< Jeremia 27 >

1 I begynnelsen av Jojakims, Josias sons, Juda konungs, regering kom detta ord till Jeremia från HERREN;
Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìṣèjọba Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wí pé.
2 han sade: Så har HERREN sagt till mig: Gör dig band och ok och sätt detta på din hals.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Ṣe àjàgà àti ọ̀pá irin fún ara rẹ, kí o sì fiwé ọrùn rẹ.
3 Sänd det sedan till konungen i Edom, konungen i Moab, konungen över Ammons barn, konungen i Tyrus och konungen i Sidon, genom de sändebud som hava kommit till Sidkia, Juda konung, i Jerusalem.
Kí o rán ọ̀rọ̀ sí ọba ti Edomu, Moabu, Ammoni, Tire àti Sidoni láti ọwọ́ àwọn ikọ̀ tí ó wá sí Jerusalẹmu sọ́dọ̀ Sedekiah ọba Juda.
4 Och bjud dem med dessa ord framföra sitt budskap till sina herrar: Så säger HERREN Sebaot, Israels Gud: Så skolen I säga till edra herrar:
Kí o sì pàṣẹ fún wọn láti wí fún àwọn olúwa wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: “Sọ èyí fún àwọn olúwa rẹ.
5 Jag är den som genom min stora kraft och min uträckta arm har gjort jorden, med de människor och djur som äro på jorden; och jag giver den åt vem jag vill.
Pẹ̀lú agbára ńlá mi àti ọwọ́ nínà mi ni Èmi dá ayé, ènìyàn àti ẹranko tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, mo sì fún ẹni tí ó wu ọkàn mi.
6 Så giver jag nu alla dessa länder i min tjänare Nebukadnessars, den babyloniske konungens, hand; ja ock markens djur giver jag honom, för att de må tjäna honom.
Nísinsin yìí, Èmi yóò fa gbogbo orílẹ̀-èdè rẹ fún Nebukadnessari ọba Babeli ìránṣẹ́ mi; Èmi yóò sì mú àwọn ẹranko búburú wọ̀n-ọn-nì jẹ́ tirẹ̀.
7 Och alla folk skola vara honom och hans son och hans sonson underdåniga, till dess att också för hans land tiden är inne, att mäktiga folk och stora konungar skola göra honom sig underdånig.
Gbogbo orílẹ̀-èdè ni yóò máa sìn ín àti àwọn ọmọdọ́mọ rẹ̀ títí ilẹ̀ rẹ yóò fi dé; ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè àti àwọn ọba ńlá ni yóò tẹríba fún.
8 Och det folk och det rike som icke vill vara honom, Nebukadnessar, konungen i Babel, underdånigt, och som icke vill giva sin hals under den babyloniske konungens ok, det folket skall jag hemsöka med svärd, hungersnöd och pest, säger HERREN, till dess att jag har förgjort dem genom hans hand.
“‘“Ṣùgbọ́n tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan kò bá ní sin Nebukadnessari ọba Babeli, tàbí kí ó tẹ orí rẹ̀ ba ní abẹ́ àjàgà rẹ̀, Èmi yóò fi ìyà jẹ orílẹ̀-èdè náà nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, ni Olúwa wí títí Èmi yóò fi run wọ́n nípa ọwọ́ rẹ̀.
9 Därför mån I icke höra på edra profeter och spåman, på edra drömmar, på edra teckentydare och trollkarlar, när dessa säga till eder: "I skolen icke komma att tjäna konungen i Babel";
Nítorí náà, ẹ má ṣe tẹ́tí sílẹ̀ sí àwọn wòlíì yín, àwọn aláfọ̀ṣẹ yín, àwọn tí ń rọ́ àlá fún un yín, àwọn oṣó yín, tàbí àwọn àjẹ́ yín tí wọ́n ń sọ fún un yín pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli.’
10 ty de profetera lögn för eder, och komma så åstad att I bliven förda långt undan från edert land, i det jag måste driva eder bort, så att I förgåns.
Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ fún un yín èyí tí yóò mú u yín jìnnà réré kúrò ní ilẹ̀ yín; kí Èmi kí ó lè lé yín jáde, kí ẹ̀yin ó sì ṣègbé.
11 Men det folk som böjer sin hals under den babyloniske konungens ok och tjänar honom, det skall jag låta få ro i sitt land, säger HERREN, så att de kunna bruka det och bo däri.
Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kankan bá tẹ orí rẹ̀ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, tí ó sì sìn ín, Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè náà wà lórí ilẹ̀ rẹ̀ láti máa ro ó, àti láti máa gbé ibẹ̀ ni Olúwa wí.”’”
12 Till Sidkia, Juda konung, talade jag på alldeles samma sätt; jag sade: Böjen eder hals under den babyloniske konungens ok, och tjänen honom och hans folk, så skolen I få leva.
Èmi sì sọ ọ̀rọ̀ náà fún Sedekiah ọba Juda wí pé: “Tẹ orí rẹ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, sìn ín ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ, ìwọ yóò sì yè.
13 Icke viljen I dö, du och ditt folk, genom svärd, hunger och pest, såsom HERREN har sagt att det skall ske med det folk som icke vill tjäna konungen i Babel?
Kí ló dé tí ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ yóò ṣe kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, èyí tí Olúwa fi ń halẹ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè tí kò bá sin ọba Babeli?
14 Hören alltså icke på de profeters ord, som säga till eder "I skolen icke komma att tjäna konungen i Babel"; ty de profetera lögn för eder.
Ẹ má ṣe fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì tí ó ń sọ wí pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli,’ nítorí pé àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fún un yín.
15 Jag har icke sänt dem, säger HERREN; det är de själva som profetera lögn i mitt namn, och de komma så åstad att jag måste driva eder bort, så att I förgåns, jämte de profeter som profetera för eder.
‘Èmi kò rán wọn ni Olúwa wí. Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi. Nítorí náà, Èmi yóò lé wọn, wọn yóò sì ṣègbé, ẹ̀yin pẹ̀lú àwọn wòlíì tí ó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún un yín.’”
16 Och till prästerna och till hela detta folk talade jag och sade: Så säger HERREN: Hören icke på edra profeters ord, när de profetera för eder och säga: "Se, de kärl som höra till HERRENS hus skola nu snart föras tillbaka från Babel"; ty de profetera lögn för eder.
Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹ má ṣe fetí sí nǹkan tí àwọn wòlíì ń sọ pé, ‘Láìpẹ́ ohun èlò ilé Olúwa ni a ó kó padà láti Babeli,’ àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ. Ẹ má tẹ́tí sí wọn.
17 Hören icke på dem, utan tjänen konungen i Babel, så skolen I få leva. Icke viljen I att denna stad skall bliva ödelagd?
Má ṣe tẹ́tí sí wọn, ẹ máa sin ọba Babeli, ẹ̀yin yóò sì yè. Èéṣe tí ìlú yóò fi di ahoro?
18 Om de verkligen äro profeter och hava HERRENS ord, så må de lägga sig ut hos HERREN Sebaot, för att de kärl som ännu äro kvar i HERRENS hus och i Juda konungs hus och i Jerusalem icke också må föras bort till Babel
Tí wọ́n bá jẹ́ wòlíì, tí wọ́n sì ní ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ kí wọ́n bẹ Olúwa àwọn ọmọ-ogun kí a má ṣe kó ohun èlò tí ó kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
19 Ty så säger HERREN Sebaot om pelarna och havet och bäckenställen och det övriga som ännu är kvar här i staden,
Nítorí pé, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ nípa àwọn opó, omi Òkun ní ti ìpilẹ̀ṣẹ̀ àti ní ti ohun èlò ìyókù tí ó kù ní ìlú náà.
20 därför att Nebukadnessar, konungen i Babel, icke tog det med sig, när han förde bort Jekonja, Jojakims son, Juda konung, från Jerusalem till Babel, jämte alla ädlingar i Juda och Jerusalem --
Èyí tí Nebukadnessari ọba Babeli kò kó lọ nígbà tí ó mú Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí Babeli, pẹ̀lú àwọn ọlọ́lá Juda àti Jerusalẹmu.
21 ja, så säger HERREN Sebaot, Israels Gud, om det som ännu är kvar här i HERRENS hus och i Juda konungs hus och i Jerusalem:
Lóòótọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí nípa àwọn ohun ìṣúra tí ó ṣẹ́kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti ní Jerusalẹmu:
22 Till Babel skall det föras, och där skall det förbliva ända till den dag då jag ser därtill, säger HERREN, och för det upp till denna plats igen.
‘A ó mú wọn lọ sí ilẹ̀ Babeli, ní ibẹ̀ ni wọn ó sì wà títí di ìgbà tí mo bá padà,’ èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa. ‘Lẹ́yìn èyí, Èmi yóò mú wọn padà, Èmi yóò sì ṣe wọ́n lọ́jọ̀ ní ibí yìí.’”

< Jeremia 27 >