< Josué 15 >

1 Y fue la suerte de la tribu de los hijos de Judá por sus familias junto al término de Edom del desierto de Zin al mediodía al lado del Sur.
Ìpín fún ẹ̀yà Juda, ní agbo ilé agbo ilé, títí dé agbègbè Edomu, títí dé aginjù Sini ní òpin ìhà gúúsù.
2 Y su término de la parte del mediodía fue desde la costa de la mar salada, desde la lengua que mira hacia el mediodía.
Ààlà wọn ní ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ láti etí òpin ìhà gúúsù Òkun Iyọ̀,
3 Y de allí salía hacia el mediodía a la subida de Acrabim pasando hasta Zín; y subiendo por el mediodía hasta Cádes-barne, pasando a Jesrón, y subiendo por Addar daba vuelta a Carcaa.
ó sì gba gúúsù Akrabbimu lọ, títí dé Sini àti sí iwájú ìhà gúúsù Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà ó sì tún kọjá Hesroni lọ sí Adari, ó sì tún yípo yíká lọ sí Karka.
4 De allí pasaba a Asemona, y salía al arroyo de Egipto: y sale este término al occidente. Este pues os será el término del mediodía.
Ó tún kọjá lọ sí Asmoni, ó sì papọ̀ mọ́ Wadi ti Ejibiti, ó parí sí Òkun. Èyí ni ààlà wọn ní ìhà gúúsù.
5 El término del oriente es la mar salada hasta el fin del Jordán: Y el término de la parte del norte, desde la lengua de la mar, desde el fin del Jordán.
Ààlà wọn ní ìhà ìlà-oòrùn ní Òkun Iyọ̀ títí dé ẹnu Jordani. Ààlà àríwá bẹ̀rẹ̀ láti etí òkun ní ẹnu Jordani,
6 Y este término sube por Bet-agla, y pasa del norte a Bet-araba; y de aquí sube este término a la piedra de Boen hijo de Rubén.
ààlà náà sì tún dé Beti-Hogla, ó sì lọ sí ìhà àríwá Beti-Araba. Ààlà náà sì tún dé ibi Òkúta Bohani ti ọmọ Reubeni.
7 Y torna a subir este término a Debera desde el valle de Acor: y al norte mira sobre Galgala, que está delante de la subida de Adommim, la cual está al mediodía del arroyo: y pasa este término a las aguas de Ensames, y sale a la fuente de Rogel.
Ààlà náà gòkè lọ títí dé Debiri láti àfonífojì Akori, ó sì yípadà sí àríwá Gilgali, èyí tí ń bẹ ní iwájú òkè Adummimu, tí ń bẹ ní ìhà gúúsù odò náà. Ó sì tẹ̀síwájú sí apá omi En-Ṣemeṣi, ó sì jáde sí En-Rogeli.
8 Y sube este término del valle del hijo de Ennom al lado del Jebuseo al mediodía. Esta es Jerusalem. Y sube este término por la cumbre del monte que está delante del valle de Ennom hacia el occidente, el cual está al cabo del valle de los gigantes al norte.
Ààlà náà sì tún gòkè lọ sí àfonífojì Beni-Hinnomu ní ìhà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ gúúsù ti Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu). Ó sì gòkè lọ sí orí òkè tí ó wà lórí àfonífojì Hinnomu tí ń bẹ ní ìpẹ̀kun àfonífojì Refaimu ní ìhà àríwá.
9 Y rodea este término desde la cumbre del monte hasta la fuente de las aguas de Neftoa, y sale a las ciudades del monte de Efrón: y rodea este término a Baala, la cual es Cariat-jarim.
Ààlà náà sì lọ láti orí òkè lọ sí ìsun omi Nefitoa, ó sì jáde sí ìlú òkè Efroni, ó sì lọ sí apá ìsàlẹ̀ Baalahi (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu).
10 Y torna este término desde Baala hacia el occidente al monte de Seir: y pasa al lado del monte de Jarim hacia el norte, esta es Queslón y desciende a Bet-sames, y pasa a Tamna.
Ààlà tí ó yípo láti Baalahi lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn sí òkè Seiri, ó sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Jearimu (tí í ṣe, Kesaloni), ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beti-Ṣemeṣi, ó sì kọjá lọ sí Timna.
11 Y sale este término al lado de Accarón hacia el norte, y rodea este término a Secrón, y pasa por el monte de Baala, y sale a Jebneel: y sale este término a la mar.
Ààlà náà sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Ekroni, ó sì yípadà lọ sí Ṣikkeroni, ó sì yípadà lọ sí òkè Baalahi, ó sì dé Jabneeli, ààlà náà sì parí sí Òkun.
12 El término del occidente es la mar grande. Y este término es el término de los hijos de Judá al derredor por sus familias.
Ààlà ìwọ̀-oòrùn sì jẹ́ agbègbè Òkun Ńlá. Ìwọ̀nyí ni ààlà àyíká ènìyàn Juda ní agbo ilé wọn.
13 Mas a Caleb, hijo de Jefone, dio parte entre los hijos de Judá conforme al mandamiento de Jehová a Josué, a Cariat-arbe del padre de Enac, que es Hebrón.
Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Olúwa pa fún Joṣua, ó fi ìpín fún Kalebu ọmọ Jefunne, ìpín ní Juda—Kiriati-Arba, tí í ṣe Hebroni. (Arba sì ní baba ńlá Anaki.)
14 Y Caleb echó de allí tres hijos de Enac: Sesai, Ahimam, y Tolmai, que fueron hijos de Enac.
Kalebu sì lé àwọn ọmọ Anaki mẹ́ta jáde láti Hebroni; Ṣeṣai, Ahimani, àti Talmai, ìran Anaki.
15 De aquí subió a los que moraban en Dabir, y el nombre de Dabir era antes Cariat-sefer.
Ó sì wọ́de ogun láti ibẹ̀ lọ bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Debiri (tí à ń pè ní Kiriati-Seferi nígbà kan rí).
16 Y dijo Caleb: Al que hiriere a Cariat-sefer, y la tomare, yo le daré a mi hija Aja por mujer.
Kalebu sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọbìnrin mi Aksa fún ọkùnrin tí ó bá kọlu Kiriati-Seferi, tí ó sì gbà á ní ìgbéyàwó.”
17 Y tomóla Otoniel hijo de Cenez hermano de Caleb: y él le dio por mujer a su hija Aja:
Otnieli ọmọ Kenasi, arákùnrin Kalebu, sì gbà á, báyìí ni Kalebu sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Aksa fún un ní ìyàwó.
18 Y aconteció que cuando la llevaban, él la persuadió que pidiese a su padre tierras para labrar. Ella entonces descendió del asno. Y Caleb le dijo: ¿Qué tienes?
Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Aksa lọ sí ọ̀dọ̀ Otnieli, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà náà ni Aksa sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kalebu sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”
19 Y ella respondió. Dáme alguna bendición: pues que me has dado tierra de secadal, dáme también fuentes de aguas. El entonces le dio las fuentes de arriba, y las de abajo.
Ó sì dáhùn pé, “Mo ń fẹ́ kí o ṣe ojúrere kan fún mi, nígbà ti o ti fún mi ní ilẹ̀ ní gúúsù, fún mi ní ìsun omi náà pẹ̀lú.” Kalebu sì fún un ní ìsun òkè àti ìsun ìsàlẹ̀.
20 Esta pues es la herencia de la tribu de los hijos de Judá por sus familias.
Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bi ìdílé wọn.
21 Y fueron las ciudades del término de la tribu de los hijos de Judá hacia el término de Edom al mediodía, Cabseel, y Eder, y Jagur,
Ìlú ìpẹ̀kun gúúsù ti ẹ̀yà Juda ní gúúsù ní ààlà Edomu nìwọ̀nyí: Kabṣeeli, Ederi, Jaguri,
22 Y Cina, y Demona, y Adada,
Kina, Dimona, Adada,
23 Y Cedes, y Asor, y Jetnán,
Kedeṣi, Hasori, Itina,
24 Zif, y Telén, y Balot,
Sifi, Telemu, Bealoti,
25 Y Asor, Hadata, y Cariot, Jesrón, que es Asor,
Hasori Hadatta, Kerioti Hesroni (tí í ṣe Hasori),
26 Amán, y Sama, y Molada,
Amamu, Ṣema, Molada,
27 Y Asar-gadda, y Hassemón, Bet-felet,
Hasari Gada, Heṣmoni, Beti-Peleti,
28 Y Haser-sual, Beer-seba, y Baziotia,
Hasari-Ṣuali, Beerṣeba, Bisiotia,
29 Baala, y Jim, y Esem,
Baalahi, Limu, Esemu,
30 Y Eltolad, y Cesil, y Jarma,
Eltoladi, Kesili, Horma,
31 Y Siceleg, y Medema, Sensena,
Siklagi, Madmana, Sansanna,
32 Y Lebaot, Selim, y Aén, y Remmon; en todas veinte y nueve ciudades con sus aldeas:
Leboati, Ṣilhimu, Aini àti Rimoni, àpapọ̀ ìlú mọ́kàndínlọ́gbọ̀n àti àwọn ìletò wọn.
33 En las campañas, Estoal, y Sarea, y Asena,
Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ẹsẹ̀ òkè: Eṣtaoli, Sora, Aṣna,
34 Y Zanoe, y Engennim, Tappua, y Enaim,
Sanoa, Eni-Gannimu, Tapua, Enamu,
35 Jerimot, y Adullam, Soco, y Azeca,
Jarmatu, Adullamu, Soko, Aseka,
36 Y Saraim, y Aditaim, y Gedera, y Gederotaim; catorce ciudades con sus aldeas:
Ṣaaraimu, Adittaimu àti Gedera (tàbí Gederotaimu). Ìlú mẹ́rìnlá àti àwọn ìletò wọn.
37 Sanán, y Hadassa, y Magdalgad,
Senani, Hadaṣa, Migdali Gadi,
38 Y Deleán, y Masepa, y Jectel,
Dileani, Mispa, Jokteeli,
39 Laquis, y Bascat, y Eglón,
Lakiṣi, Boskati, Egloni,
40 Y Quebbón, y Lehemán, y Cetlis,
Kabboni, Lamasi, Kitlisi,
41 Y Giderot, Bet-dagón, y Naama, y Maceda; diez y seis ciudades con sus aldeas:
Gederoti, Beti-Dagoni, Naama àti Makkeda, ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
42 Labana, y Eter, y Asán,
Libina, Eteri, Aṣani,
43 Y Jefta, y Esna, y Nesib,
Hifita, Aṣna, Nesibu,
44 Y Ceila, y Aczib, y Maresa; nueve ciudades con sus aldeas:
Keila, Aksibu àti Meraṣa: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò wọn.
45 Accarón con sus villas y sus aldeas:
Ekroni, pẹ̀lú ibùgbé àti àwọn ìletò rẹ̀ tó yí i ká,
46 Desde Accarón hasta la mar; todas las que están a la costa de Azoto con sus aldeas:
ìwọ̀-oòrùn Ekroni, gbogbo èyí tí ń bẹ nítòsí Aṣdodu, pẹ̀lú àwọn ìletò wọn,
47 Azoto con sus villas y sus aldeas; Gaza con sus villas y sus aldeas hasta el río de Egipto, y la gran mar con sus términos:
Aṣdodu, agbègbè ìlú rẹ̀ àti ìletò; àti Gasa, ìlú rẹ̀ àti ìletò, títí ó fi dé odò Ejibiti àti agbègbè Òkun Ńlá.
48 Y en las montañas Samir, y Jeter, y Socot,
Ní ilẹ̀ òkè náà: Ṣamiri, Jattiri, Soko,
49 Y Danna, y Cariat-senna, que es Dabir,
Dannah, Kiriati-Sannnah (tí í ṣe Debiri),
50 Y Anab, e Istemo, y Anim,
Anabu, Eṣitemo, Animu,
51 Y Gosén, y Olón, y Gilo; once ciudades con sus aldeas:
Goṣeni, Holoni àti Giloni, ìlú mọ́kànlá àti ìletò wọn.
52 Arab, y Duma, y Esaán,
Arabu, Duma, Eṣani,
53 Y Janum, y Bet-tappua, y Afeca,
Janimu, Beti-Tapua, Afeka,
54 Y Atmata, y Cariat-arbe, que es Hebrón, y Sior; nueve ciudades con sus aldeas:
Hamuta, Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) àti Ṣiori: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò rẹ̀
55 Maón, Carmel, y Zif, y Jota,
Maoni, Karmeli, Sifi, Jutta,
56 Y Jezrael, Jucadam, y Zanoe,
Jesreeli, Jokdeamu, Sanoa,
57 Accaim, Gabaa, y Tamma; diez ciudades con sus aldeas:
Kaini, Gibeah àti Timna: ìlú mẹ́wàá àti àwọn ìletò wọn.
58 Halul, y Betsur, y Gedeor,
Halhuli, Beti-Suri, Gedori,
59 Y Maret, y Bet-anot, y Eltecon; seis ciudades con sus aldeas:
Maarati, Beti-Anoti àti Eltekoni: ìlú mẹ́fà àti àwọn ìletò wọn.
60 Cariat-baal que es Cariat-jarim, y Arebba; dos ciudades con sus aldeas:
Kiriati-Baali (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu) àti Rabba ìlú méjì àti ìletò wọn.
61 En el desierto, Bet-araba, Meddín, y Sacaca,
Ní aginjù: Beti-Araba, Middini, Sekaka,
62 Y Nebsán, y la ciudad de la sal, y Engadí: seis ciudades con sus aldeas.
Nibṣani, Ìlú Iyọ̀ àti En-Gedi: ìlú mẹ́fà àti ìletò wọn.
63 Mas los Jebuseos que habitaban en Jerusalem, los hijos de Judá no los pudieron desarraigar: antes quedó el Jebuseo en Jerusalem con los hijos de Judá hasta hoy.
Juda kò lè lé àwọn ọmọ Jebusi jáde, tí wọ́n ń gbé ní Jerusalẹmu. Àwọn ará Jebusi sì ń gbé pẹ̀lú àwọn ènìyàn Juda títí dí òní.

< Josué 15 >