< Números 25 >

1 Cuando Israel vivía en Sitim, y el pueblo empezó a fornicar con las hijas de Moab:
Nígbà tí àwọn Israẹli dúró ní Ṣittimu, àwọn ènìyàn sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin Moabu,
2 Porque enviaron para que la gente estuviera presente en las ofrendas hechas a sus dioses; y la gente tomó parte en sus fiestas y honró a sus dioses.
tí ó pè wọ́n sí ibi ẹbọ òrìṣà wọn. Àwọn ènìyàn náà jẹun wọ́n sì foríbalẹ̀ níwájú òrìṣà wọn.
3 Así que Israel tuvo relaciones con las mujeres de Moab en honor del Baal-Peor. Y el Señor se enfureció contra Israel.
Báyìí ni Israẹli ṣe darapọ̀ mọ́ wọn tí wọ́n sì jọ ń sin Baali-Peori. Ìbínú Olúwa sì ru sí wọn.
4 Entonces el Señor le dijo a Moisés: Toma a todos los jefes del pueblo, ahorcarlos y ponlos en el sol delante del Señor, para que la ira del Señor se aparte de Israel.
Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú gbogbo àwọn olórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, pa wọ́n kí o sì fi wọ́n kọ́ sórí igi ní gbangba nínú oòrùn níwájú Olúwa, kí ìbínú Olúwa lè kúrò ní ọ̀dọ̀ Israẹli.”
5 Entonces Moisés dijo a los jueces de Israel: Maten a todos aquellos de sus hombres que han tenido relaciones con las mujeres de Moab en honor al Baal de Peor.
Mose sọ fún àwọn onídàájọ́ Israẹli, “Ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbọdọ̀ pa arákùnrin rẹ̀ èyí tí ó darapọ̀ ní fífi orí balẹ̀ fún Baali-Peori.”
6 Entonces uno de los hijos de Israel se acercó a sus hermanos, llevando consigo a una mujer de Madián, ante los ojos de Moisés y de toda la reunión del pueblo, mientras lloraban a la puerta de la Tienda de reunión.
Nítòótọ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọkùnrin Israẹli sì mú obìnrin Midiani wá síwájú ojú Mose àti gbogbo ìjọ ti Israẹli wọ́n sì ń sọkún ní àbáwọlé àgọ́ ìpàdé.
7 Y al ver Finees, hijo de Eleazar, hijo de Aarón el sacerdote, se levantó de entre el pueblo y tomó una lanza en su mano.
Nígbà tí Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni, àlùfáà, rí èyí, ó fi ìjọ sílẹ̀, pẹ̀lú ọ̀kọ̀ ní ọwọ́ rẹ̀.
8 Y fue tras el hombre de Israel a la tienda, conduciendo la lanza a través de los dos, a través del hombre de Israel y a través del estómago de la mujer. Así se detuvo la enfermedad entre los hijos de Israel.
Ó sì tẹ̀lé arákùnrin Israẹli yìí lọ sínú àgọ́. Ó sì fi ọ̀kọ̀ gún àwọn méjèèjì ní àgúnyọ láti ara ọkùnrin Israẹli àti sí ara obìnrin náà. Nígbà náà ni àjàkálẹ̀-ààrùn lórí àwọn ọmọ Israẹli sì dúró;
9 Pero veinticuatro mil de ellos habían muerto por la enfermedad.
ṣùgbọ́n gbogbo àwọn tí ó kú nínú àjàkálẹ̀-ààrùn náà jẹ́ ẹgbàá méjìlá.
10 Y él Señor dijo a Moisés:
Olúwa sì tún sọ fún Mose pé,
11 A través de Finees, y debido a su pasión por mi honor, mi ira ha sido apartada de los hijos de Israel, por lo que no he enviado destrucción sobre ellos en mi ira.
“Finehasi ọmọ Eleasari ọmọ Aaroni, àlùfáà, ti yí ìbínú mi padà kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli, nítorí tí ó ní ìtara bí èmi náà ti ní ìtara fún iyì mi láàrín wọn, kí ó lè jẹ́ pé èmi ló pa wọ́n run nínú ìtara mi sí wọn.
12 Entonces diles a ellos que les doy un acuerdo de paz.
Nítorí náà sọ fún un pé èmi ṣe májẹ̀mú àlàáfíà mi pẹ̀lú rẹ̀.
13 Y por este acuerdo, él y sus hijos después de él tienen el derecho de ser sacerdotes para siempre; porque, por su cuidado por el honor de su Dios, quitó el pecado de los hijos de Israel.
Òun àti irú-ọmọ rẹ̀ yóò ní májẹ̀mú láéláé fún iṣẹ́ àlùfáà, nítorí pé ó ní ìtara fún Ọlọ́run rẹ̀ láti fi yẹ́ Ọlọ́run sí, ó sì ṣe ètùtù fún àwọn ọmọ Israẹli.”
14 Ahora bien, el hombre de Israel que fue condenado a muerte con la mujer de Madián fue Zimri, el hijo de Salu, el jefe de una de las familias de Simeón.
Orúkọ ọmọ Israẹli tí a pa pẹ̀lú obìnrin Midiani náà ni Simri, ọmọ Salu, olórí ilé kan nínú àwọn ọmọ Simeoni.
15 Y la mujer de Madián que fue condenada a muerte fue Cozbi, la hija de Zur; Él era el jefe de una familia en Madián.
Orúkọ ọmọbìnrin Midiani náà tí a pa ní Kosbi ọmọbìnrin Suri, tí ṣe olóyè àwọn ẹ̀yà kan nínú ìdílé kan ní Midiani.
16 Entonces el SEÑOR dijo a Moisés:
Olúwa sì tún sọ fún Mose pé,
17 Hostiguen a los madianitas y atácalos;
“Ka àwọn ará Midiani sí ọ̀tá, kí o sì pa wọ́n,
18 Porque así como los afligieron con sus engaños, con los que los engañaron a ustedes al adorar a Baal-Peor, y en él caso de Cozbi, su hermana, la hija del jefe de Midian, quien fue ejecutada en el momento de la enfermedad que vino sobre ustedes por causa de Baal-Peor.
nítorí pé wọ́n ṣe sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá nígbà tí wọ́n tàn yín nípa ìṣẹ̀lẹ̀ Peori, àti arábìnrin wọn Kosbi ọmọbìnrin ìjòyè Midiani kan, obìnrin tí a pa nígbà tí àjàkálẹ̀-ààrùn ṣẹlẹ̀ nítorí Peori.”

< Números 25 >