< Jeremia 2 >

1 Och HERRENS ord kom till mig; han sade:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé:
2 Gå åstad och predika för Jerusalem och säg: Så säger HERREN: Jag kommer ihåg, dig till godo, din ungdoms kärlek, huru du älskade mig under din brudtid, huru du följde mig i öknen, i landet där man intet sår.
“Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé: “Báyìí ni Olúwa wí, “‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ, ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù, nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.
3 Ja, en HERRENS heliga egendom är Israel, förstlingen av hans skörd; alla som vilja äta därav ådraga sig skuld, olycka kommer över dem, säger HERREN.
Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa, àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀, gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi, ibi yóò sì wá sí orí wọn,’” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.
4 Hören HERRENS ord, I av Jakobs hus, I alla släkter av Israels hus.
Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.
5 Så säger HERREN: Vad orätt funno edra fäder hos mig, eftersom de gingo bort ifrån mig och följde efter fåfängliga avgudar och bedrevo fåfänglighet?
Báyìí ni Olúwa wí: “Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi, tí wọ́n fi jìnnà sí mi? Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán, àwọn fúnra wọn sì di asán.
6 De frågade icke: "Var är HERREN, han som förde oss upp ur Egyptens land, han som ledde oss i öknen, det öde och oländiga landet, torrhetens och dödsskuggans land, det land där ingen vägfarande färdades, och där ingen människa bodde?"
Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà, tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, tí ó mú wa la aginjù já, tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò, ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri, ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’
7 Och jag förde eder in i det bördiga landet, och I fingen äta av dess frukt och dess goda. Men när I haden kommit ditin, orenaden I mitt land och gjorden min arvedel till en styggelse.
Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́, ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.
8 Prästerna frågade icke: "Var är HERREN?" De som hade lagen om händer ville icke veta av mig, och herdarna avföllo från mig; profeterna profeterade i Baals namn och följde efter sådana som icke kunde hjälpa.
Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé, ‘Níbo ni Olúwa wà?’ Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí, àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi. Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali, wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.
9 Därför skall jag än vidare gå till rätta med eder, säger HERREN, ja, ännu med edra barnbarn skall jag gå till rätta.
“Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,” ni Olúwa wí. “Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ.
10 Dragen bort till kittéernas öländer och sen efter, sänden bud till Kedar och forsken noga efter; sen till, om något sådant där har skett.
Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó, ránṣẹ́ lọ sí ìlú Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi; kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?
11 Har väl något hednafolk bytt bort sina gudar? Och dock äro dessa inga gudar. Men mitt folk har bytt bort sin ära mot en avgud som icke kan hjälpa.
Orílẹ̀-èdè kan ha á pa ọlọ́run rẹ̀ dà? (Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ ọlọ́run.) Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀ Ọlọ́run ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.
12 Häpnen häröver, I himlar; förskräckens och bäven storligen, säger HERREN.
Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,” ni Olúwa wí.
13 Ty mitt folk har begått en dubbel synd: mig hava de övergivit, en källa med friskt vatten, och de hava gjort sig brunnar, usla brunnar, som icke hålla vatten.
“Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì, wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi orísun omi ìyè, wọ́n sì ti ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè gba omi dúró.
14 Är väl Israel en träl eller en hemfödd slav, eftersom han så har lämnats till plundring?
Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀ ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a dé tí ó fi di ìkógun?
15 Lejon ryta mot honom, de låta höra sitt skri. De göra hans land till en ödemark, hans städer brännas upp, så att ingen kan bo i dem.
Àwọn kìnnìún ké ramúramù; wọ́n sì ń bú mọ́ wọn. Wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò; ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì ti di ìkọ̀sílẹ̀.
16 Till och med Nofs och Tapanhes' barn avbeta dina berg.
Bákan náà, àwọn ọkùnrin Memfisi àti Tafanesi wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.
17 Men är det ej du själv som vållar dig detta, därmed att du övergiver HERREN din Gud, när han vill leda dig på den rätta vägen?
Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí ara yín nípa kíkọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀ nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?
18 Varför vill du nu gå till Egypten och dricka av Sihors vatten? Och varför vill du gå till Assyrien och dricka av flodens vatten?
Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti láti lọ mu omi ní Ṣihori? Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?
19 Det är din ondska som bereder dig tuktan, det är din avfällighet som ådrager dig straff. Märk därför och besinna vilken olycka och sorg det har med sig att du övergiver HERREN, din Gud, och icke vill frukta mig, säger Herren, HERREN Sebaot.
Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀, ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
20 Ty för länge sedan bröt du sönder ditt ok och slet av dina band och sade: "Jag vill ej tjäna." Och på alla höga kullar och under alla gröna träd lade du dig ned för att öva otukt.
“Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ; ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’ Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀ ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.
21 Jag hade ju planterat dig såsom ett ädelt vinträd av alltigenom äkta art; huru har du då kunnat förvandlas för mig till vilda rankor av ett främmande vinträd?
Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá. Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi di àjàrà búburú àti aláìmọ́?
22 Ja, om du ock tvår dig med lutsalt och tager än så mycken såpa, så förbliver dock din missgärning oren inför mig, säger Herren, HERREN.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
23 Huru kan du säga: "Jag har ej orenat mig, jag har icke följt efter Baalerna"? Besinna vad du har bedrivit i dalen, ja, betänk vad du har gjort. Du är lik ett ystert kamelsto, som löper hit och dit.
“Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́, Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’? Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì; wo ohun tí o ṣe. Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ tí ń sá síyìn-ín sọ́hùn-ún.
24 Du är lik en vildåsna, fostrad i öknen, en som flåsar i sin brunst, och vars brånad ingen kan stävja; om någon vill till henne, behöver han ej löpa sig trött; när hennes månad kommer, träffar man henne.
Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ, ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀? Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara, nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.
25 Akta din fot, så att den icke tappar skon, och din strupe, så att den ej bliver torr av törst. Men du svarar: "Du mödar dig förgäves. Nej, jag älskar de främmande, och efter dem vill jag följa."
Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà, àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni! Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì, àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’
26 Såsom tjuven står där med skam, när han ertappas, så skall Israels hus komma på skam, med sina konungar, och furstar, med sina präster och profeter,
“Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u, bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli— àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.
27 dessa som säga till trästycket: "Du är min fader", och säga till stenen: "Du har fött mig." Ty de vända ryggen till mig och icke ansiktet; men när olycka är på färde, ropa de: "Upp och fräls oss!"
Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’ àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’ wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi, wọn kò kọ ojú sí mi síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro, wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’
28 Var äro då dina gudar, de som du gjorde åt dig? Må de stå upp. Kunna de frälsa dig i din olyckas tid? Ty så många som dina städer äro, så många hava dina gudar blivit, du Juda.
Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí ẹ ṣe fúnra yín ha a wà? Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì gbà yín nígbà tí ẹ bá wà nínú ìṣòro! Nítorí pé ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.
29 Huru kunnen I gå till rätta med mig? I haven ju alla avfallit från mig, säger HERREN.
“Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí? Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,” ni Olúwa wí.
30 Förgäves har jag slagit edra barn; de hava icke velat taga emot tuktan. Edert svärd har förtärt edra profeter, såsom vore det ett förhärjande lejon.
“Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín, wọn kò sì gba ìbáwí. Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run, gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.
31 Du onda släkte, giv akt på HERRENS ord. Har jag då för Israel varit en öken eller ett mörkrets land, eftersom mitt folk säger: "Vi hava gjort oss fria, vi vilja ej mer komma till dig"?
“Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa: “Mo ha ti di aginjù sí Israẹli tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri? Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé, ‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri; àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’
32 Icke förgäter en jungfru sina smycken eller en brud sin gördel? Men mitt folk har förgätit mig sedan urminnes tid.
Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀? Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.
33 Huru skickligt går du icke till väga, när du söker älskog! Därför har du ock blivit förfaren på det ondas vägar.
Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́! Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ.
34 Ja, på dina mantelflikar finner man blod av arma och oskyldiga, som du har dödat, icke därför att de ertappades vid inbrott, nej, därför att din håg står till allt sådant.
Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀ àwọn tálákà aláìṣẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́ níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé. Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí
35 Och dock säger du: "Jag går fri ifrån straff; hans vrede mot mig har förvisso upphört." Nej, jag vill gå till rätta med dig, om du än säger: "Jag har icke syndat."
ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀; kò sì bínú sí mi.’ Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’
36 Varför har du nu så brått att vandra åstad på en annan väg? Också med Egypten skall du komma på skam, likasom du kom på skam med Assyrien.
Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri láti yí ọ̀nà rẹ padà? Ejibiti yóò dójútì ọ́ gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria.
37 Också därifrån skall du få gå din väg, med händerna på huvudet. Ty HERREN förkastar dem som du förlitar dig på, och du skall icke bliva lyckosam med dem.
Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ, nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀, kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.

< Jeremia 2 >