< Hesekiel 31 >

1 I elfte året, på första dagen i tredje månaden, kom HERRENS ord till mig; han sade:
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kẹta ọdún kọkànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Du människobarn, säg till Farao, konungen i Egypten, och till hans larmande hop: Vem kan förliknas med dig i din storhet?
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún Farao ọba Ejibiti àti sí ìjọ rẹ̀: “‘Ta ní a le fiwé ọ ní ọláńlá?
3 Se, du är ett ädelt träd, en ceder på Libanon, med sköna grenar och skuggrik krona och hög stam, en som med sin topp räcker upp bland molnen.
Kíyèsi Asiria, tí ó jẹ́ igi kedari ni Lebanoni ní ìgbà kan rí, pẹ̀lú àwọn ẹ̀ka dáradára tí ó ṣẹ́ ìji bo igbó náà; tí ó ga sókè, òkè rẹ̀ lókè ni ewé tí ó nípọn wà.
4 Vatten gåvo den växt, djupets källor gjorde den hög. Ty med sina strömmar omflöto de platsen där den var planterad; först sedan sände de sina flöden till alla andra träd på marken.
Omi mú un dàgbàsókè: orísun omi tí ó jinlẹ̀ mú kí o dàgbàsókè; àwọn odo rẹ̀ ń sàn yí ìdí rẹ̀ ká, ó sì rán ìṣàn omi rẹ̀ sí gbogbo igi orí pápá.
5 Så fick den högre stam än alla träd på marken, den fick talrika kvistar och långa grenar, genom det myckna vatten den hade, när den sköt skott.
Nítorí náà ó ga sí òkè fíofío ju gbogbo igi orí pápá lọ; ẹ̀ka rẹ̀ pọ̀ sí i àwọn ẹ̀ka rẹ̀ sì gùn, wọn tẹ́ rẹrẹ nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.
6 Alla himmelens fåglar byggde sig nästen bland dess kvistar, under dess grenar födde alla markens djur sina ungar, och i dess skugga bodde allahanda stora folk.
Ẹyẹ ojú ọ̀run kọ ilé sí ẹ̀ka rẹ̀ gbogbo ẹranko igbó ń bímọ ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀; gbogbo orílẹ̀-èdè ńlá ń gbé abẹ́ ìji rẹ̀.
7 Och den blev skön genom sin storhet och genom sina grenars längd, där den stod med sin rot invid stora vatten.
Ọláńlá ní ẹwà rẹ̀ jẹ́, pẹ̀lú títẹ́ rẹrẹ ẹ̀ka rẹ̀, nítorí gbòǹgbò rẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ sí ibi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi wà.
8 Ingen ceder i Guds lustgård gick upp emot denna, ingen cypress hade kvistar som kunde förliknas med dennas, ingen lönn bar grenar, jämförliga med dennas; nej, intet träd i Guds lustgård liknade den i skönhet
Àwọn igi kedari nínú ọgbà Ọlọ́run kò lè è bò ó mọ́lẹ̀; tàbí kí àwọn igi junifa ṣe déédé pẹ̀lú ẹ̀ka rẹ̀, tàbí kí a fi igi títẹ́ rẹrẹ wé ẹ̀ka rẹ̀, kò sí igi nínú ọgbà Ọlọ́run tí ó dà bí rẹ̀ ní ẹwà rẹ̀.
9 Så skön hade jag låtit den bliva, i dess rikedom på grenar, att alla Edens träd i Guds lustgård måste avundas den.
Mo mú kí ó ní ẹwà pẹ̀lú ẹ̀ka lọ́pọ̀lọ́pọ̀ tó fi jẹ́ ìlara àwọn igi gbogbo ní Edeni tí í ṣe ọgbà Ọlọ́run.
10 Därför säger Herren, HERREN så Eftersom du växte så hög, ja, eftersom ditt träd sträckte sin topp upp bland molnen och förhävde sig i sitt hjärta över att det var så högt,
“‘Nítorí náà, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ó ga lọ sókè fíofío, tí ó sì gbé òkè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ, àti nítorí pé gíga rẹ mú kí ó gbéraga,
11 därför skall jag prisgiva det åt en som är väldig bland folken. Han skall förvisso utföra sitt verk därpå, ty för dess ogudaktighets skull har jag förkastat det.
mo fi lé alákòóso àwọn orílẹ̀-èdè náà lọ́wọ́, fún un láti fi ṣe ẹ̀tọ́ fún un gẹ́gẹ́ bí ìwà búburú rẹ̀. Mo pa á tì sí ẹ̀gbẹ́ kan,
12 Ja, främlingar hava fått hugga ned det, de grymmaste folk, och hava låtit det ligga. Dess kvistar hava nu fallit på bergen och i alla dalar; dess grenar hava blivit avbrutna och kastade i alla landets bäckar, och alla folk på jorden hava måst draga bort därifrån och försaka dess skugga och låta det ligga.
àwọn orílẹ̀-èdè àjèjì aláìláàánú jùlọ ké e lulẹ̀, wọn sì fi kalẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ ṣubú sórí òkè àti sí gbogbo àárín àwọn òkè; àwọn ẹ̀ka rẹ̀ tí ó ṣẹ nà sílẹ̀ ní gbogbo àlàfo jíjìn ilẹ̀. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ilẹ̀ ayé jáde kúrò ní abẹ́ ìji rẹ̀ wọn sì fi sílẹ̀.
13 På dess kullfallna stam bo alla himmelens fåglar, och på dess grenar lägra sig alla markens djur.
Gbogbo àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ṣe àtìpó ni orí igi tí ó ṣubú lulẹ̀ náà, gbogbo àwọn ẹranko igbó wà ní àárín ẹ̀ka rẹ̀.
14 Så sker, för att ett träd som växer vid vatten aldrig skall yvas över sin höjd och sträcka sin topp upp bland molnen; ja, för att icke ens de väldigaste av dem skola stå och yvas, intet träd som har haft vatten att dricka. Ty de äro allasammans hemfallna åt döden och måste ned i jordens djup, till att vara där bland människors barn, hos dem som hava farit ned i graven.
Nítorí náà kò sí igi mìíràn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi tí ó lè fi ìgbéraga ga sókè fíofío, tí yóò sì gbé sókè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ. Kò sí igi mìíràn tí ó ní omi tó bẹ́ẹ̀ tí ó lè ga tó bẹ́ẹ̀; gbogbo wọn ni a kádàrá ikú fún, fún ìsàlẹ̀ ilẹ̀, ní àárín àwọn alààyè ènìyàn, pẹ̀lú àwọn tí o lọ sí ọ̀gbun ní ìsàlẹ̀.
15 Så säger Herren, HERREN: På den dag då det for ned till dödsriket lät jag djupet för dess skull hölja sig i sorgdräkt; jag hämmade strömmarna där, och de stora vattnen höllos tillbaka. Jag lät Libanon för dess skull kläda sig i svart, och alla träd på marken förtvinade i sorg över det. (Sheol h7585)
“‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ ti a mú u wá sí isà òkú mo fi ọ̀fọ̀ ṣíṣe bo orísun omi jíjìn náà, mo dá àwọn ìṣàn omi rẹ̀ dúró, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi rẹ̀ ní a dí lọ́nà. Nítorí rẹ̀ mo fi ìwúwo ọkàn wọ Lebanoni ní aṣọ, gbogbo igi igbó gbẹ dànù. (Sheol h7585)
16 Genom dånet av dess fall kom jag folken att bäva, när jag störtade det ned i dödsriket, till dem som hade farit ned i graven. Men då tröstade sig i jordens djup alla Edens träd, de yppersta och bästa på Libanon, alla de som hade haft vatten att dricka. (Sheol h7585)
Mo mú kí orílẹ̀-èdè wárìrì sì ìró ìṣubú rẹ̀ nígbà tí mo mú un wá sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun ìsàlẹ̀. Nígbà náà gbogbo igi Edeni, àṣàyàn àti èyí tí ó dára jùlọ nínú Lebanoni, gbogbo igi tí ó ní omi dáradára ni a tù nínú ni ayé ìsàlẹ̀. (Sheol h7585)
17 Också de hade, såsom det trädet, måst fara ned till dödsriket, till dem som voro slagna med svärd; dit foro ock de som hade varit dess stöd och hade bott i dess skugga bland folken. (Sheol h7585)
Àwọn tí ó ń gbé ní abẹ́ òjìji rẹ̀, àwọn àjèjì rẹ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè náà, ti lọ sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú rẹ̀, ní dídárapọ̀ mọ́ àwọn tí a fi idà pa. (Sheol h7585)
18 Kan nu något bland Edens träd förliknas med dig i härlighet och storhet? Och dock skall du, såsom Edens träd, störtas ned i jordens djup och ligga där bland oomskurna, hos dem som äro slagna med svärd. Så skall det gå Farao och hela hans larmande hop, säger Herren, HERREN.
“‘Èwo lára igi Edeni ní a lè fiwé ọ ní dídán àti ọláńlá? Síbẹ̀ ìwọ, gan an wá sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn igi Edeni lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀; ìwọ yóò sùn ni àárín àwọn aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa. “‘Èyí yìí ní Farao àti ìjọ rẹ̀, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”

< Hesekiel 31 >