< Salmos 130 >

1 De los profundos te llamo, o! Jehová.
Orin fún ìgòkè. Láti inú ibú wá ni èmi ń ké pè é ọ́ Olúwa
2 Señor, oye mi voz. Sean tus orejas atentas a la voz de mi oración.
Olúwa, gbóhùn mi, jẹ́ kí etí rẹ kí o tẹ́ sílẹ̀ sí ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
3 Jehová, si mirares a los pecados, Señor ¿quién persistirá?
Olúwa, ìbá ṣe pé kí ìwọ máa sàmì ẹ̀ṣẹ̀, Olúwa, tá ni ìbá dúró.
4 Por lo cual hay perdón acerca de ti: para que seas temido.
Nítorí ìdáríjì wà lọ́dọ̀ rẹ, kí a lè máa bẹ̀rù rẹ.
5 Yo esperé a Jehová, mi alma esperó: a su palabra he esperado.
Èmi dúró de Olúwa, ọkàn mi dúró, àti nínú ọ̀rọ̀ rẹ ni èmi ń ṣe ìrètí.
6 Mi alma esperó a Jehová, más que las guardas esperan a la mañana: las guardas a la mañana.
Ọkàn mi dúró de Olúwa, ju àwọn tí ń ṣọ́nà òwúrọ̀ lọ, àní ju àwọn tí ń ṣọ́nà òwúrọ̀ lọ.
7 Espere Israel a Jehová, porque con Jehová está la misericordia; y abundante redención cerca de él.
Israẹli, ìwọ ní ìrètí ní ti Olúwa: nítorí pé lọ́dọ̀ Olúwa ni àánú wà, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìdáǹdè wà.
8 Y él redimirá a Israel de todos sus pecados.
Òun ó sì dá Israẹli ní ìdè kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ gbogbo.

< Salmos 130 >