< Job 40 >

1 Y respondió Jehová a Job, y dijo:
Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,
2 ¿Es sabiduría contender con el Omnipotente? El que disputa con Dios, responda a esto.
“Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́? Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”
3 Y respondió Job a Jehová, y dijo:
Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,
4 He aquí, que yo soy vil, ¿qué te responderé? Mi mano pongo sobre mi boca.
“Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà? Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
5 Una vez hablé, y no responderé; y dos veces; mas no tornaré a hablar.
Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́; lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”
6 Y respondió Jehová a Job desde la oscuridad, y dijo:
Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,
7 Cíñete ahora, como varón, tus lomos: yo te preguntaré, y házme saber.
“Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin, èmi ó bi ọ léèrè, kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
8 ¿Invalidarás tú también mi juicio? ¿condenarme has a mi para justificarte a ti?
“Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán? Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo.
9 ¿Tienes tú brazo como Dios? ¿y tronarás tú con voz como él?
Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
10 Ahora atavíate de magestad y de alteza, y vístete de honra y de hermosura.
Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́, tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
11 Esparce furores de tu ira, y mira a todo soberbio, y abátele.
Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde; kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
12 Mira a todo soberbio, y póstrale; y quebranta los impíos en su asiento.
Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀ kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
13 Encúbrelos a todos en el polvo; y ata sus rostros en oscuridad;
Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀, kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú.
14 Y yo también te confesaré, que tu diestra te salvará.
Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé, ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.
15 He aquí ahora Behemot, al cual yo hice contigo; yerba come como buey.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti, tí mo dá pẹ̀lú rẹ, òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
16 He aquí ahora que su fuerza está en sus lomos; y su fortaleza en el ombligo de su vientre:
Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
17 Su cola mueve como un cedro; y los nervios de sus genitales son entretejidos:
Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari, iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
18 Sus huesos son fuertes como acero, y sus miembros como barras de hierro:
Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ, Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
19 Él es la cabeza de los caminos de Dios: el que le hizo le acercará de su espada.
Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run; síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
20 Ciertamente los montes llevan renuevo para él; y toda bestia del campo retoza allá.
Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá, níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
21 Debajo de las sombras se echará, en lo oculto de las cañas, y de los lugares húmedos.
Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì, lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
22 Los árboles sombríos le cubren con su sombra; los sauces del arroyo le cercan.
Igi lótusì síji wọn bò o; igi arọrọ odò yí i káàkiri.
23 He aquí que él robará el río que no corra; y confíase que el Jordán pasará por su boca.
Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ; ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
24 El le tomará por sus ojos en los tropezaderos, y le horadará la nariz.
Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀, tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?

< Job 40 >