí Malkomu yóò lọ sí ìgbèkùn, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti ìjòyè rẹ̀.
4 Varför berömmer du dig av dina dalar, av att din dal flödar över, du avfälliga dotter? Du som förlitar dig på dina skatter och säger: "Vem skall väl komma åt mig?",
Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣògo nínú àfonífojì rẹ, ṣògo nínú àfonífojì rẹ fún èso? Ẹ̀yin ọmọbìnrin Ammoni aláìṣòótọ́, ẹ gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ yín, ẹ sì wí pé, ‘Ta ni yóò kò mí lójú?’
5 se, jag skall låta förskräckelse komma över dig från alla dem som bo omkring dig, säger Herren, HERREN Sebaot. Och I skolen varda bortdrivna, var och en åt sitt håll och ingen skall församla de flyktande.
Èmi yóò mu ẹ̀rù wá lórí rẹ láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí ọ ká,” ni Olúwa, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
6 Men därefter skall jag åter upprätta Ammons barn, säger HERREN.
“Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Gbogbo yín ni ó lé jáde, kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò dá ìkólọ Ammoni padà,” ni Olúwa wí.
7 Om Edom. Så säger HERREN Sebaot: Finnes då ingen vishet mer i Teman? Har all rådighet försvunnit ifrån de förståndiga? Är deras vishet uttömd?
Nípa Edomu. Èyí ní ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ṣe kò ha sí ọgbọ́n mọ́ ni Temani? Ṣé a ti ké ìmọ̀ràn kúrò ní ọ̀dọ̀ olóyè? Ṣé ọgbọ́n wọn ti bàjẹ́ bí?
8 Flyn, vänden om, gömmen eder djupt nere, I Dedans inbyggare. Ty över Esau skall jag låta ofärd komma på hans hemsökelses tid.
Yípadà kí o sálọ, sá pamọ́ sínú ihò, ìwọ tí ó ń gbé ní Dedani, nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí Esau, ní àkókò tí èmi ó bẹ̀ ẹ́ wò.
9 När vinbärgare komma över dig, skola de icke lämna kvar någon efterskörd. När tjuvar komma om natten, skola de fördärva så mycket dem lyster.
Tí àwọn tí ń ṣa èso bá tọ̀ ọ́ wá; ǹjẹ́ wọn kò ní fi èso díẹ̀ sílẹ̀? Tí olè bá wá ní òru; ǹjẹ́ wọn kò ní kó gbogbo ohun tí wọ́n bá fẹ́?
10 Ty jag skall blotta Esau, jag skall uppenbara hans gömslen, och han skall icke lyckas hålla sig dold; fördärv skall drabba hans barn, hans bröder och grannar, och han skall icke mer vara till.
Ṣùgbọ́n èmi yóò tu Esau sí ìhòhò, èmi ti fi ibi ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ hàn, nítorí kí o máa ba à fi ara rẹ pamọ́. Àwọn ọmọ rẹ, ẹbí rẹ àti àwọn ará ilé rẹ yóò parun. Wọn kò sì ní sí mọ́.
11 Bekymra dig ej om dina faderlösa, jag vill behålla dem vid liv; och må dina änkor förtrösta på mig.
Fi àwọn ọmọ aláìní baba sílẹ̀ èmi yóò dáàbò bo ẹ̀mí wọn. Àwọn opó rẹ gan an lè gbẹ́kẹ̀lé mi.”
12 Ty så säger HERREN: Se, de som icke hade förskyllt att dricka kalken, de nödgas att dricka den; skulle då du bliva ostraffad? Nej, du skall icke bliva ostraffad, utan skall nödgas att dricka den.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí bí ẹnikẹ́ni tí kò bá yẹ kí ó mu ago náà bá mú un, kí ló dé tí ìwọ yóò fi lọ láìjìyà? Ìwọ kò ní lọ láìjìyà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò mú un.
13 Ty vid mig själv har jag svurit, säger HERREN, att Bosra skall bliva ett föremål för häpnad och smälek; det skall förödas och bliva ett exempel som man nämner, när man förbannar; och alla dess lydstäder skola bliva ödemarker för evärdlig tid.
Èmi fi ara mi búra ni Olúwa wí, wí pé, “Bosra yóò ba ayé ara rẹ̀ jẹ́. Yóò di ẹni ẹ̀gàn, ẹni èpè àti ẹni ègún, àti gbogbo ìlú rẹ̀ yóò di ìbàjẹ́ títí láé.”
14 Ett budskap har jag hört från HERREN, och en budbärare är utsänd bland folken: "Församlen eder och kommen emot det, och stån upp till strid.
Ní gbígbọ́, èmi ti gbọ́ ìró kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa, a rán ikọ̀ kan sí orílẹ̀-èdè pé, ẹ kó ara yín jọ, ẹ wá sórí rẹ̀, ẹ sì dìde láti jagun.
15 Ty se, jag skall göra dig ringa bland folken, föraktad bland människorna.
“Ní báyìí, èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo; ẹni ẹ̀gàn láàrín àwọn ènìyàn.
16 Den förfäran du väckte har bedragit dig, ja, ditt hjärtas övermod, där du sitter ibland bergsklyftorna och håller dig fast högst uppe på höjden. Om du än byggde ditt näste så högt uppe som örnen, så skulle jag dock störta dig ned därifrån, säger HERREN.
Ìpayà tí ìwọ ti fà sínú ìgbéraga ọkàn rẹ sì ti tàn ọ́ jẹ; ìwọ tí ń gbé ní pàlàpálá àpáta, tí o jókòó lórí ìtẹ́ gíga síbẹ̀ o kọ́ ìtẹ́ rẹ ga gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ idì; láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá,” ni Olúwa wí.
17 Och Edom skall bliva ett föremål för häpnad; alla som gå där fram skola häpna och vissla vid tanken på alla dess plågor.
“Edomu yóò di ahoro gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò jáyà, wọn ó sì fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà nítorí gbogbo ìpalára rẹ.
18 Likasom när Sodom och Gomorra med sina grannstäder omstörtades, säger HERREN, så skall ingen mer bo där och intet människobarn där vistas.
Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe gba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú tí ó wà ní àyíká rẹ,” ní Olúwa wí. “Bẹ́ẹ̀ ni, kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé níbẹ̀; kò sì ní sí ènìyàn tí yóò tẹ̀dó síbẹ̀ mọ́.
19 Se, lik ett lejon som drager upp från Jordanbygdens snår och bryter in på frodiga betesmarker skall jag i ett ögonblick jaga dem bort därifrån; och den som jag utväljer skall jag sätta till herde över dem. Ty vem är min like, och vem kan ställa mig till ansvar? Och vilken är den herde som kan bestå inför mig?
“Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Edomu kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
20 Hören därför det råd som HERREN har lagt mot Edom, och de tankar som han har mot Temans inbyggare: Ja, herdegossarna skola sannerligen släpas bort; sannerligen, deras betesmark skall häpna över dem.
Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí Olúwa ní fún Edomu, ohun tí ó ní ní pàtàkì fún àwọn tí ń gbé ní Temani. Àwọn ọ̀dọ́ àgbò ni à ó lé jáde; pápá oko wọn ni yóò run nítorí wọn.
21 Vid dånet av deras fall bävar jorden; man skriar så, att ljudet höres ända borta vid Röda havet.
Ilẹ̀ yóò mì tìtì nípa ariwo ìṣubú wọn, a ó gbọ́ igbe wọn ní Òkun pupa.
22 Se, en som liknar en örn lyfter sig och svävar fram och breder ut sina vingar över Bosra. Och Edoms hjältars hjärtan bliva på den dagen såsom en kvinnas hjärta, när hon är i barnsnöd.
Wò ó! Ẹyẹ idì yóò gòkè fò wálẹ̀, yóò tẹ ìyẹ́ rẹ̀ lórí Bosra. Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn ajagun Edomu yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ń rọbí.
23 Om Damaskus. Hamat och Arpad komma på skam; ty ett ont budskap få de höra, och de betagas av ångest. I havet råder oro; det kan ej vara stilla.
Nípa Damasku. “Inú Hamati àti Arpadi bàjẹ́ nítorí wọ́n gbọ́ ìròyìn búburú, ìjayà dé bá wọn, wọ́n sì dààmú bí omi Òkun.
24 Damaskus förlorar modet, det vänder sig om till flykt, ty skräck har fattat det; ångest och vånda har gripit det, lik en barnaföderskas.
Damasku di aláìlera, ó pẹ̀yìndà láti sálọ, ìwárìrì sì dé bá a; ìbẹ̀rù àti ìrora dìímú, ìrora bí ti obìnrin tí ó wà ní ipò ìrọbí.
25 Varför lät man den icke vara, den berömda staden, min glädjes stad?
Kí ló dé tí ìlú olókìkí di ohun ìkọ̀sílẹ̀; ìlú tí mo dunnú sí.
26 Så måste nu dess unga män falla på dess gator, och alla dess stridsmän förgöras på den dagen, säger HERREN Sebaot.
Lóòtítọ́, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ yóò ṣubú lójú pópó, gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ yóò pa ẹnu mọ́ ní ọjọ́ náà,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
27 Och jag skall tända eld på Damaskus' murar, och elden skall förtära Ben-Hadads palatser.
“Èmi yóò fi iná sí odi Damasku, yóò sì jó gbọ̀ngàn Beni-Hadadi run.”
28 Om Kedar och Hasors riken, som blevo slagna av Nebukadressar, konungen i Babel. Så säger HERREN: Upp, ja, dragen åstad upp mot Kedar, och fördärven Österlandets söner.
Nípa ìlú Kedari àti ìjọba Hasori èyí ti Nebukadnessari ọba Babeli dojú ìjà kọ, èyí ni ohun tí Olúwa sọ, “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ ìlú Kedari, kí o sì pa àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn run.
29 Deras hyddor och deras hjordar må man taga, deras tält och allt deras bohag och deras kameler må föras bort ifrån dem och man må ropa över dem; "Skräck från alla sidor!"
Àgọ́ wọn àti agbo àgùntàn wọn ni wọn ó kó lọ; àgọ́ wọn yóò di ìṣínípò padà pẹ̀lú gbogbo ẹrù àti ìbákasẹ wọn. Àwọn ènìyàn yóò ké sórí wọ́n pé, ‘Ẹ̀rù yí káàkiri!’
30 Flyn, ja, flykten med hast, gömmen eder djupt nere, I Hasors inbyggare, säger HERREN, ty Nebukadressar, konungen i Babel, har lagt råd mot eder och tänkt ut mot eder ett anslag.
“Sálọ kíákíá! Fi ara pamọ́ sí ibi jíjìn, ẹ̀yin olùgbé Hasori,” ni Olúwa wí. “Nebukadnessari ọba Babeli ti dojú ìjà kọ ọ́.
31 Upp, säger HERREN, ja, dragen ditupp mot ett fredligt folk, som bor där i trygghet, utan både portar och bommar, i sin avskilda boning.
“Dìde kí o sì dojú ìjà kọ orílẹ̀-èdè tí ó wà nínú ìrọ̀rùn, èyí tí ó gbé ní àìléwu,” ní Olúwa wí. “Orílẹ̀-èdè tí kò ní odi tàbí irin, àwọn ènìyàn rẹ̀ ń dágbé.
32 Deras kameler skola bliva edert byte, och deras myckna boskap skall bliva edert rov; och jag skall förströ dem åt alla väderstreck, männen med det kantklippta håret och från alla sidor skall jag låta ofärd komma över dem, säger HERREN.
Àwọn ìbákasẹ á di ẹrù àti àwọn ẹran ọ̀sìn, wọ́n á di ìkógun. Èmi yóò tú àwọn tí ó wà ní òkèèrè sí inú afẹ́fẹ́. Èmi yóò sì mú ibi wá sí àyíká gbogbo,” báyìí ní Olúwa wí.
33 Och Hasor skall bliva en boning för schakaler en ödemark till evärdlig tid; ingen skall mer bo där och intet människobarn där vistas.
“Hasori yóò di ibi ìdọdẹ àwọn akátá, ibi ìkọ̀sílẹ̀ ayérayé, kò sí ẹni tí yóò gbé ní ibẹ̀.”
34 Detta är vad som kom till profeten Jeremia såsom HERRENS ord om Elam, i begynnelsen av Sidkias, Juda konungs, regering; han sade:
Èyí ní ọ̀rọ̀ Olúwa èyí tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa Elamu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Sedekiah ọba Juda.
35 Så säger HERREN Sebaot: Se, jag skall bryta sönder Elams båge, deras yppersta makt.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “Wò ó, èmi yóò fọ́ ìtẹ̀gùn Elamu, ẹni tí wọ́n sinmi lé nípa agbára.
36 Och från himmelens fyra ändar skall jag låta fyra vindar komma mot Elam, och skall förströ dess folk åt alla dessa väderstreck; och intet folk skall finnas, dit icke de fördrivna ifrån Elam skola komma.
Èmi yóò mú kí afẹ́fẹ́ orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin àgbáyé lòdì sí Elamu. Èmi yóò tú wọn ká sí ìpín afẹ́fẹ́ mẹ́rin àti pé, kò sí orílẹ̀-èdè tí ilẹ̀ àjèjì Elamu kò ní lọ.
37 Och jag skall göra elamiterna förfärade för sina fiender och för dem som stå efter deras liv, och jag skall låta olycka komma över dem, min vredes glöd, säger HERREN. Jag skall sända svärdet efter dem, till dess att jag har gjort ände på dem.
Èmi yóò kẹ́gàn Elamu níwájú àwọn ọ̀tá wọn, àti níwájú àwọn tí wọ́n ń wá ẹ̀mí wọn, Èmi yóò mú ibi wá sí orí wọn, àní, ìbínú gbígbóná mi,” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí. “Èmi yóò lé wọn pẹ̀lú idà, di ìgbà tí èmi yóò rẹ́yìn wọn.
38 Och jag skall sätta upp min tron i Elam och förgöra där både konung och furstar, säger HERREN.
Èmi yóò sì gbé ìtẹ́ mi kalẹ̀ ní Elamu, èmí yóò sì pa ọba wọn àti ìjòyè wọn run,” báyìí ni Olúwa wí.
39 Men i kommande dagar skall jag åter upprätta Elam, säger HERREN.
“Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọ Elamu padà láìpẹ́ ọjọ́,” báyìí ni Olúwa wí.

< Jeremia 49 >