< 2 Krönikeboken 18 >

1 När Josafat nu hade kommit till stor rikedom och ära, befryndade han sig med Ahab.
Nísinsin yìí Jehoṣafati sì ní ọrọ̀ àti ọlá púpọ̀, ó sì dá àna pẹ̀lú Ahabu nípa fífẹ́ ọmọ rẹ̀.
2 Och efter några års förlopp for han ned till Ahab i Samaria. Och Ahab lät för honom och folket som han hade med sig slakta får och fäkreatur i myckenhet; och han sökte intala honom att draga upp mot Ramot i Gilead.
Lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, ó sọ̀kalẹ̀ láti lọ bá Ahabu lálejò ní Samaria. Ahabu sì pa àgùntàn àti màlúù púpọ̀ fún àti àwọn ènìyàn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ó sì rọ̀ ọ́ láti dojú ìjà kọ Ramoti Gileadi.
3 Ahab, Israels konung, frågade alltså Josafat, Juda konung: "Vill du draga med mig mot Ramot i Gilead?" Han svarade honom: "Jag såsom du, och mitt folk såsom ditt folk! Jag vill följa med dig i striden."
Ahabu ọba Israẹli sì béèrè lọ́wọ́ ọba Jehoṣafati, ọba Juda pé, “Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi sí Ramoti Gileadi?” Jehoṣafati sì dá a lóhùn pé, “Èmi wà gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe wà, àti àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ènìyàn rẹ àwa yóò pẹ̀lú rẹ nínú ogun náà”.
4 Men Josafat sade ytterligare till Israels konung: "Fråga dock först HERREN härom."
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati náà sì tún wí fún ọba Israẹli pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”
5 Då församlade Israels konung profeterna, fyra hundra män, och frågade dem: "Skola vi draga åstad till Ramot i Gilead för att belägra det, eller skall jag avstå därifrån?" De svarade: "Drag ditupp; Gud skall giva det i konungens hand."
Bẹ́ẹ̀ ọba Israẹli kó àwọn wòlíì papọ̀, irinwó ọkùnrin ó sì bi wọ́n pé, “Kí àwa kí lọ sí ogun Ramoti Gileadi tàbí kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ?” Wọ́n dáhùn pé, “Lọ, nítorí tí Ọlọ́run yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
6 Men Josafat sade: "Finnes här ingen annan HERRENS profet, så att vi kunna fråga genom honom?"
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati béèrè pé, “Ṣé kò ha sí wòlíì Olúwa níbí ẹni tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”
7 Israels konung svarade Josafat: "Här finnes ännu en man, Mika, Jimlas son, genom vilken vi kunna fråga HERREN; men han är mig förhatlig, ty han profeterar aldrig lycka åt mig, utan beständigt allenast olycka." Josafat sade: "Konungen säge icke så."
Ọba Israẹli dá Jehoṣafati lóhùn pé, “Ọkùnrin kan wà síbẹ̀ lọ́dọ̀ ẹni tí àwa ìbá tún béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n èmi kórìíra rẹ̀ nítorí kò jẹ́ sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun rere kan nípa mi ṣùgbọ́n bí kò ṣe ohun búburú, ní gbogbo ìgbà òun náà ni Mikaiah ọmọ Imla.” Jehoṣafati sì dá lóhùn pé, “Ọba kò gbọdọ̀ sọ bẹ́ẹ̀.”
8 Då kallade Israels konung till sig en hovman och sade: "Skaffa skyndsamt hit Mika, Jimlas son."
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pe ọ̀kan lára àwọn ìjòyè ó sì wí pé, “Ẹ mú Mikaiah ọmọ Imla kí ó yára wá.”
9 Israels konung och Josafat, Juda konung, sutto nu var och en på sin tron, iklädda sina skrudar; de sutto på en tröskplats vid Samarias port, under det att alla profeterna profeterade inför dem.
Wọ́n wọ aṣọ ìgúnwà wọn, ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda wọ́n jókòó sórí ìtẹ́ wọ́n ní ìta ẹnu-bodè Samaria, pẹ̀lú gbogbo àwọn wòlíì tí ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn.
10 Då gjorde sig Sidkia, Kenaanas son, horn av järn och sade: "Så säger HERREN: Med dessa skall du stånga araméerna, så att de förgöras."
Nísinsin yìí Sedekiah ọmọ Kenaana sì ti ṣe ìwo irin, ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Pẹ̀lú èyí ìwọ yóò kan àwọn ará Siria títí ìwọ ó fi pa wọ́n run.’”
11 Och alla profeterna profeterade på samma sätt och sade: "Drag upp mot Ramot i Gilead, så skall du bliva lyckosam; HERREN skall giva det i konungens hand."
Gbogbo àwọn wòlíì tí ó kù ni wọn ń sọtẹ́lẹ̀ ní àkókò kan náà. Wọ́n sì wí pé, “Dojúkọ Ramoti Gileadi ìwọ yóò sì ṣẹ́gun, nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
12 Och budet som hade gått för att kalla på Mika talade till honom och sade: "Det är så, att profeterna med en mun lova konungen lycka; så låt nu ock ditt tal stämma överens med deras, och lova också du lycka."
Ìránṣẹ́ tí ó ti lọ pe Mikaiah sì wí fún un pé, “Ẹ wò ó, gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin kan àti òmíràn wòlíì fi ẹnu kan sọ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ kí ó dàbí ọ̀kan nínú tiwọn, kí o sì sọ rere.”
13 Men Mika svarade: "Så sant HERREN lever, jag skall allenast tala det som min Gud säger."
Ṣùgbọ́n Mikaiah wí pe, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa ń bẹ láààyè, èmi yóò sọ ohun tí Ọlọ́run mi sọ.”
14 När han sedan kom till konungen, frågade konungen honom: "Mika, skola vi draga åstad till Ramot i Gilead för att belägra det, eller skall jag avstå därifrån?" Han svarade: "Dragen ditupp, så skolen I bliva lyckosamma; de skola bliva givna i eder hand."
Nígbà tí ó dé, ọba béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, “Mikaiah, ṣe kí àwa ki ó lọ sí ogun ti Ramoti Gileadi, tàbí kí àwa kí ó fàsẹ́yìn?” Ó sì dáhùn pé, “Ẹ dojúkọ wọ́n kí ẹ sì ṣẹ́gun, nítorí a ó fi wọ́n lé yín lọ́wọ́.”
15 Men konungen sade till honom: "Huru många gånger skall jag besvärja dig att icke tala till mig annat än sanning i HERRENS namn?"
Ọba sì wí fún un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi ó fi ọ́ búra láti sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe ọ̀rọ̀ òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”
16 Då sade han: "Jag såg hela Israel förskingrat på bergen, likt får som icke hava någon herde. Och HERREN sade: 'Dessa hava icke någon herre; må de vända tillbaka hem i frid, var och en till sitt.'"
Mikaiah sì dáhùn pé, “Mo rí gbogbo Israẹli túká kiri lórí àwọn òkè bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn wọ̀nyí kò ní olúwa. Jẹ́ kí olúkúlùkù padà sí ilé rẹ̀ ní àlàáfíà.’”
17 Då sade Israels konung till Josafat: "Sade jag dig icke att denne aldrig profeterar lycka åt mig, utan allenast olycka?"
Ọba Israẹli wí fún Jehoṣafati pé, “Ṣe èmi kò sọ fún ọ wí pé òun kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kankan nípa mi rí, ṣùgbọ́n búburú nìkan?”
18 Men han sade: "Hören alltså HERRENS ord. Jag såg HERREN sitta på sin tron och himmelens hela härskara stå på hans högra sida och på hans vänstra.
Mikaiah tẹ̀síwájú pé, “Nítorí náà, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, mo rí Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀ gbogbo ogun ọ̀run sì dúró lápá ọ̀tún àti lápá òsì.
19 Och HERREN sade: 'Vem vill locka Ahab, Israels konung, att draga upp mot Ramot i Gilead, för att han må falla där?' Då sade den ene så och den andre så.
Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Ahabu ọba Israẹli lọ sí Ramoti Gileadi kí ó sì lọ kú ikú rẹ̀ níbẹ̀?’ “Èkínní sì sọ tìhín, òmíràn sì sọ tọ̀hún.
20 Slutligen kom anden fram och ställde sig inför HERREN och sade: 'Jag vill locka honom därtill.' HERREN frågade honom: 'På vad sätt?'
Ní ìparí, ni ẹ̀mí kan wá síwájú, ó dúró níwájú Olúwa ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’ “‘Nípa ọ̀nà wo?’ Olúwa béèrè.
21 Han svarade: 'Jag vill gå ut och bliva en lögnens ande i alla hans profeters mun." Då sade han: 'Du må försöka att locka honom därtill och du skall också lyckas; gå ut och gör så.'
“‘Èmi yóò lọ láti lọ di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì.’ “‘Ìwọ yóò sì borí nínú ìtànjẹ rẹ̀ báyìí,’ ni Olúwa wí. ‘Lọ kí ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.’
22 Och se, nu har HERREN lagt en lögnens ande i dessa dina profeters mun, medan HERREN ändå har beslutit att olycka skall komma över dig."
“Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu àwọn wòlíì rẹ. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”
23 Då trädde Sidkia, Kenaanas son, fram och gav Mika ett slag på kinden och sade: "På vilken väg har då HERRENS Ande gått bort ifrån mig för att tala med dig?"
Nígbà náà Sedekiah ọmọ Kenaana lọ sókè ó sì gbá Mikaiah ní ojú. Ó sì béèrè pé, “Ní ọ̀nà wo ni ẹ̀mí Olúwa gbà kọjá lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?”
24 Mika svarade: "Du skall få se det på den dag då du nödgas springa från kammare till kammare för att gömma dig."
Mikaiah sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò ṣe ìwádìí ní ọjọ́ tí ìwọ yóò sá pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.”
25 Men Israels konung sade: "Tagen Mika och fören honom tillbaka till Amon, hövitsmannen i staden, och till Joas, konungasonen.
Ọba Israẹli pa á láṣẹ pé, “Mú Mikaiah kí o sì ran padà sí Amoni olórí ìlú àti sí Joaṣi ọmọ ọba,
26 Och sägen: Så säger konungen: Sätten denne i fängelse och bespisen honom med fångkost, till dess jag kommer välbehållen tillbaka."
Ó sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí ọba sọ, ẹ fi ènìyàn yìí sínú túbú kí ẹ má sì ṣe fún un ní ohunkóhun ṣùgbọ́n àkàrà àti omi títí tí èmi yóò fi dé ní àlàáfíà.’”
27 Mika svarade: "Om du kommer välbehållen tillbaka, så har HERREN icke talat genom mig." Och han sade ytterligare: "Hören detta, I folk, allasammans."
Mikaiah sì wí pe, “Tí ìwọ bá padà ní àlàáfíà, Olúwa kò sọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.” Nígbà náà, ó sì fi kún un pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn!”
28 Så drog nu Israels konung jämte Josafat, Juda konung, upp till Ramot i Gilead.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda lọ sókè ní Ramoti Gileadi.
29 Och Israels konung sade till Josafat: "Jag vill förkläda mig, när jag drager ut i striden, men du må vara klädd i dina egna kläder." Så förklädde sig Israels konung, när de drogo ut i striden.
Ọba Israẹli sọ fún Jehoṣafati pé, “Èmi yóò lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ wọ aṣọ ìgúnwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pa aṣọ rẹ̀ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.
30 Men konungen i Aram hade bjudit och sagt till sina vagnshövitsmän: "I skolen icke giva eder i strid med någon, vare sig liten eller stor, utom med Israels konung allena."
Nísinsin yìí ọba Siria ti pàṣẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ tí ó wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ má ṣe jà pẹ̀lú ẹnìkankan, èwe tàbí àgbà àyàfi ọba Israẹli.”
31 När då hövitsmannen över vagnarna fingo se Josafat, tänkte de: "Detta är Israels konung", och omringade honom därför, i avsikt att anfalla honom. Då gav Josafat upp ett rop, och HERREN hjälpte honom, Gud vände dem bort ifrån honom.
Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rí Jehoṣafati, wọ́n rò wí pé, “Èyí ní ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yípadà láti bá a jà. Ṣùgbọ́n Jehoṣafati kégbe sókè, Olúwa sì ràn án lọ́wọ́. Ọlọ́run sì lé wọn kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀,
32 Så snart nämligen hövitsmännen över vagnarna märkte att det icke var Israels konung, vände de om och läto honom vara.
Ó sì ṣe, nígbà tí olórí kẹ̀kẹ́ rí i wí pé kì í ṣe ọba Israẹli, wọ́n sì dáwọ́ lílé rẹ̀ dúró.
33 Men en man som spände sin båge och sköt på måfå träffade Israels konung i en fog på rustningen. Då sade denne till sin körsven: "Sväng om vagnen och för mig ut ur hären, ty jag är sårad."
Ṣùgbọ́n ẹnìkan fa ọrun rẹ̀ láì pète, ó sì bá ọba Israẹli láàrín ìpàdé ẹ̀wù irin, ọba sì sọ fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ padà, kí o sì wà mí jáde kúrò lójú ìjà. Nítorí èmi ti gbọgbẹ́.”
34 Och striden blev på den dagen allt häftigare, och Israels konung höll sig ända till aftonen upprätt i sin vagn, vänd mot araméerna; men vid den tid då solen gick ned gav han upp andan.
Ní ọjọ́ pípẹ́, ìjà náà sì ń pọ̀ sí i, ọba Israẹli dúró nínú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ kọjú sí àwọn ará Siria títí ó fi di àṣálẹ́. Lẹ́yìn náà ní àkókò ìwọ oòrùn, ó sì kú.

< 2 Krönikeboken 18 >